< Job 16 >
1 Ìgbà náà ní Jobu dáhùn, ó sì wí pé,
Felele pedig Jób, és monda:
2 “Èmi ti gbọ́ irú ohun púpọ̀ bẹ́ẹ̀ rí ayọnilẹ́nu onítùnú ènìyàn ní gbogbo yín.
Efféle dolgokat sokat hallottam. Nyomorult vigasztalók vagytok ti mindnyájan!
3 Ọ̀rọ̀ asán lè ni òpin? Tàbí kí ni ó gbó ọ láyà tí ìwọ fi dáhùn?
Vége lesz-é már a szeles beszédeknek, avagy mi ingerel téged, hogy így felelsz?
4 Èmi pẹ̀lú le sọ bí ẹ̀yin; bí ọkàn yín bá wà ní ipò ọkàn mi, èmi le sọ ọ̀rọ̀ dáradára púpọ̀ sí yín ní ọrùn, èmi a sì mi orí mi sí i yín.
Én is szólhatnék úgy mint ti, csak volna a ti lelketek az én lelkem helyén! Szavakat fonhatnék össze ellenetek; csóválhatnám miattatok a fejemet;
5 Èmi ìbá fi ọ̀rọ̀ ẹnu mi gbà yín ni ìyànjú, àti ṣíṣí ètè mi ìbá sì tu ìbìnújẹ́ yín.
Erősíthetnélek titeket csak a szájammal és ajakim mozgása kevesbítené fájdalmatokat.
6 “Bí èmi tilẹ̀ sọ̀rọ̀, ìbìnújẹ́ mi kò lọ; bí mo sì tilẹ̀ dákẹ́, níbo ni ìtùnú mí ko kúrò?
Ha szólnék is, nem kevesbbednék a keserűségem; ha veszteglek is: micsoda távozik el tőlem?
7 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó dá mi lágara; ìwọ Ọlọ́run mú gbogbo ẹgbẹ́ mi takété.
Most pedig már fáraszt engemet. Elpusztítád egész házam népét.
8 Ìwọ fi ìhunjọ kùn mí lára, èyí tí o jẹ́rìí tì mí; àti rírù tí ó hàn lára mi, ó jẹ́rìí tì mí ní ojú.
Hogy összenyomtál engem, ez bizonyság lett; felkelt ellenem az én ösztövérségem is, szemtől-szembe bizonyít ellenem.
9 Ọlọ́run fi i ìbínú rẹ̀ fà mí ya, ó sì gbóguntì mí; ó pa eyín rẹ̀ keke sí mi, ọ̀tá mi sì gbójú rẹ̀ sí mi.
Haragja széttépett és üldöz engem. Fogait csikorgatta rám, ellenségemként villogtatja felém tekintetét.
10 Wọ́n ti fi ẹnu wọn yẹ̀yẹ́ mi; Wọ́n gbá mi ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ ni ìgbá ẹ̀gàn; wọ́n kó ara wọn pọ̀ sí mi.
Feltátották ellenem szájokat, gyalázatosan arczul csapdostak engem, összecsődültek ellenem.
11 Ọlọ́run ti fi mí lé ọwọ́ ẹni búburú, ó sì mú mi ṣubú sí ọwọ́ ènìyàn ìkà.
Adott engem az Isten az álnoknak, és a gonoszok kezébe ejte engemet.
12 Mo ti jókòó jẹ́ẹ́, ṣùgbọ́n ó fà mí já; ó sì dì mí ni ọrùn mú, ó sì gbọ̀n mí túútúú, ó sì gbé mi kalẹ̀ láti ṣe àmì ìtafàsí rẹ̀;
Csendességben valék, de szétszaggata engem; nyakszirten ragadott és szétzúzott engem, czéltáblává tűzött ki magának.
13 àwọn tafàtafà rẹ̀ dúró yí mi káàkiri. Ó là mí láyà pẹ̀rẹ̀, kò si dá sí, ó sì tú òróòro ara mi dà sílẹ̀.
Körülvettek az ő íjászai; veséimet meghasítja és nem kimél; epémet a földre kiontja.
14 Ìbàjẹ́ lórí ìbàjẹ́ ní ó fi bà mí jẹ́; ó súré kọlù mi bí jagunjagun.
Rést rés után tör rajtam, és rám rohan, mint valami hős.
15 “Mo rán aṣọ ọ̀fọ̀ bò ara mi, mo sì rẹ̀ ìwo mi sílẹ̀ nínú erùpẹ̀.
Zsák-ruhát varrék az én fekélyes bőrömre, és a porba fúrtam be az én szarvamat.
16 Ojú mi ti pọ́n fún ẹkún, òjìji ikú sì ṣẹ́ sí ìpéǹpéjú mi.
Orczám a sírástól kivörösödött, szempilláimra a halál árnyéka szállt;
17 Kì í ṣe nítorí àìṣòótọ́ kan ní ọwọ́ mi; àdúrà mi sì mọ́ pẹ̀lú.
Noha erőszakosság nem tapad kezemhez, és az én imádságom tiszta.
18 “Háà! Ilẹ̀ ayé, ìwọ má ṣe bò ẹ̀jẹ̀ mi, kí ẹkún mi má ṣe wà ní ipò kan.
Oh föld, az én véremet el ne takard, és ne legyen hely az én kiáltásom számára!
19 Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi i, ẹlẹ́rìí mi ń bẹ ní ọ̀run, ẹ̀rí mi sì ń bẹ lókè ọ̀run.
Még most is ímé az égben van az én bizonyságom, és az én tanuim a magasságban!
20 Àwọn ọ̀rẹ́ mi ń fi mí ṣẹ̀sín, ṣùgbọ́n ojú mi ń da omijé sọ́dọ̀ Ọlọ́run,
Csúfolóim a saját barátaim, azért az Istenhez sír fel az én szemem,
21 ìbá ṣe pé ẹnìkan le è máa ṣe alágbàwí fún ẹnìkejì lọ́dọ̀ Ọlọ́run, bí ènìyàn kan ti í ṣe alágbàwí fún ẹnìkejì rẹ̀.
Hogy ítélje meg az embernek Istennel, és az ember fiának az ő felebarátjával való dolgát.
22 “Nítorí nígbà tí iye ọdún díẹ̀ rékọjá tán, nígbà náà ni èmi ó lọ sí ibi tí èmi kì yóò padà bọ̀.”
Mert a kiszabott esztendők letelnek, és én útra kelek és nem térek vissza.