< Job 15 >
1 Ìgbà náà ní Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé,
Majd felele a Témánból való Elifáz és monda:
2 “Ọlọ́gbọ́n a máa sọ̀rọ̀ ìmọ̀ asán kí ó sì máa fi afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn kún ara rẹ̀ nínú?
Vajjon a bölcs felelhet-é ilyen szeles tudománynyal, és megtöltheti-é a hasát keleti széllel?
3 Òun lè máa fi àròyé sọ̀rọ̀ tí kò ní èrè, tàbí pẹ̀lú ọ̀rọ̀ nínú èyí tí kò lè fi ṣe rere?
Vetekedvén oly beszéddel, a mely nem használ, és oly szavakkal, a melyekkel semmit sem segít.
4 Ṣùgbọ́n ìwọ ṣá ìbẹ̀rù tì, ìwọ sì dí iṣẹ́ ìsìn lọ́nà níwájú Ọlọ́run.
Te már semmivé akarod tenni az Isten félelmét is; és megkevesbíted az Isten előtt való buzgólkodást is!
5 Nítorí pé ẹnu ara rẹ̀ ni ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ìwọ sì yàn ahọ́n alárékérekè ni ààyò.
Mert gonoszságod oktatja a te szádat, és a csalárdok nyelvét választottad.
6 Ẹnu ara rẹ̀ ni ó dá lẹ́bi, kì í ṣe èmi; àní ètè ara rẹ̀ ni ó jẹ́rìí gbè ọ́.
A te szád kárhoztat téged, nem én, és a te ajakaid bizonyítanak ellened.
7 “Ìwọ ha í ṣe ọkùnrin tí a kọ́ bí? Tàbí a ha dá ọ ṣáájú àwọn òkè?
Te születtél-é az első embernek; elébb formáltattál-é, mint a halmok?
8 Ìwọ gbúròó àṣírí Ọlọ́run rí? Tàbí ìwọ ha dá ọgbọ́n dúró sọ́dọ̀ ara rẹ?
Az Isten tanácsában hallgatóztál-é, és a bölcseséget magadhoz ragadtad-é?
9 Kí ni ìwọ mọ̀ tí àwa kò mọ̀? Òye kí ní ó yé ọ tí kò sí nínú wa?
Mit tudsz te, a mit mi nem tudunk, és mit értesz olyat, a mi nálunk nem volna meg?
10 Àwọn arúgbó àti ògbólógbòó ènìyàn wà pẹ̀lú wa, tí wọ́n dàgbà ju baba rẹ lọ.
Ősz is, agg is van közöttünk, jóval idősebb a te atyádnál.
11 Ìtùnú Ọlọ́run ha kéré lọ́dọ̀ rẹ? Ọ̀rọ̀ kan sì ṣe jẹ́jẹ́ jù lọ́dọ̀ rẹ?
Csekélységek-é előtted Istennek vigasztalásai, és a beszéd, a mely szeliden bánt veled?
12 Èéṣe ti ọkàn rẹ fi ń ti ọ kiri, kí ni ìwọ tẹjúmọ́ tóbẹ́ẹ̀.
Merre ragadt téged a szíved, és merre pillantottak a te szemeid?
13 Tí ìwọ fi yí ẹ̀mí rẹ padà lòdì sí Ọlọ́run, tí ó fi ń jẹ́ ki ọ̀rọ̀kọ́rọ̀ kí ó máa bọ́ ní ẹnu rẹ̀ bẹ́ẹ̀?
Hogy Isten ellen fordítod a te haragodat, és ilyen szavakat eresztesz ki a szádon?
14 “Kí ni ènìyàn tí ó fi jẹ mímọ́, àti ẹni tí a tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo?
Micsoda a halandó, hogy tiszta lehetne, és hogy igaz volna, a ki asszonytól születik?
15 Kíyèsi i, bi Ọlọ́run ko ba gbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀, àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀,
Ímé, még az ő szenteiben sem bízok, az egek sem tiszták az ő szemében:
16 mélòó mélòó ni ènìyàn, ẹni ìríra àti eléèérí, tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mu omi.
Mennyivel kevésbbé az útálatos és a megromlott ember, a ki úgy nyeli a hamisságot, mint a vizet?!
17 “Èmi ó fihàn ọ́, gbọ́ ti èmi; èyí tí èmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ,
Elmondom néked, hallgass rám, és a mint láttam, úgy beszélem el;
18 ohun tí àwọn ọlọ́gbọ́n ti pa ní ìtàn láti ọ̀dọ̀ àwọn baba wọn wá, ti wọ́n kò sì fi pamọ́.
A mit a bölcsek is hirdettek, és nem titkoltak el, mint atyáiktól valót;
19 Àwọn tí a fi ilẹ̀ ayé fún nìkan, ti àlejò kan kò sì là wọ́n kọjá.
A kiknek egyedül adatott vala a föld, és közöttük idegen nem megy vala.
20 Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá, pẹ̀lú ìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo, àti iye ọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára.
Az istentelen kínozza önmagát egész életében, és az erőszakoskodó előtt is rejtve van az ő esztendeinek száma.
21 Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀; nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i.
A félelem hangja cseng az ő füleiben; a békesség idején tör rá a pusztító!
22 Kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrò nínú òkùnkùn; a sì ṣà á sápá kan fún idà.
Nem hiszi, hogy kijut a sötétségből, mert kard hegyére van ő kiszemelve.
23 Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé, níbo ní ó wà? Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn súnmọ́ tòsí.
Kenyér után futkos, hogy hol volna? Tudja, hogy közel van hozzá a sötétség napja.
24 Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú un bẹ̀rù, wọ́n ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ìmúra ogun.
Háborgatják őt a nyomorúság és rettegés; leverik őt, mint valami háborúra felkészült király.
25 Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdì sí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmarè,
Mert az Isten ellen nyujtotta ki kezét, és erősködött a Mindenható ellen;
26 ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn gíga, àní fi ike-kókó àpáta rẹ̀ tí ó nípọn kọlù ú.
Kinyujtott nyakkal rohant ellene, domború pajzsainak fellege alatt.
27 “Nítorí tí òun fi ọ̀rá rẹ̀ bo ara rẹ̀ lójú, o sì ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.
Mivel befedezte az arczát kövérséggel, és hájat borított tomporára;
28 Òun sì gbé inú ahoro ìlú, àti nínú ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé mọ́, tí ó múra tán láti di àlàpà.
És lakozott elrombolt városokban; lakatlan házakban, a melyek dűlőfélben vannak:
29 Òun kò lé di ọlọ́rọ̀, bẹ́ẹ̀ ohun ìní rẹ̀ kò lè dúró pẹ́; bẹ́ẹ̀ kò lè mú pípé rẹ̀ dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
Meg nem gazdagodik, vagyona meg nem marad, jószága nem lepi el a földet.
30 Òun kì yóò jáde kúrò nínú òkùnkùn; ọ̀wọ́-iná ni yóò jó ẹ̀ka rẹ̀, àti nípasẹ̀ ẹ̀mí ẹnu Ọlọ́run ní a ó gba kúrò.
Nem menekül meg a setétségtől, sarjadékát láng perzseli el, és szájának lehelletétől pusztul el.
31 Kí òun kí ó má ṣe gbẹ́kẹ̀lé asán, kí ó má sì ṣe tan ara rẹ̀ jẹ. Nítorí pé asán ní yóò jásí èrè rẹ̀.
Ne higyjen a hívságnak, a ki megcsalatott, mert hívság lészen annak jutalma.
32 A ó mú un ṣẹ ṣáájú pípé ọjọ́ rẹ̀, ẹ̀ka rẹ̀ kì yóò sì tutù.
Nem idejében telik el élete, és az ága ki nem virágzik.
33 Yóò dàbí àjàrà tí a gbọn èso àìpọ́n rẹ̀ dànù, yóò sì rẹ̀ ìtànná rẹ̀ dànù bí i ti igi Olifi.
Lehullatja, mint a szőlővessző az ő egresét, elhányja, mint az olajfa az ő virágát.
34 Nítorí pé ayọ̀ àwọn àgàbàgebè yóò túká, iná ní yóò sì jó àgọ́ àwọn tí ó fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
Mert a képmutató házanépe meddő, és tűz emészti meg az ajándékból való sátrakat.
35 Wọ́n lóyún ìwà ìkà, wọ́n sì bí ẹ̀ṣẹ̀, ikùn wọn sì pèsè ẹ̀tàn.”
Nyomorúságot fogan, álnokságot szül, és az ő méhök csalárdságot érlel.