< Jeremiah 6 >

1 “Ẹ̀yin ènìyàn Benjamini, sá sí ibi ààbò! Ẹ sá kúrò ní Jerusalẹmu. Ẹ fọn fèrè ní Tekoa! Kí ẹ gbé àmì sókè lórí Beti-Hakeremu! Nítorí àjálù farahàn láti àríwá, àní ìparun tí ó lágbára.
Benjamin canaw na hlout nahanelah Jerusalem khothung hoi yawng awh leih. Tekoa vah mongka ueng awh, Bethhakkerem vah thaisaknae hmai hah paang awh. Bangkongtetpawiteh, rucatnae kalen poung rawknae teh atunglah hoi a tho toe.
2 Èmi yóò pa ọmọbìnrin Sioni run, tí ó jẹ́ arẹwà àti ẹlẹgẹ́.
Zion canu meikahawi kanaw e hah, ka raphoe han toe.
3 Olùṣọ́-àgùntàn pẹ̀lú agbo wọn yóò gbóguntì wọ́n. Wọn yóò pa àgọ́ yí wọn ká, olúkúlùkù yóò máa jẹ ní ilé rẹ̀.”
Tukhoumnaw ni a tuhunaw hoi ahni koe pha awh han, petkâkalup lah lukkareirimnaw a sak awh vaiteh, amamae tuhunaw rip a khoum awh han.
4 “Ẹ ya ará yín sí mímọ́ láti bá a jagun! Dìde, kí a kọlù ú ní ìgbà ọ̀sán! Ṣùgbọ́n ó ṣe, nítorí ọjọ́ lọ tán, ọjọ́ alẹ́ náà sì gùn sí i.
Ahnimanaw tuk hanlah kârakueng awh leih, thaw awh leih, kanîthun vah tuk awh sei, maimouh han a ru poung bangkongtetpawiteh, kanîthun a hloi teh tangmin kho a hmo toe.
5 Nítorí náà, ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a kọlù ú ní àṣálẹ́ kí a sì ba odi alágbára rẹ̀ jẹ́.”
Thaw awh leih, karum vah tuk awh sei, a im kahawi kahawi naw hah raphoe awh sei.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ ké àwọn igi náà lulẹ̀ kí ẹ sì mọ odi ààbò yí Jerusalẹmu ká. Èyí ni ìlú títóbi tí a ó bẹ̀wò, nítorí pé ó kún fún ìninilára.
Rasahu BAWIPA ni hettelah a dei, thingnaw tâtueng awh nateh, Jerusalem bout tuk nahanelah, luennae hah sak awh. Hote khopui heh rek hanelah ao. Hatei khopui thung vah kâyue kâounnae seng doeh akawi toe.
7 Gẹ́gẹ́ bí kànga ṣe ń da omi inú rẹ̀ sílẹ̀, náà ni ó ń tú ìwà búburú rẹ̀ jáde. Ìwà ipá àti ìparun ń tún pariwo nínú rẹ̀; nígbà gbogbo ni àìsàn àti ọgbẹ́ rẹ̀ ń wà níwájú mi.
Tuikhu ni tui a tâco sak e patetlah ahnimouh ni kathoute a tâcokhai van. Athung vah kâounnae hoi rawknae niyah akawi, ka hmalah lungmathoenae hoi patawnae pout laipalah ao.
8 Ìwọ Jerusalẹmu, gba ìkìlọ̀, kí Èmi kí ó má ba à lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, kí n sì sọ ilẹ̀ rẹ di ahoro, tí kò ní ní olùgbé.”
Oe Jerusalem kâhruetcuet, telah nahoeh pawiteh, ka hringnae ni hnamthun takhai vaiteh, athung vah kingdi ram lah ka coung sak han.
9 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Jẹ́ kí wọn pèsè ìyókù Israẹli ní tónítóní bí àjàrà; na ọwọ́ rẹ sí àwọn ẹ̀ka nì lẹ́ẹ̀kan sí i gẹ́gẹ́ bí ẹnìkan ti í kó èso àjàrà jọ.”
Rasahu BAWIPA ni hettelah a dei, misur paw kacawirae khi e patetlah ahnimouh ni Isarelnaw kacawirae hah abuemlah he a khi awh han. Misur paw kakhikung ni a khi e patetlah na kut hah tangthung dawk bout tapu ei.
10 Ta ni ẹni tí mo lè bá sọ̀rọ̀ àti tí mo lè fún ní ìmọ̀ràn? Ta ni yóò tẹ́tí sílẹ̀ sí mi? Etí wọn ti di, nítorí náà wọn kò lè gbọ́. Ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ ohun búburú sí wọn, wọn kò sì ní inú dídùn nínú rẹ̀.
Api koe maw lawk ka dei pouh vaiteh, kâhruetcuetnae ka poe han. A hnânaw a tabuem awh dawkvah, thai thai awh hoeh. BAWIPA e lawk hah ahnimouh hane dudam e lah ao teh, thaingainae roeroe tawn awh hoeh.
11 Èmi kún fún ìbínú Olúwa, èmi kò sì le è pa á mọ́ra. “Tú u sí orí àwọn ọmọ ńigboro, àti sórí àwọn ọmọkùnrin tí wọn kó ra wọn jọ pọ̀, àti ọkọ àti aya ni a ò mú sínú rẹ̀, àti àwọn arúgbó tí ó ní ọjọ́ kíkún lórí.
Hatdawkvah, BAWIPA e lungkhueknae hoi ka kawi teh ka khang thai hoeh toe. Lam dawk kaawm e camonaw hoi a kamkhueng e nawsainaw koe ka kamnue sak, yuvâ roi ni hot teh a khang han, matawng kum kacuenaw ni hai a khang awh han.
12 Ilé wọn o sì di ti ẹlòmíràn, oko wọn àti àwọn aya wọn, nígbà tí èmi bá na ọwọ́ mi sí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí.
A imlawnaw hoi a yunaw hai ayânaw koe koung ka poe han, ram thung vah kaawmnaw lathueng kai ni kut ka tha han toe, telah BAWIPA ni a dei.
13 “Láti orí ẹni tí ó kéré sí orí ẹni tí ó tóbi ju, gbogbo wọn ni ó sì ní ojúkòkòrò fún èrè, àwọn wòlíì àti àlùfáà lápapọ̀ sì kún fún ẹ̀tàn.
Kathoengca koehoi kalenpoung koe totouh, tami pueng ni a hounloun awh, profetnaw hoi vaihmanaw hai la awh hoeh, laithoe dei hoi a kâroe awh.
14 Wọ́n sì ń wo ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi bí ẹni pé kò tó nǹkan. Wọ́n ń wí pé, ‘Àlàáfíà, Àlàáfíà,’ nígbà tí kò sì sí àlàáfíà.
Ka taminaw e a hmâ lah ahawi han doeh, ahawi han doeh ati awh teh, phouhoucalah a khet awh, hawi katang hoeh.
15 Ojú ha a tì wọ́n nítorí ìwà ìríra wọn bí? Rárá, wọn kò ní ìtìjú mọ́, wọn kò tilẹ̀ ní oorun ìtìjú. Nítorí náà, wọn ó ṣubú láàrín àwọn tó ṣubú, a ó sì ké wọn lulẹ̀ nígbà tí mo bá bẹ̀ wọ́n wò,” ni Olúwa wí.
Panuet ka tho e hno a sak awh navah a kaya awh maw. Kayak awh hoeh. Kayak roeroe awh hoeh. Minhmai kangna hai paling awh hoeh. Hatdawkvah, karawmnaw koe rawp awh van han, kai ni ahnimanaw ka rek toteh, ahnimanaw teh rahim lah a bo awh han telah BAWIPA ni ati.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Ẹ dúró sí ìkóríta, kí ẹ sì wò, ẹ béèrè fún ọ̀nà àtijọ́, ẹ béèrè ọ̀nà dáradára nì, kí ẹ rìn nínú rẹ, ẹ̀yin yóò sì rí ìsinmi fún ọkàn yín. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa kì yóò rìn nínú rẹ̀.’
BAWIPA ni hettelah a dei, lam dawk kangdout nateh, khenhaw! ayan e lamruem hah pacei nateh, lam kahawi namaw ao telah pacei awh nateh, hote lam dawk dawn awh, telah pawiteh na muitha hanlah kâhatnae na hmu awh han. Hatei, nangmouh ni hote lam dawk ka cet awh mahoeh na ti awh.
17 Èmi yan olùṣọ́ fún un yín, mo sì wí pé: ‘Tẹ́tí sí dídún fèrè náà,’ ẹ̀yìn wí pé, ‘Àwa kì yóò tẹ́tí sílẹ̀.’
Kai ni nangmouh hanelah karingkung tami ka hmoun, mongka lawk thai awh! na ti pouh awh. Hatei, nangmouh ni, ka thai awh mahoeh na ti awh.
18 Nítorí náà, gbọ́ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè; kíyèsi, kí ẹ sì jẹ́ ẹlẹ́rìí, ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí wọn.
Hatdawkvah, miphunnaw thai awh haw, taminaw voi, ahnimanaw e lathueng ka phat hane hah pâkuem van awh.
19 Gbọ́, ìwọ ayé! Mò ń mú ìparun bọ̀ sórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, èso ìrò inú wọn, nítorí wọn kò fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, wọ́n sì ti kọ òfin mi sílẹ̀.
Oe talai, thai haw! hete taminaw lathueng vah, ronae ka pha sak han toe, amamouh ni a pouknae a paw letlang ni bangkongmaw kaie lawk hoi kâlawk a pahnawt awh.
20 Èrè wo ni ó wà fún mi nínú tùràrí láti Ṣeba wá, tàbí èso dáradára láti ilẹ̀ jíjìn réré? Ẹbọ sísun yín kò ṣe ìtẹ́wọ́gbà, ọrẹ yín kò sì wù mí.”
Sheba e hmuitui hoi kho hlanae koehoi e kacingtui ka radip e kai ni bangmaw ka ti nahan. Nangmae hmaisawi thuengnae ka dâw mahoeh, sathei thuengnae ni ka lunghawi sak mahoeh.
21 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Èmi yóò gbé ohun ìdènà síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Àwọn baba àti ọmọ yóò jùmọ̀ ṣubú lù wọ́n, àwọn aládùúgbò àti ọ̀rẹ́ yóò ṣègbé.”
Hatdawkvah, BAWIPA ni hettelah a dei, hete taminaw hmalah tâlaw nahan ka ta pouh han. A napanaw hoi a canaw ni a tâlaw awh han, imri hoi huikonaw rei a rawk awh han, ati.
22 Báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, àwọn ọmọ-ogun ń bọ̀ wá láti ilẹ̀ àríwá, a ó sì gbé orílẹ̀-èdè ńlá dìde láti òpin ayé wá.
BAWIPA ni hettelah a dei, khenhaw! atunglae ram koehoi ransanaw a tho toe, talai poutnae koehoi miphun kalenpoung kamthaw toe.
23 Wọ́n sì dìmọ́ra pẹ̀lú ọrun àti ọ̀kọ̀, wọ́n jẹ́ ẹni ibi, wọn kò sì ní àánú. Wọ́n ń hó bí omi Òkun, bí wọ́n ti ṣe ń gun àwọn ẹṣin wọn lọ; wọ́n sì wá bí ọkùnrin tí yóò jà ọ́ lógun, ìwọ ọmọbìnrin Sioni.”
Pala hoi tahroe patuep awh teh, tamikathout, pahrennae roeroe ka tawn hoeh naw lah ao. A pawlawk teh tuipui pawlawk patetlah ao teh, marang dawk a kâcui awh teh, tamipueng senehmaica a kâmahrawk awh teh, Oe! Zion canu, nang tuk hanlah a tho awh toe, ati.
24 Àwa ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wa sì di rírọ, ìrora sì mú wa bí obìnrin tí ń rọbí.
Ahnimae kamthang ka thai awh navah, ka kut tha pouk a bo. Runae teh manu ni ca khe patawnae a khang e patetlah khik na moum toe.
25 Má ṣe jáde lọ sí orí pápá tàbí kí o máa rìn ní àwọn ojú ọ̀nà, nítorí ọ̀tá náà ní idà, ìpayà sì wà níbi gbogbo.
Kahrawng tâcawt awh hanh, lam dawk hai cet awh hanh awh, tarannaw koe tahloi ao, avoivang taki a tho.
26 Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀, kí ẹ sì sùn nínú eérú, ẹ ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ìpohùnréré ẹkún gẹ́gẹ́ bí i lórí ọmọkùnrin yín kan ṣoṣo nítorí pé lójijì ni àwọn apanirun yóò kọlù wá.
Oe! Ka tami canunaw voi, buri kâkhu awh nateh, vaiphu dawk kamawp awh nateh, capa buet touh dueng kadout e ka khai e patetlah kap awh. Bangkongtetpawiteh, vaitalahoi karaphoekung teh maimae lathueng a pha han toe.
27 “Èmi ti fi ẹ́ ṣe ẹni tí yóò máa yọ́ irú àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bi irin tútù, kí wọn kí ó lè ṣe àkíyèsí, kí ó sì dán ọ̀nà wọn wò.
Ka taminaw katanoukkung hoi pakhingpalang hanelah na sak, telah pawiteh doeh ahnimae nuencang hah na pathoup thai awh tih.
28 Ọlọ́tẹ̀ tí ọkàn rẹ̀ le ní gbogbo wọn. Wọ́n ń lọ káàkiri láti sọ̀rọ̀-òdì. Wọ́n jẹ́ idẹ àti irin, wọ́n sì kún fún ìwà ìbàjẹ́.
Ahnimouh teh a lungpata awh ni teh tarankathaw e, tamthoe kadeinaw doeh, rahum hoi sum patetlah ao awh teh, abuemlahoi kahawihoehe dueng katâcawtkhaikung lah ao awh.
29 Ewìrì a fẹ́ná kíkankíkan, kí ó lè yọ́ òjé, ẹni tí ń yọ́ ọ ń yọ́ ọ lásán; a kò si ya ènìyàn búburú kúrò.
Konlawk hai hmai dawk a kahma toe, hmaipho hai a tum toe. Tamikathoutnaw teh kangcing awh roeroe hoeh rah.
30 A pè wọ́n ní fàdákà tí a kọ̀sílẹ̀, nítorí Olúwa ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀.”
Hotnaw teh BAWIPA ni a pahnawt toung dawkvah, ayânaw ni nguneinaw telah ati pouh awh han, telah ati.

< Jeremiah 6 >