< Jeremiah 9 >

1 Háà! Orí ìbá jẹ́ orísun omi kí ojú mi sì jẹ́ orísun omijé! Èmi yóò sì sọkún tọ̀sán tòru nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.
Awu, sengathi ngabe ikhanda lami lingumthombo wamanzi, lamehlo ami angumthombo wezinyembezi! Kade ngizakhala emini lebusuku ngikhalela abantu bami ababuleweyo.
2 Háà, èmi ìbá ní ni aginjù ilé àgbàwọ̀ fún àwọn arìnrìn-àjò, kí n ba à lè fi àwọn ènìyàn mi sílẹ̀ kí n sì lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn: nítorí gbogbo wọn jẹ́ panṣágà àjọ aláìṣòótọ́ ènìyàn.
Awu, sengathi ngabe enkangala ngilendawo engahlala izihambi, ukuba ngisuke ebantwini bami ngisuke kubo, ngoba bonke bayizifebe, ixuku labantu abangathembekanga.
3 Wọ́n ti pèsè ahọ́n wọn sílẹ̀ bí ọfà láti fi pa irọ́; kì í ṣe nípa òtítọ́ ni wọ́n fi borí ní ilẹ̀ náà. Wọ́n ń lọ láti inú ẹ̀ṣẹ̀ kan sí òmíràn; wọn kò sì náání mi, ní Olúwa wí.
“Benza izindimi zabo zilunge njengesavutha ukuba batshoke amanga, ukuthi bayanqoba elizweni akusikho ngeqiniso. Basuka kokunye ukona baye kokunye; kabangamukeli,” kutsho uThixo.
4 “Ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ; má ṣe gbẹ́kẹ̀lé àwọn arákùnrin rẹ. Nítorí pé oníkálùkù arákùnrin jẹ́ atannijẹ, oníkálùkù ọ̀rẹ́ sì jẹ́ abanijẹ́.
“Qaphela abangane bakho, ungabathembi abafowenu. Ngoba wonke umfowenu ungumkhohlisi, njalo wonke umngane ungumhlebi.
5 Ọ̀rẹ́ ń dalẹ̀ ọ̀rẹ́. Kò sì ṣí ẹni tó sọ òtítọ́, wọ́n ti kọ́ ahọ́n wọn láti máa purọ́. Wọ́n sọ ara wọn di onírẹ̀wẹ̀sì pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀
Umngane ukhohlisa umngane, njalo kakho okhuluma iqiniso. Sebafundisa izindimi zabo ukuqamba amanga, bayazidinisa ngokona.
6 Ó ń gbé ní àárín ẹ̀tàn; wọ́n kọ̀ láti mọ̀ mí nínú ẹ̀tàn wọn,” ni Olúwa wí.
Lihlala phakathi kwenkohliso, ngenkohliso yabo bayala ukungamukela,” kutsho uThixo.
7 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Wò ó, èmi dán wọn wo; nítorí pé kí ni èmi tún le è ṣe? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi?
Ngakho uThixo uSomandla uthi: “Khangelani, ngizabacolisa ngibahlole, ngoba kuyini okunye engingakwenza ngenxa yesono sabantu bami?
8 Ahọ́n wọn dàbí ọfà olóró; ó ń sọ ẹ̀tàn. Oníkálùkù sì ń fi ẹnu rẹ̀ sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò rẹ̀, ní inú ọkàn rẹ̀, ó dẹ tàkúté sílẹ̀.
Ulimi lwabo lungumtshoko olobuthi, lukhuluma inkohliso. Lowo lalowo ukhuluma kuhle kubomakhelwane bakhe, kodwa enhliziyweni zabo bebathiya ngemijibila.
9 Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n nítorí èyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò ha gbẹ̀san ara mi lórí irú orílẹ̀-èdè yìí bí?”
Kakufanele ngibajezisele lokhu na?” kubuza uThixo. “Kakufanele ngiphindisele esizweni esinjengalesi na?”
10 Èmi yóò sì sọkún, pohùnréré ẹkún fún àwọn òkè àti ẹkún ìrora lórí pápá oko aginjù wọ̀n-ọn-nì. Nítorí wọ́n di ahoro, wọn kò sì kọjá ní ibẹ̀. A kò sì gbọ́ igbe ẹran ọ̀sìn. Àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ti sálọ, bẹ́ẹ̀ náà ni àwọn ẹranko sì ti lọ.
Ngizakhala ngililele izintaba ngibuye ngililele lamadlelo asenkangala. Atshabalele njalo kakho ohambela kuwo, lokubhonsa kwezinkomo akuzwakali. Izinyoni zasemoyeni sezibalekile, lezinyamazana kazisekho.
11 “Èmi yóò sì sọ Jerusalẹmu di òkìtì àlàpà àti ihò àwọn ìkookò. Èmi ó sì sọ ìlú Juda di ahoro tí ẹnikẹ́ni kò sì ní le è gbé.”
“IJerusalema ngizalenza libe yinqumbi yonxiwa, isikhundla samakhanka, njalo ngizawadiliza amadolobho akoJuda ukuze kungabikhona ohlala kuwo.”
12 Ta ni ẹni náà tí ó ní ọgbọ́n láti mòye nǹkan wọ̀nyí? Ta ni Olúwa ti sọ èyí fún, tí ó sì lè ṣàlàyé rẹ̀? Èéṣe tí ilẹ̀ náà fi ṣègbé bí aginjù, tí ẹnìkankan kò sì le là á kọjá?
Nguphi umuntu ohlakaniphileyo ukuba akuzwisise lokhu? Ngubani ofundiswe nguThixo ongakuchaza? Kungani ilizwe litshabalalisiwe lachithwa njengenkangala ukuze kungadluli muntu kulo?
13 Olúwa sì wí pé, nítorí pé wọ́n ti kọ òfin mi sílẹ̀, èyí tí mo gbé kalẹ̀ níwájú wọn, wọn ṣe àìgbọ́ràn sí wọn, wọn kò sì rìn nínú òfin mi.
UThixo wathi, “Kungenxa yokuthi sebelahle umthetho wami engababekela wona; kabangilalelanga, lomthetho wami kabawulandelanga.
14 Dípò èyí, wọ́n ti tẹ̀lé agídí ọkàn wọn, wọ́n ti tẹ̀lé Baali gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe kọ́ wọn.
Esikhundleni salokho, bona balandele ubulukhuni bezinhliziyo zabo; balandele oBhali, njengokufundiswa kwabo ngoyise.”
15 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, “Wò ó, Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí jẹ oúnjẹ kíkorò àti láti mu omi májèlé.
Ngakho-ke, uThixo uSomandla, uNkulunkulu ka-Israyeli uthi: “Khangelani, abantu laba ngizabadlisa ukudla okubabayo ngibanathise lamanzi alobuthi.
16 Èmi yóò sì tú wọn ká láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, nínú èyí tí àwọn tàbí àwọn baba wọn kò mọ̀. Èmi yóò sì lépa wọn pẹ̀lú idà títí èmi yóò fi pa wọ́n run.”
Ngizabahlakazela ezizweni bona kanye laboyise abangazange bazazi, njalo ngizabalandela ngenkemba ngize ngibaqede du.”
17 Èyí sì ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí: “Sá à wò ó nísinsin yìí! Ké sí obìnrin ti ń ṣọ̀fọ̀ nì kí ó wá; sì ránṣẹ́ pe àwọn tí ó mòye nínú wọn.
UThixo uSomandla uthi: “Cabangani khathesi! Bizani abesifazane abalilayo beze, libize labo abalobuciko obumangalisayo.
18 Jẹ́ kí wọn wá kíákíá, kí wọn wá pohùnréré ẹkún lé wa lórí títí ojú wa yóò fi sàn fún omijé tí omi yóò sì máa sàn àwọn ìpéǹpéjú wa.
Kabeze ngokuphangisa, bazesililela amehlo ethu aze ehlise inyembezi lempophoma zamanzi zigeleze, ziphuma enkopheni zethu.”
19 A gbọ́ igbe ìpohùnréré ẹkún ní Sioni: ‘Àwa ti ṣègbé tó! A gbọdọ̀ fi ilẹ̀ wa sílẹ̀, nítorí pé àwọn ilé wa ti parun.’”
Ilizwi lokukhala liyezwakala livela eZiyoni: “Yeka kunganani ukuchithakala kwethu! Yeka ubukhulu behlazo lethu! Kumele sisuke elizweni lethu ngoba izindlu zethu zidiliziwe.”
20 Nísinsin yìí, ẹ̀yin obìnrin ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa; ṣí etí yín sí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ. Kọ́ àwọn ọmọbìnrin yín ní ìpohùnréré ẹkún, kí ẹ sì kọ́ ara yín ní arò.
Khathesi, lina abesifazane, zwanini ilizwi likaThixo, vulani indlebe zenu lizwe amazwi omlomo wakhe. Fundisani amadodakazi enu ukulila, lifundisane amazwi okukhala.
21 Ikú ti gba ojú fèrèsé wa wọlé ó sì ti wọ odi alágbára wa ó ti ké àwọn ọmọ kúrò ní àdúgbò àti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò ní gbọ̀ngàn ìta gbangba.
Ukufa kukhwele kwangena ngamafastela ethu, njalo kungenile lasezinqabeni zethu, sekususe abantwana emigwaqweni kanye lamajaha ezindaweni zikazulu.
22 Sọ pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Òkú àwọn ènìyàn yóò ṣubú bí ààtàn ní oko gbangba àti bí ìbùkúnwọ́ lẹ́yìn olùkórè láìsí ẹnìkankan láti kó wọn jọ.’”
Tshono uthi, uThixo uthi, “‘izidumbu zabafileyo zizalala njengezibi egangeni, njengamabele aqunywe ngemva kovunayo, okungekho ozawabutha.’”
23 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Má ṣe jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n yangàn nítorí agbára ọgbọ́n rẹ̀, tàbí alágbára nítorí agbára rẹ̀, tàbí ọlọ́rọ̀ nítorí ọrọ̀ rẹ̀.
UThixo uthi: “Ohlakaniphileyo kangazincomi ngokuhlakanipha kwakhe, loba indoda elamandla izincome ngamandla ayo, loba indoda enothileyo izincome ngenotho yayo,
24 Ẹ jẹ́ kí ẹni tí ń ṣògo nípa èyí nì wí pé: òun ní òye, òun sì mọ̀ mí wí pé, Èmi ni Olúwa tí ń ṣe òtítọ́, ìdájọ́ àti òdodo ní ayé, nínú èyí ni mo ní inú dídùn sí,” Olúwa wí.
kodwa lowo ozincomayo, kazincome ngokuthi uyaqedisisa njalo uyangazi, ukuthi mina nginguThixo, osebenzisa umusa, imfanelo lokulunga emhlabeni, ngoba lezizinto ziyangithokozisa,” kutsho uThixo.
25 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí a kọ ilà fún nínú ara nìkan.
UThixo uthi, “Insuku ziyeza, lapho engizabajezisa khona bonke abasoke enyameni kuphela,
26 Ejibiti, Juda, Edomu, Ammoni, Moabu àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní ọ̀nà jíjìn réré ní aginjù. Nítorí pé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jẹ́ aláìkọlà gbogbo àwọn ará ilé Israẹli sì jẹ́ aláìkọlà ọkàn.”
iGibhithe, loJuda, lo-Edomi, lo-Amoni loMowabi labo bonke abahlala enkangala ezindaweni ezikhatshana. Ngoba izizwe zonke lezi kazisokanga, njalo lendlu yonke ka-Israyeli kayisokanga enhliziyweni.”

< Jeremiah 9 >