< Job 17 >
1 “Ẹ̀mí mi bàjẹ́, ọjọ́ mi ni a ti gé kúrú, isà òkú dúró dè mí.
Mon souffle est corrompu, mes jours s’éteignent: pour moi sont les sépulcres!
2 Nítòótọ́ àwọn ẹlẹ́yà wà lọ́dọ̀ mi, ojú mi sì tẹ̀mọ́ ìmúnibínú wọn.
Les moqueurs ne sont-ils pas autour de moi, et mes yeux ne demeurent-ils pas au milieu de leurs insultes?
3 “Fi fún mi Olúwa, ìlérí tí ìwọ fẹ́; ta ni yóò le ṣe ààbò fún mi?
Dépose, je te prie, [un gage]; cautionne-moi auprès de toi-même: qui donc frappera dans ma main?
4 Nítorí pé ìwọ ti sé wọ́n láyà kúrò nínú òye; nítorí náà ìwọ kì yóò gbé wọn lékè.
Car tu as fermé leur cœur à l’intelligence; c’est pourquoi tu ne les élèveras pas.
5 Ẹni tí ó sọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn dídún fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ fún èrè, òun ni ojú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò mú òfo.
Celui qui trahit ses amis pour qu’ils soient pillés, les yeux de ses fils seront consumés.
6 “Ọlọ́run ti sọ mi di ẹni òwe fún àwọn ènìyàn; níwájú wọn ni mo dàbí ẹni ìtutọ́ sí ní ojú.
Et il a fait de moi un proverbe des peuples, et je suis devenu un homme auquel on crache au visage.
7 Ojú mí ṣú bàìbàì nítorí ìbìnújẹ́, gbogbo ẹ̀yà ara mi sì dàbí òjìji.
Mon œil est terni par le chagrin, et mes membres sont tous comme une ombre.
8 Àwọn olódodo yóò yanu sí èyí, ẹni aláìṣẹ̀ sì bínú sí àwọn àgàbàgebè.
Les hommes droits en seront étonnés, et l’innocent s’élèvera contre l’impie;
9 Olódodo pẹ̀lú yóò di ọ̀nà rẹ̀ mú, àti ọlọ́wọ́ mímọ́ yóò máa lera síwájú.
Mais le juste tiendra ferme dans sa voie, et celui qui a les mains pures croîtra en force.
10 “Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti gbogbo yín, ẹ yípadà, kí ẹ si tún padà nísinsin yìí; èmi kò le rí ọlọ́gbọ́n kan nínú yín.
Mais quant à vous tous, revenez encore, je vous prie; mais je ne trouverai pas un sage parmi vous.
11 Ọjọ́ tí èmi ti kọjá, ìrò mi ti fà yá, àní ìrò ọkàn mi.
Mes jours sont passés, mes desseins sont frustrés, – les plans chéris de mon cœur.
12 Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń ṣọ́ òru di ọ̀sán; wọ́n ní, ìmọ́lẹ̀ súnmọ́ ibi tí òkùnkùn dé.
Ils font de la nuit le jour, la lumière proche en présence des ténèbres.
13 Bí mo tilẹ̀ ní ìrètí, ipò òku ní ilé mi; mo ti tẹ́ ibùsùn mi sínú òkùnkùn. (Sheol )
Si j’espère, le shéol est ma maison, j’étends mon lit dans les ténèbres; (Sheol )
14 Èmi ti wí fún ìdíbàjẹ́ pé, ìwọ ni baba mi, àti fún kòkòrò pé, ìwọ ni ìyá mi àti arábìnrin mi,
Je crie à la fosse: Tu es mon père! aux vers: Ma mère et ma sœur!
15 ìrètí mi ha dà nísinsin yìí? Bí ó ṣe ti ìrètí mi ni, ta ni yóò rí i?
Où donc est mon espoir? Et mon espoir, qui le verra?
16 Yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ipò òkú, nígbà tí a jùmọ̀ sinmi pọ̀ nínú erùpẹ̀ ilẹ̀?” (Sheol )
Il descendra vers les barres du shéol, lorsque ensemble nous aurons du repos dans la poussière. (Sheol )