< Jeremiah 8 >

1 “‘Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, wọn yóò mú egungun àwọn ọba Juda àti egungun àwọn ìjòyè, egungun àwọn àlùfáà àti egungun àwọn wòlíì àti egungun àwọn olùgbé Jerusalẹmu kúrò nínú ibojì.
Czasu onego, mówi Pan, wybiorą kości królów Judzkich, i kości książąt ich, i kości kapłanów, i kości proroków, i kości obywateli Jeruzalemskich z grobów ich;
2 A ó yọ wọ́n síta fún oòrùn àti òṣùpá àti gbogbo àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run tí wọ́n ti fẹ́ràn tí wọ́n sì ti sìn, àti àwọn tí wọ́n ti tọ̀ lẹ́yìn tí wọ́n ti wá tí wọ́n sì ti foríbalẹ̀ fún. Kì yóò ṣà wọ́n jọ tàbí sìn wọ́n, wọn yóò dàbí ìdọ̀tí tó wà lórí ilẹ̀.
I rozrzucą je przed słońce, i przed miesiąc, i przed wszystko wojsko niebieskie, które miłują, i którym służą, i za którymi chodzą, i których szukają, i którym się kłaniają; nie pozbierają ich, ani pogrzebią, ale będą miasto gnoju na wierzchu ziem i.
3 Níbikíbi tí mo bá lé wọn lọ, gbogbo àwọn ìyókù wọn yóò fẹ́ ikú ju ìyè lọ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.’
I obiorą raczej śmierć niżeli żywot wszystkie ostatki, które zostaną z tego rodzaju złośliwego po wszystkich miejscach, gdziebykolwiek zostali, tam, kędy ich zapędzę, mówi Pan zastępów.
4 “Wí fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Bí ènìyàn bá ṣubú lulẹ̀, wọn kì í padà dìde bí? Nígbà tí ènìyàn bá yà kúrò ní ọ̀nà rẹ, kì í yí padà bí?
Przetoż rzeczesz do nich: Tak mówi Pan: Także upadli, aby nie mogli powstać? także się odwrócił, aby się zaś nie mógł nawrócić?
5 Èéṣe nígbà náà àwọn ènìyàn wọ̀nyí fi yà kúrò lọ́nà rẹ̀? Kí ló dé tí Jerusalẹmu fi yà kúrò ní gbogbo ìgbà? Wọ́n rọ̀ mọ́ ẹ̀tàn; wọ́n kọ̀ láti yípadà.
Przeczże się odwrócił ten lud Jeruzalemski odwróceniem wiecznem? chwytają się kłamstwa a nie chcą się nawracać.
6 Mo ti fetísílẹ̀ dáradára, wọn kò sọ ohun tí ó tọ́. Kò sí ẹnìkan tó ronúpìwàdà nínú ìwà búburú rẹ̀, kí ó wí pé, “Kí ni mo ṣe?” Olúkúlùkù ń tọ ọ̀nà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹṣin tó ń lọ sójú ogun.
Pilnowałem i słuchałem: nic nie mówiąc, co jest prawego; niemasz ktoby żałował złości swej, mówiąc: Cóżem uczynił? Każdy się obrócił za biegiem swoim, jako koń, który pędem bieży ku potkaniu.
7 Kódà, ẹyẹ àkọ̀ ojú ọ̀run mọ ìgbà tirẹ̀, àdàbà, alápáǹdẹ̀dẹ̀ àti lékèélékèé mọ àkókò ìṣípò padà wọn. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kò mọ ohun tí Olúwa wọn fẹ́.
I bocian na powietrzu zna ustawione czasy swoje, i synogarlica, i żuraw, i jaskółka przestrzegają czasu przylecenia swego; ale lud mój nie zna sądu Pańskiego.
8 “‘Báwo ni ẹ̀yin ṣe lè wí pé, “Àwa gbọ́n, nítorí a ní òfin Olúwa,” nígbà tí ó jẹ́ pé kálámù èké àwọn akọ̀wé ti àwọn sọ ọ́ di ẹ̀tàn.
Jakoż mówicie: Myśmy mądrzy, a zakon Pański jest przy nas? zaprawdę, oto daremnie pióro pisarz czyni; daremnie są w zakonie biegłymi.
9 Ojú yóò ti àwọn ọlọ́gbọ́n, a ó dà wọ́n láàmú, wọn yóò sì kó sí ìgbèkùn. Nítorí wọ́n ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa, irú ọgbọ́n wo ló kù tí wọ́n ní?
Kogoż zawstydzili ci mędrcy? Którzyż są przestraszeni i pojmani? Oto słowo Pańskie odrzucają; cóż to tedy za mądrość ich?
10 Nítorí náà, èmi yóò fi ìyàwó wọn fún àwọn ọkùnrin mìíràn àti ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹlòmíràn. Láti èyí tó kéré jù dé èyí tó dàgbà jù, gbogbo wọn ni èrè àjẹjù ń jẹ lógún; àwọn wòlíì àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú ń hùwà ẹ̀tàn.
Dlatego dam żony ich innym, pola ich tym, którzy ich opanują; bo od najmniejszego aż do największego, wszyscy zgoła udali się za łakomstwem; od proroka aż do kapłana wszyscy przewodzą kłamstwo.
11 Wọ́n tọ́jú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí èyí tí kò jinlẹ̀. “Àlàáfíà, àlàáfíà,” ni wọ́n ń wí, nígbà tí kò sí àlàáfíà.
Bo leczą skruszenie córki ludu mego tylko po wierzchu, mówiąc: Pokój, pokój! choć niemasz pokoju.
12 Ǹjẹ́ wọ́n tijú fún ìṣe ìríra wọn? Bẹ́ẹ̀ kọ́, wọn kò ní ìtìjú rárá; wọn kò tilẹ̀ mọ bí wọ́n ti ṣe ń tì jú. Nítorí náà wọn yóò ṣubú pẹ̀lú àwọn tó ti ṣubú, a ó sì wó wọ́n lulẹ̀ nígbà tí a bá bẹ̀ wọ́n wò, ni Olúwa wí.
Izali się zawstydzili, przeto, że obrzydliwość czynili? Zaiste, ani się zapałać ani wstydzić umieli; przetoż upadną między padającymi, czasu nawiedzenia swego upadną, mówi Pan.
13 “‘Èmi yóò mú ìkórè wọn kúrò, ni Olúwa wí. Kì yóò sí èso lórí igi àjàrà. Kì yóò sí ọ̀pọ̀tọ́ lórí igi, ewé wọn yóò sì rẹ̀ sílẹ̀. Ohun tí mo ti fi fún wọn ni à ó gbà kúrò.’”
Do szczętu ich wykorzenię, mówi Pan; nie będzie żadnego grona na winnej macicy, ani żadnych fig na drzewie figowem; nawet i liść opadnie, a com im dał, odjęte będzie.
14 “Èéṣe tí àwa fi jókòó ní ibí yìí? A kó ara wa jọ! Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi kí a sì ṣègbé síbẹ̀. Nítorí tí Olúwa Ọlọ́run wa ti pinnu pé a ó ṣègbé. Yóò sì fún wa ní omi onímájèlé mu, nítorí àwa ti ṣẹ̀ sí i.
Przecz my tu siedzimy? Zejdźcie się, a wynijdżmy do miast obronnych, a tam odpoczniemy; ale Pan, Bóg nasz każe nam odpocznąć, gdy nas napoi wodą żółci, iżeśmy zgrzeszyli przeciwko Panu.
15 Àwa ń retí àlàáfíà kò sí ìre kan, tí ó wá ní ìgbà ìmúláradá bí kò ṣe ìpayà nìkan.
Czekaj pokoju, alić nic dobrego; czasu uzdrowienia, alić oto strach.
16 Ìró ìfọn imú ẹṣin àwọn ọlọ̀tẹ̀ là ń gbọ́ láti Dani, yíyan àwọn akọ ẹṣin mú gbogbo ilẹ̀ wárìrì. Wọ́n wá láti pa ilẹ̀ náà run, gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, ìlú náà àti gbogbo olùgbé ibẹ̀.
Od Dan słyszeć chrapanie koni jego, od głosu wykrzykania mocarzy jego wszystka ziemia zadrżała, którzy ciągną, aby pożarli ziemię, i wszystko, co jest na niej, miasto i tych, którzy mieszkają w niem.
17 “Wò ó, èmi yóò rán àwọn ejò olóró sí àárín yín, paramọ́lẹ̀ tí ẹ kò lè pa oró wọn, yóò sì bù yín jẹ,” ni Olúwa wí.
Bo oto Ja poślę na was węże najjadowitsze, przeciwko którym niemasz zaklinania; i pokąsają was, mówi Pan.
18 Olùtùnú mi, nígbà tí ìbànújẹ́ ọkàn mi, rẹ̀wẹ̀sì nínú mi.
Serce moje we mnie, któreby mię miało posilać w smutku, mdłe jest.
19 Fetí sí ẹkún àwọn ènìyàn mi láti ilẹ̀ jíjìnnà wá: “Olúwa kò ha sí ní Sioni bí? Ọba rẹ̀ kò sí níbẹ̀ mọ́ ni?” “Èéṣe tí wọ́n fi mú mi bínú pẹ̀lú ère wọn, pẹ̀lú àwọn òrìṣà àjèjì tí wọn kò níláárí?”
Oto głos krzyku córki ludu mego z ziemi bardzo dalekiej mówiącej: Izali Pana niemasz na Syonie? Izali króla jego niemasz na nim? Przeczże mię wzruszyli do gniewu bałwanami swemi, próżnościami cudzoziemców? mówi Pan.
20 “Ìkórè ti rékọjá, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn ti parí, síbẹ̀ a kò gbà wá là.”
Pominęło żniwo, skończyło się lato, a myśmy nie wybawieni.
21 Níwọ́n ìgbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run, èmi náà run pẹ̀lú, èmi ṣọ̀fọ̀, ìrora sì mú mi káká.
Dla skruszenia córki ludu mojego skruszonym jest, żałobę ponoszę, zdumienie zdjęło mię.
22 Kò ha sí ìkunra ní Gileadi bí? Kò ha sí àwọn oníṣègùn níbẹ̀? Kí ló ha dé tí kò fi sí ìwòsàn fún ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi?
Izali niemasz balsamu w Galaad? Izali tam niemasz lekarza? Czemuż tedy nie jest uleczona córka ludu mojego?

< Jeremiah 8 >