< Jeremiah 9 >

1 Háà! Orí ìbá jẹ́ orísun omi kí ojú mi sì jẹ́ orísun omijé! Èmi yóò sì sọkún tọ̀sán tòru nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.
О, де мь-ар фи капул плин ку апэ, де мь-ар фи окий ун извор де лакримь, аш плынӂе зи ши ноапте пе морций фийчей попорулуй меу!
2 Háà, èmi ìbá ní ni aginjù ilé àgbàwọ̀ fún àwọn arìnrìn-àjò, kí n ba à lè fi àwọn ènìyàn mi sílẹ̀ kí n sì lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn: nítorí gbogbo wọn jẹ́ panṣágà àjọ aláìṣòótọ́ ènìyàn.
О, дак-аш авя ун хан де кэлэторь ын пустиу, аш пэрэси пе попорул меу ши м-аш депэрта де ел! Кэч тоць сунт ниште прякурварь ши о чатэ де мишей.
3 Wọ́n ti pèsè ahọ́n wọn sílẹ̀ bí ọfà láti fi pa irọ́; kì í ṣe nípa òtítọ́ ni wọ́n fi borí ní ilẹ̀ náà. Wọ́n ń lọ láti inú ẹ̀ṣẹ̀ kan sí òmíràn; wọn kò sì náání mi, ní Olúwa wí.
„Ау лимба ынтинсэ ка ун арк ши арункэ минчуна, ши ну прин адевэр сунт ей путерничь ын царэ, кэч мерг дин рэутате ын рэутате ши ну Мэ куноск”, зиче Домнул.
4 “Ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ; má ṣe gbẹ́kẹ̀lé àwọn arákùnrin rẹ. Nítorí pé oníkálùkù arákùnrin jẹ́ atannijẹ, oníkálùkù ọ̀rẹ́ sì jẹ́ abanijẹ́.
„Фиекаре сэ се пэзяскэ де приетенул луй ши сэ ну се ынкрядэ ын ничунул дин фраций сэй, кэч орьче фрате каутэ сэ ыншеле ши орьче приетен умблэ ку бырфель.
5 Ọ̀rẹ́ ń dalẹ̀ ọ̀rẹ́. Kò sì ṣí ẹni tó sọ òtítọ́, wọ́n ti kọ́ ahọ́n wọn láti máa purọ́. Wọ́n sọ ara wọn di onírẹ̀wẹ̀sì pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀
Се траг пе сфоарэ уний пе алций ши ну спун адевэрул; ышь депринд лимба сэ минтэ ши се трудеск сэ факэ рэу.
6 Ó ń gbé ní àárín ẹ̀tàn; wọ́n kọ̀ láti mọ̀ mí nínú ẹ̀tàn wọn,” ni Olúwa wí.
Локуинца та есте ын мижлокул фэцэрничией ши, де фэцарничь че сунт, ну вор сэ Мэ куноаскэ”, зиче Домнул.
7 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Wò ó, èmi dán wọn wo; nítorí pé kí ni èmi tún le è ṣe? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi?
Де ачея, аша ворбеште Домнул оштирилор: „Ятэ, ый вой топи ын куптор ши ый вой ынчерка. Кэч кум аш путя сэ мэ порт алтфел ку фийка попорулуй Меу?
8 Ahọ́n wọn dàbí ọfà olóró; ó ń sọ ẹ̀tàn. Oníkálùkù sì ń fi ẹnu rẹ̀ sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò rẹ̀, ní inú ọkàn rẹ̀, ó dẹ tàkúté sílẹ̀.
Лимба лор есте о сэӂятэ учигэтоаре, ну спун декыт минчунь; ку гура ворбеск апроапелуй лор де паче, ши ын фундул инимий ый ынтинд курсе.
9 Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n nítorí èyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò ha gbẹ̀san ara mi lórí irú orílẹ̀-èdè yìí bí?”
Сэ ну-й педепсеск Еу пентру ачесте лукрурь”, зиче Домнул, „сэ ну Мэ рэзбун Еу пе ун асеменя попор?”
10 Èmi yóò sì sọkún, pohùnréré ẹkún fún àwọn òkè àti ẹkún ìrora lórí pápá oko aginjù wọ̀n-ọn-nì. Nítorí wọ́n di ahoro, wọn kò sì kọjá ní ibẹ̀. A kò sì gbọ́ igbe ẹran ọ̀sìn. Àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ti sálọ, bẹ́ẹ̀ náà ni àwọn ẹranko sì ti lọ.
Мунций вряу сэ-й плынг ши сэ ӂем пентру ей, пентру кымпииле пустиите вряу сэ фак о желание, кэч сунт арсе де тот ши нимень ну май трече прин еле; ну се май ауде ын еле бехэитул турмелор; пэсэриле черулуй ши добитоачеле ау фуӂит ши ау перит.
11 “Èmi yóò sì sọ Jerusalẹmu di òkìtì àlàpà àti ihò àwọn ìkookò. Èmi ó sì sọ ìlú Juda di ahoro tí ẹnikẹ́ni kò sì ní le è gbé.”
„Вой фаче ши Иерусалимул ун морман де петре, о визуинэ де шакаль, ши четэциле луй Иуда ле вой префаче ынтр-ун пустиу фэрэ локуиторь.”
12 Ta ni ẹni náà tí ó ní ọgbọ́n láti mòye nǹkan wọ̀nyí? Ta ni Olúwa ti sọ èyí fún, tí ó sì lè ṣàlàyé rẹ̀? Èéṣe tí ilẹ̀ náà fi ṣègbé bí aginjù, tí ẹnìkankan kò sì le là á kọjá?
Унде есте омул ынцелепт каре сэ ынцелягэ ачесте лукрурь? Сэ спунэ ачела кэруя й-а ворбит гура Домнулуй, пентру че есте нимичитэ цара, арсэ ка ун пустиу пе унде ну май трече нимень?
13 Olúwa sì wí pé, nítorí pé wọ́n ti kọ òfin mi sílẹ̀, èyí tí mo gbé kalẹ̀ níwájú wọn, wọn ṣe àìgbọ́ràn sí wọn, wọn kò sì rìn nínú òfin mi.
Домнул зиче: „Пентру кэ ау пэрэсит Леӂя Мя пе каре ле-о пусесем ынаинте; пентру кэ н-ау аскултат гласул Меу ши ну л-ау урмат,
14 Dípò èyí, wọ́n ti tẹ̀lé agídí ọkàn wọn, wọ́n ti tẹ̀lé Baali gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe kọ́ wọn.
чи ау умблат дупэ аплекэриле инимий лор ши ау мерс дупэ бааль, кум й-ау ынвэцат пэринций лор.”
15 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, “Wò ó, Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí jẹ oúnjẹ kíkorò àti láti mu omi májèlé.
Де ачея, аша ворбеште Домнул оштирилор, Думнезеул луй Исраел: „Ятэ, вой хрэни попорул ачеста ку пелин ши-й вой да сэ бя апе отрэвите.
16 Èmi yóò sì tú wọn ká láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, nínú èyí tí àwọn tàbí àwọn baba wọn kò mọ̀. Èmi yóò sì lépa wọn pẹ̀lú idà títí èmi yóò fi pa wọ́n run.”
Ый вой рисипи принтре ниште нямурь пе каре ну ле-ау куноскут нич ей, нич пэринций лор ши вой тримите сабия ын урма лор пынэ-й вой нимичи.”
17 Èyí sì ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí: “Sá à wò ó nísinsin yìí! Ké sí obìnrin ti ń ṣọ̀fọ̀ nì kí ó wá; sì ránṣẹ́ pe àwọn tí ó mòye nínú wọn.
Аша ворбеште Домнул оштирилор: „Кэутаць ши кемаць плынгэтоареле сэ винэ! Тримитець ла фемеиле искусите ка сэ винэ!
18 Jẹ́ kí wọn wá kíákíá, kí wọn wá pohùnréré ẹkún lé wa lórí títí ojú wa yóò fi sàn fún omijé tí omi yóò sì máa sàn àwọn ìpéǹpéjú wa.
Сэ се грэбяскэ сэ факэ о кынтаре де жале асупра ноастрэ, ка сэ не кургэ лакримиле дин окь ши сэ кургэ апа дин плеоапеле ноастре!
19 A gbọ́ igbe ìpohùnréré ẹkún ní Sioni: ‘Àwa ti ṣègbé tó! A gbọdọ̀ fi ilẹ̀ wa sílẹ̀, nítorí pé àwọn ilé wa ti parun.’”
Кэч стригэте де жале се ауд дин Сион: ‘Кыт сунтем де прэпэдиць! Кыт де жалник сунтем акопериць де рушине! Требуе сэ пэрэсим цара, кэч не-ау сурпат локуинцеле!’”
20 Nísinsin yìí, ẹ̀yin obìnrin ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa; ṣí etí yín sí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ. Kọ́ àwọn ọmọbìnrin yín ní ìpohùnréré ẹkún, kí ẹ sì kọ́ ara yín ní arò.
Аскултаць, фемеилор, Кувынтул Домнулуй ши сэ приндэ урекя воастрэ че спуне гура Луй! Ынвэцаць пе копиий воштри кынтече де жале, ынвэцаци-вэ плынӂерь унеле пе алтеле!
21 Ikú ti gba ojú fèrèsé wa wọlé ó sì ti wọ odi alágbára wa ó ti ké àwọn ọmọ kúrò ní àdúgbò àti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò ní gbọ̀ngàn ìta gbangba.
Кэч моартя с-а суит пе ферестреле ноастре, а пэтрунс ын каселе ноастре ымпэрэтешть; а нимичит пе копий пе улицэ ши пе тинерь, ын пеце.
22 Sọ pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Òkú àwọn ènìyàn yóò ṣubú bí ààtàn ní oko gbangba àti bí ìbùkúnwọ́ lẹ́yìn olùkórè láìsí ẹnìkankan láti kó wọn jọ.’”
„Спуне: ‘Аша ворбеште Домнул: «Трупуриле моарте але оаменилор вор кэдя ка гуноюл пе кымпий, кум каде ынапоя сечерэторулуй ун сноп пе каре ну-л стрынӂе нимень!»’”
23 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Má ṣe jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n yangàn nítorí agbára ọgbọ́n rẹ̀, tàbí alágbára nítorí agbára rẹ̀, tàbí ọlọ́rọ̀ nítorí ọrọ̀ rẹ̀.
Аша ворбеште Домнул: „Ынцелептул сэ ну се лауде ку ынцелепчуня луй, чел таре сэ ну се лауде ку тэрия луй, богатул сэ ну се лауде ку богэция луй.
24 Ẹ jẹ́ kí ẹni tí ń ṣògo nípa èyí nì wí pé: òun ní òye, òun sì mọ̀ mí wí pé, Èmi ni Olúwa tí ń ṣe òtítọ́, ìdájọ́ àti òdodo ní ayé, nínú èyí ni mo ní inú dídùn sí,” Olúwa wí.
Чи чел че се лаудэ сэ се лауде кэ аре причепере ши кэ Мэ куноаште, кэ штие кэ Еу сунт Домнул, каре фак милэ, жудекатэ ши дрептате пе пэмынт! Кэч ын ачестя гэсеск плэчере Еу”, зиче Домнул.
25 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí a kọ ilà fún nínú ara nìkan.
„Ятэ, вин зилеле”, зиче Домнул, „кынд вой педепси пе тоць чей тэяць ымпрежур, каре ну сунт тэяць ымпрежур ку инима,
26 Ejibiti, Juda, Edomu, Ammoni, Moabu àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní ọ̀nà jíjìn réré ní aginjù. Nítorí pé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jẹ́ aláìkọlà gbogbo àwọn ará ilé Israẹli sì jẹ́ aláìkọlà ọkàn.”
пе еӂиптень, пе иудей, пе едомиць, пе амониць, пе моабиць, пе тоць чей че ышь рад колцуриле бэрбий, пе чей че локуеск ын пустиу, кэч тоате нямуриле сунт нетэяте ымпрежур ши тоатэ каса луй Исраел аре инима нетэятэ ымпрежур.”

< Jeremiah 9 >