< Job 12 >

1 Jobu sì dáhùn, ó sì wí pé,
Zatem odpowiedział Ijob i, rzekł:
2 “Kò sí àní àní níbẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni àwọn ènìyàn náà, ọgbọ́n yóò sì kú pẹ̀lú yín!
Wieraście wy sami ludźmi? i z wamiż umrze mądrość?
3 Ṣùgbọ́n èmi ní ìyè nínú gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin; èmi kò kéré sí i yín. Àní, ta ni kò mọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí?
Teżci ja mam serce jako i wy, anim jest podlejszym niżeli wy; a któż i tego nie wie, co i wy?
4 “Èmi dàbí ẹni tí a ń fi ṣe ẹlẹ́yà lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀, tí ó ké pe Ọlọ́run, tí ó sì dá a lóhùn, à ń fi olóòtítọ́ ẹni ìdúró ṣinṣin rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà!
Pośmiewiskiem jestem przyjacielowi memu, który gdy woła do Boga, ozywa mu się; naśmiewiskiem jest sprawiedliwy i doskonały.
5 Ó rọrùn fún ènìyàn láti fi ìbànújẹ́ ẹlòmíràn ṣe ẹlẹ́yà gẹ́gẹ́ bí ìpín àwọn ẹni tí ẹsẹ̀ wọn ṣetán láti yọ̀.
Ten, co jest upadku bliski, jest pochodnią wzgardzoną człowiekowi, według myśli pokoju zażywającemu.
6 Àgọ́ àwọn ìgárá ọlọ́ṣà wá láìní ìbẹ̀rù; àwọn tí ó sì ń mú Ọlọ́run bínú wà láìléwu, àwọn ẹni tí ó sì gbá òrìṣà mú ní ọwọ́ wọn.
Spokojne i bezpieczne są namioty zbójców tych, którzy draźnią Boga, którym Bóg daje w ręce dobre rzeczy.
7 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí bí àwọn ẹranko léèrè, wọn o kọ́ ọ ní ẹ̀kọ́, àti ẹyẹ ojú ọ̀run, wọn ó sì sọ fún ọ.
A nawet pytaj się proszę bydląt, a one cię nauczą; i ptastwa niebieskiego, a oznajmi tobie.
8 Tàbí ba ilẹ̀ ayé sọ̀rọ̀, yóò sì kọ́ ọ, àwọn ẹja inú òkun yóò sì sọ fún ọ.
Albo się rozmów z ziemią, a ona cię nauczy, i rozpowiedząć ryby morskie.
9 Ta ni kò mọ̀ nínú gbogbo nǹkan wọ̀nyí pé, ọwọ́ Olúwa ni ó ṣe nǹkan yìí?
Któż nie wie z tych wszystkich rzeczy, że to ręka Pańska sprawiła?
10 Ní ọwọ́ ẹni tí ẹ̀mí ohun alààyè gbogbo gbé wà, àti ẹ̀mí gbogbo aráyé.
W którego ręku jest dusza wszelkiej rzeczy żywej, i duch wszelkiego ciała ludzkiego.
11 Etí kì í dán ọ̀rọ̀ wò bí tàbí adùn ẹnu kì í sì í tọ́ oúnjẹ rẹ̀ wò bí?
Azaż nie ucho mowy doświadcza, jako usta pokarmu smakują?
12 Àwọn arúgbó ni ọgbọ́n wà fún, àti nínú gígùn ọjọ́ ni òye.
W ludziach starych jest mądrość, a w długich dniach roztropność.
13 “Ti Ọlọ́run ni ọgbọ́n àti agbára; òun ló ni ìmọ̀ àti òye.
Dopieroż u Pana jest mądrość, i siła, i rada, i umiejętność.
14 Kíyèsi i, ó bì wó, a kò sì lè gbe ró mọ́; Ó sé ènìyàn mọ́, kò sì sí ìtúsílẹ̀ kan.
Oto on burzy, a nikt nie zbuduje; zamknie człowieka, a nikt mu nie otworzy.
15 Kíyèsi i, ó dá àwọn omi dúró, wọ́n sì gbẹ; Ó sì rán wọn jáde, wọ́n sì ṣẹ̀ bo ilẹ̀ ayé yípo.
On gdy zatrzyma wody, wyschną; a gdy je wypuści, podwracają ziemię.
16 Tìrẹ ni agbára àti ìṣẹ́gun; ẹni tí ń ṣìnà àti ẹni tí ń mú ni ṣìnà, tirẹ̀ ni wọ́n ń ṣe.
U niego jest moc i mądrość. Jego jest błądzący, i w błąd zawodzący.
17 Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòhò a sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀.
On obiera radców z mądrości, a sędziów przywodzi do głupstwa.
18 Ó tú ìdè ọba ó sì fi àmùrè gbà wọ́n ní ọ̀já.
On pas królów rozwiązuje, i znowu przepasuje pasem biodra ich.
19 Ó mú àwọn àlùfáà lọ ní ìhòhò ó sì tẹ orí àwọn alágbára ba.
Podaje książęta na łup, a mocarze podwraca.
20 Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò ó sì ra àwọn àgbàgbà ní iyè.
Odejmuje usta krasomówcom, a rozsądek starym odbiera.
21 Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́lá ó sì tú àmùrè àwọn alágbára.
Wylewa wzgardę na książęta, a mdli siły mocarzów.
22 Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá ó sì mú òjìji ikú wá sínú ìmọ́lẹ̀.
On odkrywa głębokie rzeczy z ciemności, a wywodzi na jaśnię cień śmierci.
23 Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n; òun a sọ orílẹ̀-èdè di ńlá, a sì tún ṣẹ̀ wọn kù.
Rozmnaża narody, i wytraca je; rozszerza lud, i umniejsza go.
24 Òun a gba òye àwọn olórí àwọn ènìyàn aráyé, a sì máa mú wọn rin kiri nínú ijù níbi tí ọ̀nà kò sí.
On odejmuje serca przełożonym ludu ziemi, a czyni, że błądzą po pustyni bezdrożnej;
25 Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀; òun a sì máa mú ìrìn ìsìn wọn bí ọ̀mùtí.
Że macają w ciemnościach, gdzie nie masz światłości, a sprawuje, że błądzą jako pijani.

< Job 12 >