< Job 11 >

1 Ìgbà náà ni Sofari, ará Naama, dáhùn, ó sì wí pé,
And he answered Zophar the Naamathite and he said.
2 “A ha lè ṣe kí a máa dáhùn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rọ̀? A ha lè fi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí da ènìyàn láre?
¿ A multitude of words not will it be answered and or? a man of lips will he be acquitted.
3 Ṣé àmọ̀tán rẹ le mú ènìyàn pa ẹnu wọn mọ́ bí? Ṣé ẹnikẹ́ni kò ní bá ọ wí bí ìwọ bá yọ ṣùtì sí ni?
Empty boasts your men will they silence? and have you mocked? and there not [is one who] puts to shame.
4 Ìwọ sá à ti wí fún Ọlọ́run pé, ‘Ìṣe mi jẹ́ aláìléérí, èmi sì mọ́ ní ojú rẹ.’
And you have said [is] pure teaching my and clean I am in view your.
5 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ìbá jẹ́ sọ̀rọ̀, kí ó sì ya ẹnu rẹ̀ sí ọ
And but who? will he give God to speak and he may open lips his with you.
6 kí ó sì fi àṣírí ọgbọ́n hàn ọ́ pé, ó pọ̀ ju òye ènìyàn lọ, nítorí náà, mọ̀ pé Ọlọ́run ti gbàgbé àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kan.
And may he tell to you - [the] secrets of wisdom for double [belongs] to sound wisdom and know that he will cause to forget to you God some of iniquity your.
7 “Ìwọ ha le ṣe àwárí ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run bí? Ìwọ ha le ṣe àwárí ibi tí Olódùmarè dé bi?
¿ [the] searching of God will you find or? to [the] end of [the] Almighty will you find.
8 Ó ga ju àwọn ọ̀run lọ; kí ni ìwọ le è ṣe? Ó jìn ju jíjìn isà òkú lọ; kí ni ìwọ le mọ̀? (Sheol h7585)
[the] heights of [the] heavens What? will you do deep more than Sheol what? will you know. (Sheol h7585)
9 Ìwọ̀n rẹ̀ gùn ju ayé lọ, ó sì ní ibú ju òkun lọ.
[is] long More than [the] earth measure its and broad more than [the] sea.
10 “Bí òun bá rékọjá, tí ó sì sé ọnà tàbí tí ó sì mú ni wá sí ìdájọ́, ǹjẹ́, ta ni ó lè dí i lọ́wọ́?
If he will pass by and he may shut up so he may summon an assembly and who? will he turn back him.
11 Òun sá à mọ ẹlẹ́tàn ènìyàn; àti pé ṣé bí òun bá rí ohun búburú, ṣé òun kì i fi iyè sí i?
For he he knows men of falsehood and he has seen wickedness and not he shows himself attentive.
12 Ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn ki yóò di ọlọ́gbọ́n bi ko ti rọrùn fún ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó láti bí ènìyàn.
And a person hollow he will become intelligent and a male donkey of a wild donkey a human being it will be born.
13 “Bí ìwọ bá fi ọkàn rẹ fún un, tí ìwọ sì na ọwọ́ rẹ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀,
If you you have directed heart your and you will spread out to him palms your.
14 bí ìwọ bá gbé ẹ̀ṣẹ̀ tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ jù sọnù tí ìwọ kò sì jẹ́ kí aburú gbé nínú àgọ́ rẹ,
If wickedness [is] in hand your put far away it and may not you cause to dwell in tents your injustice.
15 nígbà náà ni ìwọ ó gbé ojú rẹ sókè láìní àbàwọ́n, àní ìwọ yóò dúró ṣinṣin, ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù.
For then - you will lift up face your from blemish and you will be firmly established and not you will fear.
16 Nítorí pé ìwọ ó gbàgbé ìṣòro rẹ; ìwọ ó sì rántí rẹ̀ bí omi tí ó ti sàn kọjá lọ.
For you trouble you will forget like waters [which] they have passed away you will remember [it].
17 Ọjọ́ ayé rẹ yóò sì mọ́lẹ̀ ju ọ̀sán gangan lọ, bí òkùnkùn tilẹ̀ bò ọ́ mọ́lẹ̀ nísinsin yìí, ìwọ ó dàbí òwúrọ̀.
And more than noon it will rise lifespan it will be dark like the morning it will become.
18 Ìwọ ó sì wà láìléwu, nítorí pé ìrètí wà; àní ìwọ ó rin ilé rẹ wò, ìwọ ó sì sinmi ní àlàáfíà.
And you will be secure for there [is] hope and you will be well protected to security you will lie down.
19 Ìwọ ó sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú, kì yóò sì sí ẹni tí yóò dẹ́rùbà ọ́, àní ènìyàn yóò máa wá ojúrere rẹ.
And you will lie down and there not [will be one who] disturbs and they will entreat face your many [people].
20 Ṣùgbọ́n ojú ìkà ènìyàn yóò mófo; gbogbo ọ̀nà àbáyọ ni yóò nù wọ́n, ìrètí wọn a sì dàbí ẹni tí ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́.”
And [the] eyes of wicked [people] they will fail and a place of escape it will be lost from them and hope their [will be] a gasp of life.

< Job 11 >