< Job 12 >
1 Jobu sì dáhùn, ó sì wí pé,
Y Job respondió y dijo:
2 “Kò sí àní àní níbẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni àwọn ènìyàn náà, ọgbọ́n yóò sì kú pẹ̀lú yín!
Sin duda ustedes son el pueblo, y la sabiduría terminará con ustedes.
3 Ṣùgbọ́n èmi ní ìyè nínú gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin; èmi kò kéré sí i yín. Àní, ta ni kò mọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí?
Pero tengo una mente como ustedes; Soy igual a ustedes: sí, ¿quién no tiene conocimiento de cosas como estas?
4 “Èmi dàbí ẹni tí a ń fi ṣe ẹlẹ́yà lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀, tí ó ké pe Ọlọ́run, tí ó sì dá a lóhùn, à ń fi olóòtítọ́ ẹni ìdúró ṣinṣin rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà!
¡Parece que debo ser como uno que es motivo de burla a su prójimo, uno que hace su oración a Dios y recibe respuesta! ¡El hombre recto que no ha hecho nada malo es escarnecido!
5 Ó rọrùn fún ènìyàn láti fi ìbànújẹ́ ẹlòmíràn ṣe ẹlẹ́yà gẹ́gẹ́ bí ìpín àwọn ẹni tí ẹsẹ̀ wọn ṣetán láti yọ̀.
En el pensamiento de aquel que está a gusto, no hay respeto por alguien que está en problemas; tal es el destino de aquellos cuyos pies se están deslizando.
6 Àgọ́ àwọn ìgárá ọlọ́ṣà wá láìní ìbẹ̀rù; àwọn tí ó sì ń mú Ọlọ́run bínú wà láìléwu, àwọn ẹni tí ó sì gbá òrìṣà mú ní ọwọ́ wọn.
Hay abundancia en las tiendas de aquellos que hacen la destrucción, y aquellos por quienes Dios es movido a la ira están a salvo; incluso aquellos los que Dios les ha dado el poder.
7 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí bí àwọn ẹranko léèrè, wọn o kọ́ ọ ní ẹ̀kọ́, àti ẹyẹ ojú ọ̀run, wọn ó sì sọ fún ọ.
Pero ahora pregunta a las bestias, y aprende de ellas; o a las aves del cielo, y te informarán;
8 Tàbí ba ilẹ̀ ayé sọ̀rọ̀, yóò sì kọ́ ọ, àwọn ẹja inú òkun yóò sì sọ fún ọ.
O a las cosas en la tierra, y te darán sabiduría; Y los peces del mar te darán noticias de ello.
9 Ta ni kò mọ̀ nínú gbogbo nǹkan wọ̀nyí pé, ọwọ́ Olúwa ni ó ṣe nǹkan yìí?
¿Quién no ve por todos estos que la mano del Señor ha hecho esto?
10 Ní ọwọ́ ẹni tí ẹ̀mí ohun alààyè gbogbo gbé wà, àti ẹ̀mí gbogbo aráyé.
En cuya mano está el alma de todo ser viviente, y el aliento de toda carne humana.
11 Etí kì í dán ọ̀rọ̀ wò bí tàbí adùn ẹnu kì í sì í tọ́ oúnjẹ rẹ̀ wò bí?
¿No son las palabras probadas por el oído, al igual que la comida se prueba por la boca?
12 Àwọn arúgbó ni ọgbọ́n wà fún, àti nínú gígùn ọjọ́ ni òye.
Los ancianos tienen sabiduría, y una larga vida da conocimiento.
13 “Ti Ọlọ́run ni ọgbọ́n àti agbára; òun ló ni ìmọ̀ àti òye.
En Dios hay sabiduría y poder. El consejo y el conocimiento son suyos.
14 Kíyèsi i, ó bì wó, a kò sì lè gbe ró mọ́; Ó sé ènìyàn mọ́, kò sì sí ìtúsílẹ̀ kan.
En verdad, no hay reconstrucción de lo que es derribado por Dios; cuando un hombre es aprisionado por Dios, nadie puede soltarlo.
15 Kíyèsi i, ó dá àwọn omi dúró, wọ́n sì gbẹ; Ó sì rán wọn jáde, wọ́n sì ṣẹ̀ bo ilẹ̀ ayé yípo.
En verdad, él retiene las aguas y están secas; Él los envía y la tierra se inunda.
16 Tìrẹ ni agbára àti ìṣẹ́gun; ẹni tí ń ṣìnà àti ẹni tí ń mú ni ṣìnà, tirẹ̀ ni wọ́n ń ṣe.
Con él están el poder y la sabiduría; el que es guiado al error, junto con su guía, está en sus manos;
17 Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòhò a sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀.
Él quita la sabiduría de los guías sabios, y hace que los jueces sean necios;
18 Ó tú ìdè ọba ó sì fi àmùrè gbà wọ́n ní ọ̀já.
Él deshace las cadenas de los reyes, y ata sus cinturas con lazos;
19 Ó mú àwọn àlùfáà lọ ní ìhòhò ó sì tẹ orí àwọn alágbára ba.
Él hace a los sacerdotes prisioneros, volcando a los que están en posiciones seguras;
20 Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò ó sì ra àwọn àgbàgbà ní iyè.
Él hace las palabras de personas responsables sin efecto, y quita el entendimiento a los ancianos;
21 Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́lá ó sì tú àmùrè àwọn alágbára.
Él avergüenza a los jefes, y quita el poder de los fuertes;
22 Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá ó sì mú òjìji ikú wá sínú ìmọ́lẹ̀.
Descubriendo cosas profundas de la oscuridad, y saca la sombra profunda a la luz;
23 Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n; òun a sọ orílẹ̀-èdè di ńlá, a sì tún ṣẹ̀ wọn kù.
Engrandece a las naciones y las destruye; Extendiendo las tierras de los pueblos, y luego las reúne.
24 Òun a gba òye àwọn olórí àwọn ènìyàn aráyé, a sì máa mú wọn rin kiri nínú ijù níbi tí ọ̀nà kò sí.
Él quita la sabiduría de los gobernantes de la tierra, y los envía vagando en un desierto donde no hay camino.
25 Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀; òun a sì máa mú ìrìn ìsìn wọn bí ọ̀mùtí.
Ellos van a tientas en la oscuridad sin luz, tambaleándose, como los borrachos.