< Jeremiah 6 >

1 “Ẹ̀yin ènìyàn Benjamini, sá sí ibi ààbò! Ẹ sá kúrò ní Jerusalẹmu. Ẹ fọn fèrè ní Tekoa! Kí ẹ gbé àmì sókè lórí Beti-Hakeremu! Nítorí àjálù farahàn láti àríwá, àní ìparun tí ó lágbára.
Voi copii ai lui Beniamin, adunați-vă pentru a fugi din mijlocul Ierusalimului și sunați trâmbița în Tecoa și înălțați un semn de foc în Bet-Hacherem, pentru că din nord apare răul și o mare nimicire.
2 Èmi yóò pa ọmọbìnrin Sioni run, tí ó jẹ́ arẹwà àti ẹlẹgẹ́.
Am asemănat pe fiica Sionului cu o femeie frumoasă și delicată.
3 Olùṣọ́-àgùntàn pẹ̀lú agbo wọn yóò gbóguntì wọ́n. Wọn yóò pa àgọ́ yí wọn ká, olúkúlùkù yóò máa jẹ ní ilé rẹ̀.”
Păstorii cu turmele lor vor veni la ea; își vor înălța corturile împotriva ei de jur împrejur; vor paște fiecare în locul lui.
4 “Ẹ ya ará yín sí mímọ́ láti bá a jagun! Dìde, kí a kọlù ú ní ìgbà ọ̀sán! Ṣùgbọ́n ó ṣe, nítorí ọjọ́ lọ tán, ọjọ́ alẹ́ náà sì gùn sí i.
Pregătiți război împotriva ei; ridicați-vă și să ne urcăm la amiază. Vai nouă! pentru că ziua pleacă, pentru că umbrele serii se întind.
5 Nítorí náà, ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a kọlù ú ní àṣálẹ́ kí a sì ba odi alágbára rẹ̀ jẹ́.”
Ridicați-vă, să ne urcăm noaptea și să îi distrugem palatele.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ ké àwọn igi náà lulẹ̀ kí ẹ sì mọ odi ààbò yí Jerusalẹmu ká. Èyí ni ìlú títóbi tí a ó bẹ̀wò, nítorí pé ó kún fún ìninilára.
Pentru că astfel a spus DOMNUL oștirilor: Retezați copaci și aruncați un val de pământ împotriva Ierusalimului; aceasta este cetatea de cercetat; ea este în întregime oprimată în mijlocul ei.
7 Gẹ́gẹ́ bí kànga ṣe ń da omi inú rẹ̀ sílẹ̀, náà ni ó ń tú ìwà búburú rẹ̀ jáde. Ìwà ipá àti ìparun ń tún pariwo nínú rẹ̀; nígbà gbogbo ni àìsàn àti ọgbẹ́ rẹ̀ ń wà níwájú mi.
Precum fântâna își varsă apele, tot astfel ea își varsă stricăciunea: violență și jefuire se aud în ea; înaintea mea se află continuu mâhnire și răni.
8 Ìwọ Jerusalẹmu, gba ìkìlọ̀, kí Èmi kí ó má ba à lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, kí n sì sọ ilẹ̀ rẹ di ahoro, tí kò ní ní olùgbé.”
Instruiește-te, Ierusalime, ca nu cumva sufletul meu să se depărteze de tine; ca nu cumva să te fac pustiu, o țară nelocuită.
9 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Jẹ́ kí wọn pèsè ìyókù Israẹli ní tónítóní bí àjàrà; na ọwọ́ rẹ sí àwọn ẹ̀ka nì lẹ́ẹ̀kan sí i gẹ́gẹ́ bí ẹnìkan ti í kó èso àjàrà jọ.”
Astfel spune DOMNUL oștirilor: Ei vor culege în întregime rămășița lui Israel ca pe o vie; întoarce-ți înapoi mâna la coșuri, ca un culegător.
10 Ta ni ẹni tí mo lè bá sọ̀rọ̀ àti tí mo lè fún ní ìmọ̀ràn? Ta ni yóò tẹ́tí sílẹ̀ sí mi? Etí wọn ti di, nítorí náà wọn kò lè gbọ́. Ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ ohun búburú sí wọn, wọn kò sì ní inú dídùn nínú rẹ̀.
Cui să îi vorbesc și pe cine să avertizez, ca ei să asculte? Iată, urechea lor este necircumcisă și nu pot să dea ascultare; iată, cuvântul DOMNULUI este pentru ei o ocară; nu au desfătare în el.
11 Èmi kún fún ìbínú Olúwa, èmi kò sì le è pa á mọ́ra. “Tú u sí orí àwọn ọmọ ńigboro, àti sórí àwọn ọmọkùnrin tí wọn kó ra wọn jọ pọ̀, àti ọkọ àti aya ni a ò mú sínú rẹ̀, àti àwọn arúgbó tí ó ní ọjọ́ kíkún lórí.
De aceea sunt plin de furia DOMNULUI; sunt obosit de ținerea ei; o voi turna asupra copiilor de afară și asupra adunării împreună a tinerilor; căci și soțul cu soția vor fi luați, cel bătrân cu cel sătul de zile.
12 Ilé wọn o sì di ti ẹlòmíràn, oko wọn àti àwọn aya wọn, nígbà tí èmi bá na ọwọ́ mi sí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí.
Și casele lor vor fi trecute în mâna altora, împreună cu câmpurile și soțiile lor, pentru că îmi voi întinde mâna asupra locuitorilor țării, spune DOMNUL.
13 “Láti orí ẹni tí ó kéré sí orí ẹni tí ó tóbi ju, gbogbo wọn ni ó sì ní ojúkòkòrò fún èrè, àwọn wòlíì àti àlùfáà lápapọ̀ sì kún fún ẹ̀tàn.
Pentru că de la cel mai mic al lor până la cel mai mare al lor fiecare este dedat la poftire; și de la profet până la preot fiecare tratează cu falsitate.
14 Wọ́n sì ń wo ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi bí ẹni pé kò tó nǹkan. Wọ́n ń wí pé, ‘Àlàáfíà, Àlàáfíà,’ nígbà tí kò sì sí àlàáfíà.
Ei au vindecat de asemenea vătămarea fiicei poporului meu cu ușurătate, spunând: Pace, pace; când nu este pace.
15 Ojú ha a tì wọ́n nítorí ìwà ìríra wọn bí? Rárá, wọn kò ní ìtìjú mọ́, wọn kò tilẹ̀ ní oorun ìtìjú. Nítorí náà, wọn ó ṣubú láàrín àwọn tó ṣubú, a ó sì ké wọn lulẹ̀ nígbà tí mo bá bẹ̀ wọ́n wò,” ni Olúwa wí.
Au fost ei rușinați că au comis urâciune? Nu, nu au fost deloc rușinați, nici nu puteau să roșească; de aceea ei vor cădea printre cei care cad; la timpul când îi cercetez vor fi doborâți, spune DOMNUL.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Ẹ dúró sí ìkóríta, kí ẹ sì wò, ẹ béèrè fún ọ̀nà àtijọ́, ẹ béèrè ọ̀nà dáradára nì, kí ẹ rìn nínú rẹ, ẹ̀yin yóò sì rí ìsinmi fún ọkàn yín. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa kì yóò rìn nínú rẹ̀.’
Astfel spune DOMNUL: Stați pe căi și vedeți și întrebați de cărările cele vechi, unde este calea bună; și umblați în ea și veți găsi odihnă pentru sufletele voastre. Dar ei au spus: Refuzăm să umblăm în ea.
17 Èmi yan olùṣọ́ fún un yín, mo sì wí pé: ‘Tẹ́tí sí dídún fèrè náà,’ ẹ̀yìn wí pé, ‘Àwa kì yóò tẹ́tí sílẹ̀.’
De asemenea am pus paznici peste voi, spunând: Dați ascultare la sunetul trâmbiței. Dar ei au spus: Refuzăm să dăm ascultare.
18 Nítorí náà, gbọ́ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè; kíyèsi, kí ẹ sì jẹ́ ẹlẹ́rìí, ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí wọn.
De aceea ascultați, voi națiunilor; și cunoaște, tu adunare, ce este printre ei.
19 Gbọ́, ìwọ ayé! Mò ń mú ìparun bọ̀ sórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, èso ìrò inú wọn, nítorí wọn kò fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, wọ́n sì ti kọ òfin mi sílẹ̀.
Ascultă, pământule; iată, voi aduce răul asupra acestui popor, rodul gândurilor lor, pentru că nu au dat ascultare la cuvintele mele, nici la legea mea, ci au respins-o.
20 Èrè wo ni ó wà fún mi nínú tùràrí láti Ṣeba wá, tàbí èso dáradára láti ilẹ̀ jíjìn réré? Ẹbọ sísun yín kò ṣe ìtẹ́wọ́gbà, ọrẹ yín kò sì wù mí.”
Pentru ce vine la mine tămâie din Seba și trestia dulce de zahăr dintr-o țară îndepărtată? Ofrandele voastre arse nu sunt bine primite, nici sacrificiile voastre nu îmi sunt dulci.
21 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Èmi yóò gbé ohun ìdènà síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Àwọn baba àti ọmọ yóò jùmọ̀ ṣubú lù wọ́n, àwọn aládùúgbò àti ọ̀rẹ́ yóò ṣègbé.”
De aceea astfel spune DOMNUL: Iată, voi pune pietre de poticnire înaintea acestui popor, și părinții și fiii împreună vor cădea peste ele; vecinul și prietenul lui vor pieri.
22 Báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, àwọn ọmọ-ogun ń bọ̀ wá láti ilẹ̀ àríwá, a ó sì gbé orílẹ̀-èdè ńlá dìde láti òpin ayé wá.
Astfel spune DOMNUL: Iată, un popor vine din țara de nord și o națiune mare va fi ridicată de la marginile pământului.
23 Wọ́n sì dìmọ́ra pẹ̀lú ọrun àti ọ̀kọ̀, wọ́n jẹ́ ẹni ibi, wọn kò sì ní àánú. Wọ́n ń hó bí omi Òkun, bí wọ́n ti ṣe ń gun àwọn ẹṣin wọn lọ; wọ́n sì wá bí ọkùnrin tí yóò jà ọ́ lógun, ìwọ ọmọbìnrin Sioni.”
Ei vor apuca arcul și sulița; ei sunt cruzi și nu au milă; vocea lor răcnește ca marea; și călăresc pe cai, desfășurați ca bărbați pentru război împotriva ta, fiică a Sionului.
24 Àwa ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wa sì di rírọ, ìrora sì mú wa bí obìnrin tí ń rọbí.
Noi am auzit de faima lor, mâinile noastre slăbesc, chinul ne-a apucat și durere, ca a unei femei la naștere.
25 Má ṣe jáde lọ sí orí pápá tàbí kí o máa rìn ní àwọn ojú ọ̀nà, nítorí ọ̀tá náà ní idà, ìpayà sì wà níbi gbogbo.
Nu ieșiți la câmp, nici nu umblați pe cale, pentru că sabia dușmanului și frica este de fiecare parte.
26 Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀, kí ẹ sì sùn nínú eérú, ẹ ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ìpohùnréré ẹkún gẹ́gẹ́ bí i lórí ọmọkùnrin yín kan ṣoṣo nítorí pé lójijì ni àwọn apanirun yóò kọlù wá.
Fiică a poporului meu, încinge-te cu pânză de sac și tăvălește-te în cenușă; jelește, ca pentru singurul fiu, cea mai amară plângere, pentru că prădătorul va veni dintr-odată asupra noastră.
27 “Èmi ti fi ẹ́ ṣe ẹni tí yóò máa yọ́ irú àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bi irin tútù, kí wọn kí ó lè ṣe àkíyèsí, kí ó sì dán ọ̀nà wọn wò.
Eu te-am pus ca un turn și o fortăreață în poporul meu, ca să le cunoști și să le încerci calea.
28 Ọlọ́tẹ̀ tí ọkàn rẹ̀ le ní gbogbo wọn. Wọ́n ń lọ káàkiri láti sọ̀rọ̀-òdì. Wọ́n jẹ́ idẹ àti irin, wọ́n sì kún fún ìwà ìbàjẹ́.
Ei sunt toți răzvrătiți apăsători, umblând cu defăimări, ei sunt aramă și fier; ei sunt toți corupători.
29 Ewìrì a fẹ́ná kíkankíkan, kí ó lè yọ́ òjé, ẹni tí ń yọ́ ọ ń yọ́ ọ lásán; a kò si ya ènìyàn búburú kúrò.
Foalele sunt arse, plumbul este mistuit de foc; topitorul topește în zadar; căci cei stricați nu sunt smulși.
30 A pè wọ́n ní fàdákà tí a kọ̀sílẹ̀, nítorí Olúwa ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀.”
Argint lepădat vor fi numiți [de oameni], pentru că DOMNUL i-a lepădat.

< Jeremiah 6 >