< Jeremiah 9 >

1 Háà! Orí ìbá jẹ́ orísun omi kí ojú mi sì jẹ́ orísun omijé! Èmi yóò sì sọkún tọ̀sán tòru nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.
Vajha fejem víz volna és szemem könnyek forrása, hogy siratnám nappal és éjjel népem leányának megöltjeit!
2 Háà, èmi ìbá ní ni aginjù ilé àgbàwọ̀ fún àwọn arìnrìn-àjò, kí n ba à lè fi àwọn ènìyàn mi sílẹ̀ kí n sì lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn: nítorí gbogbo wọn jẹ́ panṣágà àjọ aláìṣòótọ́ ènìyàn.
Vajha volna számomra, a pusztában utasok szállása, hogy elhagynám népemet és elmennék tőlük, mert mindnyájan házasságtörők, hűtlenkedők gyülekezete.
3 Wọ́n ti pèsè ahọ́n wọn sílẹ̀ bí ọfà láti fi pa irọ́; kì í ṣe nípa òtítọ́ ni wọ́n fi borí ní ilẹ̀ náà. Wọ́n ń lọ láti inú ẹ̀ṣẹ̀ kan sí òmíràn; wọn kò sì náání mi, ní Olúwa wí.
Kifeszítették nyelvüket, az ő íjukat, hazugságra, nem hűségért hatalmaskodtak az országban, mert rosszaságtól rosszaságra indultak és engem nem ismernek, úgymond az Örökkévaló.
4 “Ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ; má ṣe gbẹ́kẹ̀lé àwọn arákùnrin rẹ. Nítorí pé oníkálùkù arákùnrin jẹ́ atannijẹ, oníkálùkù ọ̀rẹ́ sì jẹ́ abanijẹ́.
Kiki barátjától óvakodjatok és még testvérben se bízzatok, mert minden testvér csalva csal és minden barát rágalmazva jár.
5 Ọ̀rẹ́ ń dalẹ̀ ọ̀rẹ́. Kò sì ṣí ẹni tó sọ òtítọ́, wọ́n ti kọ́ ahọ́n wọn láti máa purọ́. Wọ́n sọ ara wọn di onírẹ̀wẹ̀sì pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀
Kiki felebarátját ámítja és igazat nem beszélnek, nyelvüket tanították hazugságot beszélni, ferdén cselekedni fáradoztak.
6 Ó ń gbé ní àárín ẹ̀tàn; wọ́n kọ̀ láti mọ̀ mí nínú ẹ̀tàn wọn,” ni Olúwa wí.
Lakozásod csalárdság közepette van, csalárdságból vonakodnak megismerni engem, úgymond az Örökkévaló.
7 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Wò ó, èmi dán wọn wo; nítorí pé kí ni èmi tún le è ṣe? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi?
Azért így szól az Örökkévaló, a seregek ura: Íme én megolvasztom őket, hogy megvizsgáljam, mert mi másképpen cselekedhetném népem leánya miatt?
8 Ahọ́n wọn dàbí ọfà olóró; ó ń sọ ẹ̀tàn. Oníkálùkù sì ń fi ẹnu rẹ̀ sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò rẹ̀, ní inú ọkàn rẹ̀, ó dẹ tàkúté sílẹ̀.
Sebző nyíl az ő nyelvük, kiki csalárdságot beszél, szájával békét beszél felebarátjával, de belsejében lest hány neki.
9 Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n nítorí èyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò ha gbẹ̀san ara mi lórí irú orílẹ̀-èdè yìí bí?”
Vajon ezekért ne büntessem-e meg őket, úgymond az Örökkévaló, avagy oly nemzeten, mint ez, ne álljon-e bosszút lelkem?
10 Èmi yóò sì sọkún, pohùnréré ẹkún fún àwọn òkè àti ẹkún ìrora lórí pápá oko aginjù wọ̀n-ọn-nì. Nítorí wọ́n di ahoro, wọn kò sì kọjá ní ibẹ̀. A kò sì gbọ́ igbe ẹran ọ̀sìn. Àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ti sálọ, bẹ́ẹ̀ náà ni àwọn ẹranko sì ti lọ.
A hegyek fölött hangoztatok sírást és jajgatást és a puszta tanyái fölött gyászdalt, mert elpusztultak, úgy, hogy ember ott nem jár, és nem hallják a nyájnak hangját; az ég madarától a vadig, elköltöztek, tovamentek.
11 “Èmi yóò sì sọ Jerusalẹmu di òkìtì àlàpà àti ihò àwọn ìkookò. Èmi ó sì sọ ìlú Juda di ahoro tí ẹnikẹ́ni kò sì ní le è gbé.”
És teszem Jeruzsálemet kőhalmokká, sakálok tanyájává, és Jehúda városait teszem pusztasággá, lakó nélkül.
12 Ta ni ẹni náà tí ó ní ọgbọ́n láti mòye nǹkan wọ̀nyí? Ta ni Olúwa ti sọ èyí fún, tí ó sì lè ṣàlàyé rẹ̀? Èéṣe tí ilẹ̀ náà fi ṣègbé bí aginjù, tí ẹnìkankan kò sì le là á kọjá?
Ki a bölcs férfiú, hogy megértse ezt és amit szólt hozzá az Örökkévaló szája, hogy jelentse: mi miatt veszett el az ország, pusztult el, mint a sivatag, úgy hogy nem járnak ott?
13 Olúwa sì wí pé, nítorí pé wọ́n ti kọ òfin mi sílẹ̀, èyí tí mo gbé kalẹ̀ níwájú wọn, wọn ṣe àìgbọ́ràn sí wọn, wọn kò sì rìn nínú òfin mi.
Mondta az Örökkévaló: Mert elhagyták tanomat, melyet eléjük tettem, nem hallgattak szavamra és nem jártak aszerint:
14 Dípò èyí, wọ́n ti tẹ̀lé agídí ọkàn wọn, wọ́n ti tẹ̀lé Baali gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe kọ́ wọn.
és jártak szívük makacssága szerint és a Báalok után, melyekre tanították őseik.
15 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, “Wò ó, Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí jẹ oúnjẹ kíkorò àti láti mu omi májèlé.
Azért így szól az Örökkévaló, a seregek ura, Izrael Istene: Íme én enni adok a népnek ürmöt és inni adok nekik méregvizet.
16 Èmi yóò sì tú wọn ká láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, nínú èyí tí àwọn tàbí àwọn baba wọn kò mọ̀. Èmi yóò sì lépa wọn pẹ̀lú idà títí èmi yóò fi pa wọ́n run.”
Szétszórom őket a nemzetek között, amelyeket nem ismertek sem ők, sem őseik és utánuk bocsátom a kardot, míg meg nem semmisítettem őket.
17 Èyí sì ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí: “Sá à wò ó nísinsin yìí! Ké sí obìnrin ti ń ṣọ̀fọ̀ nì kí ó wá; sì ránṣẹ́ pe àwọn tí ó mòye nínú wọn.
Így szól az Örökkévaló, a seregek ura: Gondoljátok meg és hívjátok el a siratónőket, hadd jöjjenek, és a bölcs nőkhöz küldjetek, hadd jöjjenek el.
18 Jẹ́ kí wọn wá kíákíá, kí wọn wá pohùnréré ẹkún lé wa lórí títí ojú wa yóò fi sàn fún omijé tí omi yóò sì máa sàn àwọn ìpéǹpéjú wa.
Siessenek és hangoztassanak fölöttünk jajgatást, hogy szemeink szétáradjanak könnyektől és szempilláink folyjanak víztől.
19 A gbọ́ igbe ìpohùnréré ẹkún ní Sioni: ‘Àwa ti ṣègbé tó! A gbọdọ̀ fi ilẹ̀ wa sílẹ̀, nítorí pé àwọn ilé wa ti parun.’”
Mert jajgatás hangja hallatszott Cziónból: hogyan pusztultunk el! Nagyon megszégyenültünk, mert elhagytuk az országot, mert kivetettek bennünket hajlékaink.
20 Nísinsin yìí, ẹ̀yin obìnrin ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa; ṣí etí yín sí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ. Kọ́ àwọn ọmọbìnrin yín ní ìpohùnréré ẹkún, kí ẹ sì kọ́ ara yín ní arò.
Mert halljátok, asszonyok, az Örökkévaló igéjét, és vegye be fületek szájának igéjét: tanítsátok leányaitokat jajgatásra és egyik asszony a másikát gyászdalra.
21 Ikú ti gba ojú fèrèsé wa wọlé ó sì ti wọ odi alágbára wa ó ti ké àwọn ọmọ kúrò ní àdúgbò àti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò ní gbọ̀ngàn ìta gbangba.
Mert fölszállt a halál ablakainkba, bejött palotáinkba, hogy kiirtson gyermeket az utcáról, ifjakat a piacokról
22 Sọ pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Òkú àwọn ènìyàn yóò ṣubú bí ààtàn ní oko gbangba àti bí ìbùkúnwọ́ lẹ́yìn olùkórè láìsí ẹnìkankan láti kó wọn jọ.’”
– beszélj, így szól az Örökkévaló – és esni fog az ember hullája, mint a trágya a mező színén, s mint a kéve az arató mögött, és nincs ki összeszedi.
23 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Má ṣe jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n yangàn nítorí agbára ọgbọ́n rẹ̀, tàbí alágbára nítorí agbára rẹ̀, tàbí ọlọ́rọ̀ nítorí ọrọ̀ rẹ̀.
Így szól az Örökkévaló: Ne dicsekedjék a bölcs az ő bölcsességével és ne dicsekedjék a vitéz az ő vitézségével, ne dicsekedjék a gazdag az ő gazdagságával,
24 Ẹ jẹ́ kí ẹni tí ń ṣògo nípa èyí nì wí pé: òun ní òye, òun sì mọ̀ mí wí pé, Èmi ni Olúwa tí ń ṣe òtítọ́, ìdájọ́ àti òdodo ní ayé, nínú èyí ni mo ní inú dídùn sí,” Olúwa wí.
hanem azzal dicsekedjék, aki dicsekszik: hogy belátó és hogy megismer engem, hogy én, az Örökkévaló, szeretetet, jogot és igazságot művelek a földön, mert ezekben van kedvem, úgymond az Örökkévaló.
25 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí a kọ ilà fún nínú ara nìkan.
Íme napok jönnek, úgymond az Örökkévaló, és megbüntetek minden körülmetéltet a körülmetéletlenséggel együtt:
26 Ejibiti, Juda, Edomu, Ammoni, Moabu àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní ọ̀nà jíjìn réré ní aginjù. Nítorí pé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jẹ́ aláìkọlà gbogbo àwọn ará ilé Israẹli sì jẹ́ aláìkọlà ọkàn.”
Egyiptomot, Jehúdát, Edómot, Ammón fiait és Móábot, és mind a levágott hajszélűeket, kik a pusztában laknak, mert mind a nemzetek körülmetéletlenek, Izrael egész háza pedig körülmetéletlen szívű.

< Jeremiah 9 >