< Jeremiah 51 >

1 Ohùn ti Olúwa wí nìyìí: “Wò ó èmi yóò ru afẹ́fẹ́ apanirun sókè sí Babeli àti àwọn ènìyàn Lebikamai,
Itsho njalo iNkosi: Khangela ngizavusela iBhabhiloni lalabo abahlala enhliziyweni yalabo abangivukelayo umoya ochithayo.
2 Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn sí Babeli láti fẹ́ ẹ, tí yóò sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di òfo; wọn yóò takò ó ní gbogbo ọ̀nà ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.
Ngithume eBhabhiloni abelayo, abazakuyela, bathulule ilizwe layo, ngoba bazamelana layo bevela inhlangothi zonke ngosuku lobubi.
3 Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀, jáde tàbí kí ó di ìhámọ́ra rẹ̀. Má ṣe dá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sí; pátápátá ni kí o pa àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
Kakuthi otshokayo agobise idandili lakhe emelene loligobisayo, njalo emelene loziphakamisayo ebhatshini lakhe lensimbi; njalo lingawayekeli amajaha ayo, lilitshabalalise ibutho layo lonke.
4 Gbogbo wọn ni yóò ṣubú ní Babeli, tí wọn yóò sì fi ara pa yánnayànna ní òpópónà.
Ngokunjalo ababuleweyo bazakuwa elizweni lamaKhaladiya, labagwazwe ezitaladeni zayo.
5 Nítorí pé Juda àti Israẹli ni Ọlọ́run wọn tí í ṣe Olúwa àwọn ọmọ-ogun, kò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọn kún fún kìkì ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Israẹli.
Ngoba uIsrayeli kayikutshiywa, loJuda nguNkulunkulu wabo, yiNkosi yamabandla, lanxa ilizwe labo ligcwele icala koNgcwele kaIsrayeli.
6 “Sá kúrò ní Babeli! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Àsìkò àti gbẹ̀san Olúwa ni èyí; yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.
Balekani liphume phakathi kweBhabhiloni, likhulule ngulowo lalowo umphefumulo wakhe; lingaqunywa esiphambekweni sayo; ngoba lesi yisikhathi sempindiselo yeNkosi, ophindisela impindiselo kuyo.
7 Ife wúrà ni Babeli ní ọwọ́ Olúwa; ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí. Gbogbo orílẹ̀-èdè mu ọtí rẹ̀, wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.
IBhabhiloni yayiyinkezo yegolide esandleni seNkosi, eyayidakisa umhlaba wonke; izizwe zanatha okwewayini layo; ngenxa yalokho izizwe zahlanya.
8 Babeli yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́. Ẹ hu fun un! Ẹ mú ìkunra fún ìrora rẹ, bóyá yóò le wo ọ́ sàn.
IBhabhiloni yahle yawa, yephuka; qhinqani isililo ngayo, lithathele ubuhlungu bayo ibhalisamu, mhlawumbe ingelatshwa.
9 “‘À bá ti wo Babeli sàn, ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀, kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè, ó ga àní títí dé òfúrufú.’
Besingayelapha iBhabhiloni, kodwa kayelaphekanga; itshiyeni, asihambeni ngulowo lalowo aye elizweni lakhe; ngoba isigwebo sayo sifinyelele emazulwini, siphakanyisiwe kwaze kwafika esibhakabhakeni.
10 “‘Olúwa ti dá wa láre, wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Sioni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa ti ṣe.’
INkosi ikhuphe ukulunga kwethu; wozani, silandise eZiyoni umsebenzi weNkosi uNkulunkulu wethu.
11 “Ṣe ọfà rẹ ní mímú, mú àpáta! Olúwa ti ru ọba Media sókè, nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Babeli run. Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
Lolani imitshoko, liqoqe izihlangu; iNkosi ivusile umoya wamakhosi amaMede; ngoba icebo layo limelene leBhabhiloni ukuyichitha; ngoba lokho kuyimpindiselo yeNkosi, impindiselo yethempeli layo.
12 Gbé àsíá sókè sí odi Babeli! Ẹ ṣe àwọn ọmọ-ogun gírí, ẹ pín àwọn olùṣọ́ káàkiri, ẹ ṣètò àwọn tí yóò sá pamọ́ Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde, òfin rẹ̀ sí àwọn ará Babeli.
Phakamisani isiboniso phezu kwemiduli yeBhabhiloni, liqinise ukulinda, libeke abalindi, lilungise abacathami, ngoba iNkosi isikucebile, futhi izakwenza lokho ekukhulume ngabahlali beBhabhiloni.
13 Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀, tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé, àní àsìkò láti ké ọ kúrò!
Wena ohlala emanzini amanengi, owande ngamagugu, ukuphela kwakho sekufikile, isilinganiso senzuzo yakho embi.
14 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀, Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú, wọn yóò yọ ayọ̀, ìṣẹ́gun lórí rẹ.
INkosi yamabandla ifungile ngomphefumulo wayo yathi: Isibili ngizakugcwalisa ngabantu njengamacimbi, njalo bazahlabelela umkhosi ngawe.
15 “Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀, o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.
Wenza umhlaba ngamandla akhe, walimisa ilizwe ngenhlakanipho yakhe, langokuqedisisa kwakhe wendlala amazulu.
16 Nígbà tí ará omi ọ̀run hó ó mú kí òfúrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.
Lapho ekhupha ilizwi lakhe, kulokuhlokoma kwamanzi amanengi emazulwini, ukhuphula inkungu ivela emkhawulweni womhlaba, enze imibane kanye lezulu, akhuphe umoya eziphaleni zakhe.
17 “Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọ tí kò sì ní ìmọ̀, olúkúlùkù alágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀. Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn; wọn kò ní èémí nínú.
Wonke umuntu uyisiphukuphuku kalalwazi; wonke umkhandi wegolide uyangiswa yisithombe esibaziweyo, ngoba isithombe sakhe esibunjwe ngokuncibilikisa siyinkohliso, njalo kakulamoya kuzo.
18 Asán ni wọ́n, àti iṣẹ́ ìsìnà, nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn ó ṣègbé.
Ziyize, umsebenzi wezinkohliso; ngesikhathi sokuhanjelwa kwazo zizabhubha.
19 Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jakọbu kó rí bí ìwọ̀nyí; nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo, àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Isabelo sikaJakobe kasinjengazo; ngoba yena nguye umbumbi wakho konke, loIsrayeli uyintonga yelifa lakhe; iNkosi yamabandla libizo lakhe.
20 “Ìwọ ni kùmọ̀ ogun ohun èlò ogun mi, ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀-èdè túútúú, èmi ó bà àwọn ilé ọba jẹ́.
Wena uyinduku yami yempi, izikhali zempi; ngoba ngawe ngizaphahlaza izizwe, langawe ngichithe imibuso,
21 Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀; èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lú èmi ó pa awakọ̀,
langawe ngiphahlaze ibhiza lomgadi walo, langawe ngiphahlaze inqola lomkhweli wayo,
22 pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin, pẹ̀lú rẹ, mo pa àgbàlagbà àti ọmọdé, pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.
langawe ngiphahlaze indoda lowesifazana, langawe ngiphahlaze ixhegu lomutsha, langawe ngiphahlaze ijaha lentombi,
23 Èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ olùṣọ́-àgùntàn, àti agbo àgùntàn rẹ̀ túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ àgbẹ̀ àti àjàgà màlúù túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ túútúú.
langawe ngiphahlaze umelusi lomhlambi wakhe, langawe ngiphahlaze umlimi lesipani sakhe, langawe ngiphahlaze ababusi lezinduna.
24 “Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Babeli àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Sioni,” ni Olúwa wí.
Njalo ngizayiphindisela iBhabhiloni labo bonke abahlali beKhaladiya konke okubi kwabo abakwenzileyo eZiyoni emehlweni enu, itsho iNkosi.
25 “Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirun ìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,” ni Olúwa wí. “Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ, èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta, Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.
Khangela, ngimelana lawe, wena ntaba echithayo, itsho iNkosi, echitha umhlaba wonke; ngizakwelulela isandla sami kuwe, ngikugiqe usuke emadwaleni, ngikwenze ube yintaba yokutshiswa.
26 A kò ní mú òkúta kankan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbí fún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò di ahoro títí ayé,” ní Olúwa wí.
Njalo kabayikuthatha kuwe ilitshe libe ngelengonsi, lelitshe libe ngelezisekelo; ngoba uzakuba ngamanxiwa aphakade, itsho iNkosi.
27 “Gbé àsíá sókè ní ilẹ̀ náà! Fọn ìpè láàrín àwọn orílẹ̀-èdè! Sọ àwọn orílẹ̀-èdè di mímọ́ sórí rẹ̀, pe àwọn ìjọba yìí láti dojúkọ ọ́: Ararati, Minini àti Aṣkenasi. Yan olùdarí ogun láti kọlù ú, rán àwọn ẹṣin sí i bí ọ̀pọ̀ eṣú.
Phakamisani isiboniso elizweni, livuthele uphondo phakathi kwezizwe, lilungise izizwe ukumelana layo, liyibizele ndawonye imibuso yeArarathi, iMini, leAshikenazi; libeke umlawuli webutho emelene layo, lenyuse amabhiza njengentethe ezimaxhakaxhaka.
28 Sọ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú àwọn ọba Media di mímọ́ sórí rẹ̀, àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ ọba lé lórí.
Lungisani izizwe ukumelana layo, amakhosi amaMede, induna zayo, lababusi bayo bonke, lelizwe lonke lombuso wayo.
29 Ilẹ̀ wárìrì síyìn-ín sọ́hùn-ún, nítorí pé ète Olúwa, sí Babeli dúró, láti ba ilẹ̀ Babeli jẹ́ lọ́nà tí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.
Lelizwe lizazamazama libe lobuhlungu, ngoba ngalinye lamacebo eNkosi lima limelene leBhabhiloni, ukwenza ilizwe leBhabhiloni libe yincithakalo engelamhlali.
30 Gbogbo àwọn jagunjagun Babeli tó dáwọ́ ìjà dúró sínú àgọ́ wọn. Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin. Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun, gbogbo irin ẹnu-ọ̀nà wọn ti di fífọ́.
Amaqhawe eBhabhiloni ayekele ukulwa, ahlala ezinqabeni, amandla awo aphelile, sebengabesifazana; bathungele indawo zayo zokuhlala, imigoqo yayo yephukile.
31 Ìránṣẹ́ kan ń tẹ̀lé òmíràn láti sọ fún ọba Babeli pé gbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.
Isigijimi sizagijima ukuhlangana lesigijimi, lombiki ukuhlangana lombiki, ukutshela inkosi yeBhabhiloni ukuthi umuzi wayo uthunjiwe kusukela ekucineni,
32 Odò tí ó sàn kọjá kò sàn mọ́ ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”
lamazibuko abanjiwe, lamaxhaphozi atshiswe ngomlilo, lamadoda empi ethukile.
33 Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli sọ nìyìí: “Ọmọbìnrin Babeli dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”
Ngoba itsho njalo iNkosi yamabandla, uNkulunkulu kaIsrayeli: Indodakazi yeBhabhiloni injengebala lokubhulela; kuyisikhathi sokuyinyathela; kuseyisikhatshana, lesikhathi sesivuno sizafika kuyo.
34 “Nebukadnessari ọba Babeli tó jẹ wá run, ó ti mú kí ìdààmú bá wa, ó ti sọ wá di àgbá òfìfo. Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì. Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀, lẹ́yìn náà ni ó pọ̀ wá jáde.
UNebhukadirezari inkosi yeBhabhiloni ungidlile, ungichobozile; wangibeka ngaba yimbiza engelalutho, wangiginya njengomgobho, wagcwalisa isisu sakhe ngezibondlo zami, wangixotsha.
35 Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe sí ẹran-ara wa wà lórí Babeli,” èyí tí àwọn ibùgbé Sioni wí. “Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogbo àwọn tí ń gbé Babeli,” ni Jerusalẹmu wí.
Udlakela lwami lolwenyama yami kube phezu kweBhabhiloni, utsho umhlalikazi weZiyoni; legazi lami libe phezu kwabahlali beKhaladiya, itsho iJerusalema.
36 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lórí ohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san, èmi yóò mú kí omi Òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.
Ngakho itsho njalo iNkosi: Khangela, ngizalumela udaba lwakho, ngiphindisele impindiselo yakho; ngomise ulwandle lwayo, ngenze umthombo wayo wome.
37 Babeli yóò parun pátápátá, yóò sì di ihò àwọn akátá, ohun ẹ̀rù àti àbùkù, ibi tí ènìyàn kò gbé.
LeBhabhiloni izakuba ngamadundulu, indawo yokuhlala yemigobho, isesabiso, lento yokuncifelwa, kungelamhlali.
38 Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramù bí ọmọ kìnnìún.
Bazabhonga kanyekanye njengamabhongo ezilwane, bahwabhe njengemidlwane yezilwane.
39 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè, èmi yóò ṣe àsè fún wọn, èmi yóò jẹ́ kí wọn mutí yó tí wọn yóò máa kọ fun ẹ̀rín, lẹ́yìn náà, wọn yóò sun oorun, wọn kì yóò jí,” ni Olúwa wí.
Ekutshisekeni kwabo ngizabenzela amadili, ngibadakise ukuze bathokoze, balale ubuthongo obulaphakade, bangavuki, itsho iNkosi.
40 “Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn tí a fẹ́ pa, gẹ́gẹ́ bí àgbò àti ewúrẹ́.
Ngizabehlisa njengamawundlu ekuhlatshweni, njengezinqama kanye lezimpongo.
41 “Báwo ni Ṣeṣaki yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé. Irú ìpayà wo ni yóò bá Babeli láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!
Ithunjwe njani iSheshaki; yebo, lubanjiwe udumo lomhlaba wonke! IBhabhiloni isibe njani yisesabiso phakathi kwezizwe!
42 Òkun yóò ru borí Babeli, gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Babeli.
Ulwandle lukhukhumele phezu kweBhabhiloni, isibekelwe ngobunengi bamagagasi alo.
43 Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro, ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.
Imizi yayo isingamanxiwa, ilizwe elomileyo, lenkangala, ilizwe okungahlali muntu kulo, okungadluli kulo indodana yomuntu.
44 Èmi yóò fi ìyà jẹ Beli ti Babeli àti pé èmi yóò jẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì. Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò jùmọ̀ sàn lọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ mọ́. Ní òótọ́ odi Babeli yóò sì wó.
Njalo ngizajezisa uBheli eBhabhiloni, ngikhuphe emlonyeni wakhe lokho akuginyileyo; lezizwe kazisayikujulukela kuyo; yebo, umduli weBhabhiloni uwile.
45 “Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ ẹ̀yin ènìyàn mi! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Sá fún ìbínú ńlá Olúwa.
Phumani phakathi kwayo, bantu bami, likhulule ngulowo lalowo umphefumulo wakhe ekuvutheni kolaka lweNkosi.
46 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrú tàbí kí o bẹ̀rù nígbà tí a bá gbọ́ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa; àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí, òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipá ní ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.
Njalo hlezi inhliziyo yenu ibe buthakathaka, lesabe ngombiko ozwakala elizweni; ngoba kuzafika umbiko ngomunye umnyaka, lemva kwalokho umbiko ngomnyaka olandelayo, lodlakela elizweni, lombusi avukele umbusi.
47 Nítorí ìgbà náà yóò wá dandan nígbà tí èmi yóò fi ìyà jẹ àwọn òrìṣà Babeli; gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó dójútì gbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárín rẹ̀.
Ngakho khangela, insuku ziyeza lapho engizahambela izithombe ezibaziweyo zeBhabhiloni; lelizwe lonke layo lizayangeka, lababuleweyo bayo bonke bawele phakathi kwayo.
48 Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn, yóò sì kọrin lórí Babeli: nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,” ni Olúwa wí.
Kuzakuthi-ke amazulu lomhlaba lakho konke okukukho kuhlabelele ngeBhabhiloni, ngoba abachithi bazayifikela bevela enyakatho, itsho iNkosi.
49 “Babiloni gbọdọ̀ ṣubú nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni Israẹli, gẹ́gẹ́ bí àwọn ti a pa ní gbogbo ayé nítorí Babeli.
Njengalokhu iBhabhiloni yenza bawe ababuleweyo bakoIsrayeli, ngokunjalo ababuleweyo bomhlaba wonke bazakuwa eBhabhiloni.
50 Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró. Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè, ẹ sì jẹ́ kí Jerusalẹmu wá sí ọkàn yín.”
Lina eliphunyukileyo enkembeni, hambani, lingemi; khumbulani iNkosi lisekhatshana, leJerusalema ivele enhliziyweni yenu.
51 “Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn: ìtìjú ti bò wá lójú nítorí àwọn àjèjì wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”
Siyangekile ngoba sizwile ihlazo; inhloni zisibekele ubuso bethu, ngoba abezizwe sebefikile ezindaweni ezingcwele zendlu yeNkosi.
52 “Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fínfín rẹ̀, àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa kérora já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀.
Ngakho khangela, insuku ziyeza, itsho iNkosi, lapho engizahambela izithombe zayo ezibaziweyo; lakulo lonke ilizwe layo kuzabubula ogwaziweyo.
53 Bí Babeli tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run, bí ó sì ṣe ìlú olódi ní òkè agbára rẹ, síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,” ní Olúwa wí.
Loba iBhabhiloni ingaphakamela emazulwini, njalo loba ingaqinisa ukuphakama kwamandla ayo, kube kanti abachithi bazayifikela bevela kimi, itsho iNkosi.
54 “Ìró igbe láti Babeli, àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kaldea!
Kulomsindo wokukhala ovela eBhabhiloni, lokufohlela okukhulu elizweni lamaKhaladiya.
55 Nítorí pé Olúwa ti ṣe Babeli ní ìjẹ, ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀; àwọn ọ̀tá wọn sì ń hó bi omi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.
Ngoba iNkosi ichithile iBhabhiloni, yabhubhisa kuyo ilizwi elikhulu. Lapho amagagasi abo ahlokoma njengamanzi amanengi, umsindo wawo uzakhupha ilizwi.
56 Nítorí pé afiniṣèjẹ dé sórí rẹ̀, àní sórí Babeli; a mú àwọn akọni rẹ̀, a ṣẹ́ gbogbo ọrun wọn: nítorí Ọlọ́run ẹ̀san ni Olúwa, yóò san án nítòótọ́.
Ngoba umchithi wehlela phezu kwayo, phezu kweBhabhiloni, amaqhawe ayo azathunjwa, amadandili awo ephukile; ngoba iNkosi, uNkulunkulu wezimpindiselo, uzayivuza sibili.
57 Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí, àti àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀ àti àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti àwọn akọni rẹ̀, wọn ó sì sun oorun láéláé, wọn kì ó sì jí mọ́,” ní ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Ngizadakisa-ke iziphathamandla zayo, lezihlakaniphi zayo, ababusi bayo, lenduna zayo, lamaqhawe ayo; njalo bazalala ubuthongo obulaphakade, bangavuki, itsho iNkosi, obizo layo nguJehova wamabandla.
58 Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Odi Babeli gbígbòòrò ní a ó wó lulẹ̀ pátápátá, ẹnu-bodè gíga rẹ̀ ní a ó sì fi iná sun: tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn ti ṣiṣẹ́ lásán, àti àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣiṣẹ́ fún iná, tí àárẹ̀ sì mú wọn.”
Itsho njalo iNkosi yamabandla: Imiduli ebanzi yeBhabhiloni izadilizwa ngokupheleleyo, lamasango ayo aphakemeyo athungelwe ngomlilo, labantu batshikatshikele ize, lezizwe zitshikatshikele umlilo, zikhathale.
59 Ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì pàṣẹ fún Seraiah, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, nígbà tí o ń lọ ni ti Sedekiah, ọba Juda, sí Babeli ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Seraiah yìí sì ní ìjòyè ibùdó.
Ilizwi uJeremiya umprofethi alilaya uSeraya indodana kaNeriya, indodana kaMahaseya, ekuhambeni kwakhe loZedekhiya inkosi yakoJuda ukuya eBhabhiloni emnyakeni wesine wokubusa kwakhe. Njalo uSeraya wayeyisiphathamandla sokuthula.
60 Jeremiah sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Babeli sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí a kọ sí Babeli.
UJeremiya wasebhala egwalweni konke okubi okuzakwehlela iBhabhiloni, wonke lamazwi abhaliweyo emelene leBhabhiloni.
61 Jeremiah sì sọ fún Seraiah pé, “Nígbà tí ìwọ bá dé Babeli, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
UJeremiya wasesithi kuSeraya: Lapho usufikile eBhabhiloni, ubone ufunde wonke lamazwi.
62 Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’
Ubususithi: Nkosi, wena ukhulumile ngalindawo ukuthi uzayiquma, ukuze kungabi khona umhlali kiyo, kusukela emuntwini kusiya enyamazaneni, kodwa ibe zincithakalo phakade.
63 Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárín odò Eufurate.
Kuzakuthi-ke usuqedile ukulufunda lolugwalo, ubophele ilitshe kulo, uluphosele phakathi kweYufrathi,
64 Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Babeli yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’” Títí dé ìhín ni ọ̀rọ̀ Jeremiah.
ubususithi: Ngokunjalo iBhabhiloni izatshona, ingabe isavumbuluka, ngenxa yobubi engizayehlisela bona; njalo bazadinwa. Kuze kube lapha ngamazwi kaJeremiya.

< Jeremiah 51 >