< Jeremiah 6 >

1 “Ẹ̀yin ènìyàn Benjamini, sá sí ibi ààbò! Ẹ sá kúrò ní Jerusalẹmu. Ẹ fọn fèrè ní Tekoa! Kí ẹ gbé àmì sókè lórí Beti-Hakeremu! Nítorí àjálù farahàn láti àríwá, àní ìparun tí ó lágbára.
Zgromadźcie się, synowie Benjaminowi! z pośrodku Jeruzalemu, a w Tekue trąbcie w trąbę, i nad Betcherem podnieście chorągiew! bo złe ukazało się z północy, i zburzenie wielkie.
2 Èmi yóò pa ọmọbìnrin Sioni run, tí ó jẹ́ arẹwà àti ẹlẹgẹ́.
Pięknej, rozkosznej pannie przypodobałem był córkę Syońską;
3 Olùṣọ́-àgùntàn pẹ̀lú agbo wọn yóò gbóguntì wọ́n. Wọn yóò pa àgọ́ yí wọn ká, olúkúlùkù yóò máa jẹ ní ilé rẹ̀.”
Ale do niej przyciągną pasterze i trzody ich; rozbiją przeciwko niej namioty w około, spasie każdy miejsce swoje, i rzeką:
4 “Ẹ ya ará yín sí mímọ́ láti bá a jagun! Dìde, kí a kọlù ú ní ìgbà ọ̀sán! Ṣùgbọ́n ó ṣe, nítorí ọjọ́ lọ tán, ọjọ́ alẹ́ náà sì gùn sí i.
Podnieście przeciwko niej wojnę, wstańcie, a wtargniemy w południe; biada nam, że się nachylił dzień, że się rozciągnęły cienie wieczorne!
5 Nítorí náà, ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a kọlù ú ní àṣálẹ́ kí a sì ba odi alágbára rẹ̀ jẹ́.”
Wstańcie, a wtargniemy w nocy, i rozwalmy pałace jej.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ ké àwọn igi náà lulẹ̀ kí ẹ sì mọ odi ààbò yí Jerusalẹmu ká. Èyí ni ìlú títóbi tí a ó bẹ̀wò, nítorí pé ó kún fún ìninilára.
Bo tak mówi Pan zastępów: Narąbcie drzewa, a usypcie przeciw Jeruzalemowi szańce; toć to miasto jest, które ma być nawiedzione; jakożkolwiek wielkie, niemasz jedno ucisk w pośrodku jego.
7 Gẹ́gẹ́ bí kànga ṣe ń da omi inú rẹ̀ sílẹ̀, náà ni ó ń tú ìwà búburú rẹ̀ jáde. Ìwà ipá àti ìparun ń tún pariwo nínú rẹ̀; nígbà gbogbo ni àìsàn àti ọgbẹ́ rẹ̀ ń wà níwájú mi.
Jako źródło wylewa wody swe, tak ono wylewa złość swoję; ucisk i spustoszenie słychać w niem przed obliczem mojem ustawicznie, boleść i bicie.
8 Ìwọ Jerusalẹmu, gba ìkìlọ̀, kí Èmi kí ó má ba à lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, kí n sì sọ ilẹ̀ rẹ di ahoro, tí kò ní ní olùgbé.”
Ćwicz się Jeruzalemie! by snać nie odstąpiła dusza moja od ciebie, bym cię snać nie obrócił w pustynię ziemi do mieszkania niesposobną,
9 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Jẹ́ kí wọn pèsè ìyókù Israẹli ní tónítóní bí àjàrà; na ọwọ́ rẹ sí àwọn ẹ̀ka nì lẹ́ẹ̀kan sí i gẹ́gẹ́ bí ẹnìkan ti í kó èso àjàrà jọ.”
Tak mówi Pan zastępów: Ostatek Izraela aż do grona wyzbierają, jako winnicę, i rzeką: Sięgaj ręką twoją, jako ten, co zbiera wino do kosza.
10 Ta ni ẹni tí mo lè bá sọ̀rọ̀ àti tí mo lè fún ní ìmọ̀ràn? Ta ni yóò tẹ́tí sílẹ̀ sí mi? Etí wọn ti di, nítorí náà wọn kò lè gbọ́. Ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ ohun búburú sí wọn, wọn kò sì ní inú dídùn nínú rẹ̀.
Do kogoż mówić będę, i kim oświadczę, aby słyszeli? Oto nieobrzezane są uszy ich, tak, że słuchać nie mogą; oto słowo Pańskie mają za hańbę i nie kochają się w niem.
11 Èmi kún fún ìbínú Olúwa, èmi kò sì le è pa á mọ́ra. “Tú u sí orí àwọn ọmọ ńigboro, àti sórí àwọn ọmọkùnrin tí wọn kó ra wọn jọ pọ̀, àti ọkọ àti aya ni a ò mú sínú rẹ̀, àti àwọn arúgbó tí ó ní ọjọ́ kíkún lórí.
Przetoż pełenem zapalczywości Pańskiej, upracowałem się, zawściągając ją w sobie. Wylana będzie tak na maluczkiego na ulicy, jako i na zebranie młodzieńców; owszem, i mąż z żoną, a starzec ze zgrzybiałym pojmany będzie.
12 Ilé wọn o sì di ti ẹlòmíràn, oko wọn àti àwọn aya wọn, nígbà tí èmi bá na ọwọ́ mi sí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí.
I przypadną domy ich na inszych, także pola i żony ich, gdyż wyciągnę rękę moję na obywateli tej ziemi, mówi Pan.
13 “Láti orí ẹni tí ó kéré sí orí ẹni tí ó tóbi ju, gbogbo wọn ni ó sì ní ojúkòkòrò fún èrè, àwọn wòlíì àti àlùfáà lápapọ̀ sì kún fún ẹ̀tàn.
Zaiste, od najmniejszego z nich aż do największego z nich, wszyscy się udali za łakomstwem; od proroka aż do kapłana, wszyscy zgoła bawią się kłamstwem.
14 Wọ́n sì ń wo ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi bí ẹni pé kò tó nǹkan. Wọ́n ń wí pé, ‘Àlàáfíà, Àlàáfíà,’ nígbà tí kò sì sí àlàáfíà.
I leczą skruszenie córki ludu mego tylko po wierzchu, mówiąc: Pokój, pokój! choć niemasz pokoju.
15 Ojú ha a tì wọ́n nítorí ìwà ìríra wọn bí? Rárá, wọn kò ní ìtìjú mọ́, wọn kò tilẹ̀ ní oorun ìtìjú. Nítorí náà, wọn ó ṣubú láàrín àwọn tó ṣubú, a ó sì ké wọn lulẹ̀ nígbà tí mo bá bẹ̀ wọ́n wò,” ni Olúwa wí.
Izali się zawstydzili, przeto że obrzydłość czynili? Zaiste ani się lud wstydził, ani ich prorocy do wstydu przywieść mogli; przetoż upadną między padającymi; czasu, którego ich nawiedzę, upadną, mówi Pan.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Ẹ dúró sí ìkóríta, kí ẹ sì wò, ẹ béèrè fún ọ̀nà àtijọ́, ẹ béèrè ọ̀nà dáradára nì, kí ẹ rìn nínú rẹ, ẹ̀yin yóò sì rí ìsinmi fún ọkàn yín. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa kì yóò rìn nínú rẹ̀.’
Gdy tak Pan mawiał: Zastanówcie się na drogach, a spojrzyjcie i pytajcie się o ścieszkach starych, któraby była droga dobra, a chodźcie nią, a znajdziecie odpocznienie duszy waszej: tedy odpowiadali: Nie będziemy chodzili.
17 Èmi yan olùṣọ́ fún un yín, mo sì wí pé: ‘Tẹ́tí sí dídún fèrè náà,’ ẹ̀yìn wí pé, ‘Àwa kì yóò tẹ́tí sílẹ̀.’
A gdym postanawiał nad wami stróżów, mówiąc: Słuchajcie głosu trąby! tedy mawiali: Nie będziemy słuchać.
18 Nítorí náà, gbọ́ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè; kíyèsi, kí ẹ sì jẹ́ ẹlẹ́rìí, ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí wọn.
Przetoż słuchajcie, o narody! a poznaj, o zgromadzenie! co się dzieje między nimi.
19 Gbọ́, ìwọ ayé! Mò ń mú ìparun bọ̀ sórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, èso ìrò inú wọn, nítorí wọn kò fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, wọ́n sì ti kọ òfin mi sílẹ̀.
Słuchaj, o ziemio! Oto Ja przywiodę złe na ten lud, owoce myśli ich, przeto, że nie słuchają słów moich, ani zakonu mego, ale go odrzucają.
20 Èrè wo ni ó wà fún mi nínú tùràrí láti Ṣeba wá, tàbí èso dáradára láti ilẹ̀ jíjìn réré? Ẹbọ sísun yín kò ṣe ìtẹ́wọ́gbà, ọrẹ yín kò sì wù mí.”
Na cóż mi kadzidło z Saby przychodzi, a cynamon wonny wyborny z ziemi dalekiej? Całopalenia wasze nie są mi przyjemne, i ofiary wasze nie podobają mi się.
21 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Èmi yóò gbé ohun ìdènà síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Àwọn baba àti ọmọ yóò jùmọ̀ ṣubú lù wọ́n, àwọn aládùúgbò àti ọ̀rẹ́ yóò ṣègbé.”
Przetoż tak mówi Pan: Oto ja nakładę ludowi temu zawad, o które się otrącać będą ojcowie, także i synowie, sąsiad i bliźni jego, i poginą.
22 Báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, àwọn ọmọ-ogun ń bọ̀ wá láti ilẹ̀ àríwá, a ó sì gbé orílẹ̀-èdè ńlá dìde láti òpin ayé wá.
Tak mówi Pan: Oto lud przyciągnie z ziemi północnej, a naród wielki powstanie od kończyn ziemi;
23 Wọ́n sì dìmọ́ra pẹ̀lú ọrun àti ọ̀kọ̀, wọ́n jẹ́ ẹni ibi, wọn kò sì ní àánú. Wọ́n ń hó bí omi Òkun, bí wọ́n ti ṣe ń gun àwọn ẹṣin wọn lọ; wọ́n sì wá bí ọkùnrin tí yóò jà ọ́ lógun, ìwọ ọmọbìnrin Sioni.”
Łuk i włócznię pochwyci, okrutny będzie, a nie zlituje się. Głos ich jako morze zahuczy, a na koniach jeździć będą, naród uszykowany jako mąż do boju przeciwko tobie, o córko Syońska!
24 Àwa ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wa sì di rírọ, ìrora sì mú wa bí obìnrin tí ń rọbí.
Skoro usłyszymy wieść o nim, osłabieją ręce nasze, ucisk nas ogarnie, i boleść jako rodzącą.
25 Má ṣe jáde lọ sí orí pápá tàbí kí o máa rìn ní àwọn ojú ọ̀nà, nítorí ọ̀tá náà ní idà, ìpayà sì wà níbi gbogbo.
Nie wychodźcie na pole, i w drogę nie chodźcie; bo miecz nieprzyjacielski a strach w około.
26 Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀, kí ẹ sì sùn nínú eérú, ẹ ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ìpohùnréré ẹkún gẹ́gẹ́ bí i lórí ọmọkùnrin yín kan ṣoṣo nítorí pé lójijì ni àwọn apanirun yóò kọlù wá.
O córko ludu mojego! przepasz się worem a walaj się w popiele; uczyń sobie żal jako po jedynaku, żal gorzki; bo na nas nagle burzyciel przypadnie.
27 “Èmi ti fi ẹ́ ṣe ẹni tí yóò máa yọ́ irú àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bi irin tútù, kí wọn kí ó lè ṣe àkíyèsí, kí ó sì dán ọ̀nà wọn wò.
Dałem cię za basztę i za wieżę w ludu moim, abyś upatrywał i doświadczał drogi ich.
28 Ọlọ́tẹ̀ tí ọkàn rẹ̀ le ní gbogbo wọn. Wọ́n ń lọ káàkiri láti sọ̀rọ̀-òdì. Wọ́n jẹ́ idẹ àti irin, wọ́n sì kún fún ìwà ìbàjẹ́.
Wszyscy są między krnąbrnymi najkrnąbrniejsi, chodzą jako obmowca, są jako miedź i żelaza; wszyscy zgoła są skażonymi.
29 Ewìrì a fẹ́ná kíkankíkan, kí ó lè yọ́ òjé, ẹni tí ń yọ́ ọ ń yọ́ ọ lásán; a kò si ya ènìyàn búburú kúrò.
Murzszeją miechy, ołów od ognia niszczeje, próżno ustawicznie złotnik pławi; bo złe rzeczy nie mogą być oddalone.
30 A pè wọ́n ní fàdákà tí a kọ̀sílẹ̀, nítorí Olúwa ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀.”
Srebrem fałszywem będą nazwani; bo ich Pan odrzucił.

< Jeremiah 6 >