< Job 12 >

1 Jobu sì dáhùn, ó sì wí pé,
Felélt Jób és mondta:
2 “Kò sí àní àní níbẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni àwọn ènìyàn náà, ọgbọ́n yóò sì kú pẹ̀lú yín!
Valóban, ti vagytok ám a nép, s veletek kihal a bölcsesség!
3 Ṣùgbọ́n èmi ní ìyè nínú gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin; èmi kò kéré sí i yín. Àní, ta ni kò mọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí?
Nekem is van szívem mint nektek, nem esem messze tőletek, hisz kinél nem volnának effélék?
4 “Èmi dàbí ẹni tí a ń fi ṣe ẹlẹ́yà lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀, tí ó ké pe Ọlọ́run, tí ó sì dá a lóhùn, à ń fi olóòtítọ́ ẹni ìdúró ṣinṣin rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà!
Nevetségéül vagyok barátnak, ki Istent szólította s ő meghallgatta; nevetségül az igaz, a gáncstalan!
5 Ó rọrùn fún ènìyàn láti fi ìbànújẹ́ ẹlòmíràn ṣe ẹlẹ́yà gẹ́gẹ́ bí ìpín àwọn ẹni tí ẹsẹ̀ wọn ṣetán láti yọ̀.
A balvégzetnek megvetés, a gondtalannak vélekedése szerint, készen áll, a tántorgó lábúaknak.
6 Àgọ́ àwọn ìgárá ọlọ́ṣà wá láìní ìbẹ̀rù; àwọn tí ó sì ń mú Ọlọ́run bínú wà láìléwu, àwọn ẹni tí ó sì gbá òrìṣà mú ní ọwọ́ wọn.
Boldogságban vannak a rablók sátrai és biztosság azoké, kik Istent haragítják, azé, ki istenét kezében hordja.
7 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí bí àwọn ẹranko léèrè, wọn o kọ́ ọ ní ẹ̀kọ́, àti ẹyẹ ojú ọ̀run, wọn ó sì sọ fún ọ.
Azonban kérdezd csak meg a barmot, majd tanít téged, s az ég madarát, majd megjelenti neked;
8 Tàbí ba ilẹ̀ ayé sọ̀rọ̀, yóò sì kọ́ ọ, àwọn ẹja inú òkun yóò sì sọ fún ọ.
vagy szólj a földnek, majd tanít téged, és elbeszélik neked a tenger halai.
9 Ta ni kò mọ̀ nínú gbogbo nǹkan wọ̀nyí pé, ọwọ́ Olúwa ni ó ṣe nǹkan yìí?
Ki ne tudná mindezekből, hogy az Örökkévaló keze cselekedte ezt;
10 Ní ọwọ́ ẹni tí ẹ̀mí ohun alààyè gbogbo gbé wà, àti ẹ̀mí gbogbo aráyé.
kinek kezében van minden élőnek a lelke, s minden ember testének a szelleme.
11 Etí kì í dán ọ̀rọ̀ wò bí tàbí adùn ẹnu kì í sì í tọ́ oúnjẹ rẹ̀ wò bí?
Nemde a fül vizsgálja a szavakat s az íny az ételt ízleli meg?
12 Àwọn arúgbó ni ọgbọ́n wà fún, àti nínú gígùn ọjọ́ ni òye.
Aggastyánokban van bölcsesség, s hosszú élet: értelmesség.
13 “Ti Ọlọ́run ni ọgbọ́n àti agbára; òun ló ni ìmọ̀ àti òye.
Ő nála van bölcsesség és erő, övé tanács és értelmesség!
14 Kíyèsi i, ó bì wó, a kò sì lè gbe ró mọ́; Ó sé ènìyàn mọ́, kò sì sí ìtúsílẹ̀ kan.
Lám, lerombol s nem építtetik föl, rázár valakire s nem nyittatik ki neki.
15 Kíyèsi i, ó dá àwọn omi dúró, wọ́n sì gbẹ; Ó sì rán wọn jáde, wọ́n sì ṣẹ̀ bo ilẹ̀ ayé yípo.
Im elrekeszt vizeket s kiszáradnak – megereszti őket s feldúlják a földet.
16 Tìrẹ ni agbára àti ìṣẹ́gun; ẹni tí ń ṣìnà àti ẹni tí ń mú ni ṣìnà, tirẹ̀ ni wọ́n ń ṣe.
Ő nála van hatalom és üdvösség, övé a tévelygő és a megtévesztő.
17 Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòhò a sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀.
Járatja a tanácsosokat megfosztottan s a bírákat megtébolyítja;
18 Ó tú ìdè ọba ó sì fi àmùrè gbà wọ́n ní ọ̀já.
a királyok kötelékét föloldotta és reákötött övet az ő derekukra;
19 Ó mú àwọn àlùfáà lọ ní ìhòhò ó sì tẹ orí àwọn alágbára ba.
járatja a papokat megfosztottan s a szilárdakat elferdíti;
20 Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò ó sì ra àwọn àgbàgbà ní iyè.
megvonja a biztosszavúak beszédjét s a véneknek eszét elveszi;
21 Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́lá ó sì tú àmùrè àwọn alágbára.
csúfot önt a nemesekre s a hatalmasoknak kötését meglazítja.
22 Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá ó sì mú òjìji ikú wá sínú ìmọ́lẹ̀.
Feltár mély dolgokat a sötétségből s kihozza világosságra a vakhomályt.
23 Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n; òun a sọ orílẹ̀-èdè di ńlá, a sì tún ṣẹ̀ wọn kù.
Nagyra növeszti a nemzeteket s elveszíti, kiterjeszti a nemzeteket és elviszi.
24 Òun a gba òye àwọn olórí àwọn ènìyàn aráyé, a sì máa mú wọn rin kiri nínú ijù níbi tí ọ̀nà kò sí.
Szívét veszi az ország népe fejeinek s eltévelyíti úttalan pusztaságban;
25 Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀; òun a sì máa mú ìrìn ìsìn wọn bí ọ̀mùtí.
tapogatóznak sötétségben világosság nélkül, s eltévelyíti őket mint a részeget.

< Job 12 >