< Jeremiah 7 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
Словото, което дойде към Еремия от Господа, казвайки:
2 “Dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yí: “‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ọ̀nà yí wọlé láti wá sin Olúwa.
Застани в портата на дома Господен, Та възгласи там това слово, като кажеш: Слушайте словото Господно, всички юдейци, Които влизате през тези порти, за да се поклоните Господу.
3 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Tún àwọn ọ̀nà yín ṣe, èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ gbé ilẹ̀ yìí.
Така казва Господ на Силите, Израилевият Бог: Поправете пътищата си и делата си, И Аз ще ви утвърдя на това място.
4 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn gbọ́ kí ẹ sì wí pé, “Èyí ni tẹmpili Olúwa ilé tẹmpili Olúwa, ilé tẹmpili Olúwa!”
Не уповавайте на лъжливи думи, та да казвате: Храмът Господен, храмът Господен, Храмът Господен е това.
5 Bí ẹ̀yin bá tún ọ̀nà yín àti iṣẹ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ sì ń bá ara yín lò ní ọ̀nà tó tọ́.
Защото ако наистина поправите пътищата си и делата си; Ако съдите съвършено право между човека и ближния му;
6 Bí ẹ kò bá fi ara ni àwọn àlejò, àwọn ọmọ aláìní baba àti àwọn opó tí ẹ kò sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, bí ẹ kò bá sì tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn sí ìpalára ara yín.
Ако не угнетявате чужденеца, сирачето и вдовицата, И не проливате невинна кръв на това място, Нито следвате чужди богове за ваша повреда;
7 Nígbà náà ni èmi yóò jẹ́ kí ẹ gbé ìbí yìí, nílẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé.
Тогава ще ви направя да живеете на това място, В земята, която дадох на бащите от века и до века.
8 Ẹ wò ó, ẹ ń gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò níláárí gbọ́.
Ето, вие уповавате на лъжливи думи, От които няма да се ползувате.
9 “‘Ẹ̀yin yóò ha jalè, kí ẹ pànìyàn, kí ẹ ṣe panṣágà, kí ẹ búra èké, kí ẹ sun tùràrí sí Baali, kí ẹ sì tọ ọlọ́run mìíràn tí ẹ̀yin kò mọ̀ lọ?
Като крадете, убивате, прелюбодействувате, И се кълнете лъжливо, и кадите на Ваала, И следвате други богове, които не сте познавали
10 Nígbà náà ni kí ó wá dúró ní iwájú nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, “Kí ẹ wá wí pé àwa yè,” àwa yè láti ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra wọ̀nyí bí?
Дохождате ли после да стоите пред мене в тоя дом, Който се нарича с Моето име, И да казвате - Отървахме се, - за да вършите всички тия мерзости?
11 Ṣé ilé yìí, tí a fi orúkọ mi pè ti di ihò àwọn ọlọ́ṣà lọ́dọ̀ yín ni? Èmi ti ń wò ó! ni Olúwa wí.
Тоя дом, който се нарича с Моето име, Вертеп ли за разбойници стана във вашите очи? Ето, сам Аз видях това, казва Господ.
12 “‘Ẹ lọ nísinsin yìí sí Ṣilo níbi ti mo kọ́ fi ṣe ibùgbé fún orúkọ mi, kí ẹ sì rí ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú Israẹli tí í ṣe ènìyàn mi.
Но идете сега на мястото Ми, което бе в Сило, Гдето в начало настаних името си, Та вижте що му сторих Поради злодеянието на людете Си Израиля.
13 Nígbà tí ẹ̀yin ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí ni èmi bá a yín sọ̀rọ̀ léraléra ni Olúwa wí ẹ̀yin kò gbọ́, èmi pè yín, ẹ̀yin kò dáhùn.
И сега понеже извършихте всички тия дела, казва Господ, И Аз ви говорих, като ставах рано и говорех, а вие не послушахте, И ви виках, но не отговорихте;
14 Nítorí náà, èmi yóò ṣe ohun tí mo ṣe sí Ṣilo sí ilé náà tí a fi orúkọ mi pè, ilé tẹmpili nínú èyí tí ẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ààyè tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba yín.
Затова, ще направя на дома, който се нарича с Моето име, На който вие уповавате, И на мястото, което дадох вам и на бащите ви, Както направих на Сило.
15 Èmi yóò tú kúrò ní iwájú mi gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí àwọn arákùnrin yín, àwọn ará Efraimu.’
И ще ви отхвърля от лицето Си Както отхвърлих всичките ви братя, Цялото Ефремово потомство.
16 “Nítorí náà má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn; ma ṣe bẹ̀ mí, nítorí èmi kì yóò tẹ́tí sí ọ.
Затова, ти недей се моли за тия люде, И не възнасяй вик или молба за тях, Нито ходатайствувай пред мене; Защото няма да те послушам.
17 Ṣé ìwọ kò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
Не видиш ли що вършат те в Юдовите градове И по ерусалимските улици?
18 Àwọn ọmọ ṣa igi jọ, àwọn baba fi iná sí i, àwọn ìyá sì po ìyẹ̀fun láti ṣe àkàrà fún ayaba ọ̀run, wọ́n tú ẹbọ ọrẹ mímu sí àwọn ọlọ́run àjèjì láti ru bínú mi sókè.
Чадата събират дърва, и бащите кладат огъня, А жените месят тестото, За да направят пити на небесната царица, И да направят възлияния на други богове, Та да Ме разгневят.
19 Ṣùgbọ́n ṣe èmi ni wọ́n fẹ́ mú bínú? ni Olúwa wí. Ǹjẹ́ kì í ṣe pé wọ́n kúkú ń pa ara wọn lára sí ìtìjú ara wọn?
Но Мене ли разгневяват? казва Господ, - Дали не себе си разгневяват за посрамяване на своите лица?
20 “‘Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò tú ìbínú àti ìrunú mi sí orílẹ̀ yìí ènìyàn àti ẹranko, igi, pápá àti èso orí ilẹ̀, yóò sì jó tí kò ní ṣe é pa.”
Затова, така казва Господ Иеова: Ето, гневът Ми и яростта Ми ще се излеят на това място, На човек, и на животно, На полските дървета, и на земния плод; И ще пламне, и няма да угасне.
21 “‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Tẹ̀síwájú kí ẹ kó ẹbọ sísun yín àti àwọn ẹbọ yòókù papọ̀ kí ẹ̀yin kí ó sì jẹ ẹran wọ́n fúnra yín.
Така казва Господ на Силите, Израилевият Бог: Притурете всеизгарянията си на жертвите си, И яжте месото и от тях.
22 Ní tòsí nígbà tí mo mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti tí mo sì bá wọn sọ̀rọ̀. N kò pàṣẹ fún wọn lórí ẹbọ sísun lásán.
Защото не говорих на бащите ви, нито им дадох заповеди, За всеизгаряния и жертви В денят, когато ги изведох из Египетската земя;
23 Mo pàṣẹ fún wọn báyìí pé; gbọ́ tèmi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi. Máa rìn ní ojú ọ̀nà tí mo pàṣẹ fún yín, kí ó lè dára fún yín.
Но това им заповядах, като рекох: Слушайте гласа Ми, И Аз ще ви бъде Бог, И вие ще Ми бъдете люде! И ходете по всичките пътища, които ви заповядвам, За да благоденствувате.
24 Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, wọn kò sì fetísílẹ̀ dípò èyí wọ́n ń tẹ̀ sí ọ̀nà agídí ọkàn wọn. Dípò kí wọn tẹ̀síwájú wọ́n ń rẹ̀yìn.
Те, обаче, не послушаха нито преклониха ухото си, Но ходиха по намеренията и по упоритостта на своето нечестиво сърце, И отидоха назад, а не напред.
25 Láti ìgbà tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní Ejibiti títí di òní, ni èmi ti ń rán àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì sí yín.
От деня, когато излязоха бащите ви из Египетската земя, до днес Пращах всичките Си слуги пророците при вас, Като ставах рано всеки ден и ги пращах;
26 Wọn kò gbọ́ wọn kò sì fetísílẹ̀. Wọ́n wa ọrùn le, wọn wa ọrùn kì, wọ́n sì hu ìwà ìbàjẹ́ ju àwọn baba ńlá wọn.’
Те обаче не Ме послушаха, нито преклониха ухото си, Но закоравиха врата си; Постъпиха по-зле от бащите си.
27 “Nígbà tí ìwọ bá sọ gbogbo èyí fún wọn, wọn kì yóò gbọ́ tirẹ̀, nígbà tí ìwọ bá sì pè wọ́n, wọn kì yóò dáhùn.
Затова, говори им всички тия думи, Но те няма да те послушат; Тоже извикай към тях, Но те не ще ти отговорят.
28 Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ tàbí kí ó ṣe ìgbọ́ràn sí ìbáwí. Ọ̀rọ̀ òtítọ́ kò sí ní ètè wọn.
Тогава им кажи: Тоя е народът, който не слуша гласа на Господа своя Бог, Нито приема наставления; Честността изчезна и се изгуби от устата им.
29 “‘Gé irun yín kí ẹ sì dàánù, pohùnréré ẹkún lórí òkè, nítorí Olúwa ti kọ ìran yìí tí ó wà lábẹ́ ìbínú rẹ̀ sílẹ̀.
Острижи косата си, дъщерьо ерусалимска, и хвърли я, И плачи със силен глас по голите височини; Защото Господ отхвърли и остави поколението, на което се разгневи.
30 “‘Àwọn ènìyàn Juda ti ṣe búburú lójú mi, ni Olúwa wí. Wọ́n ti to àwọn ère ìríra wọn jọ sí ilé tí a fi orúkọ mi pè wọ́n sì ti sọ ọ́ di àìmọ́.
Защото Юдейците сториха това, което бе зло пред Мене, казва Господ; Поставиха мерзостите си в дома, Който се нарича с Моето име, та го оскверниха.
31 Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga ti Tofeti ní àfonífojì Beni-Hinnomu láti sun àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn nínú iná èyí tí èmi kò pàṣẹ tí kò sì wá sí ọkàn mi.
И издигнаха високите места на Тофет, Който е в долината на Еномовия син, За да горят синовете си и дъщерите си в огън, - Нещо, което не съм заповядал, нито ми е дохождало на ум.
32 Nítorí náà kíyèsára ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí, nígbà tí àwọn ènìyàn kò ní pè é ní Tafeti tàbí àfonífojì ti Beni-Hinnomu; ṣùgbọ́n yóò ma jẹ àfonífojì ìparun, nítorí wọn yóò sin òkú sí Tofeti títí kò fi ní sí ààyè mọ́.
Затова, ето, идат дни, казва Господ, Когато няма да се нарича вече Тофет, Нито долина на Еномовия син, Но долина на клането; Защото ще погребват в Тофет, понеже не ще остане място другаде;
33 Nígbà náà ni òkú àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀, kò sì ní sí ẹnìkan tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
И труповете на тия люде ще бъдат Храна на небесните птици и на земните зверове; И не ще има кой да ги плаши.
34 Èmi yóò mú òpin bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú àti ohùn àwọn tọkọtaya ní àwọn ìlú Juda àti ní ìgboro Jerusalẹmu, nítorí tí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
Тогава ще направя да престане в Юдовите градове И по Ерусалимските улици Гласът на радостта и гласът на веселието, Гласът на младоженеца и гласът на невястата; Защото земята ще запустее.

< Jeremiah 7 >