< Jeremiah 51 >

1 Ohùn ti Olúwa wí nìyìí: “Wò ó èmi yóò ru afẹ́fẹ́ apanirun sókè sí Babeli àti àwọn ènìyàn Lebikamai,
Tako govori Gospod: »Glej, vzdignil se bom zoper Babilon in zoper tiste, ki prebivajo v njihovi sredi, ki se vzdigujejo zoper mene, rušilni veter.
2 Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn sí Babeli láti fẹ́ ẹ, tí yóò sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di òfo; wọn yóò takò ó ní gbogbo ọ̀nà ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.
V Babilon bom poslal prepihovalce, ki ga bodo prevejáli in izpraznili bodo njegovo deželo, kajti v dnevu stiske bodo zoper njega naokoli.
3 Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀, jáde tàbí kí ó di ìhámọ́ra rẹ̀. Má ṣe dá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sí; pátápátá ni kí o pa àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
Zoper tistega, ki napenja, naj lokostrelec napne svoj lok in zoper tistega, ki se dviguje v svojem oklepu in ne prizanašajte njegovim mladeničem. Popolnoma uničite vso njegovo vojsko.
4 Gbogbo wọn ni yóò ṣubú ní Babeli, tí wọn yóò sì fi ara pa yánnayànna ní òpópónà.
Tako bodo umorjeni padli v deželi Kaldejcev in tisti, ki so prebodeni, na njegovih ulicah.
5 Nítorí pé Juda àti Israẹli ni Ọlọ́run wọn tí í ṣe Olúwa àwọn ọmọ-ogun, kò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọn kún fún kìkì ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Israẹli.
Kajti Izrael ni bil pozabljen niti Juda od svojega Boga, od Gospoda nad bojevniki; čeprav je bila njihova dežela napolnjena z grehom zoper Svetega Izraelovega.
6 “Sá kúrò ní Babeli! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Àsìkò àti gbẹ̀san Olúwa ni èyí; yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.
Bežite iz srede Babilona in osvobodite vsakdo svojo dušo. Ne bodite odrezani v njegovi krivičnosti, kajti to je čas Gospodovega maščevanja; on mu bo povrnil povračilo.
7 Ife wúrà ni Babeli ní ọwọ́ Olúwa; ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí. Gbogbo orílẹ̀-èdè mu ọtí rẹ̀, wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.
Babilon je bil zlata čaša v Gospodovi roki, ki je vso zemljo opijanil. Narodi so pili od njegovega vina; zato so narodi besni.
8 Babeli yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́. Ẹ hu fun un! Ẹ mú ìkunra fún ìrora rẹ, bóyá yóò le wo ọ́ sàn.
Babilon je nenadoma padel in bil uničen. Tulite za njim; vzemite balzam za njegovo bolečino, če bo tako, da bi bil lahko ozdravljen.
9 “‘À bá ti wo Babeli sàn, ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀, kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè, ó ga àní títí dé òfúrufú.’
Ozdravili bi Babilon, toda ta ni ozdravljen. Zapustite ga in naj gremo vsak v svojo lastno deželo, kajti njegova sodba sega do nebes in povzdignjen je gor, celó do neba.
10 “‘Olúwa ti dá wa láre, wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Sioni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa ti ṣe.’
Gospod je privedel našo pravičnost. Pridite, razglasimo na Sionu delo Gospoda, našega Boga.
11 “Ṣe ọfà rẹ ní mímú, mú àpáta! Olúwa ti ru ọba Media sókè, nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Babeli run. Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
Puščice naredi svetle; zberi ščite. Gospod je vzdignil duha medijskih kraljev, kajti njegov naklep je zoper Babilon, da ga uniči, kajti to je to maščevanje od Gospoda, maščevanje od njegovega templja.
12 Gbé àsíá sókè sí odi Babeli! Ẹ ṣe àwọn ọmọ-ogun gírí, ẹ pín àwọn olùṣọ́ káàkiri, ẹ ṣètò àwọn tí yóò sá pamọ́ Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde, òfin rẹ̀ sí àwọn ará Babeli.
Postavi prapor na zidove Babilona, okrepi stražo, postavi stražarje, pripravi zasede, kajti Gospod je tako zasnoval in storil to, kar je govoril, zoper prebivalce Babilona.
13 Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀, tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé, àní àsìkò láti ké ọ kúrò!
Oh ti, ki prebivaš nad mnogimi vodami, obilen v zakladih, tvoj konec je prišel in mera tvoje pohlepnosti.
14 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀, Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú, wọn yóò yọ ayọ̀, ìṣẹ́gun lórí rẹ.
Gospod nad bojevniki je prisegel pri samem sebi, rekoč: »Zagotovo te bom napolnil z ljudmi kakor z gosenicami; in vzdignili bodo krik zoper tebe.
15 “Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀, o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.
Zemljo je naredil s svojo močjo, zemeljski [krog] je utrdil s svojo modrostjo in nebesa razprostrl s svojo razumnostjo.
16 Nígbà tí ará omi ọ̀run hó ó mú kí òfúrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.
Kadar on izusti svoj glas, je na nebu množica vodá; in on povzroča meglicam, da se vzdignejo od koncev zemlje. On dela bliske z dežjem in prinaša veter iz svojih zakladnic.
17 “Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọ tí kò sì ní ìmọ̀, olúkúlùkù alágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀. Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn; wọn kò ní èémí nínú.
Vsak mož je s svojim spoznanjem brutalen, vsak livar je osramočen z rezano podobo, kajti njegova ulita podoba je neresnica in ni diha v njih.
18 Asán ni wọ́n, àti iṣẹ́ ìsìnà, nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn ó ṣègbé.
Te so ničevosti, delo zmot. V času njihovega obiskanja bodo izginile.
19 Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jakọbu kó rí bí ìwọ̀nyí; nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo, àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Jakobov delež ni enak njihovemu; kajti on je tvorec vseh stvari, in Izrael je palica njegove dediščine. Gospod nad bojevniki je njegovo ime.
20 “Ìwọ ni kùmọ̀ ogun ohun èlò ogun mi, ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀-èdè túútúú, èmi ó bà àwọn ilé ọba jẹ́.
Ti si moja bojna sekira in bojna orožja, kajti s teboj bom narode razbil na koščke in s teboj bom uničil kraljestva;
21 Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀; èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lú èmi ó pa awakọ̀,
in s teboj bom razbil na koščke konja in njegovega jezdeca; in s teboj bom razbil na koščke bojni voz in njegovega voznika;
22 pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin, pẹ̀lú rẹ, mo pa àgbàlagbà àti ọmọdé, pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.
s teboj bom razbil na koščke moškega in žensko; in s teboj bom razbil na koščke starega in mladega; in s teboj bom razbil na koščke mladeniča in deklo;
23 Èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ olùṣọ́-àgùntàn, àti agbo àgùntàn rẹ̀ túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ àgbẹ̀ àti àjàgà màlúù túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ túútúú.
prav tako bom s teboj razbil na koščke pastirja in njegov trop; in s teboj bom razbil na koščke poljedelca in njegov jarem volov; in s teboj bom razbil na koščke poveljnike in vladarje.
24 “Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Babeli àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Sioni,” ni Olúwa wí.
In povrnil bom Babilonu in vsem prebivalcem Kaldeje vse njihovo zlo, ki so ga storili na Sionu v vašem pogledu, ‹ govori Gospod.
25 “Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirun ìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,” ni Olúwa wí. “Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ, èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta, Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.
›Glej, jaz sem zoper tebe, oh uničujoča gora, ‹ govori Gospod, ›ki uničuješ vso zemljo. Svojo roko bom iztegnil nadte in te zvalil dol iz skal in te naredil požgano goro.
26 A kò ní mú òkúta kankan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbí fún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò di ahoro títí ayé,” ní Olúwa wí.
In ne bodo vzeli od tebe kamna za temeljni kamen niti kamna za temelje; temveč boš zapuščena na veke, ‹ govori Gospod.
27 “Gbé àsíá sókè ní ilẹ̀ náà! Fọn ìpè láàrín àwọn orílẹ̀-èdè! Sọ àwọn orílẹ̀-èdè di mímọ́ sórí rẹ̀, pe àwọn ìjọba yìí láti dojúkọ ọ́: Ararati, Minini àti Aṣkenasi. Yan olùdarí ogun láti kọlù ú, rán àwọn ẹṣin sí i bí ọ̀pọ̀ eṣú.
Postavite prapor v deželi, zatrobite na šofar med narodi, pripravite narode zoper njega, skličite skupaj zoper njega kraljestva Ararát, Miní in Aškenáz; določite poveljnika zoper njega; naredite konjem, da pridejo gor kakor dlakave gosenice.
28 Sọ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú àwọn ọba Media di mímọ́ sórí rẹ̀, àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ ọba lé lórí.
Pripravite zoper njega narode s kralji iz Medije, njihove poveljnike, vse njihove vladarje in vso deželo njegovega gospostva.
29 Ilẹ̀ wárìrì síyìn-ín sọ́hùn-ún, nítorí pé ète Olúwa, sí Babeli dúró, láti ba ilẹ̀ Babeli jẹ́ lọ́nà tí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.
In dežela bo trepetala in tarnala, kajti vsak Gospodov namen zoper Babilon se bo izpolnil, da stori babilonsko deželo opustošenje brez prebivalca.
30 Gbogbo àwọn jagunjagun Babeli tó dáwọ́ ìjà dúró sínú àgọ́ wọn. Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin. Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun, gbogbo irin ẹnu-ọ̀nà wọn ti di fífọ́.
Mogočni babilonski možje so se prenehali bojevati, ostali so v svojih utrdbah. Njihova moč je odpovedala; postali so kakor ženske. Požgali so njegova bivališča; njegovi zapahi so zlomljeni.
31 Ìránṣẹ́ kan ń tẹ̀lé òmíràn láti sọ fún ọba Babeli pé gbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.
En tekač bo tekel, da sreča drugega in en poslanec, da sreča drugega, da pokaže babilonskemu kralju, da je njegovo mesto zavzeto na enem koncu
32 Odò tí ó sàn kọjá kò sàn mọ́ ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”
in da so prehodi osvojeni in trstje so požgali z ognjem in bojevniki so zgroženi.‹
33 Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli sọ nìyìí: “Ọmọbìnrin Babeli dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”
Kajti tako govori Gospod nad bojevniki, Izraelov Bog: ›Babilonska hči je podobna mlatišču, čas je, da jo mlatijo, vendar še malo in čas njene žetve bo prišel.
34 “Nebukadnessari ọba Babeli tó jẹ wá run, ó ti mú kí ìdààmú bá wa, ó ti sọ wá di àgbá òfìfo. Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì. Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀, lẹ́yìn náà ni ó pọ̀ wá jáde.
Babilonski kralj Nebukadnezar me je požrl, zdrobil me je, naredil me je za prazno posodo, požrl me je kakor zmaj, svoj trebuh je napolnil z mojimi posladki, vrgel me je ven.
35 Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe sí ẹran-ara wa wà lórí Babeli,” èyí tí àwọn ibùgbé Sioni wí. “Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogbo àwọn tí ń gbé Babeli,” ni Jerusalẹmu wí.
›Nasilje, storjeno meni in mojemu mesu, naj bo nad Babilonom; ‹ bo rekel prebivalec Siona in moja kri nad prebivalci Kaldeje, bo rekla [prestolnica] Jeruzalem.
36 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lórí ohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san, èmi yóò mú kí omi Òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.
Zato tako govori Gospod: ›Glej, jaz bom zagovarjal tvojo pravdo in se zate maščeval; posušil bom njegovo morje in posušil njegove izvire.
37 Babeli yóò parun pátápátá, yóò sì di ihò àwọn akátá, ohun ẹ̀rù àti àbùkù, ibi tí ènìyàn kò gbé.
In Babilon bo spremenjen v razvaline, bivališče za zmaje, osuplost in posmeh, brez prebivalca.
38 Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramù bí ọmọ kìnnìún.
Skupaj bodo rjoveli kakor levi. Kričali bodo kakor levji mladiči.
39 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè, èmi yóò ṣe àsè fún wọn, èmi yóò jẹ́ kí wọn mutí yó tí wọn yóò máa kọ fun ẹ̀rín, lẹ́yìn náà, wọn yóò sun oorun, wọn kì yóò jí,” ni Olúwa wí.
V njihovi vročini bom naredil njihove praznike in jaz jih bom opijanil, da se bodo lahko veselili in zaspali nenehno spanje in se ne bodo zbudili, ‹ govori Gospod.
40 “Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn tí a fẹ́ pa, gẹ́gẹ́ bí àgbò àti ewúrẹ́.
›Privedel jih bom dol kakor jagnjeta h klanju, kakor ovne s kozli.
41 “Báwo ni Ṣeṣaki yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé. Irú ìpayà wo ni yóò bá Babeli láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!
Kako je Šešáh zajet! In kako je hvala celotne zemlje presenečena! Kako je Babilon postal osuplost med narodi!
42 Òkun yóò ru borí Babeli, gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Babeli.
Morje se je vzdignilo nad Babilon. Pokrit je z množico njegovih valov.
43 Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro, ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.
Njegova mesta so opustošenje, suha dežela in divjina, dežela, v kateri noben človek ne prebiva niti katerikoli človeški sin tam ne gre skozi.
44 Èmi yóò fi ìyà jẹ Beli ti Babeli àti pé èmi yóò jẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì. Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò jùmọ̀ sàn lọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ mọ́. Ní òótọ́ odi Babeli yóò sì wó.
V Babilonu bom kaznoval Bela in iz njegovih ust bom osvobodil to, kar je požrl. Narodi se ne bodo več stekali k njemu. Da, babilonsko obzidje bo padlo.
45 “Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ ẹ̀yin ènìyàn mi! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Sá fún ìbínú ńlá Olúwa.
Moje ljudstvo, pojdite ven iz njegove srede in osvobodite vsak človek svojo dušo pred kruto Gospodovo jezo.
46 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrú tàbí kí o bẹ̀rù nígbà tí a bá gbọ́ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa; àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí, òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipá ní ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.
In da ne bi vaše srce oslabelo in se boste bali zaradi govorice, ki jo bo slišati v deželi; govorica, bo tako prišla v enem letu in potem bo v drugem letu prišla govorica in nasilje v deželi, vladar zoper vladarja.
47 Nítorí ìgbà náà yóò wá dandan nígbà tí èmi yóò fi ìyà jẹ àwọn òrìṣà Babeli; gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó dójútì gbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárín rẹ̀.
Zatorej glejte, prihajajo dnevi, ko bom naredil sodbo nad rezanimi podobami Babilona in njegova celotna dežela bo zbegana in vsi njegovi umorjeni bodo padli v njegovi sredi.
48 Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn, yóò sì kọrin lórí Babeli: nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,” ni Olúwa wí.
Potem bodo nebo in zemlja in vse, kar je na njej, peli zaradi Babilona, kajti plenilci bodo prišli k njemu iz severa, ‹ govori Gospod.
49 “Babiloni gbọdọ̀ ṣubú nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni Israẹli, gẹ́gẹ́ bí àwọn ti a pa ní gbogbo ayé nítorí Babeli.
›Kakor je Babilon storil umorjenim iz Izraela, da padejo, tako bodo pri Babilonu padli umorjeni iz vse zemlje.
50 Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró. Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè, ẹ sì jẹ́ kí Jerusalẹmu wá sí ọkàn yín.”
Vi, ki ste pobegnili meču, pojdite proč, ne stojte pri miru. Spomnite se Gospoda od daleč in Jeruzalem naj pride v vaše misli.
51 “Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn: ìtìjú ti bò wá lójú nítorí àwọn àjèjì wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”
Zbegani smo, ker smo slišali grajo. Sramota je pokrila naše obraze, kajti tujci so prišli v svetišča Gospodove hiše.
52 “Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fínfín rẹ̀, àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa kérora já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀.
Zato, glejte, prihajajo dnevi, ‹ govori Gospod, da bom naredil sodbo nad njegovimi rezanimi podobami, in po vsej njegovi deželi bodo ranjeni stokali.
53 Bí Babeli tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run, bí ó sì ṣe ìlú olódi ní òkè agbára rẹ, síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,” ní Olúwa wí.
Čeprav bi se Babilon povzpel do neba in četudi bi utrdil višino svoje moči, vendar bodo od mene prišli k njemu plenitelji, ‹ govori Gospod.
54 “Ìró igbe láti Babeli, àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kaldea!
Zvok krika prihaja iz Babilona in velika poguba od dežele Kaldejcev,
55 Nítorí pé Olúwa ti ṣe Babeli ní ìjẹ, ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀; àwọn ọ̀tá wọn sì ń hó bi omi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.
ker je Gospod oplenil Babilon in iz njega uničil močan glas; ko njegovi valovi rjovijo kakor velike vode, je izusten hrup njihovega glasu,
56 Nítorí pé afiniṣèjẹ dé sórí rẹ̀, àní sórí Babeli; a mú àwọn akọni rẹ̀, a ṣẹ́ gbogbo ọrun wọn: nítorí Ọlọ́run ẹ̀san ni Olúwa, yóò san án nítòótọ́.
ker je plenilec prišel nadenj, celó nad Babilon in so njegovi mogočni možje zajeti, vsak izmed njihovih lokov je zlomljen, kajti Gospod Bog povračil bo zagotovo poplačal.
57 Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí, àti àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀ àti àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti àwọn akọni rẹ̀, wọn ó sì sun oorun láéláé, wọn kì ó sì jí mọ́,” ní ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Opijanil bom njegove prince, njegove modre može, njegove poveljnike, njegove vladarje ter njegove mogočne može in spali bodo neprestano spanje in ne bodo se zbudili, ‹ govori kralj, katerega ime je Gospod nad bojevniki.
58 Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Odi Babeli gbígbòòrò ní a ó wó lulẹ̀ pátápátá, ẹnu-bodè gíga rẹ̀ ní a ó sì fi iná sun: tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn ti ṣiṣẹ́ lásán, àti àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣiṣẹ́ fún iná, tí àárẹ̀ sì mú wọn.”
Tako govori Gospod nad bojevniki: ›Široki zidovi Babilona bodo popolnoma porušeni in njegova visoka velika vrata bodo sežgana z ognjem; in ljudstvo se bo zaman trudilo in narod v ognju in izmučeni bodo.‹«
59 Ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì pàṣẹ fún Seraiah, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, nígbà tí o ń lọ ni ti Sedekiah, ọba Juda, sí Babeli ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Seraiah yìí sì ní ìjòyè ibùdó.
Beseda, ki jo je prerok Jeremija zapovedal Serajáju, Nerijájevemu sinu, Maasejájevemu sinu, ko je s Sedekíjem, Judovim kraljem, odšel v Babilon, v četrtem letu njegovega kraljevanja. In ta Serajá je bil tih princ.
60 Jeremiah sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Babeli sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí a kọ sí Babeli.
Tako je Jeremija zapisal v knjigo vse zlo, ki naj bi prišlo nad Babilon, celó vse te besede, ki so zapisane zoper Babilon.
61 Jeremiah sì sọ fún Seraiah pé, “Nígbà tí ìwọ bá dé Babeli, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
Jeremija je rekel Serajáju: »Ko prideš v Babilon in boš videl in boš bral vse te besede;
62 Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’
potem boš rekel: »Oh Gospod, ti si govoril zoper ta kraj, da ga odrežeš, da nihče ne bo ostal v njem niti človek niti žival, temveč da bo ta zapuščen na veke.
63 Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárín odò Eufurate.
In zgodilo se bo, ko narediš konec branju te knjige, da boš k njej privezal kamen in jo vrgel v sredo Evfrata
64 Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Babeli yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’” Títí dé ìhín ni ọ̀rọ̀ Jeremiah.
in rekel boš: ›Tako bo Babilon potonil in ne bo se vzdignil od zla, ki ga bom privedel nadenj in izmučeni bodo.‹« Do tu so Jeremijeve besede.

< Jeremiah 51 >