< Job 15 >

1 Ìgbà náà ní Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé,
Тогава теманецът Елифад в отговор рече:
2 “Ọlọ́gbọ́n a máa sọ̀rọ̀ ìmọ̀ asán kí ó sì máa fi afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn kún ara rẹ̀ nínú?
Мъдър човек с вятърничаво ли знание отговаря, И с източен вятър ли пълни корема си?
3 Òun lè máa fi àròyé sọ̀rọ̀ tí kò ní èrè, tàbí pẹ̀lú ọ̀rọ̀ nínú èyí tí kò lè fi ṣe rere?
С празни думи ли се препира И с безполезни речи?
4 Ṣùgbọ́n ìwọ ṣá ìbẹ̀rù tì, ìwọ sì dí iṣẹ́ ìsìn lọ́nà níwájú Ọlọ́run.
Наистина ти унищожаваш страха от Бога, И намаляваш моленето пред Него.
5 Nítorí pé ẹnu ara rẹ̀ ni ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ìwọ sì yàn ahọ́n alárékérekè ni ààyò.
Защото беззаконието ти поучава устата ти, И си избрал езика на лукавите.
6 Ẹnu ara rẹ̀ ni ó dá lẹ́bi, kì í ṣe èmi; àní ètè ara rẹ̀ ni ó jẹ́rìí gbè ọ́.
Твоите уста те осъждат, а не аз; Твоите устни свидетелствуват против тебе.
7 “Ìwọ ha í ṣe ọkùnrin tí a kọ́ bí? Tàbí a ha dá ọ ṣáájú àwọn òkè?
Ти ли си първородният човек? Или създаден ли си преди хълмите?
8 Ìwọ gbúròó àṣírí Ọlọ́run rí? Tàbí ìwọ ha dá ọgbọ́n dúró sọ́dọ̀ ara rẹ?
Чул ли си ти Божиите тайни намерения? Или си заключил в себе си мъдростта?
9 Kí ni ìwọ mọ̀ tí àwa kò mọ̀? Òye kí ní ó yé ọ tí kò sí nínú wa?
Що знаеш ти, което ние не знаем? Що разбираш ти, което няма у нас?
10 Àwọn arúgbó àti ògbólógbòó ènìyàn wà pẹ̀lú wa, tí wọ́n dàgbà ju baba rẹ lọ.
Има и между нас и белокоси и престарели, По-напреднали на възраст и от баща ти.
11 Ìtùnú Ọlọ́run ha kéré lọ́dọ̀ rẹ? Ọ̀rọ̀ kan sì ṣe jẹ́jẹ́ jù lọ́dọ̀ rẹ?
Божиите утешения и меките Му към тебе думи Малко нещо ли са за тебе?
12 Èéṣe ti ọkàn rẹ fi ń ti ọ kiri, kí ni ìwọ tẹjúmọ́ tóbẹ́ẹ̀.
Какво те блазни сърцето ти, И на какво смигат очите ти,
13 Tí ìwọ fi yí ẹ̀mí rẹ padà lòdì sí Ọlọ́run, tí ó fi ń jẹ́ ki ọ̀rọ̀kọ́rọ̀ kí ó máa bọ́ ní ẹnu rẹ̀ bẹ́ẹ̀?
Та обръщаш духа си против Бога, И изпущаш такива думи из устата си?
14 “Kí ni ènìyàn tí ó fi jẹ mímọ́, àti ẹni tí a tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo?
Що е човек та да е чист, И роденият от жена та да е праведен?
15 Kíyèsi i, bi Ọlọ́run ko ba gbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀, àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀,
Ето, на светите Си ангели Той не се доверява, И небесата не са чисти в очите Му;
16 mélòó mélòó ni ènìyàn, ẹni ìríra àti eléèérí, tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mu omi.
Колко повече е гнусен и непотребен човек, Който пие неправда, като вода!
17 “Èmi ó fihàn ọ́, gbọ́ ti èmi; èyí tí èmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ,
Аз ще ти кажа, послушай ме; И това, което съм видял, ще ти изявя,
18 ohun tí àwọn ọlọ́gbọ́n ti pa ní ìtàn láti ọ̀dọ̀ àwọn baba wọn wá, ti wọ́n kò sì fi pamọ́.
(Което мъдрите не скриха, но възвестиха, Както бяха чули от бащите си;
19 Àwọn tí a fi ilẹ̀ ayé fún nìkan, ti àlejò kan kò sì là wọ́n kọjá.
На които биде дадена земята, и само на тях, И чужденец не замина между тях; )
20 Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá, pẹ̀lú ìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo, àti iye ọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára.
Нечестивият се мъчи през всичките си дни; И преброени години са запазени за мъчителя.
21 Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀; nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i.
Ужасни гласове има в ушите му, Че като е в спокойствие ще го нападне изтребителят;
22 Kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrò nínú òkùnkùn; a sì ṣà á sápá kan fún idà.
Не вярва, че ще се върне от тъмнината; И той е очакван от ножа;
23 Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé, níbo ní ó wà? Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn súnmọ́ tòsí.
Скита се да търси хляб, казвайки: Где е? Знае, че денят на тъмнината е готов до ръката му;
24 Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú un bẹ̀rù, wọ́n ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ìmúra ogun.
Скръб и тъга го плашат, Като цар приготвен за бой му надвиват.
25 Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdì sí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmarè,
Понеже той простря ръката си против Бога, И възгордя се против Всемогъщия,
26 ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn gíga, àní fi ike-kókó àpáta rẹ̀ tí ó nípọn kọlù ú.
Спусна се на Него с корав врат, С дебелите изпъкналости на щитовете си.
27 “Nítorí tí òun fi ọ̀rá rẹ̀ bo ara rẹ̀ lójú, o sì ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.
Понеже покри лицето си с тлъстината си, И, затлъсти кръста си,
28 Òun sì gbé inú ahoro ìlú, àti nínú ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé mọ́, tí ó múra tán láti di àlàpà.
Той се засели в разорени градове, В къщи необитаеми, Готови да станат на купове.
29 Òun kò lé di ọlọ́rọ̀, bẹ́ẹ̀ ohun ìní rẹ̀ kò lè dúró pẹ́; bẹ́ẹ̀ kò lè mú pípé rẹ̀ dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
Няма да се обогати, и имотът му няма да трае, Нито ще се навеждат до земята произведенията им.
30 Òun kì yóò jáde kúrò nínú òkùnkùn; ọ̀wọ́-iná ni yóò jó ẹ̀ka rẹ̀, àti nípasẹ̀ ẹ̀mí ẹnu Ọlọ́run ní a ó gba kúrò.
Няма да се отърве от тъмнината; Пламък ще изсуши младоците му; И от дишането на Божиите уста ще бъде завлечен.
31 Kí òun kí ó má ṣe gbẹ́kẹ̀lé asán, kí ó má sì ṣe tan ara rẹ̀ jẹ. Nítorí pé asán ní yóò jásí èrè rẹ̀.
Нека не се доверява на суетата, самоизмамен; Защото суета ще бъде заплатата му.
32 A ó mú un ṣẹ ṣáájú pípé ọjọ́ rẹ̀, ẹ̀ka rẹ̀ kì yóò sì tutù.
Преди времето си ще се изплати, И клонът му няма да раззеленее,
33 Yóò dàbí àjàrà tí a gbọn èso àìpọ́n rẹ̀ dànù, yóò sì rẹ̀ ìtànná rẹ̀ dànù bí i ti igi Olifi.
Ще изрони неузрялото си грозде като лозата, И ще хвърли цвета си като маслината.
34 Nítorí pé ayọ̀ àwọn àgàbàgebè yóò túká, iná ní yóò sì jó àgọ́ àwọn tí ó fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
Защото дружината на нечестивите ще запустее; И огън ще пояде шатрите на подкупничеството.
35 Wọ́n lóyún ìwà ìkà, wọ́n sì bí ẹ̀ṣẹ̀, ikùn wọn sì pèsè ẹ̀tàn.”
Зачват зло, и раждат беззаконие, И сърцето им подготвя измама.

< Job 15 >