< Jeremiah 51 >

1 Ohùn ti Olúwa wí nìyìí: “Wò ó èmi yóò ru afẹ́fẹ́ apanirun sókè sí Babeli àti àwọn ènìyàn Lebikamai,
Tā saka Tas Kungs: redzi, Es celšu maitātāja garu pret Bābeli un pret tiem, kas dzīvo Manu pretinieku serdē.
2 Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn sí Babeli láti fẹ́ ẹ, tí yóò sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di òfo; wọn yóò takò ó ní gbogbo ọ̀nà ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.
Un Es sūtīšu Bābelei vētītājus, kas tos vētīs un iztukšos viņas zemi, jo tie būs visapkārt ap viņu nelaimes dienā.
3 Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀, jáde tàbí kí ó di ìhámọ́ra rẹ̀. Má ṣe dá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sí; pátápátá ni kí o pa àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
Lai strēlnieks stopu uzvelk pret strēlnieku un pret to, kas lepojās savās krūšu bruņās. Un nežēlojiet viņas jaunekļus, izdeldiet visu viņas spēku,
4 Gbogbo wọn ni yóò ṣubú ní Babeli, tí wọn yóò sì fi ara pa yánnayànna ní òpópónà.
Ka nokauti krīt Kaldeju zemē un nodurti pa viņas ielām.
5 Nítorí pé Juda àti Israẹli ni Ọlọ́run wọn tí í ṣe Olúwa àwọn ọmọ-ogun, kò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọn kún fún kìkì ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Israẹli.
Jo Israēls un Jūda savā atraitnībā netaps pamesti no sava Dieva, Tā Kunga Cebaot, jebšu viņu zeme noziegusies pret to Svēto iekš Israēla.
6 “Sá kúrò ní Babeli! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Àsìkò àti gbẹ̀san Olúwa ni èyí; yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.
Bēdziet no Bābeles un izglābiet ikviens savu dvēseli, ka neejat bojā viņas noziegumā, jo šis ir Tā Kunga atriebšanas laiks, Viņš tai atmaksā algu.
7 Ife wúrà ni Babeli ní ọwọ́ Olúwa; ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí. Gbogbo orílẹ̀-èdè mu ọtí rẹ̀, wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.
Bābele bija zelta biķeris Tā Kunga rokā, kas piedzirdināja visu pasauli; tautas dzēra no viņas vīna, tāpēc tautas palika trakas.
8 Babeli yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́. Ẹ hu fun un! Ẹ mú ìkunra fún ìrora rẹ, bóyá yóò le wo ọ́ sàn.
Bābele ir piepeši kritusi un satriekta. Kauciet par viņu, ņemiet zāles viņas vātīm, varbūt tā taps dziedināta.
9 “‘À bá ti wo Babeli sàn, ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀, kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè, ó ga àní títí dé òfúrufú.’
Mēs Bābeli dziedinājām, bet tā nav sadzijusi. Atstājiet viņu, un ejam ikviens uz savu zemi, jo viņas sodība iet līdz pat debesīm un aizsniedz padebešus.
10 “‘Olúwa ti dá wa láre, wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Sioni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa ti ṣe.’
Tas Kungs ir gaismā nesis mūsu taisnību, nāciet, lai izteicam Ciānā Tā Kunga, sava Dieva, darbu.
11 “Ṣe ọfà rẹ ní mímú, mú àpáta! Olúwa ti ru ọba Media sókè, nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Babeli run. Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
Trinat bultas, sagrābiet bruņas; Tas Kungs pamodinājis Mēdiešu ķēniņu sirdi, jo Viņa padoms ir pret Bābeli, to samaitāt; jo šī ir Tā Kunga atriebšana, atriebšana Viņa nama dēļ.
12 Gbé àsíá sókè sí odi Babeli! Ẹ ṣe àwọn ọmọ-ogun gírí, ẹ pín àwọn olùṣọ́ káàkiri, ẹ ṣètò àwọn tí yóò sá pamọ́ Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde, òfin rẹ̀ sí àwọn ará Babeli.
Izceļat karogu uz Bābeles mūriem, vairojiet sargāšanu, ieceļat sargus, liekat karotājus slepenās vietās; jo Tas Kungs ir ko apņēmies un darīs arīdzan, ko Viņš runājis pret Bābeles iedzīvotājiem.
13 Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀, tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé, àní àsìkò láti ké ọ kúrò!
Tu, kas pie tā lielā ūdens dzīvo, kam daudz mantas, tavs gals nācis, un tavas mantas kārības mērs ir pilns.
14 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀, Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú, wọn yóò yọ ayọ̀, ìṣẹ́gun lórí rẹ.
Tas Kungs Cebaot ir zvērējis pie Savas dvēseles: “Lai gan Es tevi esmu pildījis ar cilvēkiem kā ar siseņiem; tomēr pret tevi dziedās prieka dziesmu.”
15 “Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀, o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.
Kas zemi radījis ar Savu spēku, kas pasauli iztaisījis ar Savu gudrību un debesis izpletis ar Savu saprašanu.
16 Nígbà tí ará omi ọ̀run hó ó mú kí òfúrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.
Kad viņa balss atskan, tad ūdeņi krāc debesīs; Viņš liek miglai celties no zemes galiem. Viņš dara zibeņus ar lietu un liek vējam ārā nākt no savām alām.
17 “Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọ tí kò sì ní ìmọ̀, olúkúlùkù alágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀. Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn; wọn kò ní èémí nínú.
Visi cilvēki paliek stulbi bez saprašanas, visi kausētāji top kaunā ar saviem tēliem; jo ko tie lej, ir meli, un dvašas tur nav.
18 Asán ni wọ́n, àti iṣẹ́ ìsìnà, nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn ó ṣègbé.
Tie ir nelietība un apsmejams darbs, piemeklēšanas laikā tie iet bojā.
19 Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jakọbu kó rí bí ìwọ̀nyí; nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo, àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Tā kā šie nav Jēkaba daļa, jo viņš ir visu lietu un savas tautas Radītājs, Kungs Cebaot ir viņa vārds.
20 “Ìwọ ni kùmọ̀ ogun ohun èlò ogun mi, ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀-èdè túútúú, èmi ó bà àwọn ilé ọba jẹ́.
Tu esi Mans veseris, Manas kara bruņas, un caur tevi Es sadauzu tautas, un caur tevi Es maitāju valstis,
21 Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀; èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lú èmi ó pa awakọ̀,
Un caur tevi Es sadauzu zirgu un viņa jātnieku, un caur tevi Es sadauzu ratus un braucējus.
22 pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin, pẹ̀lú rẹ, mo pa àgbàlagbà àti ọmọdé, pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.
Un caur tevi Es sadauzu vīrus un sievas, un caur tevi Es sadauzu vecus un jaunus, un caur tevi Es sadauzu jaunekļus un jaunietes.
23 Èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ olùṣọ́-àgùntàn, àti agbo àgùntàn rẹ̀ túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ àgbẹ̀ àti àjàgà màlúù túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ túútúú.
Un caur tevi Es sadauzu ganu un viņa ganāmo pulku, caur tevi Es sadauzu arāju un viņa jūgu, un caur tevi Es sadauzu kungus un valdniekus.
24 “Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Babeli àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Sioni,” ni Olúwa wí.
Bet Bābelei un visiem Kaldeju zemes iedzīvotājiem Es atmaksāšu pēc visas viņu bezdievības, ko tie darījuši pie Ciānas priekš jūsu acīm, saka Tas Kungs.
25 “Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirun ìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,” ni Olúwa wí. “Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ, èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta, Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.
Redzi, saka Tas Kungs, Es celšos pret tevi, maitātāja kalns, kas visu pasauli samaitā, un Es izstiepšu Savu roku pret tevi un tevi novelšu no taviem akmeņu kalniem, un darīšu tevi par degošu kalnu,
26 A kò ní mú òkúta kankan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbí fún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò di ahoro títí ayé,” ní Olúwa wí.
Ka no tevis nevar ņemt nedz stūra akmeni nedz pamata akmeni, jo tu būsi par mūžīgu posta vietu, saka Tas Kungs.
27 “Gbé àsíá sókè ní ilẹ̀ náà! Fọn ìpè láàrín àwọn orílẹ̀-èdè! Sọ àwọn orílẹ̀-èdè di mímọ́ sórí rẹ̀, pe àwọn ìjọba yìí láti dojúkọ ọ́: Ararati, Minini àti Aṣkenasi. Yan olùdarí ogun láti kọlù ú, rán àwọn ẹṣin sí i bí ọ̀pọ̀ eṣú.
Izceļat karogu virs zemes, bazūnējat ar bazūnēm starp tautām, sataisiet tautas uz karu pret viņu, aicinājiet pret viņu Ararata, Meni un Aškenasa valstis, ieceļat kara virsnieku pret viņu, atvediet zirgus kā briesmīgus siseņus;
28 Sọ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú àwọn ọba Media di mímọ́ sórí rẹ̀, àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ ọba lé lórí.
Sataisiet tautas uz karu pret viņu, Medijas ķēniņus, viņas valdniekus un visus viņas lielkungus un visas viņu valstis!
29 Ilẹ̀ wárìrì síyìn-ín sọ́hùn-ún, nítorí pé ète Olúwa, sí Babeli dúró, láti ba ilẹ̀ Babeli jẹ́ lọ́nà tí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.
Tad zeme drebēs un trīcēs, jo Tā Kunga domas pret Bābeli piepildās, darīt Bābeles zemi par posta vietu bez iedzīvotāja.
30 Gbogbo àwọn jagunjagun Babeli tó dáwọ́ ìjà dúró sínú àgọ́ wọn. Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin. Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun, gbogbo irin ẹnu-ọ̀nà wọn ti di fífọ́.
Bābeles varenie mitējušies karot, tie paliek stiprās pilīs, viņu vara ir izsīkusi, tie ir tapuši par bābām, viņas māju vietas iededzinātas, viņas aizšaujamie salauzti.
31 Ìránṣẹ́ kan ń tẹ̀lé òmíràn láti sọ fún ọba Babeli pé gbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.
Bēglis tek bēglim pretī un vēstnesis vēstnesim, un stāsta Bābeles ķēniņam, ka viņa pilsēta ieņemta no visām pusēm,
32 Odò tí ó sàn kọjá kò sàn mọ́ ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”
Un ka braslas ieņemtas, un dīķi ugunī nodeguši, un karavīri noguruši.
33 Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli sọ nìyìí: “Ọmọbìnrin Babeli dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”
Jo tā saka Tas Kungs Cebaot, Israēla Dievs: Bābeles meita ir kā klons kuļamā laikā; vēl maķenīt, tad viņai nāks pļaujamais laiks.
34 “Nebukadnessari ọba Babeli tó jẹ wá run, ó ti mú kí ìdààmú bá wa, ó ti sọ wá di àgbá òfìfo. Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì. Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀, lẹ́yìn náà ni ó pọ̀ wá jáde.
Nebukadnecars, Bābeles ķēniņš, mani aprijis, viņš mani sadauzījis, viņš mani darījis par tukšu trauku, viņš mani aprijis kā pūķis, viņš savu vēderu pildījis ar maniem gardumiem, viņš mani aizdzinis.
35 Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe sí ẹran-ara wa wà lórí Babeli,” èyí tí àwọn ibùgbé Sioni wí. “Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogbo àwọn tí ń gbé Babeli,” ni Jerusalẹmu wí.
Tas varas darbs, kas man un manai miesai darīts, lai nāk pār Bābeli, tā lai saka Ciānas iedzīvotāja, un manas asinis lai nāk pār Kaldejas iedzīvotājiem, tā lai saka Jeruzāleme.
36 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lórí ohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san, èmi yóò mú kí omi Òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.
Tādēļ Tas Kungs tā saka: “Redzi, Es tiesāšu tavu lietu un tevi atriebšu, un Es viņas jūrai likšu izsīkt un viņas avotiem izžūt.
37 Babeli yóò parun pátápátá, yóò sì di ihò àwọn akátá, ohun ẹ̀rù àti àbùkù, ibi tí ènìyàn kò gbé.
Un Bābele taps par akmeņu kopu, par šakāļu mājokli, par tuksnesi un par apsmieklu, bez iedzīvotāja.
38 Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramù bí ọmọ kìnnìún.
Tie kopā rūks kā lauvas un ņurdēs kā jauni lauvas.
39 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè, èmi yóò ṣe àsè fún wọn, èmi yóò jẹ́ kí wọn mutí yó tí wọn yóò máa kọ fun ẹ̀rín, lẹ́yìn náà, wọn yóò sun oorun, wọn kì yóò jí,” ni Olúwa wí.
Kad tie būs iekarsēti, tad es tiem celšu priekšā viņu dzērienu un tos piedzirdināšu, ka tie bļaustīsies, bet aizmigsies uz mūžīgu miegu un ne mūžam vairs neuzmodīsies,” saka Tas Kungs.
40 “Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn tí a fẹ́ pa, gẹ́gẹ́ bí àgbò àti ewúrẹ́.
“Es tos vedīšu kā jērus pie kaušanas, kā aunus ar āžiem.
41 “Báwo ni Ṣeṣaki yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé. Irú ìpayà wo ni yóò bá Babeli láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!
Kā Šešaks tā ir ieņemts un pasaules slava tā pārvarēta! Kā Bābele ir tapusi par biedēkli starp tautām!
42 Òkun yóò ru borí Babeli, gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Babeli.
Jūra ir plūdusi pār Bābeli, un ar viņas viļņu pulku tā ir apklāta.
43 Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro, ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.
Viņas pilsētas palikušas par tuksnesi, par izkaltušu sausu zemi, par zemi, kur neviens nedzīvo, kur cilvēka bērns nestaigā.
44 Èmi yóò fi ìyà jẹ Beli ti Babeli àti pé èmi yóò jẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì. Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò jùmọ̀ sàn lọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ mọ́. Ní òótọ́ odi Babeli yóò sì wó.
Un Es piemeklēšu Belu Bābelē un izraušu no viņa rīkles, ko viņš ierijis, un tautas vairs netecēs pie viņa, jo arī Bābeles mūri ir krituši.
45 “Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ ẹ̀yin ènìyàn mi! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Sá fún ìbínú ńlá Olúwa.
Izejiet, Mani ļaudis, no viņas vidus, un izglābiet ikviens savu dvēseli no Tā Kunga bardzības karstuma.
46 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrú tàbí kí o bẹ̀rù nígbà tí a bá gbọ́ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa; àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí, òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipá ní ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.
Un jūsu sirds lai netop bailīga, un neizbīstaties no tās baumas, kas tai zemē taps dzirdēta; jo bauma nāks vienā gadā, un pēc tam cita bauma otrā gadā, un varas darbs būs tai zemē, valdnieks pret valdnieku.
47 Nítorí ìgbà náà yóò wá dandan nígbà tí èmi yóò fi ìyà jẹ àwọn òrìṣà Babeli; gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó dójútì gbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárín rẹ̀.
Tāpēc redzi, nāk dienas, tad Es piemeklēšu Bābeles dievekļus, un visa viņas zeme taps kaunā un visi viņas nokautie gulēs viņas vidū.
48 Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn, yóò sì kọrin lórí Babeli: nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,” ni Olúwa wí.
Un par Bābeli gavilēs debesis un zeme, un viss, kas tur ir, ka no ziemeļa puses pār viņu nāk postītāji, saka Tas Kungs.
49 “Babiloni gbọdọ̀ ṣubú nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni Israẹli, gẹ́gẹ́ bí àwọn ti a pa ní gbogbo ayé nítorí Babeli.
Un kā Bābele gāzusi Israēla nokautos, tā Bābelē kritīs visas zemes nokautie.
50 Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró. Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè, ẹ sì jẹ́ kí Jerusalẹmu wá sí ọkàn yín.”
Jūs no zobena izglābtie, ejat un nestāviet! Pieminiet To Kungu tālā zemē un turat Jeruzālemi savā sirdī.
51 “Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn: ìtìjú ti bò wá lójú nítorí àwọn àjèjì wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”
Mēs esam palikuši kaunā, jo mēs esam dzirdējuši apsmieklu; kauns ir apklājis mūsu vaigu, tāpēc ka sveši nākuši pār Tā Kunga nama svētumu.”
52 “Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fínfín rẹ̀, àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa kérora já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀.
“Tāpēc redzi, nāk dienas,” saka Tas Kungs, “tad Es piemeklēšu viņas dievekļus, un visā viņas zemē vaidēs nāvīgi ievainotie.
53 Bí Babeli tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run, bí ó sì ṣe ìlú olódi ní òkè agbára rẹ, síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,” ní Olúwa wí.
Jebšu Bābele kāptu debesīs un stiprinātu savu varu augstībā, tad tomēr postītāji no Manis nāks pār viņu,” saka Tas Kungs.
54 “Ìró igbe láti Babeli, àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kaldea!
Kliegšanas balss ir dzirdama no Bābeles un liels posts no Kaldejas.
55 Nítorí pé Olúwa ti ṣe Babeli ní ìjẹ, ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀; àwọn ọ̀tá wọn sì ń hó bi omi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.
Jo Tas Kungs izposta Bābeli un iznīcina no tās to lielo troksni, jo viņu viļņi kauc kā vareni ūdeņi, viņu varenais troksnis skan.
56 Nítorí pé afiniṣèjẹ dé sórí rẹ̀, àní sórí Babeli; a mú àwọn akọni rẹ̀, a ṣẹ́ gbogbo ọrun wọn: nítorí Ọlọ́run ẹ̀san ni Olúwa, yóò san án nítòótọ́.
Jo postītājs nāk pār viņu, pār Bābeli, un viņas varenie top gūstīti, viņu stopi top salauzti. Jo Tas Kungs ir Dievs, tas atmaksātājs, atmaksādams viņš atmaksā.
57 Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí, àti àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀ àti àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti àwọn akọni rẹ̀, wọn ó sì sun oorun láéláé, wọn kì ó sì jí mọ́,” ní ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
“Un Es piedzirdināšu viņas lielkungus un viņas gudros, viņas valdniekus un viņas virsniekus un viņas varoņus, un tie gulēs mūžīgu miegu un neuzmodīsies,” saka tas ķēniņš, kam vārds ir Kungs Cebaot.
58 Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Odi Babeli gbígbòòrò ní a ó wó lulẹ̀ pátápátá, ẹnu-bodè gíga rẹ̀ ní a ó sì fi iná sun: tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn ti ṣiṣẹ́ lásán, àti àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣiṣẹ́ fún iná, tí àárẹ̀ sì mú wọn.”
Tā saka Tas Kungs Cebaot: “Platie Bābeles mūri visai(pilnīgi) taps nopostīti, un viņas augstie vārti ar uguni sadedzināti, tā ka tautas velti strādājušas, un ļaudis ugunij par labu pūlējušies.”
59 Ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì pàṣẹ fún Seraiah, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, nígbà tí o ń lọ ni ti Sedekiah, ọba Juda, sí Babeli ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Seraiah yìí sì ní ìjòyè ibùdó.
Šis ir tas vārds, ko pravietis Jeremija pavēlēja Serajam, Nerijas dēlam, Mazejas dēla dēlam, kad šis ar Cedeķiju, Jūda ķēniņu, gāja uz Bābeli, viņa valdīšanas ceturtā gadā, un Seraja bija tas ceļa lielkungs.
60 Jeremiah sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Babeli sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí a kọ sí Babeli.
Un Jeremija rakstīja visu to ļaunumu, kam bija nākt pār Bābeli, grāmatā, visus šos vārdus, kas rakstīti pret Bābeli.
61 Jeremiah sì sọ fún Seraiah pé, “Nígbà tí ìwọ bá dé Babeli, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
Un Jeremija sacīja uz Seraju: “Kad tu nonāksi Bābelē, tad pielūko un lasi visus šos vārdus,
62 Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’
Un saki: ak Kungs, Tu pret šo vietu esi runājis, ka to gribi izdeldēt, tā ka tur vairs nepaliek iedzīvotāju, ne cilvēku ne lopu, bet ka tai jāpaliek par mūžīgu posta vietu.
63 Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárín odò Eufurate.
Un kad tu šo grāmatu esi izlasījis, tad piesien pie tās akmeni un iemet to Eifrat upē,
64 Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Babeli yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’” Títí dé ìhín ni ọ̀rọ̀ Jeremiah.
Un saki: tāpat Bābele nogrims un nenāks vairs augšā aiz tās nelaimes, ko Es pār viņu vedīšu, un tie nogurs.” Tik tālu Jeremijas vārdi.

< Jeremiah 51 >