< Jeremiah 6 >

1 “Ẹ̀yin ènìyàn Benjamini, sá sí ibi ààbò! Ẹ sá kúrò ní Jerusalẹmu. Ẹ fọn fèrè ní Tekoa! Kí ẹ gbé àmì sókè lórí Beti-Hakeremu! Nítorí àjálù farahàn láti àríwá, àní ìparun tí ó lágbára.
Kootkaat teitänne, te Benjaminin lapset, Jerusalemista, ja puhaltakaat torveen Tekoassa, ja nostakaat lippu Betkeremissä; sillä pohjasta on pahuus ja suuri viheliäisyys käsissä.
2 Èmi yóò pa ọmọbìnrin Sioni run, tí ó jẹ́ arẹwà àti ẹlẹgẹ́.
Minä olen verrannut Zionin tyttären kauniisen ja ihanaiseen:
3 Olùṣọ́-àgùntàn pẹ̀lú agbo wọn yóò gbóguntì wọ́n. Wọn yóò pa àgọ́ yí wọn ká, olúkúlùkù yóò máa jẹ ní ilé rẹ̀.”
Mutta paimenet tulevat hänen tykönsä laumoinensa; he panevat majansa hänen ympärillensä, ja kukin kaitsee paikassansa,
4 “Ẹ ya ará yín sí mímọ́ láti bá a jagun! Dìde, kí a kọlù ú ní ìgbà ọ̀sán! Ṣùgbọ́n ó ṣe, nítorí ọjọ́ lọ tán, ọjọ́ alẹ́ náà sì gùn sí i.
(Ja sanoo: ) pyhittäkäät sota häntä vastaan, nouskaat ja käykäämme puolipäivänä ylös; voi meitä! sillä ehtoo joutuu ja varjo tulee suureksi.
5 Nítorí náà, ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a kọlù ú ní àṣálẹ́ kí a sì ba odi alágbára rẹ̀ jẹ́.”
Nouskaat ja astukaamme ylös yöllä, ja hävittäkäämme hänen jalot huoneensa.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ ké àwọn igi náà lulẹ̀ kí ẹ sì mọ odi ààbò yí Jerusalẹmu ká. Èyí ni ìlú títóbi tí a ó bẹ̀wò, nítorí pé ó kún fún ìninilára.
Sillä näin sanoo Herra Zebaot: kaatakaat puita, ja tehkäät multaseiniä Jerusalemia vastaan; sillä kaupunki pitää kuritettaman, sen sisällä on sula vääryys.
7 Gẹ́gẹ́ bí kànga ṣe ń da omi inú rẹ̀ sílẹ̀, náà ni ó ń tú ìwà búburú rẹ̀ jáde. Ìwà ipá àti ìparun ń tún pariwo nínú rẹ̀; nígbà gbogbo ni àìsàn àti ọgbẹ́ rẹ̀ ń wà níwájú mi.
Niinkuin lähde kuohuttaa vetensä; niin kuohuu myös hänen pahuutensa; vääryys ja hävitys siinä kuullaan, kitu ja vaiva on aina minun edessäni.
8 Ìwọ Jerusalẹmu, gba ìkìlọ̀, kí Èmi kí ó má ba à lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, kí n sì sọ ilẹ̀ rẹ di ahoro, tí kò ní ní olùgbé.”
Anna sinuas kurittaa, Jerusalem, ettei minun sydämeni kääntyisi pois sinusta, etten minä sinua hävittäisi, niin ettei kenkään asu siinä maassa.
9 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Jẹ́ kí wọn pèsè ìyókù Israẹli ní tónítóní bí àjàrà; na ọwọ́ rẹ sí àwọn ẹ̀ka nì lẹ́ẹ̀kan sí i gẹ́gẹ́ bí ẹnìkan ti í kó èso àjàrà jọ.”
Näin sanoo Herra Zebaot: mitä Israelissa jäänyt on, se pitää myös sulaksi saaliiksi joutuman niinkuin viinapuu; kokota kätes koriin niinkuin viinamarjain poimia.
10 Ta ni ẹni tí mo lè bá sọ̀rọ̀ àti tí mo lè fún ní ìmọ̀ràn? Ta ni yóò tẹ́tí sílẹ̀ sí mi? Etí wọn ti di, nítorí náà wọn kò lè gbọ́. Ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ ohun búburú sí wọn, wọn kò sì ní inú dídùn nínú rẹ̀.
Kenelle siis minä puhun ja todistan, että joku kuulis? Katso, heidän korvansa ovat ympärileikkaamatta eikä taida kuulla; katso, he pitävät Herran sanan pilkkana ja ei kärsi sitä.
11 Èmi kún fún ìbínú Olúwa, èmi kò sì le è pa á mọ́ra. “Tú u sí orí àwọn ọmọ ńigboro, àti sórí àwọn ọmọkùnrin tí wọn kó ra wọn jọ pọ̀, àti ọkọ àti aya ni a ò mú sínú rẹ̀, àti àwọn arúgbó tí ó ní ọjọ́ kíkún lórí.
Sentähden olen minä niin täynnä Herran vihaa, etten minä taida lakata vuodattamasta, sekä lasten päälle kaduilla, ja myös nuorukaisten kokouksen päälle yhtä haavaa; sillä sekä mies että vaimo, ijällinen ja ikivanha pitää otettaman kiinni.
12 Ilé wọn o sì di ti ẹlòmíràn, oko wọn àti àwọn aya wọn, nígbà tí èmi bá na ọwọ́ mi sí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí.
Heidän huoneensa pitää tuleman muukalaisten käsiin, heidän peltonsa ja emäntänsä yhtä haavaa; sillä minä ojennan käteni maan asujain ylitse, sanoo Herra.
13 “Láti orí ẹni tí ó kéré sí orí ẹni tí ó tóbi ju, gbogbo wọn ni ó sì ní ojúkòkòrò fún èrè, àwọn wòlíì àti àlùfáà lápapọ̀ sì kún fún ẹ̀tàn.
Sillä he kaikki ahnehtivat, sekä pienet että suuret; prophetat ja papit opettavat väärin,
14 Wọ́n sì ń wo ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi bí ẹni pé kò tó nǹkan. Wọ́n ń wí pé, ‘Àlàáfíà, Àlàáfíà,’ nígbà tí kò sì sí àlàáfíà.
Ja lohduttavat kansaani hänen viheliäisyydessänsä, sitä halpana pitämään, ja sanovat: rauha, rauha; ja ei rauhaa olekaan.
15 Ojú ha a tì wọ́n nítorí ìwà ìríra wọn bí? Rárá, wọn kò ní ìtìjú mọ́, wọn kò tilẹ̀ ní oorun ìtìjú. Nítorí náà, wọn ó ṣubú láàrín àwọn tó ṣubú, a ó sì ké wọn lulẹ̀ nígbà tí mo bá bẹ̀ wọ́n wò,” ni Olúwa wí.
Sentähden pitää heidän häpiään tuleman, että he kauhistuksen tekevät; ja vaikka he tahtovat olla häpäisemättä, eikä taida hävetä, kuitenkin pitää heidän jokaisen lankeeman toinen toisensa päälle; ja koska minä heitä kuritan, silloin pitää heidän lankeeman, sanoo Herra.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Ẹ dúró sí ìkóríta, kí ẹ sì wò, ẹ béèrè fún ọ̀nà àtijọ́, ẹ béèrè ọ̀nà dáradára nì, kí ẹ rìn nínú rẹ, ẹ̀yin yóò sì rí ìsinmi fún ọkàn yín. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa kì yóò rìn nínú rẹ̀.’
Näin sanoo Herra: seisokaat teillä, katsokaat ja kysykäät entisiä teitä, kuka oikia tie on, sitä te vaeltakaat, niin te löydätte levon teidän sieluillenne. Mutta he sanovat: emme vaella.
17 Èmi yan olùṣọ́ fún un yín, mo sì wí pé: ‘Tẹ́tí sí dídún fèrè náà,’ ẹ̀yìn wí pé, ‘Àwa kì yóò tẹ́tí sílẹ̀.’
Ja minä olen pannut teille vartiat: ottakaat vaari torven äänestä; mutta he sanovat: emme ota vaaria.
18 Nítorí náà, gbọ́ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè; kíyèsi, kí ẹ sì jẹ́ ẹlẹ́rìí, ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí wọn.
Sentähden, te pakanat, kuulkaat, ja ota vaari, sinä kokous, niistä mitkä heidän seassansa tapahtuu.
19 Gbọ́, ìwọ ayé! Mò ń mú ìparun bọ̀ sórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, èso ìrò inú wọn, nítorí wọn kò fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, wọ́n sì ti kọ òfin mi sílẹ̀.
Maa, kuule sinä; katso, minä annan tulla kovan onnen tälle kansalle, heidän ansaitun palkkansa, ettei he pidä lukua minun sanastani, mutta hylkäävät minun lakini.
20 Èrè wo ni ó wà fún mi nínú tùràrí láti Ṣeba wá, tàbí èso dáradára láti ilẹ̀ jíjìn réré? Ẹbọ sísun yín kò ṣe ìtẹ́wọ́gbà, ọrẹ yín kò sì wù mí.”
Mitä minä lukua pidän pyhästä savusta, joka rikkaasta Arabiasta tulee, eli hyvästä kanelista, joka kaukaiselta maalta tulee? Teidän polttouhrinne ei ole minulle otollinen eikä teidän uhrinne kelpaa minulle.
21 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Èmi yóò gbé ohun ìdènà síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Àwọn baba àti ọmọ yóò jùmọ̀ ṣubú lù wọ́n, àwọn aládùúgbò àti ọ̀rẹ́ yóò ṣègbé.”
Sentähden sanoo Herra näin: katso, minä annan tälle kansalle lankeemuksen: siihen pitää sekä isät että lapset kaikki itsensä loukkaaman, ja kylän miehet pitää hukkuman toinen toisensa kanssa.
22 Báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, àwọn ọmọ-ogun ń bọ̀ wá láti ilẹ̀ àríwá, a ó sì gbé orílẹ̀-èdè ńlá dìde láti òpin ayé wá.
Näin sanoo Herra: katso, kansa on tuleva pohjoisesta maakunnasta, ja suuri kansa on nouseva maan vieristä.
23 Wọ́n sì dìmọ́ra pẹ̀lú ọrun àti ọ̀kọ̀, wọ́n jẹ́ ẹni ibi, wọn kò sì ní àánú. Wọ́n ń hó bí omi Òkun, bí wọ́n ti ṣe ń gun àwọn ẹṣin wọn lọ; wọ́n sì wá bí ọkùnrin tí yóò jà ọ́ lógun, ìwọ ọmọbìnrin Sioni.”
Jolla on joutset ja kilvet, hän on julma ja armotoin; heidän äänensä pauhaa niinkuin meri; he ajavat hevosilla, he ovat niinkuin varustettu sotaväki sinua vastaan, sinä tytär Zion.
24 Àwa ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wa sì di rírọ, ìrora sì mú wa bí obìnrin tí ń rọbí.
Me olemme kuulleet heistä sanoman, ja meidän kätemme ovat nääntyneet; tuska ja ahdistus on meidät käsittänyt niinkuin lapsensynnyttäjän.
25 Má ṣe jáde lọ sí orí pápá tàbí kí o máa rìn ní àwọn ojú ọ̀nà, nítorí ọ̀tá náà ní idà, ìpayà sì wà níbi gbogbo.
Älkään kenkään lähtekö pellolle, ja älköön kenkään tielle menkö; sillä joka paikassa on rauhattomuus vihollisen miekan tähden.
26 Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀, kí ẹ sì sùn nínú eérú, ẹ ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ìpohùnréré ẹkún gẹ́gẹ́ bí i lórí ọmọkùnrin yín kan ṣoṣo nítorí pé lójijì ni àwọn apanirun yóò kọlù wá.
O sinä, minun kansani tytär, pue säkki ylles ja aseta itses tuhkaan, sure niinkuin ainoaa poikaa suurella murheella; sillä hävittäjä tulee äkisti meidän päällemme.
27 “Èmi ti fi ẹ́ ṣe ẹni tí yóò máa yọ́ irú àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bi irin tútù, kí wọn kí ó lè ṣe àkíyèsí, kí ó sì dán ọ̀nà wọn wò.
Minä olen pannut sinun vartian torniksi ja linnaksi minun kansassani, tietämään ja koettelemaan heidän teitänsä.
28 Ọlọ́tẹ̀ tí ọkàn rẹ̀ le ní gbogbo wọn. Wọ́n ń lọ káàkiri láti sọ̀rọ̀-òdì. Wọ́n jẹ́ idẹ àti irin, wọ́n sì kún fún ìwà ìbàjẹ́.
He ovat kaikki peräti pois luopuneet, vaeltain petollisesti; he ovat kaikki turmeltu vaski ja rauta.
29 Ewìrì a fẹ́ná kíkankíkan, kí ó lè yọ́ òjé, ẹni tí ń yọ́ ọ ń yọ́ ọ lásán; a kò si ya ènìyàn búburú kúrò.
Palkeet ovat tulella poltetut, lyijy raukee pois, sulaaminen on hukassa; sillä ei paha ole eroitettu.
30 A pè wọ́n ní fàdákà tí a kọ̀sílẹ̀, nítorí Olúwa ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀.”
Sentähden he myös kutsutaan hyljätyksi hopiaksi, sillä Herra on heidät hyljännyt.

< Jeremiah 6 >