< Jeremiah 7 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
Detta är det ord, som skedde till Jeremia af Herranom, som sade:
2 “Dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yí: “‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ọ̀nà yí wọlé láti wá sin Olúwa.
Gack och statt i portenom åt Herrans hus, och predika der detta ordet, och säg: Hörer Herrans ord, I alle af Juda, I som gån genom denna porten, till att tillbedja Herran.
3 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Tún àwọn ọ̀nà yín ṣe, èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ gbé ilẹ̀ yìí.
Så säger Herren Zebaoth, Israels Gud: Bättrer edart lefverne och väsende, så vill jag bo när eder i desso rumme.
4 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn gbọ́ kí ẹ sì wí pé, “Èyí ni tẹmpili Olúwa ilé tẹmpili Olúwa, ilé tẹmpili Olúwa!”
Förlåter eder icke uppå lögn, sägande: Här är Herrans tempel, här är Herrans tempel, här är Herrans tempel;
5 Bí ẹ̀yin bá tún ọ̀nà yín àti iṣẹ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ sì ń bá ara yín lò ní ọ̀nà tó tọ́.
Utan bättrer edart lefverne och väsende, att I gören hvarannan rätt;
6 Bí ẹ kò bá fi ara ni àwọn àlejò, àwọn ọmọ aláìní baba àti àwọn opó tí ẹ kò sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, bí ẹ kò bá sì tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn sí ìpalára ara yín.
Och görer främlingenom, dem faderlösa och enkone intet öfvervåld; och utgjuter intet oskyldigt blod i desso rumme, och följer icke andra gudar efter, till edar egen skada;
7 Nígbà náà ni èmi yóò jẹ́ kí ẹ gbé ìbí yìí, nílẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé.
Så vill jag evinnerliga bo när eder i desso rumme, i landena som jag edra fäder gifvit hafver.
8 Ẹ wò ó, ẹ ń gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò níláárí gbọ́.
Men nu förlåten I eder på lögn, den intet nyttig är.
9 “‘Ẹ̀yin yóò ha jalè, kí ẹ pànìyàn, kí ẹ ṣe panṣágà, kí ẹ búra èké, kí ẹ sun tùràrí sí Baali, kí ẹ sì tọ ọlọ́run mìíràn tí ẹ̀yin kò mọ̀ lọ?
Dertill ären I tjufvar, mördare, horkarlar, och menedare, och röken inför Baal, och följen främmande gudar efter; de I intet kännen.
10 Nígbà náà ni kí ó wá dúró ní iwájú nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, “Kí ẹ wá wí pé àwa yè,” àwa yè láti ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra wọ̀nyí bí?
Sedan kommen I då, och gån fram för mig i desso huse, det efter mitt Namn nämndt är, och sägen: Det hafver ingen nöd med oss, medan vi sådana styggelse görom.
11 Ṣé ilé yìí, tí a fi orúkọ mi pè ti di ihò àwọn ọlọ́ṣà lọ́dọ̀ yín ni? Èmi ti ń wò ó! ni Olúwa wí.
Hållen I då detta hus, som efter mitt Namn nämndt är, för ena mördarekulo? Si, jag ser det väl, säger Herren.
12 “‘Ẹ lọ nísinsin yìí sí Ṣilo níbi ti mo kọ́ fi ṣe ibùgbé fún orúkọ mi, kí ẹ sì rí ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú Israẹli tí í ṣe ènìyàn mi.
Går bort till mitt rum i Silo, der mitt Namn tillförene bott hafver, och ser till, hvad jag der gjort hafver, för mins folks Israels ondskos skull.
13 Nígbà tí ẹ̀yin ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí ni èmi bá a yín sọ̀rọ̀ léraléra ni Olúwa wí ẹ̀yin kò gbọ́, èmi pè yín, ẹ̀yin kò dáhùn.
Efter I nu alle sådana stycke bedrifven, säger Herren, och jag eder tidt och ofta predika låter, och I viljen icke hörat; jag ropar, och I viljen intet svara;
14 Nítorí náà, èmi yóò ṣe ohun tí mo ṣe sí Ṣilo sí ilé náà tí a fi orúkọ mi pè, ilé tẹmpili nínú èyí tí ẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ààyè tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba yín.
Så vill jag sammalunda göra med de hus, som efter mitt Namn nämndt är, der I eder uppå förlåten, och med det rum, som jag edra fäder gifvit hafver, likasom jag med Silo gjort hafver;
15 Èmi yóò tú kúrò ní iwájú mi gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí àwọn arákùnrin yín, àwọn ará Efraimu.’
Och skall kasta eder bort ifrå mitt ansigte, likasom jag bortkastat hafver alla edra bröder, alla Ephrahims säd.
16 “Nítorí náà má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn; ma ṣe bẹ̀ mí, nítorí èmi kì yóò tẹ́tí sí ọ.
Och skall du intet bedja för detta folk, ej heller någon klagan eller bön förebära, eller lägga dig ut för dem inför mig; ty jag vill intet höra dig.
17 Ṣé ìwọ kò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
Ty ser du icke hvad de göra i Juda städer, och på gatomen i Jerusalem?
18 Àwọn ọmọ ṣa igi jọ, àwọn baba fi iná sí i, àwọn ìyá sì po ìyẹ̀fun láti ṣe àkàrà fún ayaba ọ̀run, wọ́n tú ẹbọ ọrẹ mímu sí àwọn ọlọ́run àjèjì láti ru bínú mi sókè.
Barnen hemta veden, och fäderna göra upp elden, och qvinnorna göra degen, att de skola baka himmelens Drottning kakor, och gifva främmande gudar drickoffer, på det de skola förtörna mig;
19 Ṣùgbọ́n ṣe èmi ni wọ́n fẹ́ mú bínú? ni Olúwa wí. Ǹjẹ́ kì í ṣe pé wọ́n kúkú ń pa ara wọn lára sí ìtìjú ara wọn?
Men de skola icke göra mig der ondt med, säger Herren, utan sig sjelfvom, och skola till skam varda.
20 “‘Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò tú ìbínú àti ìrunú mi sí orílẹ̀ yìí ènìyàn àti ẹranko, igi, pápá àti èso orí ilẹ̀, yóò sì jó tí kò ní ṣe é pa.”
Derföre säger Herren Herren: Si, min vrede och min grymhet är utgjuten öfver detta rum, både öfver folk och fä, öfver trän på markene, och öfver fruktena på jordene; och skall brinna, så att ingen skall kunna släckat.
21 “‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Tẹ̀síwájú kí ẹ kó ẹbọ sísun yín àti àwọn ẹbọ yòókù papọ̀ kí ẹ̀yin kí ó sì jẹ ẹran wọ́n fúnra yín.
Detta säger Herren Zebaoth, Israels Gud: Görer edor bränneoffer och annor offer tillhopa, och äter kött.
22 Ní tòsí nígbà tí mo mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti tí mo sì bá wọn sọ̀rọ̀. N kò pàṣẹ fún wọn lórí ẹbọ sísun lásán.
Ty på den dagen, då jag förde edra fäder utur Egypti land, hafver jag intet sagt eller budit dem om bränneoffer och annat offer;
23 Mo pàṣẹ fún wọn báyìí pé; gbọ́ tèmi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi. Máa rìn ní ojú ọ̀nà tí mo pàṣẹ fún yín, kí ó lè dára fún yín.
Utan detta böd jag dem, och sade: Lyder min ord, så vill jag vara edar Gud, och I skolen vara mitt folk; och vandrer på alla de vägar, som jag bjuder eder, på det eder skall väl gå.
24 Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, wọn kò sì fetísílẹ̀ dípò èyí wọ́n ń tẹ̀ sí ọ̀nà agídí ọkàn wọn. Dípò kí wọn tẹ̀síwájú wọ́n ń rẹ̀yìn.
Men de ville intet höra, eller böja sin öron härtill, utan vandrade efter sitt eget råd, och efter sin onda hjertas tycko, och gingo tillbaka, och icke framåt.
25 Láti ìgbà tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní Ejibiti títí di òní, ni èmi ti ń rán àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì sí yín.
Ja, ifrå den dagen att jag edra fäder utu Egypti land förde, och intill denna dag, hafver jag dagliga sändt till eder alla mina tjenare Propheterna.
26 Wọn kò gbọ́ wọn kò sì fetísílẹ̀. Wọ́n wa ọrùn le, wọn wa ọrùn kì, wọ́n sì hu ìwà ìbàjẹ́ ju àwọn baba ńlá wọn.’
Men de ville intet höra, eller böja sin öron, utan äro halsstyfve, och görat än värre än deras fäder.
27 “Nígbà tí ìwọ bá sọ gbogbo èyí fún wọn, wọn kì yóò gbọ́ tirẹ̀, nígbà tí ìwọ bá sì pè wọ́n, wọn kì yóò dáhùn.
Och om du än allt detta säger dem, så höra de dock intet; ropar du, så svara de dock intet.
28 Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ tàbí kí ó ṣe ìgbọ́ràn sí ìbáwí. Ọ̀rọ̀ òtítọ́ kò sí ní ètè wọn.
Derföre säg till dem: Detta är det folk, som Herran sin Gud icke hörer, eller sig bättra vill; den rätta läran är platt borto, och de predika der nu intet mer af.
29 “‘Gé irun yín kí ẹ sì dàánù, pohùnréré ẹkún lórí òkè, nítorí Olúwa ti kọ ìran yìí tí ó wà lábẹ́ ìbínú rẹ̀ sílẹ̀.
Skär ditt hår af, och kasta det ifrå dig, och jämra dig klageliga på högomen; ty Herren hafver förkastat och bortdrifvit detta slägtet, der han öfver förtörnad är.
30 “‘Àwọn ènìyàn Juda ti ṣe búburú lójú mi, ni Olúwa wí. Wọ́n ti to àwọn ère ìríra wọn jọ sí ilé tí a fi orúkọ mi pè wọ́n sì ti sọ ọ́ di àìmọ́.
Förty Juda barn göra det ondt är för min ögon, säger Herren; de sätta sina styggelser uti det hus, som efter mitt Namn nämndt är, på det de skola orena det;
31 Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga ti Tofeti ní àfonífojì Beni-Hinnomu láti sun àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn nínú iná èyí tí èmi kò pàṣẹ tí kò sì wá sí ọkàn mi.
Och bygga de altare Thopheth uti Hinnoms sons dal, att de skola uppbränna deras söner och döttrar i eld, hvilket jag aldrig budit, eller någor tid i sinnet fått hafver.
32 Nítorí náà kíyèsára ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí, nígbà tí àwọn ènìyàn kò ní pè é ní Tafeti tàbí àfonífojì ti Beni-Hinnomu; ṣùgbọ́n yóò ma jẹ àfonífojì ìparun, nítorí wọn yóò sin òkú sí Tofeti títí kò fi ní sí ààyè mọ́.
Derföre, si, den tiden kommer, säger Herren, att man intet mer skall kalla det Thopheth, och Hinnoms sons dal, utan dråpodal; och Thopheth skall varda fullt med dödas grifter, derföre, att der intet annat rum på färde är.
33 Nígbà náà ni òkú àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀, kò sì ní sí ẹnìkan tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
Och detta folks kroppar skola himmelens foglom, och djuromen på jordene, till spis varda, och ingen skall drifva dem derifrå.
34 Èmi yóò mú òpin bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú àti ohùn àwọn tọkọtaya ní àwọn ìlú Juda àti ní ìgboro Jerusalẹmu, nítorí tí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
Och jag skall uti Juda städer, och på gatorna i Jerusalem, borttaga glädjes och fröjds rop, och brudgummes och bruds röst; ty landet skall öde vara.

< Jeremiah 7 >