< Jeremiah 1 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Jeremiah ọmọ Hilkiah ọ̀kan nínú àwọn àlùfáà ní Anatoti ní agbègbè ilẹ̀ Benjamini.
Maya nĩmo maũndũ marĩa maaririo nĩ Jeremia, mũrũ wa Hilikia, ũmwe wa athĩnjĩri-Ngai arĩa maatũũraga itũũra rĩa Anathothu kũu bũrũri wa Benjamini.
2 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá ní ọdún kẹtàlá ní àkókò ìjọba Josiah ọmọ Amoni ọba Juda,
Ndũmĩrĩri ya Jehova nĩyamũkinyĩrĩire mwaka-inĩ wa ikũmi na ĩtatũ wa wathani wa Josia, mũrũ wa Amoni, mũthamaki wa Juda,
3 àti títí dé àsìkò Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, títí dé oṣù karùn-ún ọdún kọkànlá Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, nígbà tí àwọn ará Jerusalẹmu lọ sí ìgbèkùn.
o na ningĩ matukũ-inĩ ma wathani wa Jehoiakimu mũrũ wa Josia, mũthamaki wa Juda, o nginya mweri wa gatano, mwaka-inĩ wa ikũmi na ũmwe wa wathani wa Zedekia mũrũ wa Josia, mũthamaki wa Juda, rĩrĩa andũ a Jerusalemu maatahirwo.
4 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé,
Ndũmĩrĩri ya Jehova nĩyanginyĩrire, ngĩĩrwo atĩrĩ,
5 “Kí ó tó di pé mo dá ọ láti inú ni mo ti mọ̀ ọ́n, kí ó sì tó di pé a bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀. Mo yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí wòlíì fún àwọn orílẹ̀-èdè.”
“Mbere ya gũkũũmba nda-inĩ ya maitũguo-rĩ, no ndaakũũĩ, o na ũtanaciarwo-rĩ, nĩndakwamũrĩte; nĩndagũtuire mũnabii wa kũrathagĩra ndũrĩrĩ.”
6 Mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, ọmọdé ni mí, èmi kò mọ bí a ṣe é sọ̀rọ̀.”
Na niĩ ngĩmũcookeria, ngiuga atĩrĩ: “Hĩ, Mwathani Jehova! Niĩ ndiũĩ kwaria; niĩ ndĩ o mwana.”
7 Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe sọ pé, ‘Ọmọdé lásán ni mí.’ O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.”
Nowe Jehova akĩnjĩĩra atĩrĩ: “Tiga kuuga atĩrĩ, ‘Niĩ ndĩ o mwana.’ No nginya ũthiĩ kũrĩ mũndũ o wothe ngũgũtũma kũrĩ we na ũmwĩre ũrĩa wothe ngũgwatha.
8 Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.
Ndũkanametigĩre, nĩgũkorwo ndĩ hamwe nawe, na nĩngakũhonokia,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
9 Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsin yìí, mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ.
Hĩndĩ ĩyo Jehova agĩtambũrũkia guoko, akĩĩhutia kanua, akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Rĩu nĩndekĩra ndũmĩrĩri yakwa kanua gaku.
10 Wò ó, mo yàn ọ́ lórí àwọn orílẹ̀-èdè àti ìjọba gbogbo láti fàtu, láti wó lulẹ̀, láti bàjẹ́, láti jágbà, láti máa kọ́, àti láti máa gbìn.
One, ũmũthĩ nĩndagũtua mũnene wa ndũrĩrĩ o na wa mothamaki, nĩgeetha ũmunyage na ũmomorage, wanangage na ũngʼaũranagie, na wakage na ũhaandage.”
11 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ mí wá wí pé: “Kí ni o rí Jeremiah?” Mo sì dáhùn wí pé, “Mo rí ẹ̀ka igi almondi.”
Ndũmĩrĩri ya Jehova nĩyanginyĩrire, ngĩũrio atĩrĩ: “Jeremia, nĩ kĩĩ ũroona?” Na niĩ ngĩcookia atĩrĩ, “Ndĩrona rũhonge rwa mũtĩ wa mũrothi.”
12 Olúwa sì wí fún mi pé, “Ó ti rí i bí ó ṣe yẹ, nítorí pé mo ti ń ṣọ láti rí i pé ọ̀rọ̀ mi wá sí ìmúṣẹ.”
Jehova akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Ĩĩ, nĩguo nĩwona wega, tondũ njũthĩrĩirie nyone atĩ ndũmĩrĩri yakwa nĩyahingio.”
13 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ mi wá ní ẹ̀ẹ̀kejì pé, “Kí ni o rí?” Mo sì dáhùn pé mo rí ìkòkò gbígbóná, tí ó ń ru láti apá àríwá.
Ningĩ ndũmĩrĩri ya Jehova nĩyanginyĩrire o rĩngĩ ngĩũrio atĩrĩ: “Nĩ kĩĩ kĩngĩ ũrona?” Na niĩ ngĩcookia atĩrĩ, “Ndĩrona nyũngũ ĩgũtherũka, ĩinamĩte kuuma mwena wa gathigathini.”
14 Olúwa sì wí fún mi pé, “Láti apá àríwá ni a ó ti mu ìdààmú wá sórí gbogbo àwọn tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà.
Nake Jehova akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Mwanangĩko uumĩte na mwena wa gathigathini, nĩũgaitĩrĩrio andũ othe arĩa matũũraga bũrũri ũyũ.
15 Mo sì ti ṣetán láti pe gbogbo àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè àríwá níjà,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọba wọn yóò wá gbé ìtẹ́ wọn ró ní ojú ọ̀nà àbáwọlé Jerusalẹmu. Wọn ó sì dìde sí gbogbo àyíká wọn àti sí gbogbo àwọn ìlú Juda.
Ndĩ hakuhĩ gwĩta andũ othe a mothamaki ma gathigathini,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga. “Athamaki ao nĩmagooka mahaande itĩ ciao cia ũthamaki matoonyero-inĩ ma ihingo cia Jerusalemu; nĩmagooka mathiũrũrũkĩrie thingo ciothe cia Jerusalemu, na mokĩrĩre matũũra mothe ma Juda.
16 Èmi yóò sì kéde ìdájọ́ mi lórí àwọn ènìyàn mi nítorí ìwà búburú wọn nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀, nípa rírúbọ sí ọlọ́run mìíràn àti sínsin àwọn ohun tí wọ́n fi ọwọ́ wọn ṣe.
Nĩngatuĩra andũ akwa matuĩro ma ciira, tondũ wa waganu wao wa kũndirika, na wa gũcinĩra ngai ingĩ ũbumba, na kũhooya indo iria methondekeire na moko mao.
17 “Wà ní ìmúrasílẹ̀! Dìde dúró kí o sì sọ fún wọn ohunkóhun tí mo bá pàṣẹ fún wọn. Má ṣe jẹ́ kí wọ́n dẹ́rùbà ọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀rù níwájú wọn.
“Ũkĩra wĩhaarĩrie! Rũgama na ũmeere ũndũ o wothe ũrĩa ngũgwatha. Ndũkamakio nĩo, kana na niĩ ngũmakie ũrĩ mbere yao.
18 Ní òní èmi ti sọ ọ́ di ìlú alágbára, òpó irin àti odi idẹ sí àwọn ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀, sí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.
Ũmũthĩ-rĩ, nĩndagũtua ta itũũra rĩirige na hinya, na ta gĩtugĩ gĩa kĩgera, na ta rũthingo rwa gĩcango, nĩgeetha wĩyũmie ũũkĩrĩre bũrũri wothe: ũũkĩrĩre athamaki a Juda, na anene, na athĩnjĩri-Ngai akuo, o na andũ othe a bũrũri ũyũ.
19 Wọn yóò dojú ìjà kọ ọ́, wọn kì yóò borí rẹ, nítorí wí pé èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì gbà ọ́,” ni Olúwa wí.
Nĩmakarũa nawe no matigaakũhoota, nĩgũkorwo ndĩ hamwe nawe na nĩndĩrĩkũhonokagia,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.

< Jeremiah 1 >