< Jeremiah 51 >

1 Ohùn ti Olúwa wí nìyìí: “Wò ó èmi yóò ru afẹ́fẹ́ apanirun sókè sí Babeli àti àwọn ènìyàn Lebikamai,
Így szól az Örökkévaló: íme én fölserkentem Bábel ellen és Támadóim-szíve lakói ellen egy pusztítónak szellemét;
2 Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn sí Babeli láti fẹ́ ẹ, tí yóò sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di òfo; wọn yóò takò ó ní gbogbo ọ̀nà ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.
és kiküldök Bábel ellen megszórókat, hogy megszólják és kiürítsék az országát; bizony ellene voltak köröskörül a veszedelem napján.
3 Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀, jáde tàbí kí ó di ìhámọ́ra rẹ̀. Má ṣe dá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sí; pátápátá ni kí o pa àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
Bárhol feszíti a feszítő az íját és bárhol fölemelkedik páncéljában, ne kíméljétek az ifjait, pusztítsátok ki egész seregét.
4 Gbogbo wọn ni yóò ṣubú ní Babeli, tí wọn yóò sì fi ara pa yánnayànna ní òpópónà.
És hulljanak el megölöttek a kaldeusok országában és az átszúrottak az utcáiban.
5 Nítorí pé Juda àti Israẹli ni Ọlọ́run wọn tí í ṣe Olúwa àwọn ọmọ-ogun, kò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọn kún fún kìkì ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Israẹli.
Mert nem özvegy Izrael és Jehúda az Istenétől, az Örökkévalótól, a seregek urától; mert országuk megtelt bűnnel Izrael szentje ellen.
6 “Sá kúrò ní Babeli! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Àsìkò àti gbẹ̀san Olúwa ni èyí; yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.
Fussatok Bábelből és mentsétek meg ki-ki a lelkét, meg ne semmisüljetek bűne által; mert a bosszú ideje az az Örökkévalónak, tettet fizet ő neki.
7 Ife wúrà ni Babeli ní ọwọ́ Olúwa; ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí. Gbogbo orílẹ̀-èdè mu ọtí rẹ̀, wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.
Arany serleg Bábel az Örökkévaló kezében, megrészegítője az egész földnek; borából ittak nemzetek, azért őrjöngnek nemzetek.
8 Babeli yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́. Ẹ hu fun un! Ẹ mú ìkunra fún ìrora rẹ, bóyá yóò le wo ọ́ sàn.
Hirtelen elesett Bábel és megtöretett; jajgassatok miatta, hozzatok balzsamot fájdalmára, hátha meggyógyítható.
9 “‘À bá ti wo Babeli sàn, ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀, kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè, ó ga àní títí dé òfúrufú.’
Gyógyítgattuk Bábelt, de nem volt gyógyítható, hagyjátok el és menjünk ki-ki az országába, mert az égig ért az ítélete és fölemelkedett a fellegekig.
10 “‘Olúwa ti dá wa láre, wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Sioni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa ti ṣe.’
Kiderítette az Örökkévaló igazainkat; gyertek és beszéljük el Cziónban az Örökkévalónak, Istenünknek művét.
11 “Ṣe ọfà rẹ ní mímú, mú àpáta! Olúwa ti ru ọba Media sókè, nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Babeli run. Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
Tisztítsátok a nyilakat, töltsétek meg a tegzeket, felserkentette az Örökkévaló Média királyainak szellemét, mert Bábel ellen van szándéka, hogy elpusztítsa, mert az Örökkévaló bosszúja az, templomának a bosszúja.
12 Gbé àsíá sókè sí odi Babeli! Ẹ ṣe àwọn ọmọ-ogun gírí, ẹ pín àwọn olùṣọ́ káàkiri, ẹ ṣètò àwọn tí yóò sá pamọ́ Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde, òfin rẹ̀ sí àwọn ará Babeli.
Bábel falai ellen emeljetek zászlót, erősítsétek meg az őrséget, állítsatok föl őröket. helyezzétek el a lesőket! Mert az Örökkévaló ki is gondolta, meg is cselekedte azt, amit kimondott Bábel lakóiról.
13 Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀, tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé, àní àsìkò láti ké ọ kúrò!
Nagy vizek mellett lakozó te, kincsekben bővelkedő, megjött a véged, kapzsiságod mértéke.
14 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀, Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú, wọn yóò yọ ayọ̀, ìṣẹ́gun lórí rẹ.
Megesküdött az Örökkévaló, a seregek ura önmagára: Bizony megtöltelek annyi emberrel, mint a sáska és kurjantást hangoztatnak fölötted.
15 “Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀, o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.
Teremtette a földet erejével, készítette a világot bölcsességével és értelmével kiterjesztette az eget.
16 Nígbà tí ará omi ọ̀run hó ó mú kí òfúrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.
Amint hangját hallatja, vizek tömege van az égen, felhőket hozott föl a föld végéről; villámokat teremtett az esőnek és kihozta a szelet tárházaiból.
17 “Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọ tí kò sì ní ìmọ̀, olúkúlùkù alágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀. Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn; wọn kò ní èémí nínú.
Elbutult minden ember, nincs megismerés, szégyent vallott minden ötvös a bálványkép miatt, mert hazugság az öntvénye és nincs szellem bennük.
18 Asán ni wọ́n, àti iṣẹ́ ìsìnà, nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn ó ṣègbé.
Hiábavalóság azok, csúfolni való munka, büntetésük idején elvesznek.
19 Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jakọbu kó rí bí ìwọ̀nyí; nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo, àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Nem olyan, mint ezek Jákob osztályrésze, mert a mindenség alkotója ő, és Izrael birtokának törzse: Örökkévaló, a seregek ura, az ő neve.
20 “Ìwọ ni kùmọ̀ ogun ohun èlò ogun mi, ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀-èdè túútúú, èmi ó bà àwọn ilé ọba jẹ́.
Pörölyöm voltál nekem, harcnak a fegyvere: összezúzok veled nemzeteket és megrontok veled királyságokat:
21 Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀; èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lú èmi ó pa awakọ̀,
összezúzok veled lovat és lovast, összezúzok veled szekeret és szekerest:
22 pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin, pẹ̀lú rẹ, mo pa àgbàlagbà àti ọmọdé, pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.
összezúzok veled férfit és asszonyt összezúzok veled öreget és fiatalt; összezúzok veled ifjút és hajadont:
23 Èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ olùṣọ́-àgùntàn, àti agbo àgùntàn rẹ̀ túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ àgbẹ̀ àti àjàgà màlúù túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ túútúú.
összezúzok veled pásztort meg nyáját, összezúzok veled földművest meg igamarháját, összezúzok veled helytartókat és kormányzókat.
24 “Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Babeli àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Sioni,” ni Olúwa wí.
De megfizetem Bábelnek és mind a Kaszdím lakóinak minden gonoszságukat, melyet elkövettek Cziónban szemeitek láttára, úgymond az Örökkévaló.
25 “Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirun ìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,” ni Olúwa wí. “Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ, èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta, Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.
Íme én ellened fordulok rontás hegye te, úgymond az Örökkévaló, amely megrontotta az egész földet; kinyújtom rád kezemet és legördítlek a sziklákról és kiégett heggyé teszlek.
26 A kò ní mú òkúta kankan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbí fún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò di ahoro títí ayé,” ní Olúwa wí.
És nem vesznek belőled követ sarokra, se követ alapzatra, mert örökös pusztasággá lesz, úgymond az Örökkévaló.
27 “Gbé àsíá sókè ní ilẹ̀ náà! Fọn ìpè láàrín àwọn orílẹ̀-èdè! Sọ àwọn orílẹ̀-èdè di mímọ́ sórí rẹ̀, pe àwọn ìjọba yìí láti dojúkọ ọ́: Ararati, Minini àti Aṣkenasi. Yan olùdarí ogun láti kọlù ú, rán àwọn ẹṣin sí i bí ọ̀pọ̀ eṣú.
Emeljetek zászlót a földön, fújjatok harsonát a nemzetek között, szenteljetek ellene nemzeteket, hívjátok össze ellene Arárat, Minní és Askenáz királyságait, rendeljetek ellene vezért, hozzatok föl annyi lovat, mint a borzas sáska.
28 Sọ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú àwọn ọba Media di mímọ́ sórí rẹ̀, àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ ọba lé lórí.
Szenteljetek ellene nemzeteket: Média királyait, helytartóit és mind a kormányzóit és uralmának egész országát.
29 Ilẹ̀ wárìrì síyìn-ín sọ́hùn-ún, nítorí pé ète Olúwa, sí Babeli dúró, láti ba ilẹ̀ Babeli jẹ́ lọ́nà tí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.
Megrendült a föld és reszketett, mert beteljesedtek Bábel ellen az Örökkévaló gondolatai, hogy Bábel országát pusztulássá tegye, lakó nélkül.
30 Gbogbo àwọn jagunjagun Babeli tó dáwọ́ ìjà dúró sínú àgọ́ wọn. Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin. Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun, gbogbo irin ẹnu-ọ̀nà wọn ti di fífọ́.
Megszűntek harcolni Bábel vitézei, a várakban ültek, elapadt a vitézségük, asszonyokká lettek; felgyújtották lakhelyeit, eltörettek reteszei.
31 Ìránṣẹ́ kan ń tẹ̀lé òmíràn láti sọ fún ọba Babeli pé gbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.
Futár futárral szemben fut; hírmondó hírmondóval szemben, hogy hírül adják Bábel királyának, hogy városa bevétetett mindenünnen;
32 Odò tí ó sàn kọjá kò sàn mọ́ ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”
és az átkelők elfoglaltattak és a mocsarakat elégették tűzben, a harcosok pedig megrémültek.
33 Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli sọ nìyìí: “Ọmọbìnrin Babeli dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”
Mert így szól az Örökkévaló, a seregek ura, Izrael Istene: Bábel leánya olyan mint a szérű, amikor tapossák; még egy kevés – és megjön az aratás ideje számára.
34 “Nebukadnessari ọba Babeli tó jẹ wá run, ó ti mú kí ìdààmú bá wa, ó ti sọ wá di àgbá òfìfo. Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì. Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀, lẹ́yìn náà ni ó pọ̀ wá jáde.
Megevett, kizavart engem Nebúkadnecczár Bábel királya, leállított üres edényként, elnyelt, mint a sárkány, megtöltötte hasát csemegéimmel, eltaszított engem;
35 Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe sí ẹran-ara wa wà lórí Babeli,” èyí tí àwọn ibùgbé Sioni wí. “Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogbo àwọn tí ń gbé Babeli,” ni Jerusalẹmu wí.
sérelmem és húsom Bábelre, mondja Czión lakója, és vérem Kaszdím lakóira, mondja Jeruzsálem.
36 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lórí ohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san, èmi yóò mú kí omi Òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.
Azért így szól az Örökkévaló: íme én viszem az ügyedet, és bosszút állok érted; kiszárítom a tengerét és kiapasztom a forrását.
37 Babeli yóò parun pátápátá, yóò sì di ihò àwọn akátá, ohun ẹ̀rù àti àbùkù, ibi tí ènìyàn kò gbé.
És kőhalmokká lesz Bábel, sakálok tanyájává, iszonyattá és pisszegéssé, lakó nélkül.
38 Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramù bí ọmọ kìnnìún.
Egyaránt ordítanak mint fiatal oroszlánok, kurrogtak, mint az oroszlánok kölykei.
39 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè, èmi yóò ṣe àsè fún wọn, èmi yóò jẹ́ kí wọn mutí yó tí wọn yóò máa kọ fun ẹ̀rín, lẹ́yìn náà, wọn yóò sun oorun, wọn kì yóò jí,” ni Olúwa wí.
Mikor fölhevülnek, rendezem majd lakomájukat és megrészegítem őket, azért hogy ujjongjanak és aludjanak örök álmot és fel ne ébredjenek, úgymond az Örökkévaló.
40 “Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn tí a fẹ́ pa, gẹ́gẹ́ bí àgbò àti ewúrẹ́.
Leszállítom őket mint bárányokat a levágásra, mint kosokat bakokkal együtt.
41 “Báwo ni Ṣeṣaki yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé. Irú ìpayà wo ni yóò bá Babeli láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!
Mint vétetett be Sésakh és elfoglaltatott az egész föld dicsősége; mint lett pusztulássá Bábel a nemzetek között!
42 Òkun yóò ru borí Babeli, gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Babeli.
Felszállt Bábelre a tenger, zúgó hullámaival elboríttatott.
43 Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro, ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.
Pusztulássá lettek városai, szárazság és sivatag földjévé, oly földdé, hogy bennük nem lakik senki és nem megy át rajtuk ember fia.
44 Èmi yóò fi ìyà jẹ Beli ti Babeli àti pé èmi yóò jẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì. Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò jùmọ̀ sàn lọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ mọ́. Ní òótọ́ odi Babeli yóò sì wó.
Megbüntetem Bélt Bábelben és kiveszem szájából amit elnyelt, és nem özönlenek többé hozzá nemzetek; Bábel fala is ledőlt.
45 “Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ ẹ̀yin ènìyàn mi! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Sá fún ìbínú ńlá Olúwa.
Vonuljatok ki belőle, népem és mentsétek meg ki-ki a lelkét az Örökkévaló fellobbant haragjától.
46 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrú tàbí kí o bẹ̀rù nígbà tí a bá gbọ́ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa; àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí, òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipá ní ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.
De hogy ne csüggedjen szívetek, hogy félnétek a hír miatt, mely hallatszik az országban; jön ugyanis ez évben a hír és az utána való évben is hír, erőszak lesz az országban, uralkodó uralkodó ellen.
47 Nítorí ìgbà náà yóò wá dandan nígbà tí èmi yóò fi ìyà jẹ àwọn òrìṣà Babeli; gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó dójútì gbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárín rẹ̀.
Azért íme napok jönnek és megbüntetem Bábel bálványképeit és egész országa meg fog szégyenülni és mind a megöltjei elesnek közepette.
48 Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn, yóò sì kọrin lórí Babeli: nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,” ni Olúwa wí.
Akkor ujjonganak Bábel fölött ég és föld és mind ami bennük van, mert északról jönnek ellene a pusztítók, úgymond az Örökkévaló.
49 “Babiloni gbọdọ̀ ṣubú nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni Israẹli, gẹ́gẹ́ bí àwọn ti a pa ní gbogbo ayé nítorí Babeli.
Bábelnek is el kell esnie, Izrael megöltjeiért: Bábel miatt is elestek az egész föld megöltjei.
50 Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró. Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè, ẹ sì jẹ́ kí Jerusalẹmu wá sí ọkàn yín.”
Kardtól menekülők ti, menjetek, ne álljatok meg, emlékezzetek meg messziről az Örökkévalóról, és Jeruzsálem jusson eszetekbe.
51 “Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn: ìtìjú ti bò wá lójú nítorí àwọn àjèjì wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”
Megszégyenültünk, mert gyalázatot hallottunk, szégyen borította arcunkat, mert idegenek jöttek az Örökkévaló házának szentélyei ellen.
52 “Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fínfín rẹ̀, àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa kérora já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀.
Azért íme napok jönnek, úgymond az Örökkévaló, és megbüntetem az ő bálványképeit és egész országában hörögnek a megöltek.
53 Bí Babeli tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run, bí ó sì ṣe ìlú olódi ní òkè agbára rẹ, síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,” ní Olúwa wí.
Ha égbe száll Bábel, ha megerősíti hatalma magasságát, tőlem jönnek pusztítók ellene, úgymond az Örökkévaló.
54 “Ìró igbe láti Babeli, àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kaldea!
Jajkiáltás hangja Bábelből és nagy romlás Kaszdím országából!
55 Nítorí pé Olúwa ti ṣe Babeli ní ìjẹ, ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀; àwọn ọ̀tá wọn sì ń hó bi omi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.
Mert elpusztítja az Örökkévaló Bábelt és elveszíti belőle a nagy zajt; zúgnak majd hullámaik, mint nagy vizek, hallatszik hangjuk zajongása.
56 Nítorí pé afiniṣèjẹ dé sórí rẹ̀, àní sórí Babeli; a mú àwọn akọni rẹ̀, a ṣẹ́ gbogbo ọrun wọn: nítorí Ọlọ́run ẹ̀san ni Olúwa, yóò san án nítòótọ́.
Mert jön rá, Bábelre, pusztító és elfogatnak vitézei, megtöretnek íjaik, mert viszonzás Istene az Örökkévaló, fizetve fizet.
57 Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí, àti àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀ àti àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti àwọn akọni rẹ̀, wọn ó sì sun oorun láéláé, wọn kì ó sì jí mọ́,” ní ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
És megrészegítem nagyjait és bölcseit, helytartóit és kormányzóit és vitézeit, örök álmot alusznak és nem ébrednek fel, úgymond a király, Örökkévaló, a seregek ura az ő neve.
58 Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Odi Babeli gbígbòòrò ní a ó wó lulẹ̀ pátápátá, ẹnu-bodè gíga rẹ̀ ní a ó sì fi iná sun: tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn ti ṣiṣẹ́ lásán, àti àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣiṣẹ́ fún iná, tí àárẹ̀ sì mú wọn.”
Így szól az Örökkévaló, a seregek ura: Bábel fala, a széles, rontva ronttatik le és magas kapui tűzben égettetnek el; fáradnak tehát a népek semmiért és a nemzetek a tűzért és elbágyadnak.
59 Ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì pàṣẹ fún Seraiah, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, nígbà tí o ń lọ ni ti Sedekiah, ọba Juda, sí Babeli ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Seraiah yìí sì ní ìjòyè ibùdó.
Az ige, melyet parancsolt Jirmejáhú próféta Szerájának, Néríja Machszéja fia fiának, midőn Czidkijáhúval, Jehúda királyával Bábelbe ment, uralkodásának negyedik évében, Szerája pedig szállásmester volt.
60 Jeremiah sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Babeli sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí a kọ sí Babeli.
És megírta Jirmejáhú mind a veszedelmet, mely majd Bábelre jön, egy könyvben: a Bábelről írt mind e szavakat.
61 Jeremiah sì sọ fún Seraiah pé, “Nígbà tí ìwọ bá dé Babeli, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
És szólt Jirmejáhú Szerájához: Amint Bábelbe érsz, lásd és olvasd mind e szavakat:
62 Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’
és szólj: Örökkévaló, te kimondtad a helyről, hogy kiirtod, úgy, hogy nem lesz benne lakó, embertől állatig, mert örök pusztasággá lesz.
63 Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárín odò Eufurate.
És lesz, amint végeztél azzal, hogy elolvastad a könyvet: akkor köss rá követ és dobjad az Eufrátesbe;
64 Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Babeli yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’” Títí dé ìhín ni ọ̀rọ̀ Jeremiah.
és szólj: így süllyedjen el Bábel és ne támadjon fel, azon veszedelem miatt, melyet én hozok rá; és lankadjanak el. Idáig Jirmejáhú szavai.

< Jeremiah 51 >