< Jeremiah 8 >
1 “‘Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, wọn yóò mú egungun àwọn ọba Juda àti egungun àwọn ìjòyè, egungun àwọn àlùfáà àti egungun àwọn wòlíì àti egungun àwọn olùgbé Jerusalẹmu kúrò nínú ibojì.
Paa den Tid, siger Herren, skulle de kaste Judas Kongers Ben og hans Fyrsters Ben og Præsternes Ben og Profeternes Ben og Jerusalems Indbyggeres Ben ud af deres Grave,
2 A ó yọ wọ́n síta fún oòrùn àti òṣùpá àti gbogbo àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run tí wọ́n ti fẹ́ràn tí wọ́n sì ti sìn, àti àwọn tí wọ́n ti tọ̀ lẹ́yìn tí wọ́n ti wá tí wọ́n sì ti foríbalẹ̀ fún. Kì yóò ṣà wọ́n jọ tàbí sìn wọ́n, wọn yóò dàbí ìdọ̀tí tó wà lórí ilẹ̀.
og udsprede dem for Solen og for Maanen og for al Himmelens Hær, hvilke de elskede, og hvilke de tjente, og hvilke de vandrede efter, og hvilke de søgte, og hvilke de tilbade; de skulle ikke sankes op og ej begraves, men vorde til Møg oven paa Jorden.
3 Níbikíbi tí mo bá lé wọn lọ, gbogbo àwọn ìyókù wọn yóò fẹ́ ikú ju ìyè lọ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.’
Og Død skal foretrækkes for Liv af hver den, som er tilovers af de overblevne af denne onde Slægt; de, som ere overblevne i alle de Stæder, hvor jeg har drevet dem hen, siger den Herre Zebaoth.
4 “Wí fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Bí ènìyàn bá ṣubú lulẹ̀, wọn kì í padà dìde bí? Nígbà tí ènìyàn bá yà kúrò ní ọ̀nà rẹ, kì í yí padà bí?
Og du skal sige til dem: Saa siger Herren: Mon man falder og staar ikke op? mon man vender sig bort og vender ikke tilbage?
5 Èéṣe nígbà náà àwọn ènìyàn wọ̀nyí fi yà kúrò lọ́nà rẹ̀? Kí ló dé tí Jerusalẹmu fi yà kúrò ní gbogbo ìgbà? Wọ́n rọ̀ mọ́ ẹ̀tàn; wọ́n kọ̀ láti yípadà.
Hvorfor er dette Folk i Jerusalem da afveget med en evig Afvigelse? de holde fast ved Svig, de vægre sig ved at vende om.
6 Mo ti fetísílẹ̀ dáradára, wọn kò sọ ohun tí ó tọ́. Kò sí ẹnìkan tó ronúpìwàdà nínú ìwà búburú rẹ̀, kí ó wí pé, “Kí ni mo ṣe?” Olúkúlùkù ń tọ ọ̀nà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹṣin tó ń lọ sójú ogun.
Jeg gav Agt og hørte til, de tale ikke Ret, der er ingen, som angrer sin Ondskab og siger: Hvad har jeg gjort? de have alle sammen vendt sig bort, hver til sit Løb, som en Hest, der render i Krigen.
7 Kódà, ẹyẹ àkọ̀ ojú ọ̀run mọ ìgbà tirẹ̀, àdàbà, alápáǹdẹ̀dẹ̀ àti lékèélékèé mọ àkókò ìṣípò padà wọn. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kò mọ ohun tí Olúwa wọn fẹ́.
Selv Storken under Himmelen kender sine bestemte Tider, og en Turteldue og en Trane og en Svale tage Vare paa den Tid, de skulle komme; men mit Folk, de kende ikke Herrens Ret.
8 “‘Báwo ni ẹ̀yin ṣe lè wí pé, “Àwa gbọ́n, nítorí a ní òfin Olúwa,” nígbà tí ó jẹ́ pé kálámù èké àwọn akọ̀wé ti àwọn sọ ọ́ di ẹ̀tàn.
Hvorledes kunne I sige: Vi ere vise, og Herrens Lov er hos os? men se, Skrivernes Løgnepen har arbejdet for Løgnen.
9 Ojú yóò ti àwọn ọlọ́gbọ́n, a ó dà wọ́n láàmú, wọn yóò sì kó sí ìgbèkùn. Nítorí wọ́n ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa, irú ọgbọ́n wo ló kù tí wọ́n ní?
De vise skulle blive til Skamme, forfærdes og besnæres; se, de have forkastet Herrens Ord, hvad for Visdom skulde de have?
10 Nítorí náà, èmi yóò fi ìyàwó wọn fún àwọn ọkùnrin mìíràn àti ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹlòmíràn. Láti èyí tó kéré jù dé èyí tó dàgbà jù, gbogbo wọn ni èrè àjẹjù ń jẹ lógún; àwọn wòlíì àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú ń hùwà ẹ̀tàn.
Derfor vil jeg give deres Hustruer til andre og deres Agre til dem, som skulle eje dem; thi fra den mindste til den største tragter enhver efter Vinding, fra Profet og indtil Præst lægge de alle Vind paa Løgn.
11 Wọ́n tọ́jú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí èyí tí kò jinlẹ̀. “Àlàáfíà, àlàáfíà,” ni wọ́n ń wí, nígbà tí kò sí àlàáfíà.
Og de lægede mit Folks Datters Brøst, som om det var en let Sag, idet de sagde: Fred! Fred! dog der var ikke Fred.
12 Ǹjẹ́ wọ́n tijú fún ìṣe ìríra wọn? Bẹ́ẹ̀ kọ́, wọn kò ní ìtìjú rárá; wọn kò tilẹ̀ mọ bí wọ́n ti ṣe ń tì jú. Nítorí náà wọn yóò ṣubú pẹ̀lú àwọn tó ti ṣubú, a ó sì wó wọ́n lulẹ̀ nígbà tí a bá bẹ̀ wọ́n wò, ni Olúwa wí.
De ere blevne til Skamme; thi de gjorde Vederstyggelighed; dog skamme de sig aldeles ikke og vide ikke at være skamfulde; derfor skulle de falde iblandt dem, som falde; i den Tid, naar de hjemsøges skulle de snuble, siger Herren.
13 “‘Èmi yóò mú ìkórè wọn kúrò, ni Olúwa wí. Kì yóò sí èso lórí igi àjàrà. Kì yóò sí ọ̀pọ̀tọ́ lórí igi, ewé wọn yóò sì rẹ̀ sílẹ̀. Ohun tí mo ti fi fún wọn ni à ó gbà kúrò.’”
Jeg vil helt rive dem bort, siger Herren; der er ikke Druer paa Vintræet og ej Figen paa Figentræet, og Bladene ere visne, og jeg gav dem til Pris for dem, der drage hen over dem.
14 “Èéṣe tí àwa fi jókòó ní ibí yìí? A kó ara wa jọ! Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi kí a sì ṣègbé síbẹ̀. Nítorí tí Olúwa Ọlọ́run wa ti pinnu pé a ó ṣègbé. Yóò sì fún wa ní omi onímájèlé mu, nítorí àwa ti ṣẹ̀ sí i.
Hvorfor sidde vi stiller samler eder, og lader os gaa ind i de faste Stæder og omkomme der; thi Herren vor Gud har ladet os omkomme og givet os besk Vand at drikke; thi vi have syndet imod Herren.
15 Àwa ń retí àlàáfíà kò sí ìre kan, tí ó wá ní ìgbà ìmúláradá bí kò ṣe ìpayà nìkan.
Man venter paa Fred, og det bliver ikke godt; paa Lægedoms Tid, og se, Forfærdelse kommer.
16 Ìró ìfọn imú ẹṣin àwọn ọlọ̀tẹ̀ là ń gbọ́ láti Dani, yíyan àwọn akọ ẹṣin mú gbogbo ilẹ̀ wárìrì. Wọ́n wá láti pa ilẹ̀ náà run, gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, ìlú náà àti gbogbo olùgbé ibẹ̀.
Fra Dan høres hans Hestes Fnysen, for Lyden af hans vældige Hestes Vrinsken ryster det ganske Land; og de komme og fortære Landet og dets Fylde, Staden og Indbyggerne derudi.
17 “Wò ó, èmi yóò rán àwọn ejò olóró sí àárín yín, paramọ́lẹ̀ tí ẹ kò lè pa oró wọn, yóò sì bù yín jẹ,” ni Olúwa wí.
Thi se, jeg sender iblandt eder Slanger, Basilisker, som ikke lade sig besværge, og de skulle bide eder, siger Herren.
18 Olùtùnú mi, nígbà tí ìbànújẹ́ ọkàn mi, rẹ̀wẹ̀sì nínú mi.
Hvor finder jeg Vederkvægelse for Sorgen! mit Hjerte er sygt i mig.
19 Fetí sí ẹkún àwọn ènìyàn mi láti ilẹ̀ jíjìnnà wá: “Olúwa kò ha sí ní Sioni bí? Ọba rẹ̀ kò sí níbẹ̀ mọ́ ni?” “Èéṣe tí wọ́n fi mú mi bínú pẹ̀lú ère wọn, pẹ̀lú àwọn òrìṣà àjèjì tí wọn kò níláárí?”
Se, mit Folks Datters Raab lyder fra et langt bortliggende Land: Er da Herren ikke i Zion? eller er dets Konge ikke der? Hvorfor have de fortørnet mig med deres udskaarne Billeder, med et fremmed Folks Afguder?
20 “Ìkórè ti rékọjá, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn ti parí, síbẹ̀ a kò gbà wá là.”
Høsten er forbi, Sommeren er til Ende, og vi ere ikke frelste.
21 Níwọ́n ìgbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run, èmi náà run pẹ̀lú, èmi ṣọ̀fọ̀, ìrora sì mú mi káká.
Jeg er sønderknust over mit Folks Datters Sønderknuselse, jeg gaar i Sørgeklæder, Forskrækkelse har betaget mig.
22 Kò ha sí ìkunra ní Gileadi bí? Kò ha sí àwọn oníṣègùn níbẹ̀? Kí ló ha dé tí kò fi sí ìwòsàn fún ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi?
Er der da ingen Balsam i Gilead? eller er der ingen Læge der? thi hvorfor er der ikke lagt Forbinding paa mit Folks Datter?