< Job 16 >

1 Ìgbà náà ní Jobu dáhùn, ó sì wí pé,
Wtedy Hiob odpowiedział:
2 “Èmi ti gbọ́ irú ohun púpọ̀ bẹ́ẹ̀ rí ayọnilẹ́nu onítùnú ènìyàn ní gbogbo yín.
Słyszałem wiele takich rzeczy; wy wszyscy jesteście przykrymi pocieszycielami.
3 Ọ̀rọ̀ asán lè ni òpin? Tàbí kí ni ó gbó ọ láyà tí ìwọ fi dáhùn?
Kiedy [będzie] koniec tych próżnych słów? Albo co cię skłania do tego, że tak odpowiadasz?
4 Èmi pẹ̀lú le sọ bí ẹ̀yin; bí ọkàn yín bá wà ní ipò ọkàn mi, èmi le sọ ọ̀rọ̀ dáradára púpọ̀ sí yín ní ọrùn, èmi a sì mi orí mi sí i yín.
Ja także mógłbym mówić jak wy; gdybyście byli w moim położeniu, mógłbym nagromadzić słów przeciwko wam i potrząsać głową nad wami.
5 Èmi ìbá fi ọ̀rọ̀ ẹnu mi gbà yín ni ìyànjú, àti ṣíṣí ètè mi ìbá sì tu ìbìnújẹ́ yín.
Ja jednak pokrzepiałbym was swoimi ustami i poruszanie moich warg ulżyłoby [waszym cierpieniom].
6 “Bí èmi tilẹ̀ sọ̀rọ̀, ìbìnújẹ́ mi kò lọ; bí mo sì tilẹ̀ dákẹ́, níbo ni ìtùnú mí ko kúrò?
[Ale] jeśli będę mówił, mojemu bólowi to nie ulży, a jeśli przestanę, czyż opuści mnie?
7 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó dá mi lágara; ìwọ Ọlọ́run mú gbogbo ẹgbẹ́ mi takété.
A teraz zmęczył mnie. Spustoszyłeś całe moje zgromadzenie.
8 Ìwọ fi ìhunjọ kùn mí lára, èyí tí o jẹ́rìí tì mí; àti rírù tí ó hàn lára mi, ó jẹ́rìí tì mí ní ojú.
Pomarszczyłeś mnie na świadectwo, a moje wychudzenie powstaje i świadczy przeciwko mnie w twarz.
9 Ọlọ́run fi i ìbínú rẹ̀ fà mí ya, ó sì gbóguntì mí; ó pa eyín rẹ̀ keke sí mi, ọ̀tá mi sì gbójú rẹ̀ sí mi.
Jego gniew [mnie] porwał, nienawidzi mnie; zgrzyta na mnie zębami. Mój wróg przeszywa mnie wzrokiem.
10 Wọ́n ti fi ẹnu wọn yẹ̀yẹ́ mi; Wọ́n gbá mi ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ ni ìgbá ẹ̀gàn; wọ́n kó ara wọn pọ̀ sí mi.
Otworzyli na mnie swe usta; znieważając, bili mnie po policzkach; zebrali się razem przeciwko mnie.
11 Ọlọ́run ti fi mí lé ọwọ́ ẹni búburú, ó sì mú mi ṣubú sí ọwọ́ ènìyàn ìkà.
Bóg wydał mnie przewrotnemu, oddał mnie w ręce niegodziwych.
12 Mo ti jókòó jẹ́ẹ́, ṣùgbọ́n ó fà mí já; ó sì dì mí ni ọrùn mú, ó sì gbọ̀n mí túútúú, ó sì gbé mi kalẹ̀ láti ṣe àmì ìtafàsí rẹ̀;
Żyłem w spokoju, ale on mnie pokruszył; chwycił mnie za kark, roztrzaskał i postawił sobie za cel.
13 àwọn tafàtafà rẹ̀ dúró yí mi káàkiri. Ó là mí láyà pẹ̀rẹ̀, kò si dá sí, ó sì tú òróòro ara mi dà sílẹ̀.
Otoczyli mnie jego strzelcy; przeszywa moje nerki, a nie oszczędził; wylał na ziemię moją żółć.
14 Ìbàjẹ́ lórí ìbàjẹ́ ní ó fi bà mí jẹ́; ó súré kọlù mi bí jagunjagun.
Rozbija mnie, ranę za raną; naciera na mnie jak olbrzym.
15 “Mo rán aṣọ ọ̀fọ̀ bò ara mi, mo sì rẹ̀ ìwo mi sílẹ̀ nínú erùpẹ̀.
Uszyłem wór na swoją skórę i prochem zbezcześciłem swój róg.
16 Ojú mi ti pọ́n fún ẹkún, òjìji ikú sì ṣẹ́ sí ìpéǹpéjú mi.
Moja twarz jest czerwona od płaczu i na moich powiekach [jest] cień śmierci.
17 Kì í ṣe nítorí àìṣòótọ́ kan ní ọwọ́ mi; àdúrà mi sì mọ́ pẹ̀lú.
Chociaż nie ma żadnej krzywdy na moich rękach, a moja modlitwa jest czysta.
18 “Háà! Ilẹ̀ ayé, ìwọ má ṣe bò ẹ̀jẹ̀ mi, kí ẹkún mi má ṣe wà ní ipò kan.
Ziemio, nie zakrywaj mojej krwi i niech moje wołanie nie znajdzie miejsca!
19 Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi i, ẹlẹ́rìí mi ń bẹ ní ọ̀run, ẹ̀rí mi sì ń bẹ lókè ọ̀run.
Oto teraz mój świadek jest w niebie, mój obrońca na wysokości.
20 Àwọn ọ̀rẹ́ mi ń fi mí ṣẹ̀sín, ṣùgbọ́n ojú mi ń da omijé sọ́dọ̀ Ọlọ́run,
Moi przyjaciele szydzą ze mnie, ale moje oko wylewa łzy ku Bogu.
21 ìbá ṣe pé ẹnìkan le è máa ṣe alágbàwí fún ẹnìkejì lọ́dọ̀ Ọlọ́run, bí ènìyàn kan ti í ṣe alágbàwí fún ẹnìkejì rẹ̀.
Oby ktoś spierał się z Bogiem o człowieka jak człowiek [spiera się] o swego bliźniego!
22 “Nítorí nígbà tí iye ọdún díẹ̀ rékọjá tán, nígbà náà ni èmi ó lọ sí ibi tí èmi kì yóò padà bọ̀.”
Upłynie bowiem niewiele lat, a pójdę ścieżką, skąd nie powrócę.

< Job 16 >