< Job 15 >

1 Ìgbà náà ní Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé,
Then Eliphaz replied to Job:
2 “Ọlọ́gbọ́n a máa sọ̀rọ̀ ìmọ̀ asán kí ó sì máa fi afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn kún ara rẹ̀ nínú?
“If you were truly wise [RHQ], you would not have replied to us by claiming that you know a lot; what you are saying is just a lot of hot air [MET].
3 Òun lè máa fi àròyé sọ̀rọ̀ tí kò ní èrè, tàbí pẹ̀lú ọ̀rọ̀ nínú èyí tí kò lè fi ṣe rere?
You should not [RHQ] be saying things that do not benefit anyone, using words that do no one any good.
4 Ṣùgbọ́n ìwọ ṣá ìbẹ̀rù tì, ìwọ sì dí iṣẹ́ ìsìn lọ́nà níwájú Ọlọ́run.
[By what you say, ] you show that you do not revere God, and you are hindering people from meditating/thinking about God.
5 Nítorí pé ẹnu ara rẹ̀ ni ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ìwọ sì yàn ahọ́n alárékérekè ni ààyò.
[It is as though] your sins are telling you what to say; you talk like people who will not admit that they are wicked.
6 Ẹnu ara rẹ̀ ni ó dá lẹ́bi, kì í ṣe èmi; àní ètè ara rẹ̀ ni ó jẹ́rìí gbè ọ́.
Everything that you say [MTY] shows that you should be punished; so, it is not necessary for me to show that.
7 “Ìwọ ha í ṣe ọkùnrin tí a kọ́ bí? Tàbí a ha dá ọ ṣáájú àwọn òkè?
[“Tell me do you know more than everyone else because you think that] you are the first person who was ever born? [SAR, RHQ] Were you born before the hills [were created]?
8 Ìwọ gbúròó àṣírí Ọlọ́run rí? Tàbí ìwọ ha dá ọgbọ́n dúró sọ́dọ̀ ara rẹ?
Were you listening when God made all his plans? [SAR, RHQ] Or do you think that you are the only person who is wise?
9 Kí ni ìwọ mọ̀ tí àwa kò mọ̀? Òye kí ní ó yé ọ tí kò sí nínú wa?
(What do you know that we do not know?/You do not know anything that we do not know.) [RHQ] You do not understand [RHQ] anything that is not also clear to us.
10 Àwọn arúgbó àti ògbólógbòó ènìyàn wà pẹ̀lú wa, tí wọ́n dàgbà ju baba rẹ lọ.
My friends and I are also wise; we acquired [wisdom] from old gray-haired people, from people who were born before your father was born.
11 Ìtùnú Ọlọ́run ha kéré lọ́dọ̀ rẹ? Ọ̀rọ̀ kan sì ṣe jẹ́jẹ́ jù lọ́dọ̀ rẹ?
God wants to comfort you, and to speak gently/kindly to you; (is that not enough for you/do you need more than that)?
12 Èéṣe ti ọkàn rẹ fi ń ti ọ kiri, kí ni ìwọ tẹjúmọ́ tóbẹ́ẹ̀.
Why do you allow yourself to be (carried away/excited) by your emotions? Why are [you very angry, with the result that] your eyes flash?
13 Tí ìwọ fi yí ẹ̀mí rẹ padà lòdì sí Ọlọ́run, tí ó fi ń jẹ́ ki ọ̀rọ̀kọ́rọ̀ kí ó máa bọ́ ní ẹnu rẹ̀ bẹ́ẹ̀?
You are angry [IDM] with God, and so you [MTY] are criticizing/denouncing him.
14 “Kí ni ènìyàn tí ó fi jẹ mímọ́, àti ẹni tí a tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo?
“(How can any person, [including you, ] be sinless?/No person, [including you], can be sinless.) [RHQ] (How can anyone on the earth be [completely] righteous?/No one on the earth can be [completely] righteous.) [RHQ]
15 Kíyèsi i, bi Ọlọ́run ko ba gbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀, àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀,
Hey, God does not even trust his angels; he does not consider even them to be [completely] pure.
16 mélòó mélòó ni ènìyàn, ẹni ìríra àti eléèérí, tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mu omi.
So, he certainly does not [trust] abominable/disgusting and depraved/corrupt people who do evil things [as easily] as they drink water [MET].
17 “Èmi ó fihàn ọ́, gbọ́ ti èmi; èyí tí èmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ,
Job, listen to what I will tell you. I will declare to you what I know,
18 ohun tí àwọn ọlọ́gbọ́n ti pa ní ìtàn láti ọ̀dọ̀ àwọn baba wọn wá, ti wọ́n kò sì fi pamọ́.
things that wise men have told me, truths that their ancestors did not keep hidden.
19 Àwọn tí a fi ilẹ̀ ayé fún nìkan, ti àlejò kan kò sì là wọ́n kọjá.
God gave this land to those ancestors, who were truly wise; no one from another country caused them to think wrongly [IDM].
20 Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá, pẹ̀lú ìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo, àti iye ọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára.
It is wicked people who suffer with great pain all the time that they are alive; that is what happens to those who (oppress/act violently toward) others.
21 Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀; nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i.
They constantly hear sounds that terrify them; while they are prospering, bandits attack them.
22 Kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrò nínú òkùnkùn; a sì ṣà á sápá kan fún idà.
Wicked people surely know that they will not escape from darkness/death, because [they are sure that someone] is waiting to kill them with a sword.
23 Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé, níbo ní ó wà? Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn súnmọ́ tòsí.
They wander around, searching for food, saying ‘Where can I find some?’ And they know that they will soon experience disasters.
24 Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú un bẹ̀rù, wọ́n ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ìmúra ogun.
Because they are afraid of those things happening to them, they are afraid and worry that these things will come to them like [the army of] a king comes to attack [their enemies and cause them to suffer] [SIM].
25 Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdì sí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmarè,
[Those things happen to them] because they (shook their fists/dared to fight) against Almighty God, and thought that they were strong enough to defeat him.
26 ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn gíga, àní fi ike-kókó àpáta rẹ̀ tí ó nípọn kọlù ú.
They stubbornly [IDM] rush to attack God [as though they were carrying] a strong shield [to protect themselves].
27 “Nítorí tí òun fi ọ̀rá rẹ̀ bo ara rẹ̀ lójú, o sì ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.
They are so fat [that they are unable to fight].
28 Òun sì gbé inú ahoro ìlú, àti nínú ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé mọ́, tí ó múra tán láti di àlàpà.
They will live in cities that have been abandoned, cities which have become a heap of ruins.
29 Òun kò lé di ọlọ́rọ̀, bẹ́ẹ̀ ohun ìní rẹ̀ kò lè dúró pẹ́; bẹ́ẹ̀ kò lè mú pípé rẹ̀ dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
But they will not remain rich very long; Everything that they own will be taken from them; their possessions will all disappear.
30 Òun kì yóò jáde kúrò nínú òkùnkùn; ọ̀wọ́-iná ni yóò jó ẹ̀ka rẹ̀, àti nípasẹ̀ ẹ̀mí ẹnu Ọlọ́run ní a ó gba kúrò.
They will not escape from the darkness [of death]; they will be like trees whose branches are burned by fire and whose blossoms are blown away by the wind.
31 Kí òun kí ó má ṣe gbẹ́kẹ̀lé asán, kí ó má sì ṣe tan ara rẹ̀ jẹ. Nítorí pé asán ní yóò jásí èrè rẹ̀.
Since they are very foolish, with the result that they trust in things that are really worthless, then things that are worthless will be all that they get.
32 A ó mú un ṣẹ ṣáájú pípé ọjọ́ rẹ̀, ẹ̀ka rẹ̀ kì yóò sì tutù.
Before they are old, they will wither; they will be like [MET] branches that wither and never become green again.
33 Yóò dàbí àjàrà tí a gbọn èso àìpọ́n rẹ̀ dànù, yóò sì rẹ̀ ìtànná rẹ̀ dànù bí i ti igi Olifi.
They will be like [SIM] vines whose grapes fall off before they are ripe, like olive trees whose blossoms fall off before they produce any fruit.
34 Nítorí pé ayọ̀ àwọn àgàbàgebè yóò túká, iná ní yóò sì jó àgọ́ àwọn tí ó fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
Wicked/godless people will not have any descendants, and fires will completely burn up the homes of [those who built those homes using] money they received from bribes.
35 Wọ́n lóyún ìwà ìkà, wọ́n sì bí ẹ̀ṣẹ̀, ikùn wọn sì pèsè ẹ̀tàn.”
They plan to cause trouble and to do evil things, and they are always preparing to deceive people.”

< Job 15 >