< Jeremiah 51 >

1 Ohùn ti Olúwa wí nìyìí: “Wò ó èmi yóò ru afẹ́fẹ́ apanirun sókè sí Babeli àti àwọn ènìyàn Lebikamai,
Jehova ekuuga ũũ: “Atĩrĩrĩ, nĩngarahũra roho wa mũniinani, ũũkĩrĩre Babuloni, o na andũ a Lebi-Kamai.
2 Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn sí Babeli láti fẹ́ ẹ, tí yóò sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di òfo; wọn yóò takò ó ní gbogbo ọ̀nà ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.
Nĩngatũma andũ a kũngĩ mathiĩ Babuloni magakũhurunje ta ũrĩa mũũngũ ũmbũragwo ihuhĩro-inĩ, na manange bũrũri ũcio ũtigwo ũtarĩ kĩndũ; makaũũkĩrĩra kuuma mĩena yothe, mũthenya ũcio waguo wa mwanangĩko.
3 Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀, jáde tàbí kí ó di ìhámọ́ra rẹ̀. Má ṣe dá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sí; pátápátá ni kí o pa àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
Mũtikanareke mũikia wa mĩguĩ ageete ũta wake, kana ehumbe nguo ciake cia ita. Mũtigacaĩre aanake akuo; anangai mbũtũ ciake cia ita, mũciniine.
4 Gbogbo wọn ni yóò ṣubú ní Babeli, tí wọn yóò sì fi ara pa yánnayànna ní òpópónà.
Makaagũa thĩ moragĩtwo kũu Babuloni, magurarĩtio nguraro cia gĩkuũ kũu barabara-inĩ ciakuo.
5 Nítorí pé Juda àti Israẹli ni Ọlọ́run wọn tí í ṣe Olúwa àwọn ọmọ-ogun, kò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọn kún fún kìkì ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Israẹli.
Nĩgũkorwo Isiraeli na Juda matitirikĩtwo nĩ Ngai wao, o we Jehova Mwene-Hinya-Wothe, o na gũtuĩka bũrũri wao ũiyũrĩtwo nĩ mahĩtia maitho-inĩ ma ũcio Mũtheru wa Isiraeli.
6 “Sá kúrò ní Babeli! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Àsìkò àti gbẹ̀san Olúwa ni èyí; yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.
“Mwĩtharei muume kũu Babuloni! Ũrai mũhonokie mĩoyo yanyu! Mwĩtharei mũtikaniinanĩrio nakuo nĩ ũndũ wa mehia makuo. Nĩ ihinda rĩa Jehova rĩa kwĩrĩhĩria; agaakũrĩha o kĩrĩa gĩkwagĩrĩire.
7 Ife wúrà ni Babeli ní ọwọ́ Olúwa; ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí. Gbogbo orílẹ̀-èdè mu ọtí rẹ̀, wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.
Babuloni kwahaanaga ta gĩkombe gĩa thahabu kĩrĩ guoko-inĩ kwa Jehova; nakuo gũgĩtũma thĩ yothe ĩhaane ta ĩrĩĩtwo nĩ njoohi. Ndũrĩrĩ nĩcianyuire ndibei yakuo; nĩ ũndũ ũcio rĩu ihaana ta igũrũkĩte.
8 Babeli yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́. Ẹ hu fun un! Ẹ mú ìkunra fún ìrora rẹ, bóyá yóò le wo ọ́ sàn.
Babuloni nĩgũkũgũa o rĩmwe na kũhehenjwo. Kũrĩrĩrei! Rehei ndawa ya kũniina ruo rwakuo; hihi kwahota kũhona.
9 “‘À bá ti wo Babeli sàn, ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀, kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè, ó ga àní títí dé òfúrufú.’
“‘Nĩtũngĩahonirie Babuloni, no rĩrĩ, gũtingĩhonio. Nĩtũgũtigei, na o mũndũ acooke bũrũri wake kĩũmbe, nĩgũkorwo ituĩro rĩakuo rĩkinyĩte o matu-inĩ, rĩambatĩte o nginya matu-inĩ marĩa mairũ.’
10 “‘Olúwa ti dá wa láre, wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Sioni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa ti ṣe.’
“‘Jehova nĩonanĩtie ũthingu witũ; ũkai tũthiĩ tũkoimbũrĩre Zayuni maũndũ marĩa Jehova Ngai witũ ekĩte.’
11 “Ṣe ọfà rẹ ní mímú, mú àpáta! Olúwa ti ru ọba Media sókè, nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Babeli run. Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
“Noorai mĩguĩ, oyai ngo! Nĩgũkorwo Jehova nĩarahũrĩte athamaki a Amedi, nĩ ũndũ nĩaciirĩire kũniina Babuloni. Jehova nĩekwĩrĩhĩria harĩo, erĩhĩrie maũndũ marĩa meekirwo hekarũ yake.
12 Gbé àsíá sókè sí odi Babeli! Ẹ ṣe àwọn ọmọ-ogun gírí, ẹ pín àwọn olùṣọ́ káàkiri, ẹ ṣètò àwọn tí yóò sá pamọ́ Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde, òfin rẹ̀ sí àwọn ará Babeli.
Haandai bendera kũrigania na thingo cia Babuloni! Ongererai agitĩri, igai arangĩri, mũhaarĩrie andũ a kũhithũkĩra njĩra-inĩ! Jehova nĩekũhingia ũrĩa aciirĩire gwĩka, ahingie uuge wake wa kũrũmĩrĩrwo, wa gũũkĩrĩra andũ a Babuloni.
13 Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀, tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé, àní àsìkò láti ké ọ kúrò!
Wee ũtũũraga gũkuhĩ na njũũĩ nyingĩ, na ũkeigĩra indo nyingĩ igĩĩna-inĩ ciaku-rĩ, ithirĩro rĩaku nĩ ikinyu, nĩ ihinda rĩaku rĩa kweherio.
14 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀, Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú, wọn yóò yọ ayọ̀, ìṣẹ́gun lórí rẹ.
Jehova Mwene-Hinya-Wothe nĩehĩtĩte akĩgwetaga rĩĩtwa rĩake, akoiga atĩrĩ: Ti-itherũ nĩngatũma ũũkĩrĩrwo nĩ andũ aingĩ o ta mĩrumbĩ ya ngigĩ, nao makuugĩrĩrie nĩ ũndũ wa gũkũhoota.
15 “Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀, o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.
“Nĩwe wombire thĩ na ũndũ wa hinya wake; ningĩ akĩhaanda thĩ na ũũgĩ wake, na agĩtambũrũkia matu mairũ na ũndũ wa ũmenyo wake.
16 Nígbà tí ará omi ọ̀run hó ó mú kí òfúrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.
Hĩndĩ ĩrĩa agũũthũka-rĩ, maaĩ marĩa marĩ igũrũ matu-inĩ nĩmarurumaga; nĩwe ũtũmaga thaatũ wambate na igũrũ kuuma ituri ciothe cia thĩ. Atũmaga rũheni rũũke rũrehanĩte na mbura, na akahingũrĩra rũhuho ruume makũmbĩ-inĩ make.
17 “Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọ tí kò sì ní ìmọ̀, olúkúlùkù alágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀. Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn; wọn kò ní èémí nínú.
“Andũ othe nĩmagĩte meciiria na makaaga ũmenyo, nake mũturi wa thahabu o wothe nĩaconorithĩtio nĩ mĩhianano ĩyo yake. Nĩ ũndũ mĩhianano ĩyo yake nĩ ya maheeni; ndĩrĩ mĩhũmũ thĩinĩ wayo.
18 Asán ni wọ́n, àti iṣẹ́ ìsìnà, nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn ó ṣègbé.
Ndĩrĩ kĩene, nĩ indo cia kũnyararwo; narĩo ihinda rĩayo rĩa gũciirithio rĩakinya-rĩ, nĩĩgathira biũ.
19 Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jakọbu kó rí bí ìwọ̀nyí; nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo, àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
We ũcio Rũgai rwa Jakubu ndatariĩ tayo, nĩgũkorwo nĩwe Mũũmbi wa indo ciothe, o hamwe na mũhĩrĩga ũrĩa eegwatĩire ũtuĩke igai rĩake; Jehova Mwene-Hinya-Wothe nĩrĩo rĩĩtwa rĩake.
20 “Ìwọ ni kùmọ̀ ogun ohun èlò ogun mi, ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀-èdè túútúú, èmi ó bà àwọn ilé ọba jẹ́.
“Nĩwe njũgũma yakwa ya ita, na nowe kĩndũ gĩakwa kĩa mbaara: nĩwe hũthagĩra kũhehenja ndũrĩrĩ, na ngatũmĩra hinya waku kũniina mothamaki.
21 Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀; èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lú èmi ó pa awakọ̀,
Nĩwe hũthagĩra kũhehenja mbarathi na mũmĩhaici, ngakũhũthĩra kũhehenja ngaari ya ita na mũmĩtwari,
22 pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin, pẹ̀lú rẹ, mo pa àgbàlagbà àti ọmọdé, pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.
ngakũhũthĩra kũhehenja mũndũ mũrũme na mũndũ-wa-nja, ngakũhũthĩra kũhehenja mũndũ mũkũrũ na ũrĩa mwĩthĩ, o na ngakũhũthĩra kũhehenja mwanake na mũirĩtu,
23 Èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ olùṣọ́-àgùntàn, àti agbo àgùntàn rẹ̀ túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ àgbẹ̀ àti àjàgà màlúù túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ túútúú.
Ngakũhũthĩra kũhehenja mũrĩithi na rũũru rwake rwa mbũri, ngakũhũthĩra kũhehenja mũrĩmi na ndegwa ciake cia kũrĩma, o na ngakũhũthĩra kũhehenja abarũthi na anene.
24 “Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Babeli àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Sioni,” ni Olúwa wí.
“Na rĩrĩ, Babuloni na arĩa othe matũũraga Kalidei, ngaamacookereria ũũru wao mũkĩĩonagĩra, ũũru wothe ũrĩa maaneka kũu Zayuni,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
25 “Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirun ìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,” ni Olúwa wí. “Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ, èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta, Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.
“Nĩngũgũũkĩrĩra wee kĩrĩma gĩkĩ gĩa kũniinana, wee ũniinaga thĩ yothe.” ũguo nĩguo Jehova ekuuga. “Nĩngũgũtambũrũkĩria guoko ngũũkĩrĩre, ngũgaragarie ngũrute ndwaro-inĩ cia mahiga, na ndũme ũtuĩke ta kĩrĩma gĩcinĩtwo nĩ mwaki.
26 A kò ní mú òkúta kankan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbí fún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò di ahoro títí ayé,” ní Olúwa wí.
Gũtirĩ ihiga rĩkarutwo harĩwe rĩtuĩke rĩa koine, o na kana ihiga o rĩothe rĩa mũthingi, nĩ ũndũ ũgũtũũra ũkirĩte ihooru nginya tene,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
27 “Gbé àsíá sókè ní ilẹ̀ náà! Fọn ìpè láàrín àwọn orílẹ̀-èdè! Sọ àwọn orílẹ̀-èdè di mímọ́ sórí rẹ̀, pe àwọn ìjọba yìí láti dojúkọ ọ́: Ararati, Minini àti Aṣkenasi. Yan olùdarí ogun láti kọlù ú, rán àwọn ẹṣin sí i bí ọ̀pọ̀ eṣú.
“Haandai bendera bũrũri-inĩ, huhai karumbeta ndũrĩrĩ-inĩ! Thagathagai ndũrĩrĩ ikahũũrane nake; ĩtai mothamaki maya meturanĩre, mamũũkĩrĩre: mothamaki ma Ararati, na Mini, na Ashikenazu. Mũigĩrei mũnene wa ita wa kũmũũkĩrĩra; ambatiai mbarathi cia ita nyingĩ ta mĩrumbĩ ya ngigĩ.
28 Sọ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú àwọn ọba Media di mímọ́ sórí rẹ̀, àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ ọba lé lórí.
Thagathagai ndũrĩrĩ ikahũũrane nake; thagathagai athamaki a Amedi, na abarũthi, na anene ao othe, na andũ a mabũrũri mothe marĩa maathagwo nĩo.
29 Ilẹ̀ wárìrì síyìn-ín sọ́hùn-ún, nítorí pé ète Olúwa, sí Babeli dúró, láti ba ilẹ̀ Babeli jẹ́ lọ́nà tí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.
Bũrũri nĩũrathingitha na ũkenyogonda nĩ ruo, nĩgũkorwo ũndũ ũrĩa Jehova aciirĩire gwĩka Babuloni nĩ mũrũmu: wa kũharagania bũrũri wa Babuloni nĩguo kwage mũndũ ũngĩtũũra kuo.
30 Gbogbo àwọn jagunjagun Babeli tó dáwọ́ ìjà dúró sínú àgọ́ wọn. Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin. Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun, gbogbo irin ẹnu-ọ̀nà wọn ti di fífọ́.
Njamba iria irĩ hinya cia Babuloni nĩitigĩte kũrũa; ciikarĩte ciĩgitio-inĩ ciacio iria nũmu. Hinya wacio nĩ mũthiru; ihaanĩte o ta andũ-a-nja. Ciikaro ciakuo nĩicinĩtwo na mwaki; mĩgĩĩka ya ihingo ciakuo nĩ miunange.
31 Ìránṣẹ́ kan ń tẹ̀lé òmíràn láti sọ fún ọba Babeli pé gbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.
Mũtwari ndũmĩrĩri ũmwe ararũmĩrĩrwo nĩ ũngĩ, nake mũrekio akarũmĩrĩrwo nĩ mũrekio ũrĩa ũngĩ, makamenyithie mũthamaki wa Babuloni atĩ itũũra rĩu rĩake inene rĩothe nĩrĩtunyane,
32 Odò tí ó sàn kọjá kò sàn mọ́ ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”
ningĩ mariũko ma njũũĩ nĩmanyiite, na kũrĩa kũrĩ marura gũgaacinwo na mwaki, nacio thigari ikanyiitwo nĩ guoya.”
33 Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli sọ nìyìí: “Ọmọbìnrin Babeli dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”
Jehova Mwene-Hinya-Wothe, o we Ngai wa Isiraeli, ekuuga atĩrĩ: “Mwarĩ wa Babuloni atariĩ ta kĩhuhĩro kĩa ngano hĩndĩ ĩrĩa yaraganĩtio ĩkĩrangĩrĩrio; kahinda gake ga kũgethwo nĩgegũkinya o narua.”
34 “Nebukadnessari ọba Babeli tó jẹ wá run, ó ti mú kí ìdààmú bá wa, ó ti sọ wá di àgbá òfìfo. Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì. Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀, lẹ́yìn náà ni ó pọ̀ wá jáde.
“Nebukadinezaru mũthamaki wa Babuloni nĩatũmeretie, nĩatũreheire kĩrigiicano, agatũma tũtuĩke ta nyũngũ ya rĩũmba ĩtarĩ kĩndũ. Nĩatũmerũkĩtie o ta ndamathia, nayo nda yake akamĩiyũria na indo ciitũ iria irĩ mũrĩo, na nĩacookete agatũtahĩka.
35 Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe sí ẹran-ara wa wà lórí Babeli,” èyí tí àwọn ibùgbé Sioni wí. “Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogbo àwọn tí ń gbé Babeli,” ni Jerusalẹmu wí.
Maũndũ ma ũhinya marĩa maanekwo nyama ciitũ-rĩ, marocookerera Babuloni,” ũguo nĩguo atũũri a Zayuni mekuuga. “Thakame iitũ ĩrocookerera acio maikaraga kũu Babuloni,” ũguo nĩguo Jerusalemu ĩkuuga.
36 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lórí ohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san, èmi yóò mú kí omi Òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.
Nĩ ũndũ wa ũguo-rĩ, Jehova ekuuga ũũ: “Atĩrĩrĩ, niĩ nĩngũkũrũĩrĩra na ngũrĩhĩrie; nĩngahũithia iria rĩake, na ndũme ithima ciake ihũe.
37 Babeli yóò parun pátápátá, yóò sì di ihò àwọn akátá, ohun ẹ̀rù àti àbùkù, ibi tí ènìyàn kò gbé.
Babuloni gũgaatuĩka hĩba ya kũndũ kwanangĩku, na imamo cia mbwe, na kũndũ gwa kũmakania, na gwa gũthekererwo, kũndũ gũtarĩ mũndũ ũngĩtũũra kuo.
38 Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramù bí ọmọ kìnnìún.
Andũ othe akuo makaararamaga ta mĩrũũthi mĩĩthĩ, makaarurumaga ta njaũ cia mĩrũũthi.
39 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè, èmi yóò ṣe àsè fún wọn, èmi yóò jẹ́ kí wọn mutí yó tí wọn yóò máa kọ fun ẹ̀rín, lẹ́yìn náà, wọn yóò sun oorun, wọn kì yóò jí,” ni Olúwa wí.
No rĩrĩ, hĩndĩ ĩrĩa magaakorwo macinĩtwo nĩ thuti-rĩ, nĩrĩo ngaamarugithĩria iruga, na ndũme marĩĩo nĩ njoohi, nĩguo magaatheka maanĩrĩire, macooke makome toro nginya tene, na maticooke gũũkĩra,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
40 “Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn tí a fẹ́ pa, gẹ́gẹ́ bí àgbò àti ewúrẹ́.
“Ngaamaikũrũkia ta tũgondu tũgĩthiĩ gũthĩnjwo, o na ta ndũrũme irĩ hamwe na thenge.
41 “Báwo ni Ṣeṣaki yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé. Irú ìpayà wo ni yóò bá Babeli láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!
“Hĩ, kaĩ Sheshaki nĩrĩkeegwatĩrwo-ĩ, itũũra rĩu rĩĩrahagwo nĩ thĩ yothe kaĩ nĩinyiite-ĩ! Babuloni gũgaatuĩka kũndũ gwa kũmakania thĩinĩ wa ndũrĩrĩ ciothe!
42 Òkun yóò ru borí Babeli, gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Babeli.
Iria rĩrĩa inene nĩrĩkaiyũra Babuloni guothe; mũrurumo wa ndiihũ ciarĩo nĩguo ũgaakũhubanĩria.
43 Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro, ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.
Matũũra makuo nĩmakirĩte ihooru, matuĩke bũrũri mũũmũ na werũ ũtarĩ kĩndũ, bũrũri ũtarĩ mũndũ ũngĩũtũũra, kũndũ gũtarĩ mũndũ ũgeragĩra kuo.
44 Èmi yóò fi ìyà jẹ Beli ti Babeli àti pé èmi yóò jẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì. Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò jùmọ̀ sàn lọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ mọ́. Ní òótọ́ odi Babeli yóò sì wó.
Nĩngaherithĩria Beli kũu Babuloni na ndũme ĩtahĩke kĩndũ kĩrĩa gĩothe ĩmeretie. Ndũrĩrĩ itigacooka kũhatĩkana igĩthiĩ kũrĩ yo. Naruo rũthingo rwa Babuloni nĩrũkaagũa.
45 “Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ ẹ̀yin ènìyàn mi! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Sá fún ìbínú ńlá Olúwa.
“Umai kũu thĩinĩ warĩo, inyuĩ andũ akwa! Mwĩtharei, mũhonokie mĩoyo yanyu! Mwĩtharei, mweherere marakara marĩa mahiũ ma Jehova.
46 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrú tàbí kí o bẹ̀rù nígbà tí a bá gbọ́ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa; àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí, òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipá ní ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.
Mũtikanareke ngoro cianyu ciũrwo nĩ hinya, kana mwĩtigĩre hĩndĩ ĩrĩa ndeto cia mũhuhu ikaiguuo bũrũri-inĩ; ũhoro ũmwe wa mũhuhu nĩũkaiguuo mwaka ũyũ, na ũngĩ ũiguuo mwaka ũcio ũngĩ ũrũmĩrĩire, mũhuhu ũkoniĩ ndeto cia haaro bũrũri-inĩ, na wa mwathani ũmwe agĩũkĩrĩra mwathani ũrĩa ũngĩ.
47 Nítorí ìgbà náà yóò wá dandan nígbà tí èmi yóò fi ìyà jẹ àwọn òrìṣà Babeli; gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó dójútì gbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárín rẹ̀.
Nĩgũkorwo ti-itherũ ihinda nĩrĩgooka rĩrĩa ngaaherithia ngai cia mĩhianano ya Babuloni; bũrũri ũcio wothe nĩũgaconorithio, nao andũ akuo arĩa othe moragĩtwo nĩmakaaragana kuo.
48 Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn, yóò sì kọrin lórí Babeli: nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,” ni Olúwa wí.
Hĩndĩ ĩyo igũrũ na thĩ na kĩrĩa gĩothe kĩrĩ kuo nĩikanĩrĩra nĩ gũkena igĩkenerera Babuloni, nĩgũkorwo aniinani nĩmakarĩtharĩkĩra, moimĩte mwena wa gathigathini,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
49 “Babiloni gbọdọ̀ ṣubú nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni Israẹli, gẹ́gẹ́ bí àwọn ti a pa ní gbogbo ayé nítorí Babeli.
“Babuloni no nginya gũkaagũa nĩ ũndũ wa andũ a Isiraeli arĩa maanooraga, ũguo noguo andũ a mabũrũri mothe makaagũa thĩ, moragĩtwo nĩ ũndũ wa Babuloni.
50 Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró. Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè, ẹ sì jẹ́ kí Jerusalẹmu wá sí ọkàn yín.”
Inyuĩ mũhonokete kũũragwo na rũhiũ rwa njora-rĩ, mwĩtharei na mũtikagonderere! Ririkanagai Jehova mũrĩ bũrũri wa kũraya, na mwĩciiragie ũhoro wa Jerusalemu.”
51 “Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn: ìtìjú ti bò wá lójú nítorí àwọn àjèjì wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”
“Nĩtũconorithĩtio, nĩgũkorwo nĩtũrumĩtwo, na tũkahumbwo thoni mothiũ maitũ, tondũ andũ a kũngĩ nĩmatoonyete kũndũ kũrĩa kwamũre thĩinĩ wa nyũmba ya Jehova.”
52 “Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fínfín rẹ̀, àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa kérora já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀.
Jehova ekuuga atĩrĩ, “Matukũ nĩmagooka rĩrĩa ngaaherithia mĩhianano yake, nao andũ arĩa agurarie kũu bũrũri-inĩ ũcio guothe nĩmagacaaya.
53 Bí Babeli tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run, bí ó sì ṣe ìlú olódi ní òkè agbára rẹ, síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,” ní Olúwa wí.
O na kũngĩtuĩka Babuloni gwĩtũũgĩrĩtie gũgakinya o matu-inĩ, na ciĩhitho ciakuo ikairigĩrwo na hinya mũno-rĩ, no ngaakũrehithĩria aniinani magũũkĩrĩre,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
54 “Ìró igbe láti Babeli, àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kaldea!
“Mũgambo wa kĩrĩro nĩũraiguuo kũu Babuloni; nĩ mũgambo wa kũniinanwo ũraiguuo kũu bũrũri wa andũ a Babuloni.
55 Nítorí pé Olúwa ti ṣe Babeli ní ìjẹ, ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀; àwọn ọ̀tá wọn sì ń hó bi omi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.
Jehova nĩakaniina Babuloni; nĩagakiria inegene rĩu inene rĩakuo. Makũmbĩ ma thũ makaahũũyũka taarĩ mũrurumo wa maaĩ maingĩ. Mũrurumo wa mĩgambo yao nĩĩkaiguuagwo.
56 Nítorí pé afiniṣèjẹ dé sórí rẹ̀, àní sórí Babeli; a mú àwọn akọni rẹ̀, a ṣẹ́ gbogbo ọrun wọn: nítorí Ọlọ́run ẹ̀san ni Olúwa, yóò san án nítòótọ́.
Mũniinani nĩagookĩrĩra Babuloni; njamba ciakuo iria irĩ hinya nĩikaanyiitwo, namo mota mao moinangwo. Nĩ ũndũ Jehova nĩ Mũrungu ũrĩhanagĩria; we akaarĩhanĩria biũ.
57 Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí, àti àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀ àti àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti àwọn akọni rẹ̀, wọn ó sì sun oorun láéláé, wọn kì ó sì jí mọ́,” ní ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Anene akuo, na andũ arĩa ogĩ, o na abarũthi akuo, o ũndũ ũmwe na anene akuo, o na njamba ciakuo iria irĩ hinya, othe nĩngatũma marĩĩo nĩ njoohi; magaakoma nginya tene, na matiũkĩre,” nĩguo Mũthamaki ekuuga, o we ũrĩa rĩĩtwa rĩake arĩ Jehova Mwene-Hinya-Wothe.
58 Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Odi Babeli gbígbòòrò ní a ó wó lulẹ̀ pátápátá, ẹnu-bodè gíga rẹ̀ ní a ó sì fi iná sun: tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn ti ṣiṣẹ́ lásán, àti àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣiṣẹ́ fún iná, tí àárẹ̀ sì mú wọn.”
Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekuuga atĩrĩ: “Rũthingo rwa Babuloni rũrĩa rwariĩ nĩrũkangʼaũranio biũ, nacio ihingo ciakuo iria ndaaya na igũrũ icinwo na mwaki; andũ menogagia tũhũ, naguo wĩra wa ndũrĩrĩ no ngũ cia gũcinwo na mwaki.”
59 Ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì pàṣẹ fún Seraiah, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, nígbà tí o ń lọ ni ti Sedekiah, ọba Juda, sí Babeli ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Seraiah yìí sì ní ìjòyè ibùdó.
Ĩno nĩo ndũmĩrĩri ĩrĩa Jeremia aaheire Seraia mũrũ wa Neria, mũrũ wa Maaseia, o ũcio warĩ mũnene ũrĩa mũrori wa maũndũ ma nyũmba ya mũthamaki, rĩrĩa aathiire Babuloni marĩ na Zedekia mũthamaki wa Juda mwaka-inĩ wa ĩna wa ũthamaki wake.
60 Jeremiah sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Babeli sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí a kọ sí Babeli.
Jeremia nĩandĩkĩte ibuku-inĩ rĩa gĩkũnjo ũhoro wothe ũkoniĩ mwanangĩko ũrĩa ũgaakinyĩrĩra Babuloni: maũndũ marĩa mothe maandĩkĩtwo makoniĩ Babuloni.
61 Jeremiah sì sọ fún Seraiah pé, “Nígbà tí ìwọ bá dé Babeli, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
Jeremia akĩĩra Seraia atĩrĩ, “Wakinya Babuloni-rĩ, ũgaatigĩrĩra atĩ nĩwathoma mohoro maya mothe wanĩrĩire.
62 Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’
Ũcooke uuge atĩrĩ, ‘Wee Jehova, nĩugĩte nĩũkũniina kũndũ gũkũ, nĩgeetha gũtikanatũũrwo nĩ mũndũ, o na kana nyamũ; gũgũtũũra gũkirĩte ihooru nginya tene.’
63 Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárín odò Eufurate.
Warĩkia gũthoma ibuku rĩu rĩa gĩkũnjo-rĩ, ũrĩoherere ihiga, ũrĩikie Rũũĩ rwa Farati.
64 Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Babeli yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’” Títí dé ìhín ni ọ̀rọ̀ Jeremiah.
Ũcooke uuge atĩrĩ, ‘Ũguo noguo Babuloni gũkaarikĩra kũũrĩre biũ, na gũtigacooka kuumĩra na igũrũ, nĩ ũndũ wa mwanangĩko ũrĩa ngaakũrehithĩria. Nao andũ akuo nĩmakaagũa.’” Ũhoro wa Jeremia ũkinyĩte hau.

< Jeremiah 51 >