< Job 1 >

1 Ọkùnrin kan wà ní ilẹ̀ Usi, orúkọ ẹni tí í jẹ́ Jobu; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́, ó dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó kórìíra ìwà búburú.
«Uz» degǝn yurtta, Ayup isimlik bir adǝm yaxiƣanidi. Bu adǝm bolsa ⱪusursiz, durus, Hudadin ⱪorⱪidiƣan, yamanliⱪtin ɵzini yiraⱪ tutidiƣan adǝm idi.
2 A sì bi ọmọkùnrin méje àti ọmọbìnrin mẹ́ta fún un.
Uningdin yǝttǝ oƣul wǝ üq ⱪiz tuƣuldi.
3 Ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ìbákasẹ, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta àjàgà ọ̀dá màlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì pọ̀; bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin yìí sì pọ̀jù gbogbo àwọn ará ìlà-oòrùn lọ.
Uning yǝttǝ ming ⱪoy, üq ming tɵgǝ, bǝx yüz jüp kala, bǝx yüz mada exǝk ⱪatarliⱪ mal-mülki bar idi. Uning malayliri bǝk kɵp idi; u xǝrⱪliⱪlǝr iqidǝ ⱨǝmmidin uluƣ idi.
4 Àwọn ọmọ rẹ̀ a sì máa lọ í jẹun àsè nínú ilé ara wọn, olúkúlùkù ní ọjọ́ rẹ̀; wọn a sì máa ránṣẹ́ pé arábìnrin wọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta láti jẹun àti láti pẹ̀lú wọn.
Uning oƣulliri nɵwǝt boyiqǝ bekitkǝn kündǝ ɵz ɵyidǝ baxⱪilar üqün dastihan selip ziyapǝt ⱪilatti. Bu künlǝrdǝ ular adǝm ǝwǝtip üq singlisini ular bilǝn billǝ tamaⱪlinixⱪa qaⱪiritatti.
5 Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ àsè wọn pé yíká, ni Jobu ránṣẹ́ lọ í yà wọ́n sí mímọ́, ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì rú ẹbọ sísun níwọ̀n iye gbogbo wọn; nítorí tí Jobu wí pé: bóyá àwọn ọmọ mi ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣọpẹ́ fún Ọlọ́run lọ́kàn wọn. Bẹ́ẹ̀ ní Jobu máa ń ṣe nígbà gbogbo.
Ularning xu ziyapǝt künliri ayaƣlixi bilǝn Ayup adǝm ǝwǝtip ularni Huda aldida paklinixⱪa orunlaxturatti. U tang sǝⱨǝrdǝ ornidin turup ularning saniƣa asasǝn kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪlarni ⱪilatti. Qünki Ayup: «Balilirim gunaⱨ ⱪilip ⱪoyup, kɵnglidǝ Hudaƣa biⱨɵrmǝtlik ⱪilip ⱪoyamdikin» dǝp oylaytti. Ayup ⱨǝrdaim ǝnǝ xundaⱪ ⱪilip turatti.
6 Ǹjẹ́ ó di ọjọ́ kan, nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá í pé níwájú Olúwa, Satani sì wá pẹ̀lú wọn.
Bir küni, Hudaning oƣulliri Pǝrwǝrdigarning ⱨuzuriƣa ⱨazir boldi. Xǝytanmu ularning arisiƣa kiriwaldi.
7 Olúwa sì bi Satani wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Nígbà náà ní Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Ní ìlọsíwá-sẹ́yìn lórí ilẹ̀ ayé, àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”
Pǝrwǝrdigar Xǝytandin: — Nǝdin kǝlding? — dǝp soridi. Xǝytan Pǝrwǝrdigarƣa jawabǝn: — Yǝr yüzini kezip paylap, uyaⱪ-buyaⱪlarni aylinip qɵrgilǝp kǝldim, dedi.
8 Olúwa sì sọ fún Satani pé, “Ìwọ ha kíyèsi Jobu ìránṣẹ́ mi, pé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí í ṣe olóòtítọ́, tí ó sì dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ti ó sì kórìíra ìwà búburú.”
Pǝrwǝrdigar uningƣa: — Mening ⱪulum Ayupⱪa diⱪⱪǝt ⱪilƣansǝn? Yǝr yüzidǝ uningdǝk mukǝmmǝl, durus, Hudadin ⱪorⱪidiƣan ⱨǝm yamanliⱪtin yiraⱪ turidiƣan adǝm yoⱪ, — dedi.
9 Nígbà náà ni Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Jobu ha bẹ̀rù Ọlọ́run ní asán bí?”
Xǝytan Pǝrwǝrdigarƣa jawabǝn: — Ayup Hudadin bikardin bikar ⱪorⱪmiƣandu?
10 “Ìwọ kò ha ti ṣọgbà yìí ká, àti yí ilé rẹ̀ àti yí ohun tí ó ní ká, ní ìhà gbogbo? Ìwọ bùsi iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì ń pọ̀ si ní ilẹ̀.
Ɵzüng uning ɵzi, ailisidikiliri ⱨǝm uning ⱨǝmmǝ nǝrsisining ǝtrapiƣa ⱪaxa ⱪoyƣan ǝmǝsmu? Sǝn uning ⱪoliƣa bǝrikǝt ata ⱪilding, xuning bilǝn uning tǝǝlluⱪati tǝrǝp-tǝrǝptin güllinip awumaⱪta.
11 Ǹjẹ́, nawọ́ rẹ nísinsin yìí, kí ó sì fi tọ́ ohun gbogbo tí ó ni; bí kì yóò sì bọ́hùn ni ojú rẹ.”
Əgǝr Sǝn ⱪolungni sozup, uning ⱨǝmmǝ nǝrsilirigǝ tegip ⱪoysang, u Sǝndin yüz ɵrüp, Seni tillimisa [Xǝytan bolmay ketǝy]! — dedi.
12 Olúwa sì dá Satani lóhùn wí pé, “Kíyèsi i, ohun gbogbo tí ó ní ń bẹ ní ìkáwọ́ rẹ, kìkì òun tìkára rẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ rẹ kàn.” Bẹ́ẹ̀ ni Satani jáde lọ kúrò níwájú Olúwa.
Pǝrwǝrdigar Xǝytanƣa: — Mana, uning ⱨǝmmǝ nǝrsisini sening ⱪolungƣa tutⱪuzdum! Biraⱪ uning ɵzigǝ tǝgküqi bolma! — dedi. Xundaⱪ ⱪilip Xǝytan Pǝrwǝrdigarning ⱨuzuridin qiⱪip kǝtti.
13 Ó sì di ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, tí wọ́n mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n wọn ọkùnrin,
Bir küni, Ayupning oƣul-ⱪizliri qong akisining ɵyidǝ tamaⱪ yǝp, xarab iqip olturatti.
14 oníṣẹ́ kan sì tọ Jobu wá wí pé, “Àwọn ọ̀dá màlúù ń tulẹ̀, àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì ń jẹ ní ẹ̀gbẹ́ wọn,
Bir hǝwǝrqi Ayupning yeniƣa kelip uningƣa: — Kalilar bilǝn yǝr ⱨǝydǝwatattuⱪ, exǝklǝr ǝtrapta otlawatatti;
15 àwọn ará Sabeani sì kọlù wọ́n, wọ́n sì ń kó wọn lọ pẹ̀lú, wọ́n ti fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa, èmi nìkan ṣoṣo ní ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ.”
Xebaliⱪlar ⱨujum ⱪilip kala-exǝklǝrni bulap kǝtti. Ixlǝwatⱪan yaxlarni ⱪiliqlap ɵltüriwǝtti. Yalƣuz mǝnla ⱪutulup ⱪelip, siligǝ hǝwǝr yǝtküzüxkǝ nesip boldi, — dedi.
16 Bí ó ti ń sọ ní ẹnu; ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé, “Iná ńlá Ọlọ́run ti ọ̀run bọ́ sí ilẹ̀, ó sì jó àwọn àgùntàn àti àwọn ìránṣẹ́; èmi nìkan ṣoṣo ní ó sálà láti ròyìn fún ọ.”
Bu adǝmning gepi tehi tügimǝy turupla, yǝnǝ birsi yügürüp kelip Ayupⱪa: — Asmandin Hudaning oti qüxüp ⱪoylar wǝ ixlǝwatⱪan yaxlarni kɵydüriwǝtti; yalƣuz mǝnla ⱪutulup ⱪaldim, siligǝ hǝwǝr yǝtküzüxkǝ nesip boldum, — dedi.
17 Bí ó sì ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan sì dé pẹ̀lú tí ó wí pé, “Àwọn ará Kaldea píngun sí ọ̀nà mẹ́ta, wọ́n sì kọlù àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì kó wọn lọ, pẹ̀lúpẹ̀lú wọ́n sì fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa; èmi nìkan ṣoṣo ni ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ!”
Bu adǝmning gepi tehi tügimǝy turupla, yǝnǝ birsi yügürüp kelip Ayupⱪa: — Kaldiylǝr üq tǝrǝptin ⱨujum ⱪilip tɵgilǝrni bulap elip kǝtti, ixlǝwatⱪan yaxlarni ⱪiliqlap ɵltürüwǝtti; yalƣuz mǝnla ⱪutulup ⱪaldim, siligǝ hǝwǝr yǝtküzüxkǝ nesip boldum, — dedi.
18 Bí ó ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin ń jẹ, wọ́n ń mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n.
Bu adǝmning gepi tehi tügimǝy turupla, yǝnǝ birsi yügürüp kelip Ayupⱪa: — Oƣulliri wǝ ⱪizliri qong akisining ɵyidǝ tamaⱪ yǝp, xarab iqip olturƣinida,
19 Sì kíyèsi i, ẹ̀fúùfù ńlá ńlá ti ìhà ijù fẹ́ wá kọlu igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilé, ó sì wó lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wọ́n sì kú, èmi nìkan ṣoṣo ni ó yọ láti ròyìn fún ọ.
tuyuⱪsiz, qɵldin ⱪattiⱪ bir boran qiⱪip ɵyning tɵt bulungini ⱪattiⱪ soⱪup, ɵy ƣulap qüxüp yaxlarni ɵltürüwǝtti; yalƣuz mǝnla ⱪutulup ⱪaldim, siligǝ hǝwǝr yǝtküzüxkǝ nesip boldum, — dedi.
20 Nígbà náà ni Jobu dìde, ó sì fa aṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya, ó sì fá orí rẹ̀ ó wólẹ̀ ó sì gbàdúrà
Ayup bolsa buni anglap ornidin dǝs turup, tonini yirtip, qeqini qüxüriwetip, ɵzini yǝrgǝ taxlap Hudaƣa ibadǝt ⱪildi: —
21 wí pé, “Ní ìhòhò ní mo ti inú ìyá mi jáde wá, ni ìhòhò ní èmi yóò sì tún padà lọ. Olúwa fi fún ni, Olúwa sì gbà á lọ, ìbùkún ni fún orúkọ Olúwa.”
Mǝn apamning ⱪorsiⱪidin yalingaq qüxkǝn, u yǝrgimu yalingaq ⱪaytimǝn; ⱨǝmmini Pǝrwǝrdigar [manga] bǝrgǝn, ǝmdi Pǝrwǝrdigar [mǝndin] elip kǝtti; Pǝrwǝrdigarning namiƣa tǝxǝkkür-mǝdⱨiyǝ ⱪayturulsun! — dedi.
22 Nínú gbogbo èyí Jobu kò ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi òmùgọ̀ pe Ọlọ́run lẹ́jọ́.
Bularning ⱨǝmmisidǝ Ayup gunaⱨ ⱪilmidi wǝ yaki Hudani ⱨeqⱪandaⱪ nalayiⱪliⱪ bilǝn ǝyiblimidi.

< Job 1 >