< Jeremiah 7 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
Detta är det ord som kom till Jeremia från HERREN; han sade:
2 “Dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yí: “‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ọ̀nà yí wọlé láti wá sin Olúwa.
Ställ dig i porten till HERRENS hus, och predika där detta ord och säg: Hören HERRENS ord, I alla av Juda, som gån in genom dessa portar för att tillbedja HERREN.
3 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Tún àwọn ọ̀nà yín ṣe, èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ gbé ilẹ̀ yìí.
Så säger HERREN Sebaot, Israels Gud: Bättren edert leverne och edert väsende, så vill jag låta eder bo kvar på denna plats.
4 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn gbọ́ kí ẹ sì wí pé, “Èyí ni tẹmpili Olúwa ilé tẹmpili Olúwa, ilé tẹmpili Olúwa!”
Förliten eder icke på lögnaktigt tal, när man säger: »Här är HERRENS tempel, HERRENS tempel, HERRENS tempel!»
5 Bí ẹ̀yin bá tún ọ̀nà yín àti iṣẹ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ sì ń bá ara yín lò ní ọ̀nà tó tọ́.
Nej, om I bättren edert leverne och edert väsende, om I dömen rätt mellan man och man,
6 Bí ẹ kò bá fi ara ni àwọn àlejò, àwọn ọmọ aláìní baba àti àwọn opó tí ẹ kò sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, bí ẹ kò bá sì tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn sí ìpalára ara yín.
om I upphören att förtrycka främlingen, den faderlöse och änkan, att utgjuta oskyldigt blod på denna plats och att följa efter andra gudar, eder själva till olycka,
7 Nígbà náà ni èmi yóò jẹ́ kí ẹ gbé ìbí yìí, nílẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé.
då vill jag för evärdliga tider låta eder bo på denna plats, i det land som jag har givit åt edra fäder.
8 Ẹ wò ó, ẹ ń gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò níláárí gbọ́.
Men se, I förliten eder på lögnaktigt tal, som icke kan hjälpa.
9 “‘Ẹ̀yin yóò ha jalè, kí ẹ pànìyàn, kí ẹ ṣe panṣágà, kí ẹ búra èké, kí ẹ sun tùràrí sí Baali, kí ẹ sì tọ ọlọ́run mìíràn tí ẹ̀yin kò mọ̀ lọ?
Huru är det? I stjälen, mörden och begån äktenskapsbrott, I svärjen falskt, I tänden offereld åt Baal och följen efter andra gudar, som I icke kännen;
10 Nígbà náà ni kí ó wá dúró ní iwájú nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, “Kí ẹ wá wí pé àwa yè,” àwa yè láti ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra wọ̀nyí bí?
sedan kommen I hit och träden fram inför mitt ansikte i detta hus, som är uppkallat efter mitt namn, och sägen: »Med oss är ingen nöd» -- för att därefter fortfara med alla dessa styggelser.
11 Ṣé ilé yìí, tí a fi orúkọ mi pè ti di ihò àwọn ọlọ́ṣà lọ́dọ̀ yín ni? Èmi ti ń wò ó! ni Olúwa wí.
Hållen I det då för en rövarkula, detta hus, som är uppkallat efter mitt namn? Ja, sannerligen, också jag anser det så, säger HERREN.
12 “‘Ẹ lọ nísinsin yìí sí Ṣilo níbi ti mo kọ́ fi ṣe ibùgbé fún orúkọ mi, kí ẹ sì rí ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú Israẹli tí í ṣe ènìyàn mi.
Gån bort till den plats i Silo, där jag först lät mitt namn bo, och sen huru jag har gjort med den, för mitt folk Israels ondskas skull.
13 Nígbà tí ẹ̀yin ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí ni èmi bá a yín sọ̀rọ̀ léraléra ni Olúwa wí ẹ̀yin kò gbọ́, èmi pè yín, ẹ̀yin kò dáhùn.
Och eftersom I haven gjort alla dessa gärningar, säger HERREN, och icke haven velat höra, fastän jag titt och ofta har talat till eder, och icke haven velat svara, fastän jag har ropat på eder,
14 Nítorí náà, èmi yóò ṣe ohun tí mo ṣe sí Ṣilo sí ilé náà tí a fi orúkọ mi pè, ilé tẹmpili nínú èyí tí ẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ààyè tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba yín.
därför vill jag nu med detta hus, som är uppkallat efter mitt namn, och som I förliten eder på, och med denna plats, som jag har givit åt eder och edra fäder, göra såsom jag gjorde med Silo.
15 Èmi yóò tú kúrò ní iwájú mi gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí àwọn arákùnrin yín, àwọn ará Efraimu.’
Och jag skall kasta eder bort ifrån mitt ansikte, såsom jag har bortkastat alla edra bröder all Efraims släkt.
16 “Nítorí náà má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn; ma ṣe bẹ̀ mí, nítorí èmi kì yóò tẹ́tí sí ọ.
Så må du nu icke bedja för detta folk eller frambära någon klagan och förbön för dem eller lägga dig ut för dem hos mig, ty jag vill icke höra dig.
17 Ṣé ìwọ kò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
Ser du icke vad de göra i Juda städer och på Jerusalems gator?
18 Àwọn ọmọ ṣa igi jọ, àwọn baba fi iná sí i, àwọn ìyá sì po ìyẹ̀fun láti ṣe àkàrà fún ayaba ọ̀run, wọ́n tú ẹbọ ọrẹ mímu sí àwọn ọlọ́run àjèjì láti ru bínú mi sókè.
Barnen samla tillhopa ved, fäderna tända upp eld och kvinnorna knåda deg, allt för att baka offerkakor åt himmelens drottning; och drickoffer utgjuta de åt andra gudar, mig till sorg.
19 Ṣùgbọ́n ṣe èmi ni wọ́n fẹ́ mú bínú? ni Olúwa wí. Ǹjẹ́ kì í ṣe pé wọ́n kúkú ń pa ara wọn lára sí ìtìjú ara wọn?
Men är det då mig som de bereda sorg därmed, säger HERREN, och icke fastmer sig själva, så att de komma på skam?
20 “‘Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò tú ìbínú àti ìrunú mi sí orílẹ̀ yìí ènìyàn àti ẹranko, igi, pápá àti èso orí ilẹ̀, yóò sì jó tí kò ní ṣe é pa.”
Därför säger Herren, HERREN så: Se, min vrede och förtörnelse skall utgjuta sig över denna plats, över både människor och djur, över både träden på marken och frukten på jorden; och den skall brinna och icke bliva utsläckt.
21 “‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Tẹ̀síwájú kí ẹ kó ẹbọ sísun yín àti àwọn ẹbọ yòókù papọ̀ kí ẹ̀yin kí ó sì jẹ ẹran wọ́n fúnra yín.
Så säger HERREN Sebaot, Israels Gud: Läggen edra brännoffer tillhopa med edra slaktoffer och äten så kött.
22 Ní tòsí nígbà tí mo mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti tí mo sì bá wọn sọ̀rọ̀. N kò pàṣẹ fún wọn lórí ẹbọ sísun lásán.
Ty på den tid då jag förde edra fäder ut ur Egyptens land gav jag dem icke någon befallning eller något bud angående brännoffer och slaktoffer;
23 Mo pàṣẹ fún wọn báyìí pé; gbọ́ tèmi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi. Máa rìn ní ojú ọ̀nà tí mo pàṣẹ fún yín, kí ó lè dára fún yín.
utan detta var det bud jag gav dem: »Hören min röst, så vill jag vara eder Gud, och I skolen vara mitt folk; och vandren i allt på den väg som jag bjuder eder, på det att det må gå eder väl.»
24 Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, wọn kò sì fetísílẹ̀ dípò èyí wọ́n ń tẹ̀ sí ọ̀nà agídí ọkàn wọn. Dípò kí wọn tẹ̀síwájú wọ́n ń rẹ̀yìn.
Men de ville icke höra eller böja sitt öra till mig, utan vandrade efter sina egna rådslag, i sina onda hjärtans hårdhet, och veko tillbaka i stället för att gå framåt.
25 Láti ìgbà tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní Ejibiti títí di òní, ni èmi ti ń rán àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì sí yín.
Allt ifrån den dag då edra fäder drogo ut ur Egyptens land ända till nu har jag dag efter dag, titt och ofta, sänt till eder alla mina tjänare profeterna.
26 Wọn kò gbọ́ wọn kò sì fetísílẹ̀. Wọ́n wa ọrùn le, wọn wa ọrùn kì, wọ́n sì hu ìwà ìbàjẹ́ ju àwọn baba ńlá wọn.’
Men man ville icke höra mig eller böja sitt öra till mig; de voro hårdnackade och gjorde ännu mer ont än deras fäder.
27 “Nígbà tí ìwọ bá sọ gbogbo èyí fún wọn, wọn kì yóò gbọ́ tirẹ̀, nígbà tí ìwọ bá sì pè wọ́n, wọn kì yóò dáhùn.
Och om du än säger dem allt detta, så skola de dock icke höra dig; och om du än ropar till dem, så skola de dock icke svara dig.
28 Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ tàbí kí ó ṣe ìgbọ́ràn sí ìbáwí. Ọ̀rọ̀ òtítọ́ kò sí ní ètè wọn.
Säg därför till dem: »Detta är det folk som icke vill höra HERRENS, sin Guds, röst eller taga emot tuktan. Sanningen är försvunnen och utrotad ur deras mun.»
29 “‘Gé irun yín kí ẹ sì dàánù, pohùnréré ẹkún lórí òkè, nítorí Olúwa ti kọ ìran yìí tí ó wà lábẹ́ ìbínú rẹ̀ sílẹ̀.
Skär av dig ditt huvudhår och kasta det bort, och stäm upp en klagosång på höjderna. Ty HERREN har förkastat och förskjutit detta släkte, som har uppväckt hans vrede.
30 “‘Àwọn ènìyàn Juda ti ṣe búburú lójú mi, ni Olúwa wí. Wọ́n ti to àwọn ère ìríra wọn jọ sí ilé tí a fi orúkọ mi pè wọ́n sì ti sọ ọ́ di àìmọ́.
Juda barn hava ju gjort vad ont är i mina ögon, säger HERREN; de hava satt upp sina styggelser i det hus som är uppkallat efter mitt namn, och de hava så orenat det.
31 Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga ti Tofeti ní àfonífojì Beni-Hinnomu láti sun àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn nínú iná èyí tí èmi kò pàṣẹ tí kò sì wá sí ọkàn mi.
Och Tofethöjderna i Hinnoms sons dal hava de byggt upp, för att där uppbränna sina söner och döttrar i eld, fastän jag aldrig har bjudit eller ens tänkt mig något sådant.
32 Nítorí náà kíyèsára ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí, nígbà tí àwọn ènìyàn kò ní pè é ní Tafeti tàbí àfonífojì ti Beni-Hinnomu; ṣùgbọ́n yóò ma jẹ àfonífojì ìparun, nítorí wọn yóò sin òkú sí Tofeti títí kò fi ní sí ààyè mọ́.
Se, därför skola dagar komma, säger HERREN, då man icke mer skall säga »Tofet» eller »Hinnoms sons dal», utan »Dråpdalen», och då man skall begrava i Tofet, därför att ingen annan plats finnes.
33 Nígbà náà ni òkú àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀, kò sì ní sí ẹnìkan tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
Ja, detta folks döda kroppar skola bliva mat åt himmelens fåglar och markens djur, och ingen skall skrämma bort dem.
34 Èmi yóò mú òpin bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú àti ohùn àwọn tọkọtaya ní àwọn ìlú Juda àti ní ìgboro Jerusalẹmu, nítorí tí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
Och i Juda städer och på Jerusalems gator skall jag göra slut på fröjderop och glädjerop, på rop för brudgum och rop för brud, ty landet skall bliva ödelagt.

< Jeremiah 7 >