< Jeremiah 6 >

1 “Ẹ̀yin ènìyàn Benjamini, sá sí ibi ààbò! Ẹ sá kúrò ní Jerusalẹmu. Ẹ fọn fèrè ní Tekoa! Kí ẹ gbé àmì sókè lórí Beti-Hakeremu! Nítorí àjálù farahàn láti àríwá, àní ìparun tí ó lágbára.
« Fuyez en sécurité, enfants de Benjamin, hors du centre de Jérusalem! Sonnez de la trompette à Tekoa et élevez un signal sur Beth Haccherem, car le malheur vient du nord avec une grande destruction.
2 Èmi yóò pa ọmọbìnrin Sioni run, tí ó jẹ́ arẹwà àti ẹlẹgẹ́.
J'extermine la belle et la délicate, la fille de Sion.
3 Olùṣọ́-àgùntàn pẹ̀lú agbo wọn yóò gbóguntì wọ́n. Wọn yóò pa àgọ́ yí wọn ká, olúkúlùkù yóò máa jẹ ní ilé rẹ̀.”
Des bergers avec leurs troupeaux viendront vers elle. Ils dresseront leurs tentes tout autour d'elle. Ils feront paître chacun à sa place. »
4 “Ẹ ya ará yín sí mímọ́ láti bá a jagun! Dìde, kí a kọlù ú ní ìgbà ọ̀sán! Ṣùgbọ́n ó ṣe, nítorí ọjọ́ lọ tán, ọjọ́ alẹ́ náà sì gùn sí i.
« Préparez la guerre contre elle! Levez-vous! Montons à midi. Malheur à nous! Car le jour décline, car les ombres du soir s'étendent.
5 Nítorí náà, ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a kọlù ú ní àṣálẹ́ kí a sì ba odi alágbára rẹ̀ jẹ́.”
Levez-vous! Montons de nuit, et détruisons ses palais. »
6 Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ ké àwọn igi náà lulẹ̀ kí ẹ sì mọ odi ààbò yí Jerusalẹmu ká. Èyí ni ìlú títóbi tí a ó bẹ̀wò, nítorí pé ó kún fún ìninilára.
Car Yahvé des armées a dit: « Abattez des arbres, et élevez un monticule contre Jérusalem. C'est la ville qu'il faut visiter. Elle est remplie d'oppression au-dedans d'elle-même.
7 Gẹ́gẹ́ bí kànga ṣe ń da omi inú rẹ̀ sílẹ̀, náà ni ó ń tú ìwà búburú rẹ̀ jáde. Ìwà ipá àti ìparun ń tún pariwo nínú rẹ̀; nígbà gbogbo ni àìsàn àti ọgbẹ́ rẹ̀ ń wà níwájú mi.
Comme un puits produit ses eaux, ainsi elle produit sa méchanceté. On entend en elle la violence et la destruction. La maladie et les plaies sont continuellement devant moi.
8 Ìwọ Jerusalẹmu, gba ìkìlọ̀, kí Èmi kí ó má ba à lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, kí n sì sọ ilẹ̀ rẹ di ahoro, tí kò ní ní olùgbé.”
Sois instruite, Jérusalem, de peur que mon âme ne se sépare de toi, que je ne fasse de toi une désolation, une terre inhabitée. »
9 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Jẹ́ kí wọn pèsè ìyókù Israẹli ní tónítóní bí àjàrà; na ọwọ́ rẹ sí àwọn ẹ̀ka nì lẹ́ẹ̀kan sí i gẹ́gẹ́ bí ẹnìkan ti í kó èso àjàrà jọ.”
Yahvé des Armées dit: « Ils glaneront à fond le reste d'Israël comme une vigne. Tourne à nouveau ta main comme un vendangeur vers les paniers. »
10 Ta ni ẹni tí mo lè bá sọ̀rọ̀ àti tí mo lè fún ní ìmọ̀ràn? Ta ni yóò tẹ́tí sílẹ̀ sí mi? Etí wọn ti di, nítorí náà wọn kò lè gbọ́. Ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ ohun búburú sí wọn, wọn kò sì ní inú dídùn nínú rẹ̀.
A qui devrais-je parler et rendre témoignage, pour qu'ils entendent? Voici, leur oreille est incirconcise, et ils ne peuvent pas écouter. Voici, la parole de Yahvé est devenue pour eux un opprobre. Ils n'y trouvent aucun plaisir.
11 Èmi kún fún ìbínú Olúwa, èmi kò sì le è pa á mọ́ra. “Tú u sí orí àwọn ọmọ ńigboro, àti sórí àwọn ọmọkùnrin tí wọn kó ra wọn jọ pọ̀, àti ọkọ àti aya ni a ò mú sínú rẹ̀, àti àwọn arúgbó tí ó ní ọjọ́ kíkún lórí.
C'est pourquoi je suis plein de la colère de Yahvé. Je suis fatigué de la retenir. « Versez-le sur les enfants dans la rue, et sur le rassemblement de jeunes hommes; car même le mari avec sa femme sera pris, le vieillard avec celui qui est plein de jours.
12 Ilé wọn o sì di ti ẹlòmíràn, oko wọn àti àwọn aya wọn, nígbà tí èmi bá na ọwọ́ mi sí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí.
Leurs maisons seront confiées à d'autres, leurs champs et leurs femmes ensemble; car j'étendrai ma main sur les habitants du pays, dit Yahvé. »
13 “Láti orí ẹni tí ó kéré sí orí ẹni tí ó tóbi ju, gbogbo wọn ni ó sì ní ojúkòkòrò fún èrè, àwọn wòlíì àti àlùfáà lápapọ̀ sì kún fún ẹ̀tàn.
« Car, depuis le plus petit jusqu'au plus grand, tous sont livrés à la convoitise. Depuis le prophète jusqu'au prêtre, tout le monde fait du faux.
14 Wọ́n sì ń wo ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi bí ẹni pé kò tó nǹkan. Wọ́n ń wí pé, ‘Àlàáfíà, Àlàáfíà,’ nígbà tí kò sì sí àlàáfíà.
Ils ont aussi guéri superficiellement la blessure de mon peuple, en disant « Paix, paix! » alors qu'il n'y a pas de paix.
15 Ojú ha a tì wọ́n nítorí ìwà ìríra wọn bí? Rárá, wọn kò ní ìtìjú mọ́, wọn kò tilẹ̀ ní oorun ìtìjú. Nítorí náà, wọn ó ṣubú láàrín àwọn tó ṣubú, a ó sì ké wọn lulẹ̀ nígbà tí mo bá bẹ̀ wọ́n wò,” ni Olúwa wí.
N'ont-ils pas eu honte quand ils ont commis des abominations? Non, ils n'avaient pas du tout honte, ils ne pouvaient pas non plus rougir. Ils tomberont donc parmi ceux qui tombent. Quand je les visiterai, ils seront renversés », dit Yahvé.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Ẹ dúró sí ìkóríta, kí ẹ sì wò, ẹ béèrè fún ọ̀nà àtijọ́, ẹ béèrè ọ̀nà dáradára nì, kí ẹ rìn nínú rẹ, ẹ̀yin yóò sì rí ìsinmi fún ọkàn yín. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa kì yóò rìn nínú rẹ̀.’
Yahvé dit: « Tenez-vous sur les chemins et regardez, et demandez les anciens sentiers: « Où est le bon chemin? » et marchez-y, et vous trouverez le repos de vos âmes. Mais ils ont dit: « Nous n'y marcherons pas.
17 Èmi yan olùṣọ́ fún un yín, mo sì wí pé: ‘Tẹ́tí sí dídún fèrè náà,’ ẹ̀yìn wí pé, ‘Àwa kì yóò tẹ́tí sílẹ̀.’
J'ai placé sur vous des sentinelles, en disant: « Écoutez le son de la trompette. Mais ils ont dit: « Nous n'écouterons pas ».
18 Nítorí náà, gbọ́ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè; kíyèsi, kí ẹ sì jẹ́ ẹlẹ́rìí, ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí wọn.
C'est pourquoi, nations, écoutez et sachez, assemblée, ce qui est au milieu d'elles.
19 Gbọ́, ìwọ ayé! Mò ń mú ìparun bọ̀ sórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, èso ìrò inú wọn, nítorí wọn kò fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, wọ́n sì ti kọ òfin mi sílẹ̀.
Écoute, terre! Voici, je vais faire venir sur ce peuple le malheur, le fruit de ses pensées, parce qu'il n'a pas écouté mes paroles, et qu'il a rejeté ma loi.
20 Èrè wo ni ó wà fún mi nínú tùràrí láti Ṣeba wá, tàbí èso dáradára láti ilẹ̀ jíjìn réré? Ẹbọ sísun yín kò ṣe ìtẹ́wọ́gbà, ọrẹ yín kò sì wù mí.”
A quoi sert l'encens de Saba qui vient à moi, et le roseau d'un pays lointain? Vos holocaustes ne sont pas agréables, et vos sacrifices ne me plaisent pas. »
21 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Èmi yóò gbé ohun ìdènà síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Àwọn baba àti ọmọ yóò jùmọ̀ ṣubú lù wọ́n, àwọn aládùúgbò àti ọ̀rẹ́ yóò ṣègbé.”
C'est pourquoi Yahvé dit: « Voici que je vais mettre des pierres d'achoppement devant ce peuple. Les pères et les fils ensemble trébucheront contre eux. Le voisin et son ami périront. »
22 Báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, àwọn ọmọ-ogun ń bọ̀ wá láti ilẹ̀ àríwá, a ó sì gbé orílẹ̀-èdè ńlá dìde láti òpin ayé wá.
Yahvé dit: « Voici qu'un peuple vient du pays du nord. Une grande nation se lève des extrémités de la terre.
23 Wọ́n sì dìmọ́ra pẹ̀lú ọrun àti ọ̀kọ̀, wọ́n jẹ́ ẹni ibi, wọn kò sì ní àánú. Wọ́n ń hó bí omi Òkun, bí wọ́n ti ṣe ń gun àwọn ẹṣin wọn lọ; wọ́n sì wá bí ọkùnrin tí yóò jà ọ́ lógun, ìwọ ọmọbìnrin Sioni.”
Ils s'emparent de l'arc et de la lance. Ils sont cruels et sans pitié. Leur voix gronde comme la mer, ils montent à cheval, tous se rangent en bataille, comme un homme, contre toi, fille de Sion. »
24 Àwa ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wa sì di rírọ, ìrora sì mú wa bí obìnrin tí ń rọbí.
Nous avons entendu son rapport. Nos mains se sont affaiblies. L'angoisse s'est emparée de nous, et les douleurs comme celles d'une femme en travail.
25 Má ṣe jáde lọ sí orí pápá tàbí kí o máa rìn ní àwọn ojú ọ̀nà, nítorí ọ̀tá náà ní idà, ìpayà sì wà níbi gbogbo.
Ne sortez pas dans les champs et ne vous promenez pas sur le chemin, car l'épée de l'ennemi et la terreur sont de tous côtés.
26 Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀, kí ẹ sì sùn nínú eérú, ẹ ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ìpohùnréré ẹkún gẹ́gẹ́ bí i lórí ọmọkùnrin yín kan ṣoṣo nítorí pé lójijì ni àwọn apanirun yóò kọlù wá.
Fille de mon peuple, revêts-toi d'un sac, et roule-toi dans la cendre! Porte le deuil, comme pour un fils unique, des lamentations très amères, car le destructeur va venir soudainement sur nous.
27 “Èmi ti fi ẹ́ ṣe ẹni tí yóò máa yọ́ irú àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bi irin tútù, kí wọn kí ó lè ṣe àkíyèsí, kí ó sì dán ọ̀nà wọn wò.
« J'ai fait de toi un testeur de métaux et une forteresse au milieu de mon peuple, pour que tu connaisses et éprouves leur voie.
28 Ọlọ́tẹ̀ tí ọkàn rẹ̀ le ní gbogbo wọn. Wọ́n ń lọ káàkiri láti sọ̀rọ̀-òdì. Wọ́n jẹ́ idẹ àti irin, wọ́n sì kún fún ìwà ìbàjẹ́.
Ils sont tous de grands rebelles, qui vont et viennent pour calomnier. Ils sont de bronze et de fer. Ils sont tous corrompus.
29 Ewìrì a fẹ́ná kíkankíkan, kí ó lè yọ́ òjé, ẹni tí ń yọ́ ọ ń yọ́ ọ lásán; a kò si ya ènìyàn búburú kúrò.
Le soufflet souffle avec violence, Le plomb se consume dans le feu. Le plomb se consume dans le feu. C'est en vain qu'on les affine, car les méchants ne sont pas arrachés.
30 A pè wọ́n ní fàdákà tí a kọ̀sílẹ̀, nítorí Olúwa ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀.”
Les hommes les appelleront de l'argent rejeté, parce que Yahvé les a rejetés. »

< Jeremiah 6 >