< Job 17 >
1 “Ẹ̀mí mi bàjẹ́, ọjọ́ mi ni a ti gé kúrú, isà òkú dúró dè mí.
Je péris emporté par une tempête; j'aspire à la tombe et je n'y puis arriver.
2 Nítòótọ́ àwọn ẹlẹ́yà wà lọ́dọ̀ mi, ojú mi sì tẹ̀mọ́ ìmúnibínú wọn.
Je péris dans mon affliction; et vous, Seigneur, qu'avez-vous fait?
3 “Fi fún mi Olúwa, ìlérí tí ìwọ fẹ́; ta ni yóò le ṣe ààbò fún mi?
Des étrangers m'ont enlevé mes richesses: Quel est cet homme? qu'il soit enchaîné par ma main.
4 Nítorí pé ìwọ ti sé wọ́n láyà kúrò nínú òye; nítorí náà ìwọ kì yóò gbé wọn lékè.
Vous avez rendu leur cœur inaccessible à la raison; gardez-vous de les glorifier.
5 Ẹni tí ó sọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn dídún fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ fún èrè, òun ni ojú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò mú òfo.
Cet homme n'a rien à dire à ses amis que des méchancetés; et ses yeux ont fondu en larmes à cause de ses fils.
6 “Ọlọ́run ti sọ mi di ẹni òwe fún àwọn ènìyàn; níwájú wọn ni mo dàbí ẹni ìtutọ́ sí ní ojú.
O mon Dieu, vous avez fait de moi la fable des nations; je suis devenu pour elles un objet de risée.
7 Ojú mí ṣú bàìbàì nítorí ìbìnújẹ́, gbogbo ẹ̀yà ara mi sì dàbí òjìji.
La colère alors a séché mes pleurs, et j'ai été vivement assiégé de toutes parts.
8 Àwọn olódodo yóò yanu sí èyí, ẹni aláìṣẹ̀ sì bínú sí àwọn àgàbàgebè.
Les gens sincères à cause de moi sont saisis de surprise, ils s'écrient: Puisse le juste s'élever au-dessus du méchant!
9 Olódodo pẹ̀lú yóò di ọ̀nà rẹ̀ mú, àti ọlọ́wọ́ mímọ́ yóò máa lera síwájú.
Que le fidèle persévère dans sa voie, que l'homme dont les mains sont pures prenne courage.
10 “Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti gbogbo yín, ẹ yípadà, kí ẹ si tún padà nísinsin yìí; èmi kò le rí ọlọ́gbọ́n kan nínú yín.
Et vous tous approchez, écoutez-moi, je ne trouve point la vérité en vous.
11 Ọjọ́ tí èmi ti kọjá, ìrò mi ti fà yá, àní ìrò ọkàn mi.
J'ai passé mes jours à murmurer, et toutes les parties de mon cœur ont été déchirées.
12 Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń ṣọ́ òru di ọ̀sán; wọ́n ní, ìmọ́lẹ̀ súnmọ́ ibi tí òkùnkùn dé.
J'ai confondu la nuit avec le jour; la lumière avec l'obscurité.
13 Bí mo tilẹ̀ ní ìrètí, ipò òku ní ilé mi; mo ti tẹ́ ibùsùn mi sínú òkùnkùn. (Sheol )
Tout ce que j'ai à attendre, c'est la terre pour demeure; ma couche est déjà étendue dans les ténèbres. (Sheol )
14 Èmi ti wí fún ìdíbàjẹ́ pé, ìwọ ni baba mi, àti fún kòkòrò pé, ìwọ ni ìyá mi àti arábìnrin mi,
J'ai surnommé la mort mon père; ma mère et ma sœur, c'est la pourriture.
15 ìrètí mi ha dà nísinsin yìí? Bí ó ṣe ti ìrètí mi ni, ta ni yóò rí i?
Où est donc mon espoir? quels sont les biens que je verrai?
16 Yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ipò òkú, nígbà tí a jùmọ̀ sinmi pọ̀ nínú erùpẹ̀ ilẹ̀?” (Sheol )
Est-ce que mon espoir et mes biens descendront avec moi sous la terre? Est-ce que nous serons placés ensemble dans le sépulcre? (Sheol )