< Job 12 >

1 Jobu sì dáhùn, ó sì wí pé,
Then Job said [to his three friends],
2 “Kò sí àní àní níbẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni àwọn ènìyàn náà, ọgbọ́n yóò sì kú pẹ̀lú yín!
“You (talk as though/You think) [SAR] that you are the people [whom everyone should listen to], and that when you die, there will be no more wise people.
3 Ṣùgbọ́n èmi ní ìyè nínú gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin; èmi kò kéré sí i yín. Àní, ta ni kò mọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí?
But I have as much good sense as you do; I am (not less wise than/certainly as wise as [LIT]) you. Certainly everyone knows [RHQ] all that you have said.
4 “Èmi dàbí ẹni tí a ń fi ṣe ẹlẹ́yà lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀, tí ó ké pe Ọlọ́run, tí ó sì dá a lóhùn, à ń fi olóòtítọ́ ẹni ìdúró ṣinṣin rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà!
My friends all laugh at me now. Previously I habitually requested God to help me, and he answered/helped me. I am righteous, a very godly man [DOU], but everyone laughs at me.
5 Ó rọrùn fún ènìyàn láti fi ìbànújẹ́ ẹlòmíràn ṣe ẹlẹ́yà gẹ́gẹ́ bí ìpín àwọn ẹni tí ẹsẹ̀ wọn ṣetán láti yọ̀.
Those [like you] who have no troubles make fun of me; they cause those [like me] who are already suffering to have more troubles.
6 Àgọ́ àwọn ìgárá ọlọ́ṣà wá láìní ìbẹ̀rù; àwọn tí ó sì ń mú Ọlọ́run bínú wà láìléwu, àwọn ẹni tí ó sì gbá òrìṣà mú ní ọwọ́ wọn.
Bandits live peacefully, and no one threatens those who cause God to become angry; their own strength is the god [that they worship].
7 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí bí àwọn ẹranko léèrè, wọn o kọ́ ọ ní ẹ̀kọ́, àti ẹyẹ ojú ọ̀run, wọn ó sì sọ fún ọ.
“But ask the wild animals [what they know about God], and [if they could speak] they would teach you. [If you could] ask the birds, they would tell you.
8 Tàbí ba ilẹ̀ ayé sọ̀rọ̀, yóò sì kọ́ ọ, àwọn ẹja inú òkun yóò sì sọ fún ọ.
[If you could] ask the creatures [that crawl] on the ground, or the fish in the sea, they would tell you [about God].
9 Ta ni kò mọ̀ nínú gbogbo nǹkan wọ̀nyí pé, ọwọ́ Olúwa ni ó ṣe nǹkan yìí?
All of them certainly know [RHQ] that it is Yahweh who has made them with his hands.
10 Ní ọwọ́ ẹni tí ẹ̀mí ohun alààyè gbogbo gbé wà, àti ẹ̀mí gbogbo aráyé.
He directs the lives of all living creatures; he gives breath to all [us] humans [to enable us to remain alive].
11 Etí kì í dán ọ̀rọ̀ wò bí tàbí adùn ẹnu kì í sì í tọ́ oúnjẹ rẹ̀ wò bí?
And when we [SYN] hear what other people [like you] say, we [RHQ] think carefully about what they say [to determine what is good and what is bad], like we [SYN] taste food [to determine what is good and what is bad].
12 Àwọn arúgbó ni ọgbọ́n wà fún, àti nínú gígùn ọjọ́ ni òye.
Old people are [often] very wise, and because of having lived many years, they understand much,
13 “Ti Ọlọ́run ni ọgbọ́n àti agbára; òun ló ni ìmọ̀ àti òye.
but God is wise and very powerful; he has good sense and understands [everything].
14 Kíyèsi i, ó bì wó, a kò sì lè gbe ró mọ́; Ó sé ènìyàn mọ́, kò sì sí ìtúsílẹ̀ kan.
If he tears [something] down, no one can rebuild it; if he puts someone in prison, no one can open [the prison doors to allow that person to escape].
15 Kíyèsi i, ó dá àwọn omi dúró, wọ́n sì gbẹ; Ó sì rán wọn jáde, wọ́n sì ṣẹ̀ bo ilẹ̀ ayé yípo.
When he prevents rain from falling, everything dries up. When he causes a lot of rain to fall, [the result is that] there are floods.
16 Tìrẹ ni agbára àti ìṣẹ́gun; ẹni tí ń ṣìnà àti ẹni tí ń mú ni ṣìnà, tirẹ̀ ni wọ́n ń ṣe.
He is the one who is truly strong and wise; he rules over those who deceive others and those whom they deceive.
17 Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòhò a sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀.
He [sometimes] causes [the king’s] officials to no longer be wise, and he causes judges to become foolish.
18 Ó tú ìdè ọba ó sì fi àmùrè gbà wọ́n ní ọ̀já.
He takes from kings the robes that they wear and puts loincloths around their waists, [causing them to become slaves].
19 Ó mú àwọn àlùfáà lọ ní ìhòhò ó sì tẹ orí àwọn alágbára ba.
He takes from priests the sacred clothes that they wear, [with the result that they no longer can do their work], and takes power from those who rule others.
20 Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò ó sì ra àwọn àgbàgbà ní iyè.
He [sometimes] causes those whom others trust to be unable to speak, and he causes old men to no longer have good sense.
21 Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́lá ó sì tú àmùrè àwọn alágbára.
He causes those who have authority to be despised, and he causes those who are powerful to no longer have any power/strength.
22 Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá ó sì mú òjìji ikú wá sínú ìmọ́lẹ̀.
He causes things that are hidden in the darkness to be revealed.
23 Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n; òun a sọ orílẹ̀-èdè di ńlá, a sì tún ṣẹ̀ wọn kù.
He causes some nations to become very great, and [later] he destroys them; he causes the territory of some nations to become much larger, and [later] he causes them to be defeated and their people to be scattered.
24 Òun a gba òye àwọn olórí àwọn ènìyàn aráyé, a sì máa mú wọn rin kiri nínú ijù níbi tí ọ̀nà kò sí.
He causes [some] rulers to become foolish/stupid, and then he causes them to wander around, lost, in an barren desert.
25 Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀; òun a sì máa mú ìrìn ìsìn wọn bí ọ̀mùtí.
They grope around in the darkness, without any light, and he causes them to stagger like [SIM] people who are drunk.”

< Job 12 >