< Job 12 >

1 Jobu sì dáhùn, ó sì wí pé,
Alors Job répondit,
2 “Kò sí àní àní níbẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni àwọn ènìyàn náà, ọgbọ́n yóò sì kú pẹ̀lú yín!
« Sans doute, mais c'est vous qui êtes le peuple, et la sagesse mourra avec vous.
3 Ṣùgbọ́n èmi ní ìyè nínú gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin; èmi kò kéré sí i yín. Àní, ta ni kò mọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí?
Mais j'ai de l'intelligence aussi bien que vous; Je ne suis pas inférieur à vous. Oui, qui ne connaît pas ce genre de choses?
4 “Èmi dàbí ẹni tí a ń fi ṣe ẹlẹ́yà lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀, tí ó ké pe Ọlọ́run, tí ó sì dá a lóhùn, à ń fi olóòtítọ́ ẹni ìdúró ṣinṣin rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà!
Je suis comme celui qui se moque de son prochain, Moi, qui ai invoqué Dieu, et il m'a répondu. Le juste, l'homme irréprochable est une blague.
5 Ó rọrùn fún ènìyàn láti fi ìbànújẹ́ ẹlòmíràn ṣe ẹlẹ́yà gẹ́gẹ́ bí ìpín àwọn ẹni tí ẹsẹ̀ wọn ṣetán láti yọ̀.
Dans la pensée de celui qui est à l'aise, il y a du mépris pour le malheur. Il est prêt pour ceux dont le pied glisse.
6 Àgọ́ àwọn ìgárá ọlọ́ṣà wá láìní ìbẹ̀rù; àwọn tí ó sì ń mú Ọlọ́run bínú wà láìléwu, àwọn ẹni tí ó sì gbá òrìṣà mú ní ọwọ́ wọn.
Les tentes des brigands prospèrent. Ceux qui provoquent Dieu sont en sécurité, qui portent leur dieu dans leurs mains.
7 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí bí àwọn ẹranko léèrè, wọn o kọ́ ọ ní ẹ̀kọ́, àti ẹyẹ ojú ọ̀run, wọn ó sì sọ fún ọ.
« Mais demande maintenant aux animaux, et ils t'apprendront; les oiseaux du ciel, et ils vous le diront.
8 Tàbí ba ilẹ̀ ayé sọ̀rọ̀, yóò sì kọ́ ọ, àwọn ẹja inú òkun yóò sì sọ fún ọ.
Ou bien parle à la terre, et elle t'enseignera. Les poissons de la mer te déclareront.
9 Ta ni kò mọ̀ nínú gbogbo nǹkan wọ̀nyí pé, ọwọ́ Olúwa ni ó ṣe nǹkan yìí?
Qui ne sait pas que dans tout cela, La main de Yahvé a fait cela,
10 Ní ọwọ́ ẹni tí ẹ̀mí ohun alààyè gbogbo gbé wà, àti ẹ̀mí gbogbo aráyé.
dans la main duquel se trouve la vie de tout être vivant, et le souffle de toute l'humanité?
11 Etí kì í dán ọ̀rọ̀ wò bí tàbí adùn ẹnu kì í sì í tọ́ oúnjẹ rẹ̀ wò bí?
L'oreille n'essaie pas les mots, même lorsque le palais goûte sa nourriture?
12 Àwọn arúgbó ni ọgbọ́n wà fún, àti nínú gígùn ọjọ́ ni òye.
Avec les hommes âgés se trouve la sagesse, dans la compréhension de la durée des jours.
13 “Ti Ọlọ́run ni ọgbọ́n àti agbára; òun ló ni ìmọ̀ àti òye.
« La sagesse et la puissance sont auprès de Dieu. Il a le conseil et la compréhension.
14 Kíyèsi i, ó bì wó, a kò sì lè gbe ró mọ́; Ó sé ènìyàn mọ́, kò sì sí ìtúsílẹ̀ kan.
Voici qu'il s'écroule, et il ne peut plus être reconstruit. Il emprisonne un homme, et il ne peut pas être libéré.
15 Kíyèsi i, ó dá àwọn omi dúró, wọ́n sì gbẹ; Ó sì rán wọn jáde, wọ́n sì ṣẹ̀ bo ilẹ̀ ayé yípo.
Voici, il retient les eaux, et elles tarissent. Encore une fois, il les envoie, et ils renversent la terre.
16 Tìrẹ ni agbára àti ìṣẹ́gun; ẹni tí ń ṣìnà àti ẹni tí ń mú ni ṣìnà, tirẹ̀ ni wọ́n ń ṣe.
Avec lui, il y a la force et la sagesse. Le trompé et le trompeur sont à lui.
17 Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòhò a sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀.
Il conduit les conseillers à l'écart, dépouillés. Il fait des juges des imbéciles.
18 Ó tú ìdè ọba ó sì fi àmùrè gbà wọ́n ní ọ̀já.
Il délie les liens des rois. Il leur attache la taille avec une ceinture.
19 Ó mú àwọn àlùfáà lọ ní ìhòhò ó sì tẹ orí àwọn alágbára ba.
Il emmène les prêtres dépouillés, et renverse les puissants.
20 Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò ó sì ra àwọn àgbàgbà ní iyè.
Il supprime la parole de ceux à qui l'on fait confiance, et enlève l'intelligence des anciens.
21 Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́lá ó sì tú àmùrè àwọn alágbára.
Il répand le mépris sur les princes, et détache la ceinture des forts.
22 Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá ó sì mú òjìji ikú wá sínú ìmọ́lẹ̀.
Il découvre des choses profondes dans les ténèbres, et fait apparaître à la lumière l'ombre de la mort.
23 Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n; òun a sọ orílẹ̀-èdè di ńlá, a sì tún ṣẹ̀ wọn kù.
Il augmente les nations, et il les détruit. Il agrandit les nations, et il les conduit en captivité.
24 Òun a gba òye àwọn olórí àwọn ènìyàn aráyé, a sì máa mú wọn rin kiri nínú ijù níbi tí ọ̀nà kò sí.
Il enlève l'intelligence aux chefs des peuples de la terre, et les fait errer dans un désert où il n'y a pas de chemin.
25 Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀; òun a sì máa mú ìrìn ìsìn wọn bí ọ̀mùtí.
Ils tâtonnent dans l'obscurité, sans lumière. Il les fait tituber comme un homme ivre.

< Job 12 >