< Job 17 >

1 “Ẹ̀mí mi bàjẹ́, ọjọ́ mi ni a ti gé kúrú, isà òkú dúró dè mí.
Dech mój skażony jest; dni moje giną; groby mię czekają.
2 Nítòótọ́ àwọn ẹlẹ́yà wà lọ́dọ̀ mi, ojú mi sì tẹ̀mọ́ ìmúnibínú wọn.
Zaiste naśmiewcy są przy mnie, a w ich draźnieniu mieszka oko moje.
3 “Fi fún mi Olúwa, ìlérí tí ìwọ fẹ́; ta ni yóò le ṣe ààbò fún mi?
Staw mi, proszę, rękojmię za się. Któż jest ten? Niech mi na to da rękę.
4 Nítorí pé ìwọ ti sé wọ́n láyà kúrò nínú òye; nítorí náà ìwọ kì yóò gbé wọn lékè.
Boś serce ich ukrył przed wyrozumieniem; przetoż ich nie wywyższysz.
5 Ẹni tí ó sọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn dídún fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ fún èrè, òun ni ojú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò mú òfo.
Kto pochlebia przyjaciołom, oczy synów jego ustaną.
6 “Ọlọ́run ti sọ mi di ẹni òwe fún àwọn ènìyàn; níwájú wọn ni mo dàbí ẹni ìtutọ́ sí ní ojú.
Wystawił mię zaiste na przypowieść ludziom, i jako śmiechowisko przed nimi.
7 Ojú mí ṣú bàìbàì nítorí ìbìnújẹ́, gbogbo ẹ̀yà ara mi sì dàbí òjìji.
Zaćmione jest dla żałości oko moje, a wszystkie myśli moje są jako cień.
8 Àwọn olódodo yóò yanu sí èyí, ẹni aláìṣẹ̀ sì bínú sí àwọn àgàbàgebè.
Zdumieją się szczerzy nad tem; a niewinny przeciwko obłudnikowi powstanie.
9 Olódodo pẹ̀lú yóò di ọ̀nà rẹ̀ mú, àti ọlọ́wọ́ mímọ́ yóò máa lera síwájú.
Będzie się trzymał sprawiedliwy drogi swojej; a kto ma czyste ręce, przyczyni mocy.
10 “Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti gbogbo yín, ẹ yípadà, kí ẹ si tún padà nísinsin yìí; èmi kò le rí ọlọ́gbọ́n kan nínú yín.
Wy tedy wszyscy nawróćcie się, a pójdźcie, proszę; bo nie znajduję między wami mądrego.
11 Ọjọ́ tí èmi ti kọjá, ìrò mi ti fà yá, àní ìrò ọkàn mi.
Dni moje przeminęły; myśli moje rozerwane są, to jest, zamysły serca mego.
12 Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń ṣọ́ òru di ọ̀sán; wọ́n ní, ìmọ́lẹ̀ súnmọ́ ibi tí òkùnkùn dé.
Noc mi się w dzień obraca; a światłość skraca się dla ciemości.
13 Bí mo tilẹ̀ ní ìrètí, ipò òku ní ilé mi; mo ti tẹ́ ibùsùn mi sínú òkùnkùn. (Sheol h7585)
Jeźlibym czego oczekiwał, grób będzie domem moim, a w ciemnościach uścielę łoże moje. (Sheol h7585)
14 Èmi ti wí fún ìdíbàjẹ́ pé, ìwọ ni baba mi, àti fún kòkòrò pé, ìwọ ni ìyá mi àti arábìnrin mi,
Do dołu rzekę: Ojcem moim jesteś; a do robaków: Wy jesteście matką moją, i siostrą moją.
15 ìrètí mi ha dà nísinsin yìí? Bí ó ṣe ti ìrètí mi ni, ta ni yóò rí i?
Bo gdzież teraz jest nadzieja moja? a oczekiwanie moje któż ogląda?
16 Yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ipò òkú, nígbà tí a jùmọ̀ sinmi pọ̀ nínú erùpẹ̀ ilẹ̀?” (Sheol h7585)
W głębię grobu zstąpię, ponieważ w prochu spólny odpoczynek wszystkich. (Sheol h7585)

< Job 17 >