< Jeremiah 7 >
1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
Det Ord, som kom fra Herren til Jeremias, der han sagde:
2 “Dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yí: “‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ọ̀nà yí wọlé láti wá sin Olúwa.
Stil dig i Herrens Hus's Port, og du skal udraabe der dette Ord og sige: Hører Herrens Ord, alle I af Juda! I, som gaa ind ad disse Porte, for at tilbede Herren!
3 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Tún àwọn ọ̀nà yín ṣe, èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ gbé ilẹ̀ yìí.
Saa siger den Herre Zebaoth, Israels Gud: Bedrer eders Veje og eders Idrætter, saa vil jeg lade eder bo paa dette Sted.
4 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn gbọ́ kí ẹ sì wí pé, “Èyí ni tẹmpili Olúwa ilé tẹmpili Olúwa, ilé tẹmpili Olúwa!”
Forlader eder ikke paa løgnagtige Ord, naar de sige: Herrens Tempel, Herrens Tempel, Herrens Tempel er her!
5 Bí ẹ̀yin bá tún ọ̀nà yín àti iṣẹ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ sì ń bá ara yín lò ní ọ̀nà tó tọ́.
Men dersom I alvorligt bedre eders Veje og eders Idrætter, og dersom I gøre Ret imellem Mand og hans Næste,
6 Bí ẹ kò bá fi ara ni àwọn àlejò, àwọn ọmọ aláìní baba àti àwọn opó tí ẹ kò sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, bí ẹ kò bá sì tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn sí ìpalára ara yín.
og I ej gøre den fremmede, den faderløse og Enken Vold og ej udøse uskyldigt Blod paa dette Sted og ej vandre efter andre Guder, eder til Ulykke:
7 Nígbà náà ni èmi yóò jẹ́ kí ẹ gbé ìbí yìí, nílẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé.
Da vil jeg lade eder bo paa dette Sted, i Landet, som jeg gav eders Fædre, altid og evindelig.
8 Ẹ wò ó, ẹ ń gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò níláárí gbọ́.
Se, I forlade eder paa løgnagtige Ord, som intet gavne.
9 “‘Ẹ̀yin yóò ha jalè, kí ẹ pànìyàn, kí ẹ ṣe panṣágà, kí ẹ búra èké, kí ẹ sun tùràrí sí Baali, kí ẹ sì tọ ọlọ́run mìíràn tí ẹ̀yin kò mọ̀ lọ?
Skulde I stjæle, slaa ihjel og bedrive Hor og sværge falskelig og gøre Røgelse for Baal og vandre efter fremmede Guder, som I ikke kende,
10 Nígbà náà ni kí ó wá dúró ní iwájú nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, “Kí ẹ wá wí pé àwa yè,” àwa yè láti ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra wọ̀nyí bí?
og saa komme og staa for mit Ansigt i dette Hus, som er kaldet efter mit Navn, og sige: Vi ere frelste for at kunne gøre alle disse Vederstyggeligheder?
11 Ṣé ilé yìí, tí a fi orúkọ mi pè ti di ihò àwọn ọlọ́ṣà lọ́dọ̀ yín ni? Èmi ti ń wò ó! ni Olúwa wí.
Mon dette Hus, som er kaldet efter mit Navn, i eders Øjne er blevet en Røverhule? ja, jeg, se, jeg har set det, siger Herren.
12 “‘Ẹ lọ nísinsin yìí sí Ṣilo níbi ti mo kọ́ fi ṣe ibùgbé fún orúkọ mi, kí ẹ sì rí ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú Israẹli tí í ṣe ènìyàn mi.
Thi gaar dog til mit Sted, som var i Silo, hvor jeg lod mit Navn bo i Begyndelsen, og ser, hvad jeg har gjort ved det for mit Folk Israels Ondskabs Skyld.
13 Nígbà tí ẹ̀yin ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí ni èmi bá a yín sọ̀rọ̀ léraléra ni Olúwa wí ẹ̀yin kò gbọ́, èmi pè yín, ẹ̀yin kò dáhùn.
Og nu, fordi I gøre alle disse Gerninger, siger Herren, og jeg talte til eder tidligt og ideligt, og I hørte ikke, og jeg kaldte ad eder, og I svarede ikke:
14 Nítorí náà, èmi yóò ṣe ohun tí mo ṣe sí Ṣilo sí ilé náà tí a fi orúkọ mi pè, ilé tẹmpili nínú èyí tí ẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ààyè tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba yín.
Saa vil jeg gøre ved dette Hus, som er kaldet efter mit Navn, og paa hvilket I forlade eder, og ved det Sted, som jeg gav eder og eders Fædre, ligesom jeg har gjort ved Silo.
15 Èmi yóò tú kúrò ní iwájú mi gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí àwọn arákùnrin yín, àwọn ará Efraimu.’
Og jeg vil bortkaste eder fra mit Ansigt, ligesom jeg bortkastede alle eders Brødre, Efraims hele Sæd.
16 “Nítorí náà má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn; ma ṣe bẹ̀ mí, nítorí èmi kì yóò tẹ́tí sí ọ.
Og du, du maa ikke bede for dette Folk og ikke opløfte Skrig eller Bøn for dem og ikke trænge ind paa mig med Forbøn; thi jeg hører dig ikke.
17 Ṣé ìwọ kò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
Ser du ikke, hvad de gøre i Judas Stæder og paa Jerusalems Gader?
18 Àwọn ọmọ ṣa igi jọ, àwọn baba fi iná sí i, àwọn ìyá sì po ìyẹ̀fun láti ṣe àkàrà fún ayaba ọ̀run, wọ́n tú ẹbọ ọrẹ mímu sí àwọn ọlọ́run àjèjì láti ru bínú mi sókè.
Børnene sanke Træ og Fædrene tænde Ilden, og Kvinderne ælte Dejg for at lave Kager til Himmelens Dronning, og de udøse Drikoffer for andre Guder for at gøre mig Fortræd.
19 Ṣùgbọ́n ṣe èmi ni wọ́n fẹ́ mú bínú? ni Olúwa wí. Ǹjẹ́ kì í ṣe pé wọ́n kúkú ń pa ara wọn lára sí ìtìjú ara wọn?
Monne de gøre mig Fortræd dermed? siger Herren; monne de ikke gøre sig selv Fortræd, til deres Ansigters Bluelse?
20 “‘Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò tú ìbínú àti ìrunú mi sí orílẹ̀ yìí ènìyàn àti ẹranko, igi, pápá àti èso orí ilẹ̀, yóò sì jó tí kò ní ṣe é pa.”
Derfor siger den Herre, Herre saaledes: Se, min Vrede og min Harme er udøst over dette Sted, over Mennesker og over Dyr og over Træer paa Marken og over Landets Frugt; og den skal brænde og ikke udslukkes.
21 “‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Tẹ̀síwájú kí ẹ kó ẹbọ sísun yín àti àwọn ẹbọ yòókù papọ̀ kí ẹ̀yin kí ó sì jẹ ẹran wọ́n fúnra yín.
Saa siger den Herre Zebaoth, Israels Gud: Lægger eders Brændofre til eders Slagtofre, og æder Kødet!
22 Ní tòsí nígbà tí mo mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti tí mo sì bá wọn sọ̀rọ̀. N kò pàṣẹ fún wọn lórí ẹbọ sísun lásán.
Thi jeg har ikke talt med eders Fædre, ej heller befalet dem paa den Dag, jeg udførte dem af Ægyptens Land, angaaende Brændoffer og Slagtoffer.
23 Mo pàṣẹ fún wọn báyìí pé; gbọ́ tèmi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi. Máa rìn ní ojú ọ̀nà tí mo pàṣẹ fún yín, kí ó lè dára fún yín.
Men denne Ting har jeg befalet dem og sagt: Hører paa min Røst, saa vil jeg være eders Gud, og I skulle være mit Folk; og I skulle vandre paa hver en Vej, som jeg befaler eder, at det maa gaa eder vel.
24 Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, wọn kò sì fetísílẹ̀ dípò èyí wọ́n ń tẹ̀ sí ọ̀nà agídí ọkàn wọn. Dípò kí wọn tẹ̀síwájú wọ́n ń rẹ̀yìn.
Men de hørte ikke og bøjede ikke deres Øre, men de vandrede i deres Raad, i deres onde Hjertes Stivhed; og de gik tilbage og ikke fremad.
25 Láti ìgbà tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní Ejibiti títí di òní, ni èmi ti ń rán àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì sí yín.
Fra den Dag, der eders Fædre udgik af Ægyptens Land, indtil denne Dag sendte jeg til eder alle mine Tjenere, Profeterne, dagligt, tidligt og ideligt.
26 Wọn kò gbọ́ wọn kò sì fetísílẹ̀. Wọ́n wa ọrùn le, wọn wa ọrùn kì, wọ́n sì hu ìwà ìbàjẹ́ ju àwọn baba ńlá wọn.’
Men de hørte mig ikke og bøjede ikke deres Øre; men de forhærdede deres Nakke; de gjorde det værre end deres Fædre.
27 “Nígbà tí ìwọ bá sọ gbogbo èyí fún wọn, wọn kì yóò gbọ́ tirẹ̀, nígbà tí ìwọ bá sì pè wọ́n, wọn kì yóò dáhùn.
Og du skal tale til dem alle disse Ord, men de skulle ikke høre dig; og du skal kalde ad dem, men de skulle ikke svare dig.
28 Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ tàbí kí ó ṣe ìgbọ́ràn sí ìbáwí. Ọ̀rọ̀ òtítọ́ kò sí ní ètè wọn.
Og du skal sige til dem: Dette er det Folk, som ikke hører paa Herrens, deres Guds Røst og ej annammer Tugt; Troskaben er gaaet til Grunde og forsvunden af deres Mund.
29 “‘Gé irun yín kí ẹ sì dàánù, pohùnréré ẹkún lórí òkè, nítorí Olúwa ti kọ ìran yìí tí ó wà lábẹ́ ìbínú rẹ̀ sílẹ̀.
Afklip din Haarprydelse og kast den bort, og opløft et Klagemaal paa de nøgne Høje; thi Herren har forkastet og forladt den Slægt, som hans Fortørnelse er imod.
30 “‘Àwọn ènìyàn Juda ti ṣe búburú lójú mi, ni Olúwa wí. Wọ́n ti to àwọn ère ìríra wọn jọ sí ilé tí a fi orúkọ mi pè wọ́n sì ti sọ ọ́ di àìmọ́.
Thi Judas Børn have gjort det, som er ondt for mine Øjne, siger Herren; de have sat deres Vederstyggeligheder i det Hus, som er kaldet efter mit Navn, til at besmitte det.
31 Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga ti Tofeti ní àfonífojì Beni-Hinnomu láti sun àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn nínú iná èyí tí èmi kò pàṣẹ tí kò sì wá sí ọkàn mi.
Og de have bygget Tofeths Høje, som ere i Ben-Hinnoms Dal, for at opbrænde deres Sønner og Døtre i Ilden, hvilket jeg ikke har budet, og hvad ej heller er kommet mig i Tanke.
32 Nítorí náà kíyèsára ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí, nígbà tí àwọn ènìyàn kò ní pè é ní Tafeti tàbí àfonífojì ti Beni-Hinnomu; ṣùgbọ́n yóò ma jẹ àfonífojì ìparun, nítorí wọn yóò sin òkú sí Tofeti títí kò fi ní sí ààyè mọ́.
Derfor se, de Dage komme, siger Herren, at man ikke skal kalde det mere Tofeth og Ben-Hinnoms Dal, men Morderdal; og de skulle begrave i Tofeth af Mangel paa Plads.
33 Nígbà náà ni òkú àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀, kò sì ní sí ẹnìkan tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
Og dette Folks døde Kroppe skulle være til Føde for Himmelens Fugle og Dyrene paa Jorden, og der skal ingen skræmme dem bort.
34 Èmi yóò mú òpin bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú àti ohùn àwọn tọkọtaya ní àwọn ìlú Juda àti ní ìgboro Jerusalẹmu, nítorí tí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
Og jeg vil lade Fryds Røst og Glædes Røst, Brudgoms Røst og Bruds Røst ophøre fra Judas Stæder og fra Gaderne i Jerusalem; thi Landet skal være øde.