< Job 16 >
1 Ìgbà náà ní Jobu dáhùn, ó sì wí pé,
Ale odpowiedział Ijob, i rzekł:
2 “Èmi ti gbọ́ irú ohun púpọ̀ bẹ́ẹ̀ rí ayọnilẹ́nu onítùnú ènìyàn ní gbogbo yín.
Słyszałem takowych rzeczy wiele; przykrymi cieszycielami wy wszyscy jesteście.
3 Ọ̀rọ̀ asán lè ni òpin? Tàbí kí ni ó gbó ọ láyà tí ìwọ fi dáhùn?
I kiedyż będzie koniec tym próżnym słowom? albo co cię przymusza, że tak odpowiadasz?
4 Èmi pẹ̀lú le sọ bí ẹ̀yin; bí ọkàn yín bá wà ní ipò ọkàn mi, èmi le sọ ọ̀rọ̀ dáradára púpọ̀ sí yín ní ọrùn, èmi a sì mi orí mi sí i yín.
Azażbym ja tak mówił, jako wy, gdybyście wy byli na miejscu mojem? azażbym zbierał przeciwko wam słowa, i kiwałlibym nad wami głową swoją?
5 Èmi ìbá fi ọ̀rọ̀ ẹnu mi gbà yín ni ìyànjú, àti ṣíṣí ètè mi ìbá sì tu ìbìnújẹ́ yín.
Owszembym was posilał ustami memi, a ruchanie warg moich ulżyłoby boleści waszych.
6 “Bí èmi tilẹ̀ sọ̀rọ̀, ìbìnújẹ́ mi kò lọ; bí mo sì tilẹ̀ dákẹ́, níbo ni ìtùnú mí ko kúrò?
Ale jeźli będę mówił, przecież się nie ukoi boleść moja; a jeźli też przestanę, izaż odejdzie odemnie?
7 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó dá mi lágara; ìwọ Ọlọ́run mú gbogbo ẹgbẹ́ mi takété.
A teraz zemdlił mię; spustoszyłeś, o Boże! wszystko zgromadzenie moje.
8 Ìwọ fi ìhunjọ kùn mí lára, èyí tí o jẹ́rìí tì mí; àti rírù tí ó hàn lára mi, ó jẹ́rìí tì mí ní ojú.
Pomarszczyłeś mię na świadectwo, a znaczne na mnie schudzenie moje na twarzy mojej, jawnie świadczy przeciwko mnie.
9 Ọlọ́run fi i ìbínú rẹ̀ fà mí ya, ó sì gbóguntì mí; ó pa eyín rẹ̀ keke sí mi, ọ̀tá mi sì gbójú rẹ̀ sí mi.
Popędliwość jego porwała mię, i wziął nienawiść przeciwko mnie; a zgrzytając na mię zębami swemi, jako nieprzyjaciel mój, bystremi oczyma swemi spojrzał na mię.
10 Wọ́n ti fi ẹnu wọn yẹ̀yẹ́ mi; Wọ́n gbá mi ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ ni ìgbá ẹ̀gàn; wọ́n kó ara wọn pọ̀ sí mi.
Rozdzierają na mię usta swe, i sromotnie mię policzkowali, zebrawszy się społu przeciwko mnie.
11 Ọlọ́run ti fi mí lé ọwọ́ ẹni búburú, ó sì mú mi ṣubú sí ọwọ́ ènìyàn ìkà.
Podał mię Bóg przewrotnemu, a w ręce niepobożnych wydał mię.
12 Mo ti jókòó jẹ́ẹ́, ṣùgbọ́n ó fà mí já; ó sì dì mí ni ọrùn mú, ó sì gbọ̀n mí túútúú, ó sì gbé mi kalẹ̀ láti ṣe àmì ìtafàsí rẹ̀;
Byłem w pokoju, ale mię potarł; a uchwyciwszy mię za szyję moję, roztrzaskał mię, i wystawił mię sobie za cel.
13 àwọn tafàtafà rẹ̀ dúró yí mi káàkiri. Ó là mí láyà pẹ̀rẹ̀, kò si dá sí, ó sì tú òróòro ara mi dà sílẹ̀.
Ogarnęli mię strzelcy jego; rozciął nerki moje, a nie przepuścił, i rozlał na ziemię żółć moję.
14 Ìbàjẹ́ lórí ìbàjẹ́ ní ó fi bà mí jẹ́; ó súré kọlù mi bí jagunjagun.
Zranił mię, raną na ranę; rzucił się na mię, jako olbrzym.
15 “Mo rán aṣọ ọ̀fọ̀ bò ara mi, mo sì rẹ̀ ìwo mi sílẹ̀ nínú erùpẹ̀.
Uszyłem wór na zsiniałą skórę moję, a oszpeciłem prochem głowę moję.
16 Ojú mi ti pọ́n fún ẹkún, òjìji ikú sì ṣẹ́ sí ìpéǹpéjú mi.
Twarz moja płaczem oszpecona, a na powiekach moich jest cień śmierci.
17 Kì í ṣe nítorí àìṣòótọ́ kan ní ọwọ́ mi; àdúrà mi sì mọ́ pẹ̀lú.
Chociaż żadnego łupiestwa niemasz w rękach moich, a modlitwa moja jest czysta. (a jeźli nie tak, )
18 “Háà! Ilẹ̀ ayé, ìwọ má ṣe bò ẹ̀jẹ̀ mi, kí ẹkún mi má ṣe wà ní ipò kan.
O ziemio! nie zakrywajże krwi mojej, a niech nie ma miejsca wołanie moje!
19 Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi i, ẹlẹ́rìí mi ń bẹ ní ọ̀run, ẹ̀rí mi sì ń bẹ lókè ọ̀run.
Otoć i teraz w niebie jest świadek mój, jest świadek mój na wysokości.
20 Àwọn ọ̀rẹ́ mi ń fi mí ṣẹ̀sín, ṣùgbọ́n ojú mi ń da omijé sọ́dọ̀ Ọlọ́run,
O krasomówcy moi, przyjaciele moi! wylewa łzy do Boga oko moje.
21 ìbá ṣe pé ẹnìkan le è máa ṣe alágbàwí fún ẹnìkejì lọ́dọ̀ Ọlọ́run, bí ènìyàn kan ti í ṣe alágbàwí fún ẹnìkejì rẹ̀.
Oby się godziło wieść spór człowiekowi z Bogiem, i jako synowi człowieczemu z bliźnim swym!
22 “Nítorí nígbà tí iye ọdún díẹ̀ rékọjá tán, nígbà náà ni èmi ó lọ sí ibi tí èmi kì yóò padà bọ̀.”
Bo lata zamierzone nadchodzą, a ścieszką, którą się nie wrócę, już idą.