< Job 15 >

1 Ìgbà náà ní Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé,
Tad Elifas no Temanas atbildēja un sacīja:
2 “Ọlọ́gbọ́n a máa sọ̀rọ̀ ìmọ̀ asán kí ó sì máa fi afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn kún ara rẹ̀ nínú?
Vai tad gudram vīram būs runāt tukšas domas un savu sirdi pildīt ar vēju?
3 Òun lè máa fi àròyé sọ̀rọ̀ tí kò ní èrè, tàbí pẹ̀lú ọ̀rọ̀ nínú èyí tí kò lè fi ṣe rere?
Pārmācīt ar vārdiem, kas nepieklājās, un ar valodu, kur labums neatlec?
4 Ṣùgbọ́n ìwọ ṣá ìbẹ̀rù tì, ìwọ sì dí iṣẹ́ ìsìn lọ́nà níwájú Ọlọ́run.
Tiešām, tu iznīcini Dieva bijāšanu un nicini pielūgšanu Dieva priekšā.
5 Nítorí pé ẹnu ara rẹ̀ ni ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ìwọ sì yàn ahọ́n alárékérekè ni ààyò.
Jo tava mute parāda tavu noziegumu, un tu esi uzņēmies runāt, kā gudrinieki runā.
6 Ẹnu ara rẹ̀ ni ó dá lẹ́bi, kì í ṣe èmi; àní ètè ara rẹ̀ ni ó jẹ́rìí gbè ọ́.
Tava mute tevi pazudina, un ne es; tavas lūpas pret tevi dod liecību.
7 “Ìwọ ha í ṣe ọkùnrin tí a kọ́ bí? Tàbí a ha dá ọ ṣáájú àwọn òkè?
Vai tu esi tas pirmais cilvēks piedzimis, vai tu esi dzemdināts, pirms kalni bija?
8 Ìwọ gbúròó àṣírí Ọlọ́run rí? Tàbí ìwọ ha dá ọgbọ́n dúró sọ́dọ̀ ara rẹ?
Vai tu esi dzirdējis Dieva apslēpto padomu, vai tu gudrību esi iezīdis?
9 Kí ni ìwọ mọ̀ tí àwa kò mọ̀? Òye kí ní ó yé ọ tí kò sí nínú wa?
Ko tu zini, ko mēs nezinātu, ko tu proti, un mēs to neprastu?
10 Àwọn arúgbó àti ògbólógbòó ènìyàn wà pẹ̀lú wa, tí wọ́n dàgbà ju baba rẹ lọ.
Arī mūsu starpā ir sirmi un veci, kas ilgāki dzīvojuši, nekā tavs tēvs.
11 Ìtùnú Ọlọ́run ha kéré lọ́dọ̀ rẹ? Ọ̀rọ̀ kan sì ṣe jẹ́jẹ́ jù lọ́dọ̀ rẹ?
Vai Dieva iepriecināšanas priekš tevis mazas, un vārds, laipnīgi uz tevi runāts?
12 Èéṣe ti ọkàn rẹ fi ń ti ọ kiri, kí ni ìwọ tẹjúmọ́ tóbẹ́ẹ̀.
Kāpēc tava sirds tevi tā apmāna, kāpēc tavas acis tā spulgo,
13 Tí ìwọ fi yí ẹ̀mí rẹ padà lòdì sí Ọlọ́run, tí ó fi ń jẹ́ ki ọ̀rọ̀kọ́rọ̀ kí ó máa bọ́ ní ẹnu rẹ̀ bẹ́ẹ̀?
Ka tavas dusmas ceļas pret Dievu un izverd tādu valodu no tavas mutes?!
14 “Kí ni ènìyàn tí ó fi jẹ mímọ́, àti ẹni tí a tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo?
Kas ir cilvēks, ka tas būtu šķīsts, un ka būtu taisns, kas no sievas dzimis?
15 Kíyèsi i, bi Ọlọ́run ko ba gbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀, àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀,
Redzi, Saviem svētiem Viņš neuztic un debesis nav šķīstas priekš Viņa acīm.
16 mélòó mélòó ni ènìyàn, ẹni ìríra àti eléèérí, tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mu omi.
Ne nu vēl tas negantais un samaitātais cilvēks, kas netaisnību dzer kā ūdeni.
17 “Èmi ó fihàn ọ́, gbọ́ ti èmi; èyí tí èmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ,
Es tev stāstīšu, klausies mani, un es tev teikšu, ko esmu redzējis,
18 ohun tí àwọn ọlọ́gbọ́n ti pa ní ìtàn láti ọ̀dọ̀ àwọn baba wọn wá, ti wọ́n kò sì fi pamọ́.
Ko gudrie stāstījuši no saviem tēviem un nav slēpuši, -
19 Àwọn tí a fi ilẹ̀ ayé fún nìkan, ti àlejò kan kò sì là wọ́n kọjá.
Tiem vien zeme bija dota, un svešinieks viņu starpā nebija nācis, -
20 Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá, pẹ̀lú ìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo, àti iye ọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára.
Bezdievīgais mokās visu mūžu, un briesmīgais, cik tam gadi nolikti.
21 Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀; nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i.
Viņa ausīs skan briesmas, pašā mierā viņam uzbrūk postītājs.
22 Kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrò nínú òkùnkùn; a sì ṣà á sápá kan fún idà.
Viņš neuzticās iznākt no tumsības; jo zobens uz viņu gaida.
23 Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé, níbo ní ó wà? Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn súnmọ́ tòsí.
Viņš skraida šurp un turp pēc maizes, kur varētu dabūt; viņš zin tumsības dienu sev tuvu klātu.
24 Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú un bẹ̀rù, wọ́n ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ìmúra ogun.
Bēdas un izbailes viņu biedē, viņu pārvar kā ķēniņš, uz kaušanos gatavs.
25 Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdì sí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmarè,
Jo viņš izstiepa savu roku pret Dievu un cēlās pret to Visuvareno.
26 ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn gíga, àní fi ike-kókó àpáta rẹ̀ tí ó nípọn kọlù ú.
Viņš skrēja pret Viņu ar pašu galvu, ar savu priekšturamo bruņu biezām pumpām.
27 “Nítorí tí òun fi ọ̀rá rẹ̀ bo ara rẹ̀ lójú, o sì ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.
Viņš savu vaigu tauki izbaroja un kopa resnu vēderu.
28 Òun sì gbé inú ahoro ìlú, àti nínú ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé mọ́, tí ó múra tán láti di àlàpà.
Viņš dzīvoja izpostītās pilsētās un namos, kur nebija jādzīvo, kuriem nolemts būt par akmeņu kopām.
29 Òun kò lé di ọlọ́rọ̀, bẹ́ẹ̀ ohun ìní rẹ̀ kò lè dúró pẹ́; bẹ́ẹ̀ kò lè mú pípé rẹ̀ dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
(Tāpēc) viņš nepaliks bagāts, un viņa manta nepastāvēs, un viņa laime neizplētīsies virs zemes.
30 Òun kì yóò jáde kúrò nínú òkùnkùn; ọ̀wọ́-iná ni yóò jó ẹ̀ka rẹ̀, àti nípasẹ̀ ẹ̀mí ẹnu Ọlọ́run ní a ó gba kúrò.
Viņš no tumsības ārā neiznāks, liesma izkaltēs viņa zarus, caur Dieva mutes dvašu viņš aizies.
31 Kí òun kí ó má ṣe gbẹ́kẹ̀lé asán, kí ó má sì ṣe tan ara rẹ̀ jẹ. Nítorí pé asán ní yóò jásí èrè rẹ̀.
Lai viņš nepaļaujas uz nelietību, ar to viņš pieviļas; jo nelietība būs viņa alga.
32 A ó mú un ṣẹ ṣáájú pípé ọjọ́ rẹ̀, ẹ̀ka rẹ̀ kì yóò sì tutù.
Tā alga nāks priekšlaiku, un viņa zars nezaļos.
33 Yóò dàbí àjàrà tí a gbọn èso àìpọ́n rẹ̀ dànù, yóò sì rẹ̀ ìtànná rẹ̀ dànù bí i ti igi Olifi.
Viņš zaudēs kā vīna koks savus ķekarus un nometīs kā eļļas koks savus ziedus.
34 Nítorí pé ayọ̀ àwọn àgàbàgebè yóò túká, iná ní yóò sì jó àgọ́ àwọn tí ó fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
Jo bezdievīgo saime paliks neauglīga, un uguns norīs dāvanu ņēmēju dzīvokļus.
35 Wọ́n lóyún ìwà ìkà, wọ́n sì bí ẹ̀ṣẹ̀, ikùn wọn sì pèsè ẹ̀tàn.”
Tie ir grūti ar netaisnību un dzemdē postu, un savām sirds domām tie pieviļas.

< Job 15 >