< Job 18 >
1 Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, dáhùn, ó sì wí pé,
Y RESPONDIÓ Bildad Suhita, y dijo:
2 “Nígbà wo ni ẹ̀yin yóò tó fi ìdí ọ̀rọ̀ tì; ẹ rò ó, nígbẹ̀yìn rẹ̀ ni àwa ó tó máa sọ.
¿Cuándo pondréis fin á las palabras? Entended, y después hablemos.
3 Nítorí kí ni a ṣe ń kà wá sí bí ẹranko, tí a sì ń kà wá si bí ẹni ẹ̀gàn ní ojú yín?
¿Por qué somos tenidos por bestias, y en vuestros ojos somos viles?
4 Ìwọ fa ara rẹ ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ nínú ìbínú rẹ̀; kí a ha kọ ayé sílẹ̀ nítorí rẹ̀ bi? Tàbí kí a sí àpáta kúrò ní ipò rẹ̀?
Oh tú, que despedazas tu alma con tu furor, ¿será dejada la tierra por tu causa, y serán traspasadas de su lugar las peñas?
5 “Nítòótọ́ ìmọ́lẹ̀ ènìyàn búburú ni a ó pa kúrò, ọ̀wọ́-iná rẹ̀ kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀.
Ciertamente la luz de los impíos será apagada, y no resplandecerá la centella de su fuego.
6 Ìmọ́lẹ̀ yóò di òkùnkùn nínú àgọ́ rẹ̀, fìtílà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni a ó sì pa pẹ̀lú.
La luz se oscurecerá en su tienda, y apagaráse sobre él su lámpara.
7 Ìrìn ẹsẹ̀ agbára rẹ̀ yóò di fífọ; ète òun tìkára rẹ̀ ni yóò bí i ṣubú.
Los pasos de su pujanza serán acortados, y precipitarálo su mismo consejo.
8 Nípa ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀ ó ti bọ́ sínú àwọ̀n, ó sì rìn lórí okùn dídẹ.
Porque red será echada en sus pies, y sobre red andará.
9 Tàkúté ni yóò mú un ní gìgísẹ̀, àwọn àwọ̀n tí a dẹ yóò sì ṣẹ́gun rẹ̀.
Lazo prenderá [su] calcañar: afirmaráse la trampa contra él.
10 A dẹkùn sílẹ̀ fún un lórí ilẹ̀, a sì wà ọ̀fìn fún un lójú ọ̀nà.
Su cuerda está escondida en la tierra, y su torzuelo sobre la senda.
11 Ẹ̀rù ńlá yóò bà á ní ìhà gbogbo, yóò sì lé e dé ẹsẹ̀ rẹ̀.
De todas partes lo asombrarán temores, y haránle huir desconcertado.
12 Àìlera rẹ̀ yóò di púpọ̀ fún ebi, ìparun yóò dìde dúró sí i nígbà tí ó bá ṣubú.
Su fuerza será hambrienta, y á su lado estará aparejado quebrantamiento.
13 Yóò jẹ ẹ̀yà ara rẹ̀; ikú àkọ́bí ni yóò jẹ agbára rẹ̀ run.
El primogénito de la muerte comerá los ramos de su piel, y devorará sus miembros.
14 A ó fà á tu kúrò nínú àgọ́ tí ó gbẹ́kẹ̀lé, a ó sì mú un tọ ọba ẹ̀rù ńlá nì lọ.
Su confianza será arrancada de su tienda, y harále esto llevar al rey de los espantos.
15 Yóò sì máa jókòó nínú àgọ́ rẹ̀ èyí tí í ṣe tirẹ̀; sulfuru ti o jóná ni a ó fún káàkiri ibùgbé rẹ̀.
En su tienda morará como si no fuese suya: piedra azufre será esparcida sobre su morada.
16 Gbòǹgbò rẹ̀ yóò gbẹ níṣàlẹ̀, a ó sì ké ẹ̀ka rẹ̀ kúrò lókè.
Abajo se secarán sus raíces, y arriba serán cortadas sus ramas.
17 Ìrántí rẹ̀ yóò parun kúrò ni ayé, kì yóò sí orúkọ rẹ̀ ní ìgboro ìlú.
Su memoria perecerá de la tierra, y no tendrá nombre por las calles.
18 A ó sì lé e láti inú ìmọ́lẹ̀ sí inú òkùnkùn, a ó sì lé e kúrò ní ayé.
De la luz será lanzado á las tinieblas, y echado fuera del mundo.
19 Kì yóò ní ọmọ tàbí ọmọ ọmọ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò kù nínú agbo ilé rẹ̀.
No tendrá hijo ni nieto en su pueblo, ni quien [le] suceda en sus moradas.
20 Ẹnu yóò ya àwọn ìran ti ìwọ̀-oòrùn sí ìgbà ọjọ́ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù ìwárìrì ti í bá àwọn ìran ti ìlà-oòrùn.
Sobre su día se espantarán los por venir, como ocupó el pavor á los que fueron antes.
21 Nítòótọ́ irú bẹ́ẹ̀ ni ibùgbé àwọn ènìyàn búburú, èyí sì ni ipò ẹni tí kò mọ̀ Ọlọ́run.”
Ciertamente tales son las moradas del impío, y este será el lugar del que no conoció á Dios.