< Job 1 >

1 Ọkùnrin kan wà ní ilẹ̀ Usi, orúkọ ẹni tí í jẹ́ Jobu; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́, ó dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó kórìíra ìwà búburú.
در زمین عوص، مردی بود که ایوب نام داشت و آن مرد کامل و راست و خداترس بود و از بدی اجتناب می‌نمود.۱
2 A sì bi ọmọkùnrin méje àti ọmọbìnrin mẹ́ta fún un.
و برای او، هفت پسر و سه دختر زاییده شدند.۲
3 Ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ìbákasẹ, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta àjàgà ọ̀dá màlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì pọ̀; bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin yìí sì pọ̀jù gbogbo àwọn ará ìlà-oòrùn lọ.
و اموال او هفت هزار گوسفند و سه هزار شتر و پانصد جفت گاو وپانصد الاغ ماده بود و نوکران بسیار کثیر داشت وآن مرد از تمامی بنی مشرق بزرگتر بود.۳
4 Àwọn ọmọ rẹ̀ a sì máa lọ í jẹun àsè nínú ilé ara wọn, olúkúlùkù ní ọjọ́ rẹ̀; wọn a sì máa ránṣẹ́ pé arábìnrin wọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta láti jẹun àti láti pẹ̀lú wọn.
و پسرانش می‌رفتند و در خانه هر یکی ازایشان، در روزش مهمانی می‌کردند و فرستاده، سه خواهر خود را دعوت می‌نمودند تا با ایشان اکل و شرب بنمایند.۴
5 Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ àsè wọn pé yíká, ni Jobu ránṣẹ́ lọ í yà wọ́n sí mímọ́, ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì rú ẹbọ sísun níwọ̀n iye gbogbo wọn; nítorí tí Jobu wí pé: bóyá àwọn ọmọ mi ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣọpẹ́ fún Ọlọ́run lọ́kàn wọn. Bẹ́ẹ̀ ní Jobu máa ń ṣe nígbà gbogbo.
و واقع می‌شد که چون دوره روزهای مهمانی‌ایشان بسر می‌رفت، ایوب فرستاده، ایشان را تقدیس می‌نمود و بامدادان برخاسته، قربانی های سوختنی، به شماره همه ایشان می‌گذرانید، زیرا ایوب می‌گفت: «شایدپسران من گناه کرده، خدا را در دل خود ترک نموده باشند» و ایوب همیشه چنین می‌کرد.۵
6 Ǹjẹ́ ó di ọjọ́ kan, nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá í pé níwájú Olúwa, Satani sì wá pẹ̀lú wọn.
و روزی واقع شد که پسران خدا آمدند تا به حضور خداوند حاضر شوند و شیطان نیز در میان ایشان آمد.۶
7 Olúwa sì bi Satani wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Nígbà náà ní Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Ní ìlọsíwá-sẹ́yìn lórí ilẹ̀ ayé, àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”
و خداوند به شیطان گفت: «از کجاآمدی؟» شیطان در جواب خداوند گفت: «ازتردد کردن در زمین و سیر کردن در آن.»۷
8 Olúwa sì sọ fún Satani pé, “Ìwọ ha kíyèsi Jobu ìránṣẹ́ mi, pé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí í ṣe olóòtítọ́, tí ó sì dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ti ó sì kórìíra ìwà búburú.”
خداوندبه شیطان گفت: «آیا در بنده من ایوب تفکر کردی که مثل او در زمین نیست؟ مرد کامل وراست و خداترس که از گناه اجتناب می‌کند.»۸
9 Nígbà náà ni Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Jobu ha bẹ̀rù Ọlọ́run ní asán bí?”
شیطان در جواب خداوند گفت: «آیا ایوب مجان از خدا می‌ترسد؟۹
10 “Ìwọ kò ha ti ṣọgbà yìí ká, àti yí ilé rẹ̀ àti yí ohun tí ó ní ká, ní ìhà gbogbo? Ìwọ bùsi iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì ń pọ̀ si ní ilẹ̀.
آیا تو گرد او و گردخانه او و گرد همه اموال او، به هر طرف حصارنکشیدی و اعمال دست او را برکت ندادی ومواشی او در زمین منتشر نشد؟۱۰
11 Ǹjẹ́, nawọ́ rẹ nísinsin yìí, kí ó sì fi tọ́ ohun gbogbo tí ó ni; bí kì yóò sì bọ́hùn ni ojú rẹ.”
لیکن الان دست خود را دراز کن و تمامی مایملک او رالمس نما و پیش روی تو، تو را ترک خواهدنمود.»۱۱
12 Olúwa sì dá Satani lóhùn wí pé, “Kíyèsi i, ohun gbogbo tí ó ní ń bẹ ní ìkáwọ́ rẹ, kìkì òun tìkára rẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ rẹ kàn.” Bẹ́ẹ̀ ni Satani jáde lọ kúrò níwájú Olúwa.
خداوند به شیطان گفت: «اینک همه اموالش در دست تو است، لیکن دستت را بر خوداو دراز مکن.» پس شیطان از حضور خداوندبیرون رفت.۱۲
13 Ó sì di ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, tí wọ́n mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n wọn ọkùnrin,
و روزی واقع شد که پسران و دخترانش درخانه برادر بزرگ خود می‌خوردند و شراب می‌نوشیدند.۱۳
14 oníṣẹ́ kan sì tọ Jobu wá wí pé, “Àwọn ọ̀dá màlúù ń tulẹ̀, àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì ń jẹ ní ẹ̀gbẹ́ wọn,
و رسولی نزد ایوب آمده، گفت: «گاوان شیار می‌کردند و ماده الاغان نزد آنهامی چریدند.۱۴
15 àwọn ará Sabeani sì kọlù wọ́n, wọ́n sì ń kó wọn lọ pẹ̀lú, wọ́n ti fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa, èmi nìkan ṣoṣo ní ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ.”
و سابیان بر آنها حمله آورده، بردند و جوانان را به دم شمشیر کشتند و من به تنهایی رهایی یافتم تا تو را خبر دهم.»۱۵
16 Bí ó ti ń sọ ní ẹnu; ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé, “Iná ńlá Ọlọ́run ti ọ̀run bọ́ sí ilẹ̀, ó sì jó àwọn àgùntàn àti àwọn ìránṣẹ́; èmi nìkan ṣoṣo ní ó sálà láti ròyìn fún ọ.”
و اوهنوز سخن می‌گفت که دیگری آمده، گفت: «آتش خدا از آسمان افتاد و گله و جوانان راسوزانیده، آنها را هلاک ساخت و من به تنهایی رهایی یافتم تا تو را خبر دهم.»۱۶
17 Bí ó sì ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan sì dé pẹ̀lú tí ó wí pé, “Àwọn ará Kaldea píngun sí ọ̀nà mẹ́ta, wọ́n sì kọlù àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì kó wọn lọ, pẹ̀lúpẹ̀lú wọ́n sì fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa; èmi nìkan ṣoṣo ni ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ!”
و او هنوزسخن می‌گفت که دیگری آمده، گفت: «کلدانیان سه فرقه شدند و بر شتران هجوم آورده، آنها را بردند و جوانان را به دم شمشیر کشتند و من به تنهایی رهایی یافتم تا تو را خبر دهم.»۱۷
18 Bí ó ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin ń jẹ, wọ́n ń mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n.
و اوهنوز سخن می‌گفت که دیگری آمده، گفت: «پسران و دخترانت در خانه برادر بزرگ خودمی خوردند و شراب می‌نوشیدند۱۸
19 Sì kíyèsi i, ẹ̀fúùfù ńlá ńlá ti ìhà ijù fẹ́ wá kọlu igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilé, ó sì wó lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wọ́n sì kú, èmi nìkan ṣoṣo ni ó yọ láti ròyìn fún ọ.
که اینک بادشدیدی از طرف بیابان آمده، چهار گوشه خانه رازد و بر جوانان افتاد که مردند و من به تنهایی رهایی یافتم تا تو را خبر دهم.»۱۹
20 Nígbà náà ni Jobu dìde, ó sì fa aṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya, ó sì fá orí rẹ̀ ó wólẹ̀ ó sì gbàdúrà
آنگاه ایوب برخاسته، جامه خود را درید وسر خود را تراشید و به زمین افتاده، سجده کرد۲۰
21 wí pé, “Ní ìhòhò ní mo ti inú ìyá mi jáde wá, ni ìhòhò ní èmi yóò sì tún padà lọ. Olúwa fi fún ni, Olúwa sì gbà á lọ, ìbùkún ni fún orúkọ Olúwa.”
و گفت: «برهنه از رحم مادر خود بیرون آمدم وبرهنه به آنجا خواهم برگشت؛ خداوند داد وخداوند گرفت و نام خداوند متبارک باد.»۲۱
22 Nínú gbogbo èyí Jobu kò ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi òmùgọ̀ pe Ọlọ́run lẹ́jọ́.
دراین همه، ایوب گناه نکرد و به خدا جهالت نسبت نداد.۲۲

< Job 1 >