< Job 19 >
1 Ìgbà náà ni Jobu dáhùn, ó sì wí pé:
Wtedy Hiob odpowiedział:
2 “Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin ó fi máa fi ìyà jẹ mí, tí ẹ̀yin ó fi máa fi ọ̀rọ̀ yìí?
Jak długo będziecie dręczyć moją duszę [i] miażdżyć mnie słowami?
3 Ìgbà mẹ́wàá ní yin yọ mi lénu ẹ̀yin ti ń gàn mí; ojú kò tì yín tí ẹ fi jẹ mí ní yà.
Już dziesięć razy znieważyliście mnie. Nie wstyd wam, [że] tak się znęcacie nade mną?
4 Kí a sì wí bẹ́ẹ̀ pé, mo ṣìnà nítòótọ́, ìṣìnà mi wà lára èmi tìkára mi.
A niech tak będzie, że zbłądziłem, błąd zostaje po mojej stronie.
5 Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ẹ̀yin ó ṣògo si mi lórí nítòótọ́, tí ẹ ó sì máa fi ẹ̀gàn mi gún mí lójú,
A jeśli rzeczywiście chcecie się wynosić nade mną i dowodzić mi mojej hańby;
6 kí ẹ mọ̀ nísinsin yìí pé, Ọlọ́run ni ó bì mí ṣubú, ó sì nà àwọ̀n rẹ̀ yí mi ká.
Wiedzcie, że to Bóg mnie powalił i swoją siecią mnie otoczył.
7 “Kíyèsi, èmi ń kígbe pe, ‘Ọwọ́ alágbára!’ Ṣùgbọ́n a kò gbọ́ ti èmi; mo kígbe fún ìrànlọ́wọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ìdájọ́.
Oto wołam o krzywdę, ale nikt nie słucha; krzyczę, ale nie ma sądu.
8 Ó ṣọgbà dí ọ̀nà mi tí èmi kò le è kọjá, Ó sì mú òkùnkùn ṣú sí ipa ọ̀nà mi.
Zagrodził mi drogę, abym nie mógł przejść, i na moich ścieżkach rozpostarł ciemność.
9 Ó ti bọ́ ògo mi, ó sì ṣí adé kúrò ní orí mi.
Odarł mnie z mojej chwały i zdjął koronę z mojej głowy.
10 Ó ti bà mí jẹ́ ní ìhà gbogbo, ẹ̀mí sì pin; ìrètí mi ni a ó sì fàtu bí igi.
Zniszczył mnie ze wszystkich stron i ginę; moją nadzieję wyrwał jak drzewo.
11 Ó sì tiná bọ ìbínú rẹ̀ sí mi, ó sì kà mí sí bí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀tá rẹ̀.
Zapłonął przeciwko mnie swoim gniewem i uważa mnie za swego wroga.
12 Ẹgbẹ́ ogun rẹ̀ sì dàpọ̀ sí mi, wọ́n sì mọ odi yí mi ká, wọ́n sì yí àgọ́ mi ká.
Przyszły razem jego oddziały, utorowały przeciw mnie swoją drogę i rozbiły obóz dokoła mojego namiotu.
13 “Ó mú àwọn arákùnrin mi jìnà sí mi réré, àti àwọn ojúlùmọ̀ mi di àjèjì sí mi pátápátá.
Moich braci oddalił ode mnie, a moi znajomi ode mnie stronią.
14 Àwọn alájọbí mi fàsẹ́yìn, àwọn ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ mi sì di onígbàgbé mi.
Opuścili mnie moi bliscy, a moi przyjaciele o mnie zapomnieli.
15 Àwọn ará inú ilé mi àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin mi kà mí sí àjèjì; èmi jásí àjèjì ènìyàn ní ojú wọn.
Przebywający w moim domu i moje służące uważają mnie za obcego. Stałem się cudzoziemcem w ich oczach.
16 Mo pe ìránṣẹ́ mi, òun kò sì dá mi lóhùn; mo fi ẹnu mi bẹ̀ ẹ́.
Wołałem na swego sługę, ale on się nie odzywa, chociaż go błagam swoimi ustami.
17 Ẹ̀mí mi ṣú àyà mi, àti òórùn mi ṣú àwọn ọmọ inú ìyá mi.
Moim oddechem brzydzi się moja żona, choć błagam ze względu na synów z mojego ciała.
18 Àní àwọn ọmọdékùnrin fi mí ṣẹ̀sín, mo dìde, wọ́n sì sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi.
Nawet małe dzieci mną gardzą; gdy powstaję, urągają mi.
19 Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mi kórìíra mi, àwọn olùfẹ́ mi sì kẹ̀yìndà mí.
Brzydzą się mną wszyscy moi najbliżsi; ci, których kocham, stanęli przeciw mnie.
20 Egungun mi lẹ̀ mọ́ ara mi àti mọ́ ẹran-ara mi, mo sì yọ́ pẹ̀lú awọ eyín mi.
Moje kości przylgnęły do mojej skóry i do mego ciała; pozostała tylko skóra wokół zębów.
21 “Ẹ ṣàánú fún mi, ẹ ṣàánú fún mi, ẹ̀yin ọ̀rẹ́ mi, nítorí ọwọ́ Ọlọ́run ti bà mí.
Zlitujcie się nade mną, zlitujcie się nade mną, moi przyjaciele, bo ręka Boża mnie dotknęła.
22 Nítorí kí ni ẹ̀yin ṣe lépa mi bí Ọlọ́run, tí ẹran-ara mi kò tẹ́ yín lọ́rùn?
Czemu mnie prześladujecie jak Bóg? Czy nie dość wam mojego ciała?
23 “Háà! Ìbá ṣe pé a le kọ̀wé ọ̀rọ̀ mi nísinsin yìí, ìbá ṣe pé a le kọ ọ sínú ìwé!
Oby teraz zostały zapisane moje słowa! Oby je w księdze utrwalono!
24 Kí a fi kálámù irin àti ti òjé kọ wọ́n sínú àpáta fún láéláé.
Oby rylcem z żelaza i ołowiem zostały na wieczną pamiątkę wyryte na skale!
25 Nítorí èmi mọ̀ pé olùdáǹdè mi ń bẹ láààyè àti pe òun ni yóò dìde dúró lórí ilẹ̀ ní ìkẹyìn;
Wiem bowiem, że mój Odkupiciel żyje i że [w] ostateczny [dzień] stanie na ziemi.
26 àti lẹ́yìn ìgbà tí a pa àwọ̀ ara mi run, síbẹ̀ láìsí ẹran-ara mi ni èmi ó rí Ọlọ́run,
A [choć] moja skóra się rozłoży, to w swoim ciele ujrzę Boga.
27 ẹni tí èmi ó rí fún ara mi, tí ojú mi ó sì wo, kì sì í ṣe ti ẹlòmíràn; ọkàn mi sì dákú ní inú mi.
Ujrzę go ja sam, ujrzą go moje oczy, a nie kto inny, choć moje nerki zniszczały w moim wnętrzu.
28 “Bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Àwa ó ti lépa rẹ̀ tó! Àti pé, gbogbo ọ̀rọ̀ náà ni a sá à rí ní ọwọ́ rẹ̀,’
Powinniście mówić: Czemu go prześladujemy? Gdyż we mnie znajduje się korzeń sprawy.
29 kí ẹ̀yin kí ó bẹ̀rù, nítorí ìbínú ní í mú ìjìyà wá nípa idà, kí ẹ̀yin kí ó lè mọ̀ pé ìdájọ́ kan ń bẹ.”
Wy sami lękajcie się miecza, bo gniew za nieprawość sprowadza miecz, abyście wiedzieli, że jest sąd.