< Job 11 >

1 Ìgbà náà ni Sofari, ará Naama, dáhùn, ó sì wí pé,
Wtedy Sofar z Naamy odpowiedział:
2 “A ha lè ṣe kí a máa dáhùn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rọ̀? A ha lè fi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí da ènìyàn láre?
Czy nie należy odpowiedzieć na takie mnóstwo słów? Czy człowiek gadatliwy ma być usprawiedliwiony?
3 Ṣé àmọ̀tán rẹ le mú ènìyàn pa ẹnu wọn mọ́ bí? Ṣé ẹnikẹ́ni kò ní bá ọ wí bí ìwọ bá yọ ṣùtì sí ni?
Czy ludzie mają milczeć na twoje kłamstwa? A gdy kpisz, nikt cię nie zawstydzi?
4 Ìwọ sá à ti wí fún Ọlọ́run pé, ‘Ìṣe mi jẹ́ aláìléérí, èmi sì mọ́ ní ojú rẹ.’
Powiedziałeś bowiem: Moja nauka jest czysta, jestem czysty w twoich oczach.
5 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ìbá jẹ́ sọ̀rọ̀, kí ó sì ya ẹnu rẹ̀ sí ọ
O gdyby Bóg zechciał przemówić i otworzyć usta przeciwko tobie;
6 kí ó sì fi àṣírí ọgbọ́n hàn ọ́ pé, ó pọ̀ ju òye ènìyàn lọ, nítorí náà, mọ̀ pé Ọlọ́run ti gbàgbé àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kan.
Gdyby objawił tajemnice mądrości – że zasługujesz na dwa razy większą [karę]. Poznaj więc, ile Bóg ci przebaczył za twoją nieprawość.
7 “Ìwọ ha le ṣe àwárí ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run bí? Ìwọ ha le ṣe àwárí ibi tí Olódùmarè dé bi?
Czy wybadasz tajemnice Boga? Czy zgłębisz doskonałość Wszechmocnego?
8 Ó ga ju àwọn ọ̀run lọ; kí ni ìwọ le è ṣe? Ó jìn ju jíjìn isà òkú lọ; kí ni ìwọ le mọ̀? (Sheol h7585)
Są wyżej niż niebiosa, co [możesz z tym] uczynić? Głębsze niż piekło, czy [możesz je] poznać? (Sheol h7585)
9 Ìwọ̀n rẹ̀ gùn ju ayé lọ, ó sì ní ibú ju òkun lọ.
Ich miara jest dłuższa niż ziemia i szersza niż morze.
10 “Bí òun bá rékọjá, tí ó sì sé ọnà tàbí tí ó sì mú ni wá sí ìdájọ́, ǹjẹ́, ta ni ó lè dí i lọ́wọ́?
Jeśli wycina, zamyka albo gromadzi, któż go powstrzyma?
11 Òun sá à mọ ẹlẹ́tàn ènìyàn; àti pé ṣé bí òun bá rí ohun búburú, ṣé òun kì i fi iyè sí i?
On bowiem zna marność ludzi i widzi niegodziwość. Czy miałby na to nie zważać?
12 Ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn ki yóò di ọlọ́gbọ́n bi ko ti rọrùn fún ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó láti bí ènìyàn.
Człowiek nierozumny może nabyć rozumu, choć człowiek rodzi się jak źrebię dzikiego osła.
13 “Bí ìwọ bá fi ọkàn rẹ fún un, tí ìwọ sì na ọwọ́ rẹ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀,
Jeśli przygotujesz swoje serce i wyciągniesz do niego swoje ręce;
14 bí ìwọ bá gbé ẹ̀ṣẹ̀ tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ jù sọnù tí ìwọ kò sì jẹ́ kí aburú gbé nínú àgọ́ rẹ,
Jeśli w twoich rękach [jest] nieprawość, oddal ją i nie pozwól, aby niegodziwość mieszkała w twoich przybytkach.
15 nígbà náà ni ìwọ ó gbé ojú rẹ sókè láìní àbàwọ́n, àní ìwọ yóò dúró ṣinṣin, ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù.
Wtedy podniesiesz swoje oblicze bez zmazy, będziesz stały i nie będziesz się bał.
16 Nítorí pé ìwọ ó gbàgbé ìṣòro rẹ; ìwọ ó sì rántí rẹ̀ bí omi tí ó ti sàn kọjá lọ.
Zapomnisz bowiem o swojej udręce i wspomnisz ją tak jak wody, które przepłynęły.
17 Ọjọ́ ayé rẹ yóò sì mọ́lẹ̀ ju ọ̀sán gangan lọ, bí òkùnkùn tilẹ̀ bò ọ́ mọ́lẹ̀ nísinsin yìí, ìwọ ó dàbí òwúrọ̀.
I [twoje] życie będzie [jaśniejsze] niż południe; twoja ciemność będzie jak poranek.
18 Ìwọ ó sì wà láìléwu, nítorí pé ìrètí wà; àní ìwọ ó rin ilé rẹ wò, ìwọ ó sì sinmi ní àlàáfíà.
Będziesz ufał, mając nadzieję; będziesz kopać dokoła i odpoczniesz bezpiecznie.
19 Ìwọ ó sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú, kì yóò sì sí ẹni tí yóò dẹ́rùbà ọ́, àní ènìyàn yóò máa wá ojúrere rẹ.
Położysz się i nikt cię nie przestraszy; wielu uniży się [przed] twoim obliczem.
20 Ṣùgbọ́n ojú ìkà ènìyàn yóò mófo; gbogbo ọ̀nà àbáyọ ni yóò nù wọ́n, ìrètí wọn a sì dàbí ẹni tí ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́.”
Ale oczy niegodziwych przygasną i nie będzie dla nich ucieczki, a ich nadzieja [będzie jak] wyzionięcie ducha.

< Job 11 >