< Jeremiah 7 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
Tämä on sana, joka tuli Jeremialle Herralta:
2 “Dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yí: “‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ọ̀nà yí wọlé láti wá sin Olúwa.
"Asetu Herran huoneen portille ja julista siellä tämä sana ja sano: Kuulkaa Herran sana, koko Juuda, te jotka tulette näistä porteista kumartaen rukoilemaan Herraa.
3 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Tún àwọn ọ̀nà yín ṣe, èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ gbé ilẹ̀ yìí.
Näin sanoo Herra Sebaot, Israelin Jumala: Vaeltakaa hyvin ja tehkää hyviä tekoja, niin minä annan teidän asua tässä paikassa.
4 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn gbọ́ kí ẹ sì wí pé, “Èyí ni tẹmpili Olúwa ilé tẹmpili Olúwa, ilé tẹmpili Olúwa!”
Älkää luottako valheen sanoihin, kun sanotaan: 'Tämä on Herran temppeli, Herran temppeli, Herran temppeli!'
5 Bí ẹ̀yin bá tún ọ̀nà yín àti iṣẹ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ sì ń bá ara yín lò ní ọ̀nà tó tọ́.
Vaan jos te todella parannatte vaelluksenne ja tekonne, jos te todella teette oikeuden niin toiselle kuin toisellekin,
6 Bí ẹ kò bá fi ara ni àwọn àlejò, àwọn ọmọ aláìní baba àti àwọn opó tí ẹ kò sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, bí ẹ kò bá sì tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn sí ìpalára ara yín.
ette sorra muukalaista, orpoa ja leskeä, ette vuodata viatonta verta tässä paikassa ettekä seuraa muita jumalia turmioksenne,
7 Nígbà náà ni èmi yóò jẹ́ kí ẹ gbé ìbí yìí, nílẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé.
niin minä annan teidän asua tässä paikassa, maassa, jonka minä olen antanut teidän isillenne, iankaikkisesta iankaikkiseen.
8 Ẹ wò ó, ẹ ń gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò níláárí gbọ́.
Mutta katso, te luotatte valheen sanoihin, joista ei ole hyötyä.
9 “‘Ẹ̀yin yóò ha jalè, kí ẹ pànìyàn, kí ẹ ṣe panṣágà, kí ẹ búra èké, kí ẹ sun tùràrí sí Baali, kí ẹ sì tọ ọlọ́run mìíràn tí ẹ̀yin kò mọ̀ lọ?
Miten on? Te varastatte, tapatte, rikotte avion, vannotte väärin, poltatte uhreja Baalille ja seuraatte vieraita jumalia, joita te ette tunne.
10 Nígbà náà ni kí ó wá dúró ní iwájú nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, “Kí ẹ wá wí pé àwa yè,” àwa yè láti ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra wọ̀nyí bí?
Ja te tulette ja astutte minun eteeni tähän huoneeseen, joka on otettu minun nimiini, ja sanotte: 'Me kyllä pelastumme' -tehdäksenne yhä kaikkia näitä kauhistuksia!
11 Ṣé ilé yìí, tí a fi orúkọ mi pè ti di ihò àwọn ọlọ́ṣà lọ́dọ̀ yín ni? Èmi ti ń wò ó! ni Olúwa wí.
Ryövärien luolaksiko te katsotte tämän huoneen, joka on otettu minun nimiini? Katso, sellaiseksi minäkin olen sen havainnut, sanoo Herra.
12 “‘Ẹ lọ nísinsin yìí sí Ṣilo níbi ti mo kọ́ fi ṣe ibùgbé fún orúkọ mi, kí ẹ sì rí ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú Israẹli tí í ṣe ènìyàn mi.
Menkääpä minun asuinpaikkaani, joka oli Siilossa, jossa minä ensin annoin nimeni asua, ja katsokaa, mitä minä olen sille tehnyt kansani Israelin pahuuden tähden!
13 Nígbà tí ẹ̀yin ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí ni èmi bá a yín sọ̀rọ̀ léraléra ni Olúwa wí ẹ̀yin kò gbọ́, èmi pè yín, ẹ̀yin kò dáhùn.
Ja koska te nyt olette kaikkia näitä tekoja tehneet, sanoo Herra, ettekä ole kuulleet, vaikka minä varhaisesta alkaen olen teille puhunut, koska ette vastanneet, vaikka minä teille huusin,
14 Nítorí náà, èmi yóò ṣe ohun tí mo ṣe sí Ṣilo sí ilé náà tí a fi orúkọ mi pè, ilé tẹmpili nínú èyí tí ẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ààyè tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba yín.
niin minä teen tälle huoneelle, joka on otettu minun nimiini, johon te luotatte, ja tälle paikalle, jonka minä olen antanut teille ja teidän isillenne, samoin kuin olen tehnyt Siilolle,
15 Èmi yóò tú kúrò ní iwájú mi gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí àwọn arákùnrin yín, àwọn ará Efraimu.’
ja heitän teidät pois kasvojeni edestä, niinkuin olen heittänyt pois kaikki teidän veljenne, kaikki Efraimin jälkeläiset.
16 “Nítorí náà má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn; ma ṣe bẹ̀ mí, nítorí èmi kì yóò tẹ́tí sí ọ.
Mutta sinä älä rukoile tämän kansan puolesta, älä kohota heidän puolestaan huutoa ja rukousta äläkä niillä minua ahdista; sillä en minä sinua kuule.
17 Ṣé ìwọ kò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
Etkö näe, mitä he tekevät Juudan kaupungeissa ja Jerusalemin kaduilla?
18 Àwọn ọmọ ṣa igi jọ, àwọn baba fi iná sí i, àwọn ìyá sì po ìyẹ̀fun láti ṣe àkàrà fún ayaba ọ̀run, wọ́n tú ẹbọ ọrẹ mímu sí àwọn ọlọ́run àjèjì láti ru bínú mi sókè.
Lapset kokoavat puita, isät sytyttävät tulen, ja vaimot sotkevat taikinaa valmistaaksensa uhrikakkuja taivaan kuningattarelle, ja he vuodattavat juomauhreja muille jumalille, minulle mielikarvaudeksi.
19 Ṣùgbọ́n ṣe èmi ni wọ́n fẹ́ mú bínú? ni Olúwa wí. Ǹjẹ́ kì í ṣe pé wọ́n kúkú ń pa ara wọn lára sí ìtìjú ara wọn?
Minulleko he tuottavat mielikarvautta, sanoo Herra, eivätkö pikemmin itselleen, omaksi häpeäksensä?
20 “‘Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò tú ìbínú àti ìrunú mi sí orílẹ̀ yìí ènìyàn àti ẹranko, igi, pápá àti èso orí ilẹ̀, yóò sì jó tí kò ní ṣe é pa.”
Sentähden, näin sanoo Herra, Herra: Katso, minun vihani ja kiivauteni on vuotava tämän paikan ylitse, ihmisten, eläinten, kedon puitten ja maan hedelmän ylitse, ja se palaa sammumatta."
21 “‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Tẹ̀síwájú kí ẹ kó ẹbọ sísun yín àti àwọn ẹbọ yòókù papọ̀ kí ẹ̀yin kí ó sì jẹ ẹran wọ́n fúnra yín.
Näin sanoo Herra Sebaot, Israelin Jumala: "Lisätkää polttouhrinne teurasuhreihinne ja syökää lihaa.
22 Ní tòsí nígbà tí mo mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti tí mo sì bá wọn sọ̀rọ̀. N kò pàṣẹ fún wọn lórí ẹbọ sísun lásán.
Sillä en minä puhunut enkä antanut käskyä teidän isillenne poltto-ja teurasuhrista silloin, kun minä vein heidät pois Egyptin maasta,
23 Mo pàṣẹ fún wọn báyìí pé; gbọ́ tèmi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi. Máa rìn ní ojú ọ̀nà tí mo pàṣẹ fún yín, kí ó lè dára fún yín.
vaan näin minä käskin heitä ja sanoin: Kuulkaa minun ääntäni, niin minä olen teidän Jumalanne ja te olette minun kansani; ja vaeltakaa aina sitä tietä, jota minä käsken teidän vaeltaa, että menestyisitte.
24 Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, wọn kò sì fetísílẹ̀ dípò èyí wọ́n ń tẹ̀ sí ọ̀nà agídí ọkàn wọn. Dípò kí wọn tẹ̀síwájú wọ́n ń rẹ̀yìn.
Mutta he eivät kuulleet, eivät korvaansa kallistaneet, vaan vaelsivat oman neuvonsa mukaan, pahan sydämensä paatumuksessa, ja käänsivät minulle selkänsä eivätkä kasvojansa.
25 Láti ìgbà tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní Ejibiti títí di òní, ni èmi ti ń rán àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì sí yín.
Siitä päivästä, jona teidän isänne lähtivät Egyptin maasta, aina tähän päivään asti olen minä lähettänyt teidän tykönne kaikki palvelijani, profeetat-lähettänyt varhaisesta alkaen, päivä päivältä.
26 Wọn kò gbọ́ wọn kò sì fetísílẹ̀. Wọ́n wa ọrùn le, wọn wa ọrùn kì, wọ́n sì hu ìwà ìbàjẹ́ ju àwọn baba ńlá wọn.’
Mutta kukaan ei kuullut minua, ei kallistanut korvaansa, vaan he olivat niskureita, tekivät enemmän pahaa kuin heidän isänsä.
27 “Nígbà tí ìwọ bá sọ gbogbo èyí fún wọn, wọn kì yóò gbọ́ tirẹ̀, nígbà tí ìwọ bá sì pè wọ́n, wọn kì yóò dáhùn.
Ja kun sinä puhut heille kaiken tämän, niin he eivät kuule sinua, ja kun sinä heille huudat, niin he eivät sinulle vastaa.
28 Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ tàbí kí ó ṣe ìgbọ́ràn sí ìbáwí. Ọ̀rọ̀ òtítọ́ kò sí ní ètè wọn.
Sentähden sano heille: Tämä on kansa, joka ei kuullut Herran, Jumalansa, ääntä eikä ottanut kuritusta varteen. Kadonnut on totuus ja hävinnyt heidän suustansa.
29 “‘Gé irun yín kí ẹ sì dàánù, pohùnréré ẹkún lórí òkè, nítorí Olúwa ti kọ ìran yìí tí ó wà lábẹ́ ìbínú rẹ̀ sílẹ̀.
Leikkaa hiuksesi ja heitä ne pois ja viritä kalliokukkuloilla itkuvirsi, sillä Herra on hyljännyt ja sysännyt pois vihansa alaisen sukupolven.
30 “‘Àwọn ènìyàn Juda ti ṣe búburú lójú mi, ni Olúwa wí. Wọ́n ti to àwọn ère ìríra wọn jọ sí ilé tí a fi orúkọ mi pè wọ́n sì ti sọ ọ́ di àìmọ́.
Sillä Juudan miehet ovat tehneet sen, mikä on pahaa minun silmissäni, sanoo Herra. He ovat asettaneet iljetyksensä temppeliin, joka on otettu minun nimiini, ja saastuttaneet sen.
31 Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga ti Tofeti ní àfonífojì Beni-Hinnomu láti sun àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn nínú iná èyí tí èmi kò pàṣẹ tí kò sì wá sí ọkàn mi.
Ja he ovat rakentaneet Toofet-uhrikukkulat Ben-Hinnomin laaksoon, polttaakseen tulessa poikiansa ja tyttäriänsä, mitä minä en ole käskenyt ja mikä ei ole minun mieleeni tullut.
32 Nítorí náà kíyèsára ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí, nígbà tí àwọn ènìyàn kò ní pè é ní Tafeti tàbí àfonífojì ti Beni-Hinnomu; ṣùgbọ́n yóò ma jẹ àfonífojì ìparun, nítorí wọn yóò sin òkú sí Tofeti títí kò fi ní sí ààyè mọ́.
Sentähden, katso, päivät tulevat, sanoo Herra, jolloin ei enää sanota 'Toofet' ja 'Ben-Hinnomin laakso', vaan 'Murha-laakso', ja Toofetiin haudataan, kun ei ole muualla tilaa.
33 Nígbà náà ni òkú àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀, kò sì ní sí ẹnìkan tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
Ja tämän kansan ruumiit joutuvat taivaan lintujen ja maan eläinten ruuaksi, eikä näitä kukaan karkoita.
34 Èmi yóò mú òpin bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú àti ohùn àwọn tọkọtaya ní àwọn ìlú Juda àti ní ìgboro Jerusalẹmu, nítorí tí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
Ja minä lopetan Juudan kaupungeista ja Jerusalemin kaduilta riemun ja ilon huudon, huudon yljälle ja huudon morsiamelle, sillä maa on tuleva raunioiksi."

< Jeremiah 7 >