< Jeremiah 8 >

1 “‘Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, wọn yóò mú egungun àwọn ọba Juda àti egungun àwọn ìjòyè, egungun àwọn àlùfáà àti egungun àwọn wòlíì àti egungun àwọn olùgbé Jerusalẹmu kúrò nínú ibojì.
En ce temps-là, dit l'Eternel, on jettera les os des Rois de Juda, et les os de ses Princes, les os des Sacrificateurs, et les os des Prophètes, et les os des habitants de Jérusalem, hors de leurs sépulcres.
2 A ó yọ wọ́n síta fún oòrùn àti òṣùpá àti gbogbo àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run tí wọ́n ti fẹ́ràn tí wọ́n sì ti sìn, àti àwọn tí wọ́n ti tọ̀ lẹ́yìn tí wọ́n ti wá tí wọ́n sì ti foríbalẹ̀ fún. Kì yóò ṣà wọ́n jọ tàbí sìn wọ́n, wọn yóò dàbí ìdọ̀tí tó wà lórí ilẹ̀.
Et on les étendra devant le soleil, et devant la lune, et devant toute l'armée des cieux, qui sont des choses qu'ils ont aimées, qu'ils ont servies et après lesquelles ils ont marché; des choses qu'ils ont recherchées, et devant lesquelles ils se sont prosternés; ils ne seront point recueillis ni ensevelis, ils seront comme du fumier sur le dessus de la terre.
3 Níbikíbi tí mo bá lé wọn lọ, gbogbo àwọn ìyókù wọn yóò fẹ́ ikú ju ìyè lọ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.’
Et la mort sera plus désirable que la vie à tous ceux qui seront restés de cette méchante race, ceux, [dis-je], qui seront restés dans tous les lieux où je les aurai chassés, dit l'Eternel des armées.
4 “Wí fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Bí ènìyàn bá ṣubú lulẹ̀, wọn kì í padà dìde bí? Nígbà tí ènìyàn bá yà kúrò ní ọ̀nà rẹ, kì í yí padà bí?
Tu leur diras donc: ainsi a dit l'Eternel: si on tombe, ne se relèvera-t-on pas? et si on se détourne, ne retournera-t-on pas [au chemin]?
5 Èéṣe nígbà náà àwọn ènìyàn wọ̀nyí fi yà kúrò lọ́nà rẹ̀? Kí ló dé tí Jerusalẹmu fi yà kúrò ní gbogbo ìgbà? Wọ́n rọ̀ mọ́ ẹ̀tàn; wọ́n kọ̀ láti yípadà.
Pourquoi [donc] s'est égaré ce peuple, [les habitants de] Jérusalem, d'un égarement continuel? ils se sont adonnés opiniâtrement à la tromperie, et ont refusé de se convertir.
6 Mo ti fetísílẹ̀ dáradára, wọn kò sọ ohun tí ó tọ́. Kò sí ẹnìkan tó ronúpìwàdà nínú ìwà búburú rẹ̀, kí ó wí pé, “Kí ni mo ṣe?” Olúkúlùkù ń tọ ọ̀nà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹṣin tó ń lọ sójú ogun.
Je me suis rendu attentif, et j'ai écouté, mais nul ne parle selon la justice, il n'y a personne qui se repente de son péché, disant: qu'ai-je fait? Ils sont tous retournés vers les objets qui les entraînent, comme le cheval qui se jette avec impétuosité parmi la bataille.
7 Kódà, ẹyẹ àkọ̀ ojú ọ̀run mọ ìgbà tirẹ̀, àdàbà, alápáǹdẹ̀dẹ̀ àti lékèélékèé mọ àkókò ìṣípò padà wọn. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kò mọ ohun tí Olúwa wọn fẹ́.
Même la cigogne a connu dans les cieux ses saisons, la tourterelle et l'hirondelle, et la grue, ont pris garde au temps qu'elles doivent venir; mais mon peuple n'a point connu le droit de l'Eternel.
8 “‘Báwo ni ẹ̀yin ṣe lè wí pé, “Àwa gbọ́n, nítorí a ní òfin Olúwa,” nígbà tí ó jẹ́ pé kálámù èké àwọn akọ̀wé ti àwọn sọ ọ́ di ẹ̀tàn.
Comment dites-vous: nous sommes les sages, et la Loi de l'Eternel est avec nous? voilà, certes on a agi faussement, et la plume des Scribes [est une plume] de fausseté.
9 Ojú yóò ti àwọn ọlọ́gbọ́n, a ó dà wọ́n láàmú, wọn yóò sì kó sí ìgbèkùn. Nítorí wọ́n ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa, irú ọgbọ́n wo ló kù tí wọ́n ní?
Les sages ont été confus, ils ont été épouvantés et pris, car ils ont rejeté la parole de l'Eternel? et en quoi seraient-ils sages?
10 Nítorí náà, èmi yóò fi ìyàwó wọn fún àwọn ọkùnrin mìíràn àti ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹlòmíràn. Láti èyí tó kéré jù dé èyí tó dàgbà jù, gbogbo wọn ni èrè àjẹjù ń jẹ lógún; àwọn wòlíì àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú ń hùwà ẹ̀tàn.
C'est pourquoi je donnerai leurs femmes à d'autres, et leurs champs à des gens qui les posséderont en héritage; car depuis le plus petit jusqu’au plus grand, chacun s'adonne au gain déshonnête, tant le Prophète que le Sacrificateur, tous agissent faussement.
11 Wọ́n tọ́jú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí èyí tí kò jinlẹ̀. “Àlàáfíà, àlàáfíà,” ni wọ́n ń wí, nígbà tí kò sí àlàáfíà.
Et ils ont pansé la plaie de la fille de mon peuple à la légère, en disant: paix, paix; et il n'y avait point de paix.
12 Ǹjẹ́ wọ́n tijú fún ìṣe ìríra wọn? Bẹ́ẹ̀ kọ́, wọn kò ní ìtìjú rárá; wọn kò tilẹ̀ mọ bí wọ́n ti ṣe ń tì jú. Nítorí náà wọn yóò ṣubú pẹ̀lú àwọn tó ti ṣubú, a ó sì wó wọ́n lulẹ̀ nígbà tí a bá bẹ̀ wọ́n wò, ni Olúwa wí.
Ont-ils été confus de ce qu'ils ont commis abomination? Ils n'en ont eu même aucune honte, et ils ne savent ce que c'est que de rougir; c'est pourquoi ils tomberont sur ceux qui seront tombés; ils tomberont au temps que je les visiterai, a dit l'Eternel.
13 “‘Èmi yóò mú ìkórè wọn kúrò, ni Olúwa wí. Kì yóò sí èso lórí igi àjàrà. Kì yóò sí ọ̀pọ̀tọ́ lórí igi, ewé wọn yóò sì rẹ̀ sílẹ̀. Ohun tí mo ti fi fún wọn ni à ó gbà kúrò.’”
En les ramassant je les consumerai entièrement dit l'Eternel; il n'y a pas une grappe dans les vignes; et il n'y a pas une figue au figuier, la feuille est flétrie, et ce que je leur ai donné sera transporté avec eux.
14 “Èéṣe tí àwa fi jókòó ní ibí yìí? A kó ara wa jọ! Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi kí a sì ṣègbé síbẹ̀. Nítorí tí Olúwa Ọlọ́run wa ti pinnu pé a ó ṣègbé. Yóò sì fún wa ní omi onímájèlé mu, nítorí àwa ti ṣẹ̀ sí i.
Pour quelle raison nous arrêtons-nous? Assemblez-vous, et entrons dans les villes fortes, et nous serons là en repos, car l'Eternel notre Dieu nous a fait taire, et nous a donné à boire de l'eau de fiel, parce que nous avons péché contre l'Eternel.
15 Àwa ń retí àlàáfíà kò sí ìre kan, tí ó wá ní ìgbà ìmúláradá bí kò ṣe ìpayà nìkan.
On attend la paix, et il n'y a rien de bon; [on attend] le temps de la guérison, et voici le trouble.
16 Ìró ìfọn imú ẹṣin àwọn ọlọ̀tẹ̀ là ń gbọ́ láti Dani, yíyan àwọn akọ ẹṣin mú gbogbo ilẹ̀ wárìrì. Wọ́n wá láti pa ilẹ̀ náà run, gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, ìlú náà àti gbogbo olùgbé ibẹ̀.
Le ronflement de ses chevaux a été ouï de Dan, et tout le pays a été ému du bruit des hennissements de ses puissants chevaux; ils sont venus et ont dévoré le pays et tout ce qui y était, la ville et ceux qui habitaient en elle.
17 “Wò ó, èmi yóò rán àwọn ejò olóró sí àárín yín, paramọ́lẹ̀ tí ẹ kò lè pa oró wọn, yóò sì bù yín jẹ,” ni Olúwa wí.
Qui plus est, voici, je m'en vais envoyer contre vous des serpents, des basilics, contre lesquels il n'y a point d'enchantement, et ils vous mordront, dit l'Eternel.
18 Olùtùnú mi, nígbà tí ìbànújẹ́ ọkàn mi, rẹ̀wẹ̀sì nínú mi.
J'ai voulu prendre des forces pour soutenir la douleur, mais mon cœur est languissant au dedans de moi.
19 Fetí sí ẹkún àwọn ènìyàn mi láti ilẹ̀ jíjìnnà wá: “Olúwa kò ha sí ní Sioni bí? Ọba rẹ̀ kò sí níbẹ̀ mọ́ ni?” “Èéṣe tí wọ́n fi mú mi bínú pẹ̀lú ère wọn, pẹ̀lú àwọn òrìṣà àjèjì tí wọn kò níláárí?”
Voici la voix du cri de la fille de mon peuple [qui crie] d'un pays éloigné; l'Eternel n'est-il point en Sion? son Roi n'est-il point au milieu d'elle? Mais pourquoi m'ont-ils irrité par leurs images taillées, par les vanités de l'étranger?
20 “Ìkórè ti rékọjá, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn ti parí, síbẹ̀ a kò gbà wá là.”
La moisson est passée; l'Eté est fini, et nous n'avons point été délivrés.
21 Níwọ́n ìgbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run, èmi náà run pẹ̀lú, èmi ṣọ̀fọ̀, ìrora sì mú mi káká.
Je suis amèrement affligé à cause de la calamité de la fille de mon peuple, j'en suis en deuil, j'en suis tout désolé.
22 Kò ha sí ìkunra ní Gileadi bí? Kò ha sí àwọn oníṣègùn níbẹ̀? Kí ló ha dé tí kò fi sí ìwòsàn fún ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi?
N'y a-t-il point de baume en Galaad? n'y a-t-il point là de médecin? pourquoi donc la plaie de la fille de mon peuple n'est-elle pas consolidée?

< Jeremiah 8 >