< Jeremiah 9 >

1 Háà! Orí ìbá jẹ́ orísun omi kí ojú mi sì jẹ́ orísun omijé! Èmi yóò sì sọkún tọ̀sán tòru nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.
Ack att mitt huvud vore en vattenbrunn och mina ögon en tårekälla, så att jag kunde gråta dag och natt över de slagna hos dottern mitt folk!
2 Háà, èmi ìbá ní ni aginjù ilé àgbàwọ̀ fún àwọn arìnrìn-àjò, kí n ba à lè fi àwọn ènìyàn mi sílẹ̀ kí n sì lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn: nítorí gbogbo wọn jẹ́ panṣágà àjọ aláìṣòótọ́ ènìyàn.
Ack att jag hade ett härbärge i öknen, så att jag kunde övergiva mitt folk och draga bort ifrån dem! Ty de äro allasammans äktenskapsbrytare, en församling av trolösa.
3 Wọ́n ti pèsè ahọ́n wọn sílẹ̀ bí ọfà láti fi pa irọ́; kì í ṣe nípa òtítọ́ ni wọ́n fi borí ní ilẹ̀ náà. Wọ́n ń lọ láti inú ẹ̀ṣẹ̀ kan sí òmíràn; wọn kò sì náání mi, ní Olúwa wí.
Sin tungas båge spänna de till att avskjuta lögner, och till sanning bruka de icke sin makt i landet. Nej, de gå från ogärning till ogärning, men mig vilja de ej veta av, säger HERREN.
4 “Ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ; má ṣe gbẹ́kẹ̀lé àwọn arákùnrin rẹ. Nítorí pé oníkálùkù arákùnrin jẹ́ atannijẹ, oníkálùkù ọ̀rẹ́ sì jẹ́ abanijẹ́.
Var och en tage sig till vara för sin vän, och ingen förlite sig på någon sin broder; ty den ene brodern gör allt för att bedraga den andre, och den ene vännen går omkring och förtalar den andre.
5 Ọ̀rẹ́ ń dalẹ̀ ọ̀rẹ́. Kò sì ṣí ẹni tó sọ òtítọ́, wọ́n ti kọ́ ahọ́n wọn láti máa purọ́. Wọ́n sọ ara wọn di onírẹ̀wẹ̀sì pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀
Var och en handlar svikligt mot sin vän, och ingen talar vad sant är; de öva sina tungor i att tala lögn de arbeta sig trötta med att göra illa.
6 Ó ń gbé ní àárín ẹ̀tàn; wọ́n kọ̀ láti mọ̀ mí nínú ẹ̀tàn wọn,” ni Olúwa wí.
Du bor mitt ibland falskhet; i sin falskhet vilja de ej veta av mig, säger HERREN.
7 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Wò ó, èmi dán wọn wo; nítorí pé kí ni èmi tún le è ṣe? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi?
Därför säger HERREN Sebaot så. Se, jag måste luttra och pröva dem; ty vad annat kan jag göra, då nu dottern mitt folk är sådan?
8 Ahọ́n wọn dàbí ọfà olóró; ó ń sọ ẹ̀tàn. Oníkálùkù sì ń fi ẹnu rẹ̀ sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò rẹ̀, ní inú ọkàn rẹ̀, ó dẹ tàkúté sílẹ̀.
Deras tunga är en mördande pil; vad den talar är svek. Med munnen tala de vänligt till sin nästa, men i hjärtat lägga de försåt för honom.
9 Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n nítorí èyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò ha gbẹ̀san ara mi lórí irú orílẹ̀-èdè yìí bí?”
Skulle jag icke för sådant hemsöka dem? säger HERREN. Skulle icke min själ hämnas på ett sådant folk som detta är?
10 Èmi yóò sì sọkún, pohùnréré ẹkún fún àwọn òkè àti ẹkún ìrora lórí pápá oko aginjù wọ̀n-ọn-nì. Nítorí wọ́n di ahoro, wọn kò sì kọjá ní ibẹ̀. A kò sì gbọ́ igbe ẹran ọ̀sìn. Àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ti sálọ, bẹ́ẹ̀ náà ni àwọn ẹranko sì ti lọ.
Över bergen vill jag gråta och sjunga sorgesång; jag vill höja klagosång över betesmarkerna i öknen. Ty de äro förbrända, så att ingen går där fram och inga läten av boskap där höras; både himmelens fåglar och fyrfotadjuren hava flytt och äro borta.
11 “Èmi yóò sì sọ Jerusalẹmu di òkìtì àlàpà àti ihò àwọn ìkookò. Èmi ó sì sọ ìlú Juda di ahoro tí ẹnikẹ́ni kò sì ní le è gbé.”
Jag skall göra Jerusalem till en stenhop, till en boning för schakaler, och Juda städer till en ödemark, där ingen bor.
12 Ta ni ẹni náà tí ó ní ọgbọ́n láti mòye nǹkan wọ̀nyí? Ta ni Olúwa ti sọ èyí fún, tí ó sì lè ṣàlàyé rẹ̀? Èéṣe tí ilẹ̀ náà fi ṣègbé bí aginjù, tí ẹnìkankan kò sì le là á kọjá?
Vem är en vis man, så att han förstår detta? Och till vem har HERRENS mun talat, så att han kan förklara detta: varför landet har blivit så fördärvat, förbränt såsom en öken, där ingen går fram?
13 Olúwa sì wí pé, nítorí pé wọ́n ti kọ òfin mi sílẹ̀, èyí tí mo gbé kalẹ̀ níwájú wọn, wọn ṣe àìgbọ́ràn sí wọn, wọn kò sì rìn nínú òfin mi.
Och HERREN svarade: Jo, därför att de hava övergivit min lag, den som jag förelade dem, och icke hava hört min röst och vandrat efter den
14 Dípò èyí, wọ́n ti tẹ̀lé agídí ọkàn wọn, wọ́n ti tẹ̀lé Baali gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe kọ́ wọn.
utan vandrat efter sina egna hjärtans hårdhet och efterföljt Baalerna, såsom deras fader lärde dem.
15 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, “Wò ó, Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí jẹ oúnjẹ kíkorò àti láti mu omi májèlé.
Därför säger HERREN Sebaot, Israels Gud, så: Se, jag skall giva detta folk malört att äta och gift att dricka.
16 Èmi yóò sì tú wọn ká láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, nínú èyí tí àwọn tàbí àwọn baba wọn kò mọ̀. Èmi yóò sì lépa wọn pẹ̀lú idà títí èmi yóò fi pa wọ́n run.”
Och jag skall förströ dem bland folk som varken de eller deras fäder hava känt, och skall sända svärdet efter dem, till dess att jag har gjort ände på dem.
17 Èyí sì ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí: “Sá à wò ó nísinsin yìí! Ké sí obìnrin ti ń ṣọ̀fọ̀ nì kí ó wá; sì ránṣẹ́ pe àwọn tí ó mòye nínú wọn.
Så säger HERREN Sebaot: Given akt; tillkallen gråterskor, för att de må komma, och sänden efter förfarna kvinnor, och låten dem komma.
18 Jẹ́ kí wọn wá kíákíá, kí wọn wá pohùnréré ẹkún lé wa lórí títí ojú wa yóò fi sàn fún omijé tí omi yóò sì máa sàn àwọn ìpéǹpéjú wa.
Låten dem med hast stämma upp sorgesång över oss, så att våra ögon flyta i tårar och vatten strömmar från våra ögonlock.
19 A gbọ́ igbe ìpohùnréré ẹkún ní Sioni: ‘Àwa ti ṣègbé tó! A gbọdọ̀ fi ilẹ̀ wa sílẹ̀, nítorí pé àwọn ilé wa ti parun.’”
Ty sorgesång höres ljuda från Sion: Huru har ej förstörelse drabbat oss! Vi hava kommit illa på skam, vi måste ju övergiva landet, ty våra boningar hava de slagit ned.
20 Nísinsin yìí, ẹ̀yin obìnrin ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa; ṣí etí yín sí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ. Kọ́ àwọn ọmọbìnrin yín ní ìpohùnréré ẹkún, kí ẹ sì kọ́ ara yín ní arò.
Ja, hören, I kvinnor, HERRENS ord, och edert öra fatte hans muns tal. Lären edra döttrar sorgesång; ja, lären varandra klagosång.
21 Ikú ti gba ojú fèrèsé wa wọlé ó sì ti wọ odi alágbára wa ó ti ké àwọn ọmọ kúrò ní àdúgbò àti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò ní gbọ̀ngàn ìta gbangba.
Ty döden stiger in genom vara fönster, han kommer in i våra palats; han utrotar barnen från gatan och ynglingarna från torgen.
22 Sọ pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Òkú àwọn ènìyàn yóò ṣubú bí ààtàn ní oko gbangba àti bí ìbùkúnwọ́ lẹ́yìn olùkórè láìsí ẹnìkankan láti kó wọn jọ.’”
Ja, tala: Så säger HERREN: Och människornas döda kroppar ligga såsom gödsel på marken och såsom kärvar efter skördemannen, vilka ingen samlar upp.
23 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Má ṣe jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n yangàn nítorí agbára ọgbọ́n rẹ̀, tàbí alágbára nítorí agbára rẹ̀, tàbí ọlọ́rọ̀ nítorí ọrọ̀ rẹ̀.
Så säger HERREN: Den vise berömme sig icke av sin vishet, den starke berömme sig icke av sin styrka, den rike berömme sig icke av sin rikedom.
24 Ẹ jẹ́ kí ẹni tí ń ṣògo nípa èyí nì wí pé: òun ní òye, òun sì mọ̀ mí wí pé, Èmi ni Olúwa tí ń ṣe òtítọ́, ìdájọ́ àti òdodo ní ayé, nínú èyí ni mo ní inú dídùn sí,” Olúwa wí.
Nej, den som vill berömma sig, han berömme sig därav att han har förstånd till att känna mig: att jag är HERREN, som gör nåd, rätt och rättfärdighet på jorden. Ty till sådana har jag behag, säger HERREN.
25 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí a kọ ilà fún nínú ara nìkan.
Se, dagar skola komma, säger HERREN, då jag skall hemsöka alla omskurna som dock äro oomskurna:
26 Ejibiti, Juda, Edomu, Ammoni, Moabu àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní ọ̀nà jíjìn réré ní aginjù. Nítorí pé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jẹ́ aláìkọlà gbogbo àwọn ará ilé Israẹli sì jẹ́ aláìkọlà ọkàn.”
Egypten, Juda, Edom, Ammons barn, Moab och alla ökenbor med kantklippt hår. Ty hednafolken äro alla oomskurna, och hela Israels hus har ett oomskuret hjärta.

< Jeremiah 9 >