< Jeremiah 7 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
Cuvântul care a venit la Ieremia de la DOMNUL, spunând:
2 “Dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yí: “‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ọ̀nà yí wọlé láti wá sin Olúwa.
Stai în picioare la poarta casei DOMNULUI și vestește acolo acest cuvânt și spune: Ascultați cuvântul DOMNULUI, voi toți cei din Iuda care intrați pe aceste porți pentru a vă închina DOMNULUI.
3 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Tún àwọn ọ̀nà yín ṣe, èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ gbé ilẹ̀ yìí.
Astfel spune DOMNUL oștirilor, Dumnezeul lui Israel: Îndreptați-vă căile și lucrările voastre și vă voi face să locuiți în acest loc.
4 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn gbọ́ kí ẹ sì wí pé, “Èyí ni tẹmpili Olúwa ilé tẹmpili Olúwa, ilé tẹmpili Olúwa!”
Nu vă încredeți în cuvinte mincinoase, spunând: Templul DOMNULUI, Templul DOMNULUI, Templul DOMNULUI sunt acestea.
5 Bí ẹ̀yin bá tún ọ̀nà yín àti iṣẹ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ sì ń bá ara yín lò ní ọ̀nà tó tọ́.
Căci dacă vă veți îndrepta în întregime căile și lucrările voastre, dacă veți face în întregime judecată între om și aproapele său;
6 Bí ẹ kò bá fi ara ni àwọn àlejò, àwọn ọmọ aláìní baba àti àwọn opó tí ẹ kò sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, bí ẹ kò bá sì tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn sí ìpalára ara yín.
Dacă nu veți oprima pe străin, pe cel fără tată și pe văduvă și nu veți vărsa sânge nevinovat în acest loc, nici nu veți umbla după alți dumnezei spre vătămarea voastră;
7 Nígbà náà ni èmi yóò jẹ́ kí ẹ gbé ìbí yìí, nílẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé.
Atunci vă voi face să locuiți în acest loc, în țara pe care am dat-o părinților voștri, pentru totdeauna și întotdeauna.
8 Ẹ wò ó, ẹ ń gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò níláárí gbọ́.
Iată, voi vă încredeți în cuvinte mincinoase, care nu sunt de folos.
9 “‘Ẹ̀yin yóò ha jalè, kí ẹ pànìyàn, kí ẹ ṣe panṣágà, kí ẹ búra èké, kí ẹ sun tùràrí sí Baali, kí ẹ sì tọ ọlọ́run mìíràn tí ẹ̀yin kò mọ̀ lọ?
Veți fura, veți ucide și veți comite adulter și veți jura fals și veți arde tămâie lui Baal și veți umbla după alți dumnezei pe care nu îi cunoașteți,
10 Nígbà náà ni kí ó wá dúró ní iwájú nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, “Kí ẹ wá wí pé àwa yè,” àwa yè láti ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra wọ̀nyí bí?
Și veți veni să stați în picioare înaintea mea în această casă, care este numită după numele meu și veți spune: Suntem eliberați! pentru a face toate aceste urâciuni?
11 Ṣé ilé yìí, tí a fi orúkọ mi pè ti di ihò àwọn ọlọ́ṣà lọ́dọ̀ yín ni? Èmi ti ń wò ó! ni Olúwa wí.
A devenit această casă, numită după numele meu, o peșteră de tâlhari în ochii voștri? Iată, chiar eu am văzut aceasta, spune DOMNUL.
12 “‘Ẹ lọ nísinsin yìí sí Ṣilo níbi ti mo kọ́ fi ṣe ibùgbé fún orúkọ mi, kí ẹ sì rí ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú Israẹli tí í ṣe ènìyàn mi.
Dar mergeți acum la locul meu care era în Șilo, unde mi-am pus numele la început, și vedeți ce i-am făcut din cauza stricăciunii poporului meu Israel.
13 Nígbà tí ẹ̀yin ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí ni èmi bá a yín sọ̀rọ̀ léraléra ni Olúwa wí ẹ̀yin kò gbọ́, èmi pè yín, ẹ̀yin kò dáhùn.
Și acum, pentru că ați făcut toate aceste lucrări, spune DOMNUL și v-am vorbit, ridicându-mă devreme și vorbind, dar nu ați ascultat, și v-am chemat, dar nu ați răspuns;
14 Nítorí náà, èmi yóò ṣe ohun tí mo ṣe sí Ṣilo sí ilé náà tí a fi orúkọ mi pè, ilé tẹmpili nínú èyí tí ẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ààyè tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba yín.
De aceea, voi face acestei case, care este numită după numele meu, în care vă încredeți, și locului pe care vi l-am dat vouă și părinților voștri, precum i-am făcut lui Șilo.
15 Èmi yóò tú kúrò ní iwájú mi gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí àwọn arákùnrin yín, àwọn ará Efraimu.’
Și vă voi alunga dinaintea feței mele, precum i-am alungat pe toți frații voștri, pe toată sămânța lui Efraim.
16 “Nítorí náà má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn; ma ṣe bẹ̀ mí, nítorí èmi kì yóò tẹ́tí sí ọ.
De aceea nu te ruga pentru acest popor, nici nu ridica strigăt nici rugăciune pentru ei, nici nu mijloci către mine: pentru că nu te voi asculta.
17 Ṣé ìwọ kò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
Nu vezi tu ce fac ei în cetățile lui Iuda și pe străzile Ierusalimului?
18 Àwọn ọmọ ṣa igi jọ, àwọn baba fi iná sí i, àwọn ìyá sì po ìyẹ̀fun láti ṣe àkàrà fún ayaba ọ̀run, wọ́n tú ẹbọ ọrẹ mímu sí àwọn ọlọ́run àjèjì láti ru bínú mi sókè.
Copiii adună lemne și părinții aprind focul și femeile își frământă aluatul, pentru a face turte împărătesei cerului și pentru a turna ofrande de băutură altor dumnezei, ca să mă mânie.
19 Ṣùgbọ́n ṣe èmi ni wọ́n fẹ́ mú bínú? ni Olúwa wí. Ǹjẹ́ kì í ṣe pé wọ́n kúkú ń pa ara wọn lára sí ìtìjú ara wọn?
Ei pe mine mă mânie? spune DOMNUL; nu se provoacă pe ei înșiși spre rușinea fețelor lor?
20 “‘Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò tú ìbínú àti ìrunú mi sí orílẹ̀ yìí ènìyàn àti ẹranko, igi, pápá àti èso orí ilẹ̀, yóò sì jó tí kò ní ṣe é pa.”
De aceea astfel spune DOMNUL Dumnezeu: Iată, mânia mea și furia mea vor fi turnate asupra acestui loc, asupra omului și asupra animalului și asupra copacilor câmpului și asupra rodului pământului; și va arde și nu se va stinge.
21 “‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Tẹ̀síwájú kí ẹ kó ẹbọ sísun yín àti àwọn ẹbọ yòókù papọ̀ kí ẹ̀yin kí ó sì jẹ ẹran wọ́n fúnra yín.
Astfel spune DOMNUL oștirilor, Dumnezeul lui Israel: Puneți ofrandele voastre la sacrificiile voastre și mâncați carne.
22 Ní tòsí nígbà tí mo mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti tí mo sì bá wọn sọ̀rọ̀. N kò pàṣẹ fún wọn lórí ẹbọ sísun lásán.
Pentru că nu referitor la ofrande arse sau la sacrificii am vorbit părinților voștri, sau le-am poruncit în ziua în care i‑am scos din țara Egiptului;
23 Mo pàṣẹ fún wọn báyìí pé; gbọ́ tèmi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi. Máa rìn ní ojú ọ̀nà tí mo pàṣẹ fún yín, kí ó lè dára fún yín.
Ci acest lucru le-am poruncit, spunând: Ascultați de vocea mea și eu voi fi Dumnezeul vostru și voi veți fi poporul meu; și să umblați în toate căile pe care vi le-am poruncit, ca să vă fie bine.
24 Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, wọn kò sì fetísílẹ̀ dípò èyí wọ́n ń tẹ̀ sí ọ̀nà agídí ọkàn wọn. Dípò kí wọn tẹ̀síwájú wọ́n ń rẹ̀yìn.
Dar ei nu au dat ascultare, nici nu și-au plecat urechea, ci au umblat în sfaturile și în închipuirea inimii lor rele; și au mers înapoi, nu înainte.
25 Láti ìgbà tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní Ejibiti títí di òní, ni èmi ti ń rán àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì sí yín.
Din ziua în care părinții voștri au ieșit din țara Egiptului până în această zi am trimis chiar pe toți servitorii mei profeții, zilnic ridicându-mă devreme și trimițându-i;
26 Wọn kò gbọ́ wọn kò sì fetísílẹ̀. Wọ́n wa ọrùn le, wọn wa ọrùn kì, wọ́n sì hu ìwà ìbàjẹ́ ju àwọn baba ńlá wọn.’
Totuși ei nu mi-au dat ascultare, nici nu și-au plecat urechea, ci și-au împietrit gâtul; ei au făcut mai rău decât părinții lor.
27 “Nígbà tí ìwọ bá sọ gbogbo èyí fún wọn, wọn kì yóò gbọ́ tirẹ̀, nígbà tí ìwọ bá sì pè wọ́n, wọn kì yóò dáhùn.
De aceea le vei vorbi toate aceste cuvinte iar ei nu îți vor da ascultare; de asemenea tu îi vei chema iar ei nu îți vor răspunde.
28 Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ tàbí kí ó ṣe ìgbọ́ràn sí ìbáwí. Ọ̀rọ̀ òtítọ́ kò sí ní ètè wọn.
Dar tu să le spui: Aceasta este o națiune care nu ascultă de vocea DOMNULUI Dumnezeului ei, nici nu primește corectare; adevărul a pierit și este stârpit din gura lor.
29 “‘Gé irun yín kí ẹ sì dàánù, pohùnréré ẹkún lórí òkè, nítorí Olúwa ti kọ ìran yìí tí ó wà lábẹ́ ìbínú rẹ̀ sílẹ̀.
Taie-ți părul, Ierusalime, și aruncă-l departe și înalță o plângere pe înălțimi, pentru că DOMNUL a respins și a părăsit generația furiei sale.
30 “‘Àwọn ènìyàn Juda ti ṣe búburú lójú mi, ni Olúwa wí. Wọ́n ti to àwọn ère ìríra wọn jọ sí ilé tí a fi orúkọ mi pè wọ́n sì ti sọ ọ́ di àìmọ́.
Deoarece copiii lui Iuda au făcut ce este rău înaintea feței mele, spune DOMNUL; și-au pus urâciunile lor în casa, numită după numele meu, pentru a o întina.
31 Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga ti Tofeti ní àfonífojì Beni-Hinnomu láti sun àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn nínú iná èyí tí èmi kò pàṣẹ tí kò sì wá sí ọkàn mi.
Și au zidit înălțimile Tofetului, care este valea fiului lui Hinom, pentru a-i arde pe fiii lor și pe fiicele lor în foc, ceea ce nu le-am poruncit, nici nu a ajuns la inima mea.
32 Nítorí náà kíyèsára ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí, nígbà tí àwọn ènìyàn kò ní pè é ní Tafeti tàbí àfonífojì ti Beni-Hinnomu; ṣùgbọ́n yóò ma jẹ àfonífojì ìparun, nítorí wọn yóò sin òkú sí Tofeti títí kò fi ní sí ààyè mọ́.
De aceea iată, vin zilele, spune DOMNUL, că nu va mai fi numit, Tofet, nici valea fiului lui Hinom, ci valea măcelului; fiindcă vor îngropa în Tofet până nu va mai fi loc.
33 Nígbà náà ni òkú àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀, kò sì ní sí ẹnìkan tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
Și trupurile moarte ale acestui popor vor fi hrană pentru păsările cerului și pentru fiarele pământului; și nimeni nu le va speria.
34 Èmi yóò mú òpin bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú àti ohùn àwọn tọkọtaya ní àwọn ìlú Juda àti ní ìgboro Jerusalẹmu, nítorí tí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
Atunci voi face să înceteze din cetățile lui Iuda și de pe străzile Ierusalimului vocea bucuriei și vocea veseliei, vocea mirelui și vocea miresei, pentru că țara va fi pustiită.

< Jeremiah 7 >