< Job 15 >

1 Ìgbà náà ní Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé,
Alors Éliphaz, le Thémanite, prit la parole,
2 “Ọlọ́gbọ́n a máa sọ̀rọ̀ ìmọ̀ asán kí ó sì máa fi afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn kún ara rẹ̀ nínú?
« Si un homme sage répond par une vaine connaissance, et se remplir du vent d'est?
3 Òun lè máa fi àròyé sọ̀rọ̀ tí kò ní èrè, tàbí pẹ̀lú ọ̀rọ̀ nínú èyí tí kò lè fi ṣe rere?
Doit-il raisonner avec des propos non profitables, ou avec des discours avec lesquels il ne peut rien faire de bon?
4 Ṣùgbọ́n ìwọ ṣá ìbẹ̀rù tì, ìwọ sì dí iṣẹ́ ìsìn lọ́nà níwájú Ọlọ́run.
Oui, vous supprimez la peur, et entravent la dévotion devant Dieu.
5 Nítorí pé ẹnu ara rẹ̀ ni ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ìwọ sì yàn ahọ́n alárékérekè ni ààyò.
Car ton iniquité enseigne ta bouche, et vous choisissez le langage des rusés.
6 Ẹnu ara rẹ̀ ni ó dá lẹ́bi, kì í ṣe èmi; àní ètè ara rẹ̀ ni ó jẹ́rìí gbè ọ́.
C'est ta propre bouche qui te condamne, et non moi. Oui, tes propres lèvres témoignent contre toi.
7 “Ìwọ ha í ṣe ọkùnrin tí a kọ́ bí? Tàbí a ha dá ọ ṣáájú àwọn òkè?
« Es-tu le premier homme qui soit né? Ou bien on vous a fait sortir avant les collines?
8 Ìwọ gbúròó àṣírí Ọlọ́run rí? Tàbí ìwọ ha dá ọgbọ́n dúró sọ́dọ̀ ara rẹ?
Avez-vous entendu le conseil secret de Dieu? Limitez-vous la sagesse à vous-même?
9 Kí ni ìwọ mọ̀ tí àwa kò mọ̀? Òye kí ní ó yé ọ tí kò sí nínú wa?
Que savez-vous que nous ne savons pas? Que comprenez-vous qui n'est pas en nous?
10 Àwọn arúgbó àti ògbólógbòó ènìyàn wà pẹ̀lú wa, tí wọ́n dàgbà ju baba rẹ lọ.
Avec nous, il y a des hommes aux cheveux gris et des hommes très âgés, beaucoup plus vieux que ton père.
11 Ìtùnú Ọlọ́run ha kéré lọ́dọ̀ rẹ? Ọ̀rọ̀ kan sì ṣe jẹ́jẹ́ jù lọ́dọ̀ rẹ?
Les consolations de Dieu sont-elles trop petites pour vous, même la parole qui est douce envers vous?
12 Èéṣe ti ọkàn rẹ fi ń ti ọ kiri, kí ni ìwọ tẹjúmọ́ tóbẹ́ẹ̀.
Pourquoi ton cœur t'emporte-t-il? Pourquoi vos yeux clignotent-ils?
13 Tí ìwọ fi yí ẹ̀mí rẹ padà lòdì sí Ọlọ́run, tí ó fi ń jẹ́ ki ọ̀rọ̀kọ́rọ̀ kí ó máa bọ́ ní ẹnu rẹ̀ bẹ́ẹ̀?
que vous tournez votre esprit contre Dieu, et laisser de telles paroles sortir de votre bouche?
14 “Kí ni ènìyàn tí ó fi jẹ mímọ́, àti ẹni tí a tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo?
Qu'est-ce que l'homme, pour qu'il soit pur? Qu'est-ce que celui qui est né d'une femme, pour qu'il soit juste?
15 Kíyèsi i, bi Ọlọ́run ko ba gbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀, àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀,
Voici, il ne fait pas confiance à ses saints. Oui, les cieux ne sont pas propres à ses yeux;
16 mélòó mélòó ni ènìyàn, ẹni ìríra àti eléèérí, tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mu omi.
combien moins celui qui est abominable et corrompu, un homme qui boit l'iniquité comme de l'eau!
17 “Èmi ó fihàn ọ́, gbọ́ ti èmi; èyí tí èmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ,
« Je vais te montrer, écoute-moi; ce que j'ai vu, je vais le déclarer
18 ohun tí àwọn ọlọ́gbọ́n ti pa ní ìtàn láti ọ̀dọ̀ àwọn baba wọn wá, ti wọ́n kò sì fi pamọ́.
(que les sages ont raconté par leurs pères, et ne l'ont pas caché;
19 Àwọn tí a fi ilẹ̀ ayé fún nìkan, ti àlejò kan kò sì là wọ́n kọjá.
à qui seul le pays a été donné, et aucun étranger ne passait parmi eux):
20 Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá, pẹ̀lú ìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo, àti iye ọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára.
Le méchant se tord de douleur tous ses jours, même le nombre d'années qui sont réservées à l'oppresseur.
21 Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀; nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i.
Un bruit de terreur est dans ses oreilles. Dans la prospérité, le destructeur viendra sur lui.
22 Kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrò nínú òkùnkùn; a sì ṣà á sápá kan fún idà.
Il ne croit pas qu'il reviendra des ténèbres. Il est attendu par l'épée.
23 Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé, níbo ní ó wà? Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn súnmọ́ tòsí.
Il erre à la recherche de pain, en disant: « Où est-il? ». Il sait que le jour des ténèbres est prêt à sa main.
24 Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú un bẹ̀rù, wọ́n ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ìmúra ogun.
La détresse et l'angoisse l'effraient. Ils l'emportent sur lui, comme un roi prêt à la bataille.
25 Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdì sí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmarè,
Parce qu'il a étendu sa main contre Dieu, et se comporte fièrement contre le Tout-Puissant,
26 ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn gíga, àní fi ike-kókó àpáta rẹ̀ tí ó nípọn kọlù ú.
il court vers lui avec un cou raide, avec les boucliers épais de ses boucliers,
27 “Nítorí tí òun fi ọ̀rá rẹ̀ bo ara rẹ̀ lójú, o sì ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.
parce qu'il s'est couvert le visage de sa graisse, et a accumulé de la graisse sur ses cuisses.
28 Òun sì gbé inú ahoro ìlú, àti nínú ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé mọ́, tí ó múra tán láti di àlàpà.
Il a habité des villes désertes, dans des maisons que personne n'habitait, qui étaient prêts à devenir des tas.
29 Òun kò lé di ọlọ́rọ̀, bẹ́ẹ̀ ohun ìní rẹ̀ kò lè dúró pẹ́; bẹ́ẹ̀ kò lè mú pípé rẹ̀ dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
Il ne sera pas riche, et sa fortune ne durera pas, et leurs biens ne s'étendront pas sur la terre.
30 Òun kì yóò jáde kúrò nínú òkùnkùn; ọ̀wọ́-iná ni yóò jó ẹ̀ka rẹ̀, àti nípasẹ̀ ẹ̀mí ẹnu Ọlọ́run ní a ó gba kúrò.
Il ne sortira pas des ténèbres. La flamme desséchera ses branches. Il s'en ira par le souffle de la bouche de Dieu.
31 Kí òun kí ó má ṣe gbẹ́kẹ̀lé asán, kí ó má sì ṣe tan ara rẹ̀ jẹ. Nítorí pé asán ní yóò jásí èrè rẹ̀.
Qu'il ne se fie pas au vide, en se trompant lui-même, car le vide sera sa récompense.
32 A ó mú un ṣẹ ṣáájú pípé ọjọ́ rẹ̀, ẹ̀ka rẹ̀ kì yóò sì tutù.
Elle s'accomplira avant son temps. Sa branche ne sera pas verte.
33 Yóò dàbí àjàrà tí a gbọn èso àìpọ́n rẹ̀ dànù, yóò sì rẹ̀ ìtànná rẹ̀ dànù bí i ti igi Olifi.
Il secouera son raisin non mûr comme la vigne, et il rejettera sa fleur comme l'olivier.
34 Nítorí pé ayọ̀ àwọn àgàbàgebè yóò túká, iná ní yóò sì jó àgọ́ àwọn tí ó fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
Car la compagnie des impies sera stérile, et le feu consumera les tentes de la corruption.
35 Wọ́n lóyún ìwà ìkà, wọ́n sì bí ẹ̀ṣẹ̀, ikùn wọn sì pèsè ẹ̀tàn.”
Ils conçoivent la malice et produisent l'iniquité. Leur cœur prépare la tromperie. »

< Job 15 >