< Jeremiah 1 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Jeremiah ọmọ Hilkiah ọ̀kan nínú àwọn àlùfáà ní Anatoti ní agbègbè ilẹ̀ Benjamini.
Benjamin prae thungah kaom Anathoth avang ih qaimanawk salakah kaom, Hilkiah capa Jeremiah khaeah lok angzoh,
2 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá ní ọdún kẹtàlá ní àkókò ìjọba Josiah ọmọ Amoni ọba Juda,
Judah siangpahrang Amon capa, Josiah angraenghaih saning hathlai thumto naah, Angraeng ih lok anih khaeah angzoh pae.
3 àti títí dé àsìkò Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, títí dé oṣù karùn-ún ọdún kọkànlá Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, nígbà tí àwọn ará Jerusalẹmu lọ sí ìgbèkùn.
Judah siangpahrang, Josiah capa Jehoiakim siangpahrang ohhaih saning, Judah siangpahrang Josiah capa Zedekiah angraenghaih saning hathlaito haih, Jerusalem kaminawk misong ah laemhhaih, khrah pangato naah doeh lok to angzoh pae.
4 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé,
Angraeng ih lok kai khaeah angzoh,
5 “Kí ó tó di pé mo dá ọ láti inú ni mo ti mọ̀ ọ́n, kí ó sì tó di pé a bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀. Mo yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí wòlíì fún àwọn orílẹ̀-èdè.”
zok thungah kang omsak ai nathuem hoiah kang panoek boeh; Na tapen ai nathuem hoiah kang ciimsak boeh; nang hae prae kaminawk boih hanah tahmaa ah kang suek boeh, tiah ang naa.
6 Mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, ọmọdé ni mí, èmi kò mọ bí a ṣe é sọ̀rọ̀.”
Kai mah, Ah, Angraeng Sithaw! khenah, lok ka thui thai ai, ka nawkta vop, tiah ka naa.
7 Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe sọ pé, ‘Ọmọdé lásán ni mí.’ O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.”
Toe Angraeng mah kai khaeah, Ka nawkta vop, tiah thui hmah; kang patoeh ih kaminawk boih khaeah caeh ah loe, thuih han kang paek ih loknawk to thui ah.
8 Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.
Nihcae to zii hmah; nang pahlong hanah, nang khaeah ka oh poe han, tiah Angraeng mah thuih.
9 Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsin yìí, mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ.
Angraeng mah a ban to payangh moe, ka pakha to ang sui pae. Angraeng mah kai khaeah, Khenah, na pakha thungah Ka lok ka suek boeh.
10 Wò ó, mo yàn ọ́ lórí àwọn orílẹ̀-èdè àti ìjọba gbogbo láti fàtu, láti wó lulẹ̀, láti bàjẹ́, láti jágbà, láti máa kọ́, àti láti máa gbìn.
Khenah, prae kaminawk hoi praenawk to aphongh moe, amtimsak hanah, phraek moe, amrosak hanah, vah pae ving moe, sak pae let pacoengah thling pae let hanah, vaihniah kang patoeh boeh, tiah ang naa.
11 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ mí wá wí pé: “Kí ni o rí Jeremiah?” Mo sì dáhùn wí pé, “Mo rí ẹ̀ka igi almondi.”
Angraeng ih lok kai khaeah angzoh; Jeremiah, timaw na hnuk? tiah ang naa. Kai mah, Almond thing tanghang maeto ka hnuk, tiah ka naa.
12 Olúwa sì wí fún mi pé, “Ó ti rí i bí ó ṣe yẹ, nítorí pé mo ti ń ṣọ láti rí i pé ọ̀rọ̀ mi wá sí ìmúṣẹ.”
Angraeng mah kai khaeah, Kamtuengah na hnuk boeh; ka lok hae koepsak hanah, ka ohcoek boeh, tiah ang naa.
13 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ mi wá ní ẹ̀ẹ̀kejì pé, “Kí ni o rí?” Mo sì dáhùn pé mo rí ìkòkò gbígbóná, tí ó ń ru láti apá àríwá.
Angraeng ih lok kai khaeah angzoh let; Timaw na hnuk? tiah ang naa. Kai mah, Aluek bangah kanghae tui tangdawh laom to ka hnuk, tiah ka naa.
14 Olúwa sì wí fún mi pé, “Láti apá àríwá ni a ó ti mu ìdààmú wá sórí gbogbo àwọn tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà.
Angraeng mah kai khaeah, Aluek bang hoiah kangzo amrohaih loe prae kaminawk boih khaeah cen tih.
15 Mo sì ti ṣetán láti pe gbogbo àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè àríwá níjà,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọba wọn yóò wá gbé ìtẹ́ wọn ró ní ojú ọ̀nà àbáwọlé Jerusalẹmu. Wọn ó sì dìde sí gbogbo àyíká wọn àti sí gbogbo àwọn ìlú Juda.
Khenah, aluek bang siangpahrang ukhaih praenawk thungah kaom kaminawk to ka kawk boih han, tiah Angraeng mah thuih; nihcae to angzo o ueloe, Jerusalem akunhaih khongkhanawk ah, khongkha taeng boih hoi Judah vangpuinawk boih ah, angmacae ih angraeng tangkhang to suem o tih.
16 Èmi yóò sì kéde ìdájọ́ mi lórí àwọn ènìyàn mi nítorí ìwà búburú wọn nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀, nípa rírúbọ sí ọlọ́run mìíràn àti sínsin àwọn ohun tí wọ́n fi ọwọ́ wọn ṣe.
Angmacae sethaih, kai ang pahnawt o moe, sithaw kalah hmaa ah hmuihoih thlaek o haih hoi angmacae ban hoi a sak o ih hmuen to a bok o pongah, nihcae to lok kacaek han.
17 “Wà ní ìmúrasílẹ̀! Dìde dúró kí o sì sọ fún wọn ohunkóhun tí mo bá pàṣẹ fún wọn. Má ṣe jẹ́ kí wọ́n dẹ́rùbà ọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀rù níwájú wọn.
To pongah kaengkaeh to angzaeng ah loe angthawk ah, kang paek ih loknawk boih to nihcae khaeah thui paeh; nihcae to zii hmah, to tih ai nahaeloe nihcae hmaa ah zithaih to nangmah hanah kang paek lat han.
18 Ní òní èmi ti sọ ọ́ di ìlú alágbára, òpó irin àti odi idẹ sí àwọn ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀, sí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.
Khenah, Judah siangpahrangnawk, ukkung angraengnawk, qaimanawk hoi prae kaminawk to tuk hanah, vaihniah kacak vangpui baktih, sum tung hoiah maw, to tih ai boeh loe sumkamling hoiah sak ih tapangnawk baktiah kang ohsak boeh.
19 Wọn yóò dojú ìjà kọ ọ́, wọn kì yóò borí rẹ, nítorí wí pé èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì gbà ọ́,” ni Olúwa wí.
Nihcae mah nang to tuh o tih; toe na pazawk o mak ai; nang pahlong hanah kang oh thuih, tiah Angraeng mah thuih.

< Jeremiah 1 >