< Jeremiah 1 >
1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Jeremiah ọmọ Hilkiah ọ̀kan nínú àwọn àlùfáà ní Anatoti ní agbègbè ilẹ̀ Benjamini.
The words of Jeremiah, the son of Hilkiah of the priests who were in Anathoth in the land of Benjamin.
2 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá ní ọdún kẹtàlá ní àkókò ìjọba Josiah ọmọ Amoni ọba Juda,
The word of the Lord, which came to him in the days of Josiah, the son of Amon, king of Judah, in the thirteenth year of his reign,
3 àti títí dé àsìkò Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, títí dé oṣù karùn-ún ọdún kọkànlá Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, nígbà tí àwọn ará Jerusalẹmu lọ sí ìgbèkùn.
and which came to him in the days of Jehoiakim, the son of Josiah, king of Judah, even until the completion of the eleventh year of Zedekiah, the son of Josiah, king of Judah, even until the transmigration of Jerusalem in the fifth month.
4 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé,
And the word of the Lord came to me, saying:
5 “Kí ó tó di pé mo dá ọ láti inú ni mo ti mọ̀ ọ́n, kí ó sì tó di pé a bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀. Mo yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí wòlíì fún àwọn orílẹ̀-èdè.”
“Before I formed you in the womb, I knew you. And before you went forth from the womb, I sanctified you. And I made you a prophet to the nations.”
6 Mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, ọmọdé ni mí, èmi kò mọ bí a ṣe é sọ̀rọ̀.”
And I said: “Alas, alas, alas, Lord God! Behold, I do not know how to speak, for I am a boy.”
7 Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe sọ pé, ‘Ọmọdé lásán ni mí.’ O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.”
And the Lord said to me: “Do not choose to say, ‘I am a boy.’ For you shall go forth to everyone to whom I will send you. And you shall speak all that I will command you.
8 Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.
You should not be afraid before their face. For I am with you, so that I may deliver you,” says the Lord.
9 Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsin yìí, mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ.
And the Lord put forth his hand, and he touched my mouth. And the Lord said to me: “Behold, I have placed my words in your mouth.
10 Wò ó, mo yàn ọ́ lórí àwọn orílẹ̀-èdè àti ìjọba gbogbo láti fàtu, láti wó lulẹ̀, láti bàjẹ́, láti jágbà, láti máa kọ́, àti láti máa gbìn.
Behold, today I have appointed you over nations and over kingdoms, so that you may root up, and pull down, and destroy, and scatter, and so that you may build and plant.”
11 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ mí wá wí pé: “Kí ni o rí Jeremiah?” Mo sì dáhùn wí pé, “Mo rí ẹ̀ka igi almondi.”
And the word of the Lord came to me, saying, “What do you see, Jeremiah?” And I said, “I see a staff, keeping watch.”
12 Olúwa sì wí fún mi pé, “Ó ti rí i bí ó ṣe yẹ, nítorí pé mo ti ń ṣọ láti rí i pé ọ̀rọ̀ mi wá sí ìmúṣẹ.”
And the Lord said to me: “You have seen well. For I will keep watch over my word, so that I may accomplish it.”
13 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ mi wá ní ẹ̀ẹ̀kejì pé, “Kí ni o rí?” Mo sì dáhùn pé mo rí ìkòkò gbígbóná, tí ó ń ru láti apá àríwá.
And the word of the Lord came to me a second time, saying, “What do you see?” And I said, “I see a cooking pot upon a fire, and its face is before the face of the north.”
14 Olúwa sì wí fún mi pé, “Láti apá àríwá ni a ó ti mu ìdààmú wá sórí gbogbo àwọn tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà.
And the Lord said to me: “From the north, an evil will spread over all the inhabitants of the earth.
15 Mo sì ti ṣetán láti pe gbogbo àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè àríwá níjà,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọba wọn yóò wá gbé ìtẹ́ wọn ró ní ojú ọ̀nà àbáwọlé Jerusalẹmu. Wọn ó sì dìde sí gbogbo àyíká wọn àti sí gbogbo àwọn ìlú Juda.
For behold, I will call together all the close associates of the kingdoms of the north, says the Lord. And they will arrive, and each one of them will place his throne at the entrance to the gates of Jerusalem, and over all its surrounding walls, and over all the cities of Judah.
16 Èmi yóò sì kéde ìdájọ́ mi lórí àwọn ènìyàn mi nítorí ìwà búburú wọn nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀, nípa rírúbọ sí ọlọ́run mìíràn àti sínsin àwọn ohun tí wọ́n fi ọwọ́ wọn ṣe.
And I will speak my judgments with them, concerning all the wickedness of those who have forsaken me, and who have offered libations to strange gods, and who have adored the work of their own hands.
17 “Wà ní ìmúrasílẹ̀! Dìde dúró kí o sì sọ fún wọn ohunkóhun tí mo bá pàṣẹ fún wọn. Má ṣe jẹ́ kí wọ́n dẹ́rùbà ọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀rù níwájú wọn.
Therefore, you should gird your waist, and rise up, and speak to them everything that I instruct you. You should not have dread before their face. For I will cause you to be unafraid of their countenance.
18 Ní òní èmi ti sọ ọ́ di ìlú alágbára, òpó irin àti odi idẹ sí àwọn ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀, sí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.
For certainly, this day, I have made you like a fortified city, and an iron pillar, and a brass wall, over all the land, to the kings of Judah, to its leaders, and to the priests, and to the people of the land.
19 Wọn yóò dojú ìjà kọ ọ́, wọn kì yóò borí rẹ, nítorí wí pé èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì gbà ọ́,” ni Olúwa wí.
And they will make war against you, but they will not prevail. For I am with you, says the Lord, so that I may free you.”