< Job 17 >
1 “Ẹ̀mí mi bàjẹ́, ọjọ́ mi ni a ti gé kúrú, isà òkú dúró dè mí.
My breath is corrupt, my days are extinct, the graves are mine.
2 Nítòótọ́ àwọn ẹlẹ́yà wà lọ́dọ̀ mi, ojú mi sì tẹ̀mọ́ ìmúnibínú wọn.
Are there not mockers around me? and doth [not] mine eye abide in their provocation?
3 “Fi fún mi Olúwa, ìlérí tí ìwọ fẹ́; ta ni yóò le ṣe ààbò fún mi?
Lay down now [a pledge], be thou surety for me with thyself: who is he that striketh hands with me?
4 Nítorí pé ìwọ ti sé wọ́n láyà kúrò nínú òye; nítorí náà ìwọ kì yóò gbé wọn lékè.
For thou hast hidden their heart from understanding; therefore thou wilt not exalt [them].
5 Ẹni tí ó sọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn dídún fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ fún èrè, òun ni ojú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò mú òfo.
He that betrayeth friends for a prey — even the eyes of his children shall fail.
6 “Ọlọ́run ti sọ mi di ẹni òwe fún àwọn ènìyàn; níwájú wọn ni mo dàbí ẹni ìtutọ́ sí ní ojú.
And he hath made me a proverb of the peoples; and I am become one to be spit on in the face.
7 Ojú mí ṣú bàìbàì nítorí ìbìnújẹ́, gbogbo ẹ̀yà ara mi sì dàbí òjìji.
And mine eye is dim by reason of grief, and all my members are as a shadow.
8 Àwọn olódodo yóò yanu sí èyí, ẹni aláìṣẹ̀ sì bínú sí àwọn àgàbàgebè.
Upright men [shall be] astonished at this, and the innocent shall be stirred up against the ungodly;
9 Olódodo pẹ̀lú yóò di ọ̀nà rẹ̀ mú, àti ọlọ́wọ́ mímọ́ yóò máa lera síwájú.
But the righteous shall hold on his way, and he that hath clean hands shall increase in strength.
10 “Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti gbogbo yín, ẹ yípadà, kí ẹ si tún padà nísinsin yìí; èmi kò le rí ọlọ́gbọ́n kan nínú yín.
But as for you all, pray come on again; and I shall not find one wise man among you.
11 Ọjọ́ tí èmi ti kọjá, ìrò mi ti fà yá, àní ìrò ọkàn mi.
My days are past, my purposes are broken off, the cherished thoughts of my heart.
12 Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń ṣọ́ òru di ọ̀sán; wọ́n ní, ìmọ́lẹ̀ súnmọ́ ibi tí òkùnkùn dé.
They change the night into day; the light [they imagine] near in presence of the darkness.
13 Bí mo tilẹ̀ ní ìrètí, ipò òku ní ilé mi; mo ti tẹ́ ibùsùn mi sínú òkùnkùn. (Sheol )
If I wait, Sheol is my house; I spread my bed in the darkness: (Sheol )
14 Èmi ti wí fún ìdíbàjẹ́ pé, ìwọ ni baba mi, àti fún kòkòrò pé, ìwọ ni ìyá mi àti arábìnrin mi,
I cry to the grave, Thou art my father! to the worm, My mother, and my sister!
15 ìrètí mi ha dà nísinsin yìí? Bí ó ṣe ti ìrètí mi ni, ta ni yóò rí i?
And where is then my hope? yea, my hope, who shall see it?
16 Yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ipò òkú, nígbà tí a jùmọ̀ sinmi pọ̀ nínú erùpẹ̀ ilẹ̀?” (Sheol )
It shall go down to the bars of Sheol, when [our] rest shall be together in the dust. (Sheol )