< Job 18 >

1 Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, dáhùn, ó sì wí pé,
A LAILA olelo aku o Biledada, no Suha, i mai la,
2 “Nígbà wo ni ẹ̀yin yóò tó fi ìdí ọ̀rọ̀ tì; ẹ rò ó, nígbẹ̀yìn rẹ̀ ni àwa ó tó máa sọ.
Ahea la e hoopau oe i na huaolelo? E noonoo, a mahope iho e olelo aku makou.
3 Nítorí kí ni a ṣe ń kà wá sí bí ẹranko, tí a sì ń kà wá si bí ẹni ẹ̀gàn ní ojú yín?
No ke aha la e mauaoia makou, e like me ua holoholona, A ua haumia imua o kou mau maka?
4 Ìwọ fa ara rẹ ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ nínú ìbínú rẹ̀; kí a ha kọ ayé sílẹ̀ nítorí rẹ̀ bi? Tàbí kí a sí àpáta kúrò ní ipò rẹ̀?
Haehae no oia ia ia iho ma kona huhu: E haaleleia anei ka honua nou? A e hooneeia aku anei ka pohaku mai kona wahi aku?
5 “Nítòótọ́ ìmọ́lẹ̀ ènìyàn búburú ni a ó pa kúrò, ọ̀wọ́-iná rẹ̀ kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀.
O ka malamalama o ka poe hewa e pio ana no ia, Aole hoi e hoomalamalama mai ka lapalapa o kona ahi.
6 Ìmọ́lẹ̀ yóò di òkùnkùn nínú àgọ́ rẹ̀, fìtílà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni a ó sì pa pẹ̀lú.
O ka malamalama he pouli ia iloko o kona halelewa, A o kona kukui me ia, e pio no ia.
7 Ìrìn ẹsẹ̀ agbára rẹ̀ yóò di fífọ; ète òun tìkára rẹ̀ ni yóò bí i ṣubú.
E hoopilikiaia kona hele ikaika, A e hookulaina kona noonoo ana ia ia.
8 Nípa ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀ ó ti bọ́ sínú àwọ̀n, ó sì rìn lórí okùn dídẹ.
No ka mea, ua hooheiia oia i ka upena ma kona wawae, A e hele ana no ia maluna o ka pahele.
9 Tàkúté ni yóò mú un ní gìgísẹ̀, àwọn àwọ̀n tí a dẹ yóò sì ṣẹ́gun rẹ̀.
E hoopaa ke kipuka ia ia ma ke kuekuewawae, E hanapaa hoi ke pahele ia ia.
10 A dẹkùn sílẹ̀ fún un lórí ilẹ̀, a sì wà ọ̀fìn fún un lójú ọ̀nà.
Ua hunaia ma ka lepo ke pahele nona, A me ka upiki nona ma ke ala.
11 Ẹ̀rù ńlá yóò bà á ní ìhà gbogbo, yóò sì lé e dé ẹsẹ̀ rẹ̀.
Ua hooweliweli na mea makau ia ia a puni, A e alualu ia ia ma kona wawae.
12 Àìlera rẹ̀ yóò di púpọ̀ fún ebi, ìparun yóò dìde dúró sí i nígbà tí ó bá ṣubú.
E nawaliwali kona ikaika no ka pololi, A e makaukau ka make ma kona aoao.
13 Yóò jẹ ẹ̀yà ara rẹ̀; ikú àkọ́bí ni yóò jẹ agbára rẹ̀ run.
E ai no ia i na apana o kona ili, O ka hanau mua o ka make, e hoopau no ia i kona mau lala.
14 A ó fà á tu kúrò nínú àgọ́ tí ó gbẹ́kẹ̀lé, a ó sì mú un tọ ọba ẹ̀rù ńlá nì lọ.
E kailiia kona mea i paa ai, mai kona halelewa aku, A e lawe aku no ia ia ia i ke alii weliweli.
15 Yóò sì máa jókòó nínú àgọ́ rẹ̀ èyí tí í ṣe tirẹ̀; sulfuru ti o jóná ni a ó fún káàkiri ibùgbé rẹ̀.
E noho no ia mea iloko o kona halelewa, no ka mea, aohe nona ia; E luluia ka luaipele maluna o kona hale.
16 Gbòǹgbò rẹ̀ yóò gbẹ níṣàlẹ̀, a ó sì ké ẹ̀ka rẹ̀ kúrò lókè.
Malalo e maloo kona mau aa, A maluna e okiia'ku kona lala.
17 Ìrántí rẹ̀ yóò parun kúrò ni ayé, kì yóò sí orúkọ rẹ̀ ní ìgboro ìlú.
E nalowale kona hoomanaoia mai ka honua aku, Aole inoa nona ma ke alanui.
18 A ó sì lé e láti inú ìmọ́lẹ̀ sí inú òkùnkùn, a ó sì lé e kúrò ní ayé.
E hookuke aku lakou ia ia mai ka malamalama a i ka pouli, A e alualu ia ia mai ka honua aku.
19 Kì yóò ní ọmọ tàbí ọmọ ọmọ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò kù nínú agbo ilé rẹ̀.
Aohe ana keiki, aohe hoi mamo mawaena o kona poe kanaka, Aole hoi he mea i koe iloko o kona mau hale.
20 Ẹnu yóò ya àwọn ìran ti ìwọ̀-oòrùn sí ìgbà ọjọ́ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù ìwárìrì ti í bá àwọn ìran ti ìlà-oòrùn.
O na hanauna mahope e kahaha lakou no kona manawa, A loaa i na kupuna ka makau.
21 Nítòótọ́ irú bẹ́ẹ̀ ni ibùgbé àwọn ènìyàn búburú, èyí sì ni ipò ẹni tí kò mọ̀ Ọlọ́run.”
He oiaio, oia na wahi noho o ka poe hewa, A oia kahi o ka mea ike ole i ke Akua.

< Job 18 >